< Mark 7 >
1 Àwọn Farisi sì péjọ sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, àti àwọn kan nínú àwọn akọ̀wé, tí ó wá láti Jerusalẹmu,
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲑⲱⲟⲩϯ ϩⲁⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲪⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲓⲥⲁϧ ⳿ⲉⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ Ⲓⲗ̅ⲏ̅ⲙ̅.
2 wọ́n sì ṣe àkíyèsí wí pé díẹ̀ nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Jesu ń fi ọwọ́ àìmọ́ jẹun, èyí yìí ni wẹ ọwọ́.
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉϩⲁⲛⲟⲩⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϫⲉ ⲥⲉⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲛⲛⲓⲱⲓⲕ ⳿ⲉⲣⲉ ⲛⲟⲩϫⲓϫ ⲑⲱⲗⲉⲃ ⳿ⲉⲧⲉ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ϫⲉ ⳿ⲛⲁⲧⲓⲁ ⲧⲟⲧⲟⲩ.
3 (Àwọn Farisi, àti gbogbo àwọn Júù, bí wọ́n kò bá wẹ ọwọ́ wọn gidigidi, wọn kì í jẹun nítorí wọ́n ti pa òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn àgbà mọ́.
ⲅ̅ⲛⲓⲪⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⲅⲁⲣ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲒⲟⲩⲇⲁⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲙⲡⲁⲩⲟⲩⲱⲙ ⲁⲩ⳿ϣⲧⲉⲙⲓⲁ ⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲥⲟⲡ ⲉⲩ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛϯⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓ⳿ⲡⲣⲉⲥⲃⲩⲧⲉⲣⲟⲥ.
4 Nígbà tí wọ́n bá sì ti ọjà dé sílé, wọn kò gbọdọ̀ fi ọwọ́ kan oúnjẹ àfi tí wọ́n bá bu omi wẹ ara wọn. Èyí sì jẹ́ ọ̀kan nínú ogunlọ́gọ̀ àpẹẹrẹ òfin àti ìlànà tí wọ́n ti dì mú fún ọ̀pọ̀lọpọ̀ ọdún sẹ́yìn, bí i fífọ kọ́ọ̀bù, àwọn ìkòkò, àti kẹ́tù.)
ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⲁⲩ⳿ϣⲧⲉⲙⲟⲙⲥⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ϯ⳿ⲁⲅⲟⲣⲁ ⳿ⲙⲡⲁⲩⲟⲩⲱⲙ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ ϩⲁⲛⲕⲉⲙⲏϣ ⳿ⲉⲁⲩϭⲓⲧⲟⲩ ⲉⲩ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ϩⲁⲛⲱⲙⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ϩⲁⲛ⳿ⲁⲫⲟⲧ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲝⲉⲥⲧⲏⲥ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲭⲁⲗⲕⲓⲟⲛ.
5 Nítorí èyí àwọn Farisi àti àwọn olùkọ́ òfin béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ pé, “Èéṣe tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò tẹ̀lé àwọn òfin àtọwọ́dọ́wọ́ àwọn àgbà nítorí wọ́n fi ọwọ́ àìmọ́ jẹun?”
ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϣⲉⲛϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲪⲁⲣⲓⲥⲉⲟⲥ ⲛⲉⲙ ⲛⲓⲥⲁϧ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⲥⲉⲙⲟϣⲓ ⲁⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉⲕⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⲕⲁⲧⲁ ϯⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓ⳿ⲡⲣⲉⲥⲃⲩⲧⲉⲣⲟⲥ ⲁⲗⲗⲁ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛϫⲓϫ ⲉⲩⲑⲱⲗⲉⲃ ⲥⲉⲟⲩⲱⲙ ⳿ⲙⲡⲓⲱⲓⲕ.
