< Micah 6 >

1 Ẹ fi etí sí ohun tí Olúwa wí: “Dìde dúró, bẹ ẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ rẹ níwájú òkè ńlá; sì jẹ́ kí àwọn òkè kéékèèké gbọ́ ohun tí ó fẹ́ wí.
Auziți acum ce spune DOMNUL: Ridică-te și luptă-te înaintea munților și dealurile să îți audă vocea.
2 “Gbọ́, ìwọ òkè ńlá, ẹ̀sùn Olúwa; gbọ́, ìwọ ìpìlẹ̀ ilé ayérayé. Nítorí Olúwa ń bá àwọn ènìyàn rẹ̀ wíjọ́; òun yóò sì bá Israẹli rojọ́.
Auziți, voi, munților, și voi, temelii tari ale pământului, cearta DOMNULUI; fiindcă DOMNUL are o ceartă cu poporul lui și el, cu Israel, se va judeca.
3 “Ẹ̀yin ènìyàn mi, kí ni mo ṣe fún yín? Àti nínú kí ni mo ti dá yin lágara? Dá mi lóhùn.
Poporul meu, ce ți-am făcut eu ție? Și cu ce te-am obosit eu? Adu mărturie împotriva mea.
4 Nítorí èmi mú un yín gòkè láti ilẹ̀ Ejibiti wá, mo sì rà yín padà láti ilẹ̀ ẹrú wá. Mo rán Mose láti darí yín, bákan náà mo rán Aaroni àti Miriamu síwájú rẹ̀.
Fiindcă te-am scos din țara Egiptului și te-am răscumpărat din casa servitorilor; și i-am trimis înaintea ta pe Moise, Aaron și Miriam.
5 Ìwọ ènìyàn mi, rántí ohun tí Balaki ọba Moabu gbèrò àti ohun tí Balaamu ọmọ Beori dáhùn. Rántí ìrìnàjò rẹ̀ láti Ṣittimu dé Gilgali, kí ìwọ ba le mọ òdodo Olúwa.”
Poporul meu, amintește-ți acum ce sfat a cerut Balac, împăratul Moabului, și ce i-a răspuns Balaam, fiul lui Beor, de la Sitim până la Ghilgal; ca voi să cunoașteți dreptatea DOMNULUI.
6 Kí ni èmi yóò ha mú wá síwájú Olúwa tí èmi ó fi tẹ ara mi ba níwájú Ọlọ́run gíga? Kí èmi ha wá sí iwájú rẹ̀ pẹ̀lú ọrẹ ẹbọ sísun, pẹ̀lú ọmọ màlúù ọlọ́dún kan?
Cu ce să vin eu înaintea DOMNULUI, să mă plec înaintea preaînaltului Dumnezeu? Să vin înaintea lui cu ofrande arse, cu viței de un an?
7 Ǹjẹ́ Olúwa yóò ní inú dídùn sí ẹgbẹgbàarùn-ún àgbò, tàbí sí ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ìṣàn òróró? Èmi yóò ha fi àkọ́bí mi sílẹ̀ fún ìré-òfin-kọjá mi, èso inú ara mi fún ẹ̀ṣẹ̀ ọkàn mi?
Va fi DOMNUL mulțumit cu mii de berbeci sau cu zeci de mii de râuri de untdelemn? Să dau pe întâiul meu născut pentru încălcarea mea, rodul trupului meu pentru păcatul sufletului meu?
8 Ó ti fihàn ọ́, ìwọ ènìyàn, ohun tí ó dára, àti ohun tí Olúwa ń béèrè lọ́wọ́ rẹ? Bí kò ṣe láti ṣe òtítọ́, kí o sì fẹ́ràn àánú, àti kí o rìn ní ìrẹ̀lẹ̀ pẹ̀lú Ọlọ́run rẹ̀.
El ți-a arătat, omule, ce este bine; și ce cere DOMNUL de la tine [altceva] decât să faci ce este drept și să iubești mila și să umbli umil cu Dumnezeul tău?
9 Gbọ́! Ohùn Olúwa kígbe sí ìlú ńlá náà, láti jẹ ọlọ́gbọ́n ni láti bẹ̀rù orúkọ rẹ. “Ẹ kíyèsi ọ̀pá rẹ̀ gbọ́ ọ̀pá àti Ẹni náà tí ó yàn án.
Vocea DOMNULUI strigă către cetate, și omul înțelepciunii va vedea numele tău. Ascultați de nuia, și pe cel ce a rânduit-o.
10 Ǹjẹ́ ìṣúra ìwà búburú ha wà ní ilé ènìyàn búburú síbẹ̀, àti òsùwọ̀n àìkún tí ó jẹ́ ohun ìbínú?
Mai sunt tezaurele stricăciunii în casa celui stricat și o blestemată efă mică?
11 Ǹjẹ́ èmi ha lè kà wọ́n sí mímọ́ pẹ̀lú òsùwọ̀n búburú, pẹ̀lú àpò òsùwọ̀n ẹ̀tàn?
Să îi socotesc puri pe cei cu balanțele stricăciunii și cu punga plină cu greutăți înșelătoare?
12 Àwọn ọlọ́rọ̀ inú rẹ̀ kún fún ìwà ipá; àwọn tí ń gbé inú rẹ̀ ti ọ̀rọ̀ èké àti ahọ́n wọn ń sọ ẹ̀tàn?
Fiindcă bogații ei sunt plini de violență și locuitorii ei au spus minciuni și limba din gura lor este înșelătoare.
13 Nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ ṣàìsàn ní lílù ọ́, láti sọ ọ́ dahoro nítorí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ.
De aceea te voi îmbolnăvi de asemenea lovindu-te, pustiindu-te datorită păcatelor tale.
14 Ìwọ yóò jẹun ṣùgbọ́n kì yóò yó; ìyàn yóò wà láàrín rẹ. Ìwọ yóò kó pamọ́, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò lò láìléwu, nítorí ohun tí ìwọ kò pamọ́ ni èmi yóò fi fún idà.
Vei mânca dar nu te vei sătura; și în mijlocul tău va fi doborârea ta; și tu vei apuca dar nu vei salva; și ce salvezi, eu voi da sabiei.
15 Ìwọ yóò gbìn ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò kórè ìwọ yóò tẹ olifi, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò fi òróró rẹ̀ kún ara rẹ; ìwọ yóò tẹ èso àjàrà, ṣùgbọ́n ìwọ kì yóò mu wáìnì.
Vei semăna, dar nu vei secera; tu vei călca măslinele, dar nu tu te vei unge cu untdelemn; și vin dulce, dar nu tu vei bea vin.
16 Nítorí tí ìwọ ti pa òfin Omri mọ́, àti gbogbo iṣẹ́ ilé Ahabu, tí ó sì ti tẹ̀lé ìmọ̀ràn wọn, nítorí náà ni èmi yóò ṣe mú ọ fún ìparun àti àwọn ènìyàn rẹ fún ìfiṣe ẹlẹ́yà; ìwọ yóò sì ru ẹ̀gàn àwọn ènìyàn mi.”
Fiindcă statutele lui Omri sunt ținute, și toate lucrările casei lui Ahab, și voi umblați în sfaturile lor; căci te voi face o ruină și pe locuitorii acesteia, o șuierare; de aceea veți purta ocara poporului meu.

< Micah 6 >