6 Jesu dá wọn lóhùn wí pé, “Ẹyin àgàbàgebè yìí, òtítọ́ ni wòlíì Isaiah ń sọtẹ́lẹ̀ nípa tí ẹ̀yin àgàbàgebè, bí a ti kọ ọ́ pé: “‘Àwọn ènìyàn wọ̀nyí fi ẹnu wọn bu ọlá fún mi ṣùgbọ́n ọkàn wọn jìnà sí mi.
ⲋ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⲁϥⲉⲣ⳿ⲡⲣⲟⲫⲏⲧⲉⲩⲓⲛ ⲉⲑⲃⲉ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ Ⲏ̇ⲥⲁ⳿ⲏⲁⲥ ϧⲁ ⲛⲓϣⲟⲃⲓ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⲉⲧ⳿ⲥϧⲏⲟⲩⲧ ϫⲉ ⲡⲁⲓⲗⲁⲟⲥ ⲉⲣⲧⲓⲙⲁⲛ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ϧⲉⲛ ⲛⲟⲩ⳿ⲥⲫⲟⲧⲟⲩ ⲡⲟⲩϩⲏⲧ ⲇⲉ ⳿ϥⲟⲩ⳿ⲏⲟⲩ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲟⲓ.
7 Ìsìn wọn jẹ́ lásán, ìkọ́ni wọ́n jẹ́ kìkìdá òfin tí àwọn ènìyàn fi ń kọ́ni.’
ⲍ̅ⲉⲩⲉⲣⲥⲉⲃⲉⲥⲑⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲓ ⳿ⲉ⳿ⲫⲗⲏⲟⲩ ⲉⲩϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲛϩⲟⲛϩⲉⲛ ⳿ⲛⲣⲱⲙⲓ.
8 Nítorí tí ẹ̀yin fi òfin Ọlọ́run sí apá kan, ẹ̀yin ń tẹ̀lé àṣà àwọn ènìyàn.”
ⲏ̅⳿ⲉⲁⲧⲉⲧⲉⲛⲭⲁ ϯⲉⲛⲧⲟⲗⲏ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⳿ⲛⲥⲁ ⲑⲏⲛⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛϯⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ϩⲁⲛⲱⲙⲥ ⳿ⲛⲧⲉ ϩⲁⲛ⳿ⲁⲫⲟϯ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛⲝⲉⲥⲧⲏⲥ ⲛⲉⲙ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲉϥⲟϣ.
9 Ó si wí fún wọn: “Ẹ̀yin sá à mọ̀ bí ẹ ti ń gbé òfin Ọlọ́run jù sẹ́yìn kí ẹ lè mú òfin tiyín ṣẹ.
ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣ⳿ⲁⲑⲉⲧⲓⲛ ⳿ⲛϯⲉⲛⲧⲟⲗⲏ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲁⲣⲉϩ ⳿ⲉⲛⲉⲧⲉⲛⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ.
10 Mose fún un yín ní òfin yìí láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run pé, ‘Bọ̀wọ̀ fún baba òun ìyá rẹ.’ Ó tún sọ pé, ‘Ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ̀rọ̀ aburú sí baba tàbí ìyá rẹ̀ ní láti kú ni.’
ⲓ̅Ⲙⲱ⳿ⲩⲥⲏⲥ ⲅⲁⲣ ⲁϥϫⲟⲥ ϫⲉ ⲙⲁⲧⲁⲓ⳿ⲉ ⲡⲉⲕⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉⲕⲙⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏⲉⲑⲛⲁⲥⲁϫⲓ ⲉϥϩⲱⲟⲩ ⳿ⲛⲥⲁ ⲡⲉϥⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ⲙⲁⲣⲉϥⲙⲟⲩ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲟⲩ.
11 Ṣùgbọ́n ẹ̀yin wá sọ pé ó dára bákan náà fún ọkùnrin kan bí kò bá tilẹ̀ pèsè fún àìní àwọn òbí rẹ̀, ṣùgbọ́n kí o sọ fún wọn pé, ‘Ẹ má ṣe bínú baba tàbí ìyá mi, n kò lè ràn yín lọ́wọ́ nísinsin yìí,’ nítorí tí mo ti fi ẹ̀bùn tí ǹ bá fi fún un yín fún Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲁ̅⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⲇⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲁⲣⲉϣⲁⲛ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ϫⲟⲥ ⳿ⲙⲡⲉϥⲓⲱⲧ ⲛⲉⲙ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ ϫⲉ ⲕⲟⲣⲃⲁⲛ ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲧⲁⲓ⳿ⲟ ⲡⲉ ⲁⲕϣⲁⲛϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲟⲓ.
12 Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò si jẹ́ kí ó ṣe ohunkóhun fún baba tàbí ìyá rẹ̀ mọ́.
ⲓ̅ⲃ̅⳿ⲛⲧⲉⲧⲉⲛⲭⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲁⲛ ⳿ⲉⲉⲣ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥⲓⲱⲧ ⲓⲉ ⲧⲉϥⲙⲁⲩ.
13 Ẹ̀yin ń fi òfin àtọwọ́dọ́wọ́ tiyín tí ẹ fi lélẹ̀, sọ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run di asán àti ọ̀pọ̀ irú nǹkan bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin ń ṣe.”
ⲓ̅ⲅ̅⳿ⲉⲣⲉⲧⲉⲛⲕⲱⲣϥ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ϧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲡⲁⲣⲁⲇⲟⲥⲓⲥ ⲑⲏ⳿ⲉⲧⲁⲣⲉⲧⲉⲛⲧⲏⲓⲥ ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲙⲏϣ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲉⲩ⳿ⲟⲛⲓ ⳿ⲛⲛⲁⲓ ⲧⲉⲧⲉⲛⲣⲁ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ.
14 Lẹ́yìn náà, Jesu pe ọ̀pọ̀ ènìyàn láti wá gbọ́ ọ̀rọ̀ rẹ̀. Ó sì wí fún wọn pé, “Gbogbo yín ẹ tẹ́tí sílẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí èyí ó yé e yín.
ⲓ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲙⲟⲩϯ ⲟⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲙⲏϣ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲥⲱⲧⲉⲙ ϫⲉ ⳿ⲉⲣⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲕⲁϯ.
15 Kò sí ohunkóhun láti òde ènìyàn, tí ó wọ inú rẹ̀ lọ, tí ó lè sọ ọ́ di aláìmọ́, ṣùgbọ́n àwọn nǹkan tí ó ti inú rẹ jáde, àwọn wọ̀nyí ní ń sọ ènìyàn di aláìmọ́.”
ⲓ̅ⲉ̅⳿ⲙⲙⲟⲛ ⳿ϩⲗⲓ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲉϥⲛⲁ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲱϥ ⳿ⲉⲟⲩⲟⲛ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲥⲟϥϥ ⲁⲗⲗⲁ ⲛⲏⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲣⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⲛⲏⲉⲧⲥⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ.
ⲓ̅ⲋ̅ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲙⲁϣϫ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⲙⲁⲣⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ.
17 Nígbà tí Jesu sì wọ inú ilé kan lọ, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn tẹ̀lé é, wọ́n sì béèrè ìtumọ̀ àwọn òwe tí ó pa.
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲟⲧⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲏⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲁ ⲡⲓⲙⲏϣ ⲛⲁⲩϣⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ⳿ⲉϯⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ.
18 Jesu béèrè wí pé, “Àbí kò sí èyí tí ó yé yín nínú ọ̀rọ̀ náà? Ẹ̀yin kò rí i wí pé ohunkóhun tí ó wọ inú ènìyàn láti òde kò lè sọ ènìyàn di aláìmọ́?
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ϩⲁⲛⲁⲧⲕⲁϯ ϩⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲉⲛⲕⲁϯ ϫⲉ ϩⲱⲃ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⲉⲧⲥⲁⲃⲟⲗ ⲉⲑⲛⲁ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲛ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲥⲟϥϥ.
19 Nítorí tí kò lọ sínú ọkàn rẹ̀, ṣùgbọ́n sínú ara, a sì yà á jáde, a sì gbá gbogbo oúnjẹ dànù.” (Nípa sísọ èyí, Jesu fihàn pé gbogbo oúnjẹ jẹ́ “mímọ́.”)
ⲓ̅ⲑ̅ϫⲉ ⲥⲉⲛⲁ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲉϥϩⲏⲧ ⲁⲛ ⲁⲗⲗⲁ ⳿ⲉⲧⲉϥⲛⲉϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁⲩϣⲉⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲛⲓⲙⲁⲛϩⲉⲙⲥⲓ ⲉϥⲧⲟⲩⲃⲟ ⳿ⲛⲛⲓ⳿ϧⲣⲏⲟⲩ⳿ⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ.
20 Nígbà náà, ó fi kún un pé, “Èyí ti ó ti ọkàn ènìyàn jáde ni ń sọ ni di aláìmọ́.
ⲕ̅ⲛⲁϥϫⲱ ⲇⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲡⲉⲑⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲉⲧⲥⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ.
21 Nítorí pé láti inú ọkàn ènìyàn ni àwọn èrò búburú wọ̀nyí ti ń jáde wá: àgbèrè, olè, ìpànìyàn, panṣágà,
ⲕ̅ⲁ̅⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲅⲁⲣ ⲥⲁϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓϩⲏⲧ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲣⲱⲙⲓ ϣⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲙⲟⲕⲙⲉⲕ ⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲛⲓⲡⲟⲣⲛⲓ⳿ⲁ ⲛⲓϭⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⲛⲓϧⲱⲧⲉⲃ.
22 ọ̀kánjúwà, odì yíyàn, ìtànjẹ, ìmọ-tara-ẹni, ìlara, ọ̀rọ̀ ẹ̀yìn, ìgbéraga, òmùgọ̀.
ⲕ̅ⲃ̅ⲛⲓⲙⲉⲧⲛⲱⲓⲕ ⲛⲓⲙⲉⲧϭⲓ⳿ⲛϫⲟⲛⲥ ⲛⲓⲙⲉⲧⲡⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲛⲓⲙⲉⲧⲇⲟⲗⲟⲥ ⲛⲓⲥⲱϥ ⲛⲓⲃⲁⲗ ⲉⲧϩⲱⲟⲩ ⲛⲓϫⲉⲟⲩ⳿ⲁ ⲟⲩϭⲓⲥⲓ ⳿ⲛϩⲏⲧ ⲟⲩⲙⲉⲧⲁⲧⲕⲁϯ.
23 Gbogbo àwọn nǹkan búburú wọ̀nyí ń tí inú wá, àwọn ló sì ń sọ yín di aláìmọ́.”
ⲕ̅ⲅ̅ⲛⲁⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲉⲩϩⲱⲟⲩ ⲉⲩⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲥⲁϧⲟⲩⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲉⲥⲱϥ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲱⲙⲓ.
24 Nígbà náà ni Jesu kúrò ní Galili, ó sí lọ sí agbègbè Tire àti Sidoni, ó sì gbìyànjú láti nìkan wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ fún àkókò díẹ̀, ṣùgbọ́n eléyìí kò ṣe é ṣe, nítorí pé kò pẹ́ púpọ̀ tí ó wọ ìlú nígbà tí ìròyìn dídé rẹ̀ tàn káàkiri.
ⲕ̅ⲇ̅⳿ⲉⲧⲁϥⲧⲱⲛϥ ⲇⲉ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉⲛⲓⲥⲁ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲧⲩⲣⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲧ̇ⲥⲓⲇⲱⲛ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲟⲩⲏⲓ ⲛⲁϥⲟⲩⲱϣ ⲁⲛ ⲡⲉ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ϣϫⲉⲙϫⲟⲙ ⳿ⲛⲭⲟⲡϥ.
25 Láìpẹ́, obìnrin kan tí ọmọbìnrin rẹ̀ ní ẹ̀mí àìmọ́ tọ̀ ọ́ wá, ó ti gbọ́ nípa Jesu, ó wá, ó sì wólẹ̀ lẹ́sẹ̀ Jesu.
ⲕ̅ⲉ̅ⲁⲗⲗⲁ ⲥⲁⲧⲟⲧⲥ ⲁⲥⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲉⲑⲃⲏⲧϥ ⲑⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲕⲁⲑⲁⲣⲧⲟⲛ ⲛⲉⲙ ⲧⲉⲥϣⲉⲣⲓ ⳿ⲉⲧⲁⲥ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲁⲥϩⲓⲧⲥ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲁ ⲛⲉϥϭⲁⲗⲁⲩϫ.
26 Giriki ní obìnrin náà, Siro-Fonisia ní orílẹ̀-èdè rẹ̀. Ó bẹ Jesu kí ó bá òun lé ẹ̀mí èṣù náà jáde lára ọmọbìnrin òun.
ⲕ̅ⲋ̅ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲇⲉ ⲛⲉ Ⲟⲩⲉⲓⲛⲓⲛ ⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲧ̇ⲥⲩⲣⲓ⳿ⲁ ⲡⲉⲥⲅⲉⲛⲟⲥ ⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ϯⲪⲟⲓⲛⲓⲕⲏ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲥϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲡⲉ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥϩⲓ ⲡⲓⲇⲉⲙⲱⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϧⲉⲛ ⲧⲉⲥϣⲉⲣⲓ.
27 Jesu sọ fún obìnrin yìí pé, “Ní àkọ́kọ́, ó yẹ kí a fi oúnjẹ tẹ́ àwọn ọmọ lọ́rùn ná. Nítorí kò tọ́ kí a mú oúnjẹ àwọn ọmọ fún àwọn ajá.”
ⲕ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲭⲁⲥ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲥⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓϣⲏⲣⲓ ϫⲉ ⲟⲩⲏⲓ ⲅⲁⲣ ⲛⲁⲛⲉⲥ ⲁⲛ ⳿ⲉⲉⲗ ⳿ⲡⲱⲓⲕ ⳿ⲛⲛⲓϣⲏⲣⲓ ⳿ⲉⲧⲏⲓϥ ⳿ⲛⲛⲓⲟⲩϩⲱⲣ.
28 Obìnrin náà dáhùn wí pé, “Òótọ́ ni ọ̀rọ̀ yín Olúwa, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ ajá pàápàá a máa ní àǹfààní láti jẹ èérún oúnjẹ tí ó bá bọ́ sílẹ̀ láti orí tábìlì.”
ⲕ̅ⲏ̅⳿ⲛⲑⲟⲥ ⲇⲉ ⲁⲥⲉⲣⲟⲩ⳿ⲱ ⲡⲉϫⲁⲥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲥⲉ Ⲡⲁ⳪ ⲛⲓⲕⲉⲟⲩϩⲱⲣ ⲥⲉⲟⲩⲱⲙ ⲥⲁ ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϯ⳿ⲧⲣⲁⲛⲉⲍⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲓⲗⲉϥⲗⲓϥⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓ⳿ⲁⲗⲱⲟⲩ⳿ⲓ.
29 “Ó sì wí fún un pé, nítorí ọ̀rọ̀ yìí, máa lọ, ẹ̀mí àìmọ́ náà ti jáde kúrò lára ọmọbìnrin rẹ.”
ⲕ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲁⲓⲥⲁϫⲓ ⲙⲁϣⲉⲛⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓ ⲧⲉϣⲉⲣⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲇⲉⲙⲱⲛ.
30 Nígbà tí ó padà dé ilé, ó bá ọmọbìnrin rẹ̀ ní ìdùbúlẹ̀ jẹ́jẹ́ lórí ibùsùn, ẹ̀mí àìmọ́ náà ti fi í sílẹ̀.
ⲗ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲥϣⲉⲛⲁⲥ ⳿ⲉⲡⲉⲥⲏⲓ ⲁⲥϫⲉⲙ ϯ⳿ⲁⲗⲟⲩ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓϭⲗⲟϫ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲓⲇⲉⲙⲱⲛ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ϩⲓⲱⲧⲥ.
31 Nígbà náà ni Jesu fi agbègbè Tire àti Sidoni sílẹ̀, ó wá si Òkun Galili láàrín agbègbè Dekapoli.
ⲗ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⲟⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲓⲑⲟϣ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲧⲩⲣⲟⲥ ⲁϥⲥⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲉⲛ ⳿Ⲧ̇ⲥⲓⲇⲱⲛ ⳿ⲉ⳿ⲫⲓⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲄⲁⲗⲓⲗⲉ⳿ⲁ ⲟⲩⲧⲉ ⲛⲓⲑⲟϣ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲏϯ ⳿ⲙⲃⲁⲕⲓ.
32 Níbẹ̀ ọkùnrin kan tí kò lè sọ̀rọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ Jesu, àwọn ènìyàn sì bẹ Jesu pé kí ó gbé ọwọ́ rẹ̀ lé e.
ⲗ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓⲛⲓ ⲛⲁϥ ⳿ⲛⲟⲩⲕⲟⲩⲣ ⳿ⲛⲉⲃⲟ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥⲭⲁ ϫⲓϫ ϩⲓϫⲱϥ.
33 Jesu sì mú ọkùnrin náà kúrò láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn. Ó sì fi àwọn ìka rẹ̀ sí etí ọkùnrin náà, ó tu itọ́ ṣọ́wọ́. Ó sì fi kan ahọ́n rẹ̀.
ⲗ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲟⲗϥ ⲥⲁ⳿ⲡⲥⲁ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲁ ⲡⲓⲙⲏϣ ⲁϥϩⲓ ⲛⲉϥⲧⲏⲃ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿⳿ⲉⲛⲉϥⲙⲁϣϫ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϩⲓⲑⲁϥ ⲁϥϭⲓⲛⲉⲙ ⲡⲉϥⲗⲁⲥ.
34 Nígbà náà ni Jesu wòkè ọ̀run, ó sì mí kanlẹ̀, ó sì pàṣẹ wí pé, “Efata!” (èyí ni, “Ìwọ ṣí!”).
ⲗ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϫⲟⲩϣⲧ ⳿ⲉ⳿ⲡϣⲱⲓ ⳿ⲉ⳿ⲧⲫⲉ ⲁϥϥⲓ⳿ⲁϩⲟⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲉⲫⲫⲁⲑⲁ ⳿ⲉⲧⲉ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ϫⲉ ⳿ⲁⲟⲩⲱⲛ.
35 Lójúkan náà, etí rẹ̀ sì ṣí, okùn ahọ́n rẹ̀ sì tú, ó sì ń sọ̀rọ̀ ketekete.
ⲗ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲟⲩⲱⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϯⲟⲩ⳿ⲱ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓ⳿ⲥⲛⲁϩ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉϥⲗⲁⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲥⲁϫⲓ ⲡⲉ ⲉϥⲥⲟⲩⲧⲱⲛ.
36 Jesu pàṣẹ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn tó wà níbẹ̀ pé kí wọn má ṣe tan ìròyìn náà ká. Ṣùgbọ́n bí ó ti ń pa wọ́n lẹ́nu mọ́ tó, náà ni wọ́n ń tan ìròyìn náà káàkiri tó.
ⲗ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲟⲧⲟⲩ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲟⲩ⳿ϣⲧⲉⲙϫⲟⲥ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ϩⲱⲥⲧⲉ ⳿ⲉⲧⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⲛⲁⲩϩⲓⲱⲓϣ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ.
37 Àwọn ènìyàn sì kún fún ìyanu, wọ́n wí pé, “Ó ṣe ohun gbogbo dáradára, Ó mú kí adití gbọ́rọ̀, odi sì sọ̀rọ̀.”
ⲗ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ ⲛⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲕⲁⲗⲱⲥ ⲁϥⲁⲓⲧⲟⲩ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲑⲣⲉ ⲛⲓⲕⲟⲩⲣ ⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲁⲧⲥⲁϫⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲥⲁϫⲓ