< Mark 6 >

1 Jesu fi ibẹ̀ sílẹ̀ lọ sí ìlú rẹ̀ pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲘⲀⲨ ⲀϤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲦⲈϤⲂⲀⲔⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ ⲚϪⲈⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ
2 Nígbà tí ó di ọjọ́ ìsinmi, ó lọ sí Sinagọgu láti kọ́ àwọn ènìyàn, ẹnu sì ya àwọn ènìyàn púpọ̀ tí ó gbọ́. Wọ́n wí pé, “Níbo ni ọkùnrin yìí gbé ti rí nǹkan wọ̀nyí? Irú ọgbọ́n kí ni èyí tí a fi fún un, tí irú iṣẹ́ ìyanu báyìí ń ti ọwọ́ rẹ̀ ṣe?
ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲚϪⲈⲞⲨⲤⲀⲂⲂⲀⲦⲞⲚ ⲀϤⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲚϮⲤⲂⲰ ϦⲈⲚϮⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲎ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲈⲦⲀ ⲪⲀⲒ ϪⲈⲘ ⲚⲀⲒ ⲐⲰⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨ ⲦⲈ ⲦⲀⲒⲤⲞⲪⲒⲀ ⲈⲦⲀⲨⲦⲎⲒⲤ ⲘⲪⲀⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲀⲒⲔⲈϪⲞⲘ ⲘⲠⲀⲒⲢⲎϮ ⲈⲦϢⲞⲠ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲈⲚ ⲚⲈϤϪⲒϪ
3 Gbẹ́nàgbẹ́nà náà kọ́ yìí? Ọmọ Maria àti arákùnrin Jakọbu àti Josẹfu, Judasi àti Simoni? Àwọn arábìnrin rẹ̀ gbogbo ha kọ́ ni ó ń bá wa gbé níhìn-ín yìí?” Wọ́n sì kọsẹ̀ lára rẹ̀.
ⲅ̅ⲘⲎ ⲪⲀⲒ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲠⲒⲀⲘϢⲈ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲘⲀⲢⲒⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲤⲞⲚ ⲚⲒⲀⲔⲰⲂⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲒⲰⲤⲎⲦⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲒⲞⲨⲆⲀⲤ ⲚⲈⲘ ⲤⲒⲘⲰⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈϤⲤⲰⲚⲒ ⲚⲤϨⲒⲘⲒ ⲚⲀⲨϨⲀⲘⲚⲀⲒ ϨⲀⲢⲞⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲈⲢⲤⲔⲀⲚⲆⲀⲖⲒⲌⲈⲤⲐⲈ ⲚϦⲎⲦϤ.
4 Nígbà náà, Jesu wí fún wọn pé, “A máa ń bu ọlá fún wòlíì níbi gbogbo àfi ní ìlú ara rẹ̀ àti láàrín àwọn ìdílé àti àwọn ẹbí òun pàápàá.”
ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ϪⲈ ⲘⲘⲞⲚ ⲞⲨⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲈϤϢⲎϢ ⲈⲂⲎⲖ ϦⲈⲚⲦⲈϤⲂⲀⲔⲒ ⲚⲈⲘ ⲦⲈϤⲤⲨⲄⲄⲈⲚⲒⲀ ⲚⲈⲘ ⲠⲈϤⲎⲒ.
5 Nítorí àìgbàgbọ́ wọn, òun kò lè ṣe iṣẹ́ ìyanu ńlá láàrín wọn, àfi àwọn aláìsàn díẹ̀ tí ó gbé ọwọ́ lé lórí, tí wọ́n sì rí ìwòsàn.
ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈϤϢϪⲈⲘϪⲞⲘ ⲘⲘⲀⲨ ⲈⲒⲢⲒ ⲞⲨⲆⲈ ⲞⲨⲒ ⲚϪⲞⲘ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲢⲈϤϢⲰⲚⲒ ⲈⲀϤⲬⲀ ϪⲒϪ ⲈϪⲰⲞⲨ ⲀϤⲈⲢⲪⲀϦⲢⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
6 Ẹnu si yà á nítorí àìgbàgbọ́ wọn. Lẹ́yìn náà, Jesu lọ sí àárín àwọn ìletò kéékèèké, ó sì ń kọ́ wọn.
ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲈⲐⲂⲈ ⲦⲞⲨⲘⲈⲦⲀⲐⲚⲀϨϮ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲘⲞⲨϢϮ ⲚⲚⲒϮⲘⲒ ⲈⲦⲈⲘⲠⲔⲰϮ ⲈϤϮⲤⲂⲰ
7 Ó sì pe àwọn méjìlá náà sọ́dọ̀ rẹ̀, ó bẹ̀rẹ̀ sí rán wọn lọ ní méjì méjì, Ó sì fi àṣẹ fún wọn lórí ẹ̀mí àìmọ́.
ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲘⲞⲨϮ ⲈⲠⲒⲒⲂ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢϨⲎ ⲦⲤ ⲚⲞⲨⲞⲢⲠⲞⲨ ⲚⲂ ⲂⲞⲨⲞϨ ⲀϤϮⲈⲢϢⲒϢⲒ ⲚⲰⲞⲨ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲀⲢⲦⲞⲚ
8 O sọ fún wọn pé, wọn kò gbọdọ̀ mú ohunkóhun lọ́wọ́, àfi ọ̀pá ìtìlẹ̀ wọn. Wọn kò gbọdọ̀ mú oúnjẹ, àpò ìgbànú, tàbí owó lọ́wọ́.
ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲚⲰⲞⲨ ⲈϢⲦⲈⲘⲈⲖ ϨⲖⲒ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ϨⲒ ⲪⲘⲰⲒⲦ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲞⲨϢⲂⲰⲦ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲞⲨⲆⲈ ⲰⲒⲔ ⲞⲨⲆⲈ ⲠⲎⲢⲀ ⲞⲨⲆⲈ ϨⲞⲘⲦ ϦⲈⲚⲚⲈⲦⲈⲚⲘⲞϪϦ
9 Wọn kò tilẹ̀ gbọdọ̀ mú ìpààrọ̀ bàtà tàbí aṣọ lọ́wọ́.
ⲑ̅ⲀⲖⲖⲀ ⲈⲢⲈ ϨⲀⲚⲤⲀⲚⲆⲀⲖⲒⲞⲚ ⲦⲞⲒ ⲈⲢⲀⲦⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲢϮ ϢⲐⲎⲚ ⲤⲚⲞⲨϮ ϨⲒ ⲐⲎⲚⲞⲨ
10 Jesu wí pé, “Ẹ dúró sí ilé kan ní ìletò kan. Ẹ má ṣe sípò padà láti ilé dé ilé, nígbà tí ẹ bá wà ní ìlú náà.
ⲓ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲠⲒⲘⲀ ⲈⲦⲈⲦⲈⲚⲚⲀϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲞⲨⲎⲒ ⲘⲘⲞϤ ϢⲰⲠⲒ ⲘⲘⲀⲨ ϢⲀⲦⲈⲦⲈⲚⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲘⲀⲨ
11 Ẹnikẹ́ni tí kò bá sì gbà yín, tí kò sì gbọ́rọ̀ yín, nígbà tí ẹ̀yin bá jáde kúrò níbẹ̀, ẹ gbọn eruku ẹsẹ̀ yín síbẹ̀ fún ẹ̀rí fún wọn.”
ⲓ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲈⲚϤⲚⲀϢⲈⲠ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲀⲚ ⲞⲨⲆⲈ ⲚⲦⲞⲨϢⲦⲈⲘⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲰⲦⲈⲚ ⲀⲚ ⲈⲢⲈⲦⲈⲚⲚⲎⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲘⲀⲨ ⲚⲈϨ ⲠϢⲰⲒϢ ⲈⲦⲤⲀⲈϦⲢⲎⲒ ⲚⲚⲈⲦⲈⲚϬⲀⲖⲀⲨϪ ⲈⲂⲞⲖ ⲈⲨⲘⲈⲦⲘⲈⲐⲢⲈ ⲚⲰⲞⲨ.
12 Wọ́n jáde lọ láti wàásù ìrònúpìwàdà fún àwọn ènìyàn.
ⲓ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲀⲨϨⲒⲰⲒϢ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲤⲈⲈⲢⲘⲈⲦⲀⲚⲞⲒⲚ
13 Wọ́n lé ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn ẹ̀mí àìmọ́ jáde. Wọ́n sì ń fi òróró kun orí àwọn tí ara wọn kò dá, wọ́n sì mú wọn láradá.
ⲓ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϨⲒ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲆⲈⲘⲰⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲢⲈϤϢⲰⲚⲒ ⲚⲀⲨⲐⲰϨⲤ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲚⲚⲈϨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲈⲢⲪⲀϦⲢⲒ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
14 Láìpẹ́, ọba Herodu gbọ́ nípa Jesu, nítorí níbi gbogbo ni a ti ń sọ̀rọ̀ iṣẹ́ ìyanu rẹ̀. Ọba náà rò pé, “Johanu Onítẹ̀bọmi jíǹde kúrò nínú òkú, nítorí náà ni iṣẹ́ ìyanu ṣe ń ṣe láti ọwọ́ rẹ.”
ⲓ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚϪⲈⲠⲞⲨⲢⲞ ⲎⲢⲰⲆⲎ ⲤⲠⲈϤⲢⲀⲚ ⲄⲀⲢ ⲀϤⲞⲨⲞⲚϨϤ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲠⲒⲢⲈϤϮⲰⲘⲤ ⲀϤⲦⲰⲚϤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲎ ⲈⲐⲘⲰⲞⲨⲦ ⲈⲐⲂⲈⲪⲀⲒ ⲚⲒϪⲞⲘ ⲤⲈⲈⲢϨⲰⲂ ⲚϦⲎⲦϤ.
15 Àwọn mìíràn wí pé, “Elijah ní.” Àwọn mìíràn wí pé, “Wòlíì bí ọ̀kan lára àwọn àtijọ́ tó ti kú ló tún padà sáyé.”
ⲓ̅ⲉ̅ϨⲀⲚⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲆⲈ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲎⲖⲒⲀⲤ ⲠⲈ ϨⲀⲚⲔⲈⲬⲰⲞⲨⲚⲒ ⲆⲈ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲠⲢⲞⲪⲎⲦⲎⲤ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚⲞⲨⲀⲒ ⲚⲚⲒⲠⲢⲞⲪⲎ ⲦⲎⲤ ⲚⲀⲢⲬⲈⲞⲤ
16 Ṣùgbọ́n nígbà tí Herodu gbọ́ èyí, ó wí pé “Johanu tí mo tí bẹ́ lórí ni ó ti jíǹde kúrò nínú òkú.”
ⲓ̅ⲋ̅ⲈⲦⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲚϪⲈⲎⲢⲰⲆⲎⲤ ⲚⲀϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲪⲎ ⲀⲚⲞⲔ ⲈⲦⲀⲒⲈⲖ ⲦⲈϤⲚⲀϨⲂⲒ ⲚⲐⲞϤ ⲠⲈⲦⲀϤⲦⲰⲚϤ.
17 Herodu fúnra rẹ̀ sá ti ránṣẹ́ mú Johanu, tìkára rẹ̀ sínú túbú nítorí Herodia aya Filipi arákùnrin rẹ̀ nítorí tí ó fi ṣe aya.
ⲓ̅ⲍ̅ⲎⲢⲰⲆⲎⲤ ⲄⲀⲢ ⲚⲈⲀϤⲀⲘⲞⲚⲒ ⲚⲒⲰⲀⲚⲚⲎ ⲤⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲤⲞⲚϨϤ ϦⲈⲚⲠⲒϢⲦⲈⲔⲞ ⲈⲐⲂⲈ ⲎⲢⲰⲆⲒⲀⲤ ⲦⲤϨⲒⲘⲒ ⲘⲪⲒⲖⲒⲠⲠⲞⲤ ⲠⲈϤⲤⲞⲚ ϪⲈⲞⲨⲎ ⲒⲄⲀⲢ ⲚⲈⲀϤϬⲒⲦⲤ ⲠⲈ
18 Johanu sì ti wí fún Herodu pé, “Kò tọ́ sí ọ láti fi ìyàwó arákùnrin rẹ ṣe aya.”
ⲓ̅ⲏ̅ⲚⲀϤϪⲰ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲤ ⲠⲈ ⲚϪⲈⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲚⲎⲢⲰⲆⲎⲤ ϪⲈ ⲤϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲀⲚ ⲈϬⲒ ⲦⲤϨⲒⲘⲒ ⲘⲠⲈⲔⲤⲞⲚ.
19 Nítorí náà ni Herodia ṣe ní sínú, òun sì fẹ́ pa á, ṣùgbọ́n kò le ṣe é.
ⲓ̅ⲑ̅ⲎⲢⲰⲆⲒⲀⲤ ⲆⲈ ⲚⲀⲤⲘⲂⲞⲚ ⲈⲢⲞϤ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲤⲞⲨⲰϢ ⲈϦⲞⲐⲂⲈϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲤϢϪⲈⲘϪⲞⲘ ⲀⲚ ⲠⲈ.
20 Nítorí Herodu bẹ̀rù Johanu, ó sì mọ̀ ọ́n ni olóòtítọ́ ènìyàn àti ẹni mímọ́, ó sì ń tọ́jú rẹ̀. Nígbà tí Herodu ba gbọ́rọ̀ Johanu, ó máa ń dààmú síbẹ̀, ó sì fi ayọ̀ gbọ́rọ̀ rẹ̀.
ⲕ̅ⲎⲢⲰⲆⲎⲤ ⲄⲀⲢ ⲀϤⲈⲢϨⲞϮ ϦⲀⲦϨⲎ ⲚⲒⲰⲀⲚⲚⲎ ⲤⲈϤⲤⲰⲞⲨⲚ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲚⲆⲒⲔⲈⲞⲤ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ϤⲞⲨⲀⲂ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲀⲢⲈϨ ⲈⲢⲞϤ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈϨⲀⲚⲘⲎϢ ⲚⲦⲞⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϢⲞⲖϨ ⲚϨⲎⲦ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ϨⲎⲆⲈⲰⲤ ⲚⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲢⲞϤ.
21 Níkẹyìn Herodia rí ààyè. Àkókò yìí ni ọjọ́ ìbí Herodu, òun sì pèsè àsè ní ààfin ọba fún àwọn olùrànlọ́wọ́ rẹ̀: àwọn balógun àti àwọn ènìyàn pàtàkì ní Galili.
ⲕ̅ⲁ̅ⲈⲦⲀ ⲞⲨⲈϨⲞⲞⲨ ⲆⲈ ϢⲰⲠⲒ ⲚⲈⲨⲔⲈⲢⲒⲀ ϨⲞⲦⲈ ⲈⲦⲀ ⲎⲢⲰⲆⲎⲤ ϦⲈⲚⲠⲈϤⲈϨⲞⲞⲨ ⲘⲘⲒⲤⲒ ⲐⲀⲘⲒⲈ ⲞⲨⲆⲒⲠⲚⲞⲚ ⲚⲚⲈϤⲚⲒϢϮ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲬⲒⲖⲒⲀⲢⲬ ⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲒϨⲞⲨⲀϮ ⲚⲦⲈϮⲄⲀⲖⲒⲖⲈⲀ.
22 Nígbà náà, ni ọmọbìnrin Herodia wọlé láti jó. Inú Herodu àti àwọn àlejò rẹ̀ dùn tó bẹ́ẹ̀. Ọba sọ fún ọmọbìnrin náà pé, “Béèrè ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́ lọ́wọ́ mi, èmi ó sì fi fún ọ.”
ⲕ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲚϪⲈⲦϢⲈⲢⲒ ⲚⲎⲢⲰⲆⲒⲀⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲤϬⲞⲤϪⲈⲤ ⲀⲤⲢⲀⲚⲀϤ ⲚⲎⲢⲰⲆⲎⲤ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲐⲢⲞⲦⲈⲂ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲠⲈϪⲈ ⲠⲞⲨⲢⲞ ⲆⲈ ⲚϮⲀⲖⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲢⲒⲈⲦⲒⲚ ⲘⲘⲞⲒ ⲘⲠⲈⲦⲈⲞⲨⲀϢϤ ⲚⲦⲀⲦⲎⲒϤ ⲚⲈ.
23 Ó sì búra fún un wí pé, “Ohunkóhun tí ìwọ bá fẹ́, ìbá à ṣe ìdajì ìjọba mi ni, èmi yóò fi fún ọ.”
ⲕ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲰⲢⲔ ⲚⲀⲤ ϪⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲈⲢⲀⲈⲢⲈⲦⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ ϮⲚⲀϮ ⲚⲈϢⲀ ⲦⲪⲀϢⲒ ⲚⲦⲀⲘⲈⲦⲞⲨⲢⲞ.
24 Ó jáde lọ sọ fún ìyá rẹ̀ pé, “Kí ní kí ń béèrè?” Ó dáhùn pé, “Orí Johanu Onítẹ̀bọmi.”
ⲕ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲠⲈϪⲀⲤ ⲚⲦⲈⲤⲘⲀⲨ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈϮⲚⲀⲈⲢⲈⲦⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ ⲚⲐⲞⲤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀⲤ ϪⲈ ⲦⲀⲪⲈ ⲚⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲠⲒⲢⲈϤϮⲰⲘⲤ
25 Ọmọbìnrin yìí sáré padà wá sọ́dọ̀ Herodu ọba. Ó sì wí fún un pé, “Mo ń fẹ́ orí Johanu Onítẹ̀bọmi nísinsin yìí nínú àwopọ̀kọ́.”
ⲕ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ϦⲈⲚⲞⲨⲤⲠⲞⲨⲆⲎ ϨⲀ ⲠⲞⲨⲢⲞ ⲀⲤⲈⲢⲈⲦⲒⲚ ⲈⲤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ϮⲞⲨⲰϢ ϨⲒⲚⲀ ϮⲚⲞⲨ ⲚⲦⲈⲔϮ ⲚⲎⲒ ⲚⲦⲀⲪⲈ ⲚⲒⲰⲀⲚⲚⲎ ⲤⲠⲒⲢⲈϤϮⲰⲘⲤ ϨⲒ ⲞⲨⲂⲒⲚⲀϪ.
26 Inú ọba sì bàjẹ́ gidigidi, ṣùgbọ́n nítorí àwọn ìbúra rẹ, àti nítorí àwọn tí ó bá a jókòó pọ̀, kò sì fẹ́ kọ̀ fún un.
ⲕ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀ ⲠϨⲎⲦ ⲘⲠⲞⲨⲢⲞ ⲘⲔⲀϨ ⲈⲐⲂⲈ ⲚⲒⲀⲚⲀⲨϢ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲐⲢⲞⲦⲈⲂ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲘⲠⲈϤⲞⲨⲰϢ ⲈϤⲞϪⲤ.
27 Nítorí èyí, ọba rán ẹ̀ṣọ́ kan, ó fi àṣẹ fún un pé, kí ó gbé orí Johanu wá. Ọkùnrin náà sì lọ, ó bẹ́ Johanu lórí nínú túbú.
ⲕ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤⲞⲨⲰⲢⲠ ⲚϪⲈⲠⲞⲨⲢⲞ ⲚⲞⲨⲤⲔⲈⲠⲰⲖⲀⲦⲞⲢ ⲀϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚⲦⲈϤⲒⲚⲒ ⲚⲦⲈϤⲀⲪⲈ ϨⲒ ⲠⲒⲂⲒⲚⲀϪ.
28 Ó sì gbé orí Johanu wa nínú àwopọ̀kọ́. Ó sì gbé e fún ọmọbìnrin náà. Òun sì gbé e tọ ìyá rẹ̀ lọ.
ⲕ̅ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲦⲎⲒⲤ ⲚϮⲀⲖⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀϮⲀⲖⲞⲨ ⲦⲎⲒⲤ ⲚⲦⲈⲤⲘⲀⲨ.
29 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu gbọ́, wọ́n wá gbé òkú rẹ̀, wọ́n sì lọ tẹ́ ẹ sínú ibojì.
ⲕ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ⲚϪⲈⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲀⲨⲒ ⲀⲨⲰⲖⲒ ⲘⲠⲒⲤⲰⲘⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲬⲀϤ ⲚϦⲞⲨⲚ ϦⲈⲚⲞⲨⲘϨⲀⲨ.
30 Àwọn aposteli kó ara wọn jọ sí ọ̀dọ̀ Jesu, wọ́n sí ròyìn ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe àti ohun gbogbo tí wọ́n ti kọ́ni.
ⲗ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲚϪⲈⲚⲒⲀⲠⲞⲤⲦⲞⲖⲞⲤ ϨⲀ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲦⲀⲘⲞϤ ⲈϨⲰⲂ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲦⲀⲨⲀⲒϤ ⲚⲈⲘ ⲪⲎ ⲈⲦⲀⲨϮⲤⲂⲰ ⲘⲘⲞϤ
31 Nígbà tí Jesu rí i pé ọ̀pọ̀ ènìyàn ń lọ tí wọ́n sì ń bọ̀ tó bẹ́ẹ̀ tí kò sí ààyè fún wọn láti jẹun, ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ jẹ́ kí a kúrò láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn wọ̀nyí fún ìgbà díẹ̀, kí a sì sinmi.”
ⲗ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲀⲘⲰⲒⲚⲒ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲤⲀⲠⲤⲀ ⲈⲞⲨⲘⲀⲚϢⲀϤⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲦⲞⲚ ⲘⲘⲰⲦⲈⲚ ⲚⲞⲨⲔⲞⲨϪⲒ ⲚⲎ ⲄⲀⲢ ⲈⲐⲚⲎⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲀⲚⲀⲨⲞϢ ⲠⲈ. ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϪⲈⲘ ⲈⲨⲔⲈⲢⲒⲀ ⲀⲚ ⲠⲈ ⲈⲈⲢ ⲠⲔⲈⲞⲨⲰⲘ
32 Nítorí náà, wọ́n wọ ọkọ̀ ojú omi kúrò níbẹ̀ lọ sí ibi tí ó parọ́rọ́.
ⲗ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ϨⲒ ⲠⲒϪⲞⲒ ⲈⲞⲨⲘⲀⲚϢⲀϤⲈ ⲤⲀⲠⲤⲀ.
33 Ṣùgbọ́n ọ̀pọ̀ ènìyàn ni o rí wọn nígbà tí wọ́n ń lọ. Àwọn wọ̀nyí sì tún wá láti ìlú ńlá gbogbo wọn sáré gba etí Òkun, wọ́n ṣáájú wọn gúnlẹ̀ ní èbúté.
ⲗ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲈⲨϨⲎⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲤⲰⲞⲨⲚⲞⲨ ⲚϪⲈⲞⲨⲘⲎϢ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϬⲞϪⲒ ⲘⲘⲀⲨ ⲚⲢⲀⲦⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲂⲀⲔⲒ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲈⲢϢⲞⲢⲠ ⲈⲢⲰⲞⲨ.
34 Bí Jesu ti ń sọ̀kalẹ̀ láti inú ọkọ̀ náà, ó bá ọ̀pọ̀ ènìyàn bí i tí àtẹ̀yìnwá, tí wọ́n ti ń dúró dè e. Ó káàánú fún wọn, nítorí wọ́n dàbí àgùntàn tí kò ní olùtọ́jú. Ó sì kọ́ wọn ni ọ̀pọ̀ nǹkan tí ó yẹ kí wọ́n mọ̀.
ⲗ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲞⲨⲘⲎϢ ⲈϤⲞϢ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈⲚϨⲎⲦ ϦⲀⲢⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲚⲀⲨⲞⲒ ⲘⲪⲢⲎϮ ⲚϨⲀⲚⲈⲤⲰⲞⲨ ⲘⲘⲞⲚⲦⲞⲨ ⲘⲀⲚⲈⲤⲰⲞⲨ ⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲚϮⲤⲂⲰ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲘⲎ Ϣ
35 Nígbà tí ọjọ́ sì ti bù lọ tán, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ tọ̀ ọ́ wá, wọ́n wí fún un pé, ibi aṣálẹ̀ ni ìbí yìí, ọjọ́ sì bù lọ tán.
ⲗ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ϨⲎⲆⲎ ⲈⲦⲀ ⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚⲞⲨⲚⲞⲨ ϢⲰⲠⲒ ⲈⲦⲀⲨⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎⲦⲎⲤ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲠⲒⲘⲀ ⲞⲨϢⲀϤⲈ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ϨⲎⲆⲎ ϮⲞⲨⲚⲞⲨ ⲀⲤⲤⲒⲚⲒ.
36 “Rán àwọn ènìyàn wọ̀nyí láti lọ sí àwọn abúlé àti ìlú láti ra oúnjẹ fún ara wọn.”
ⲗ̅ⲋ̅ⲬⲀⲨ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲞⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲈⲚⲒⲒⲞϨⲒ ⲈⲦⲔⲰϮ ⲚⲈⲘ ⲚⲒϮⲘⲒ ⲚⲦⲞⲨϢⲰⲠ ⲚⲰⲞⲨ ⲘⲠⲈⲦⲞⲨⲚⲀⲞⲨⲞⲘϤ.
37 Ṣùgbọ́n Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ fún wọn ní oúnjẹ.” Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wí fún pé, “Èyí yóò ná wa tó owó iṣẹ́ ọ̀yà oṣù mẹ́jọ, ṣe kí a lọ fi èyí ra àkàrà fún àwọn ọ̀pọ̀ ènìyàn yìí láti jẹ.”
ⲗ̅ⲍ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲀϤⲈⲢⲞⲨⲰ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲘⲞⲒ ⲚⲰⲞⲨ ⲚⲐⲰⲦⲈⲚ ⲘⲀⲢⲞⲨⲞⲨⲰⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲦⲈⲚⲚⲀϢⲈ ⲚⲀⲚ ⲚⲦⲈⲚϢⲈⲠ ⲤⲚⲤⲀⲐⲈⲢⲒ ⲚⲰⲒⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈⲚϮ ⲚⲰⲞⲨ ⲈⲞⲨⲰⲘ.
38 Jesu tún béèrè pé, “Ìṣù àkàrà mélòó ni ẹ̀yin ni lọ́wọ́? Ẹ lọ wò ó.” Wọ́n padà wá jíṣẹ́ pé, “Ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì.”
ⲗ̅ⲏ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲎⲢ ⲚⲰⲒⲔ ⲚⲦⲈⲚ ⲐⲎⲚⲞⲨ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲰⲦⲈⲚ ⲀⲚⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲈⲘⲒ ⲠⲈϪⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲈⲚⲰⲒⲔ ⲚⲈⲘ ⲦⲈⲂⲦ Ⲃ-.
39 Nígbà náà ni Jesu sọ fún ọ̀pọ̀ ènìyàn náà kí a mú wọn jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́ lórí koríko.
ⲗ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚⲰⲞⲨ ⲚⲦⲞⲨⲢⲰⲦⲈⲂ ⲚⲤⲒⲘⲠⲞⲤⲒⲞⲚ ⲤⲒⲘⲠⲞⲤⲒⲞⲚ ϨⲒϪⲈⲚ ⲠⲒⲤⲒⲘ ⲈⲐⲞⲨⲈⲦⲞⲨⲰⲦ
40 Lẹ́sẹ̀kan náà, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sí í jókòó, ní àádọ́ta tàbí ọgọọgọ́rùn-ún.
ⲙ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲢⲰⲦⲈⲂ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲘⲘⲀ ⲘⲀ ⲔⲀⲦⲀ ⲢⲢ ⲚⲈⲘ ⲔⲀⲦⲀ ⲚⲚ.
41 Nígbà tí ó sì mú ìṣù àkàrà márùn-ún àti ẹja méjì náà, ó gbé ojú rẹ̀ sókè ọ̀run. Ó dúpẹ́ fún oúnjẹ náà, ó bù wọ́n sí wẹ́wẹ́, ó fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti gbé e kalẹ̀ síwájú àwọn ènìyàn náà àti àwọn ẹja méjì náà ni ó pín fún gbogbo wọn.
ⲙ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤϬⲒ ⲘⲠⲒⲈ ⲚⲰⲒⲔ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲦⲈⲂⲦ ⲂⲀϤϪⲞⲨϢⲦ ⲈⲦⲪⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲤⲘⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲪⲰϢ ⲚⲚⲒⲰⲒⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϮ ⲚⲚⲒⲘⲀⲐⲎ ⲦⲎⲤ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲞⲨⲬⲰ ⲚⲀϨⲢⲀⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲒⲔⲈⲦⲈⲂⲦ ⲂⲀϤⲪⲀϢⲞⲨ ⲈϨⲢⲀⲨ ⲦⲎⲢⲞⲨ
42 Gbogbo wọn sì jẹ àjẹyó.
ⲙ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲞⲨⲰⲘ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲤⲒ.
43 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn sì kó agbọ̀n méjìlá tí ó kún fún àjẹkù àkàrà àti ti ẹja pẹ̀lú.
ⲙ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲰⲖⲒ ⲘⲒⲂ ⲚⲔⲞⲦ ⲚⲖⲀⲔϨ ⲈⲨⲘⲈϨ ⲚⲈⲘ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲔⲈⲦⲈⲂⲦ.
44 Àwọn tí ó sì jẹ́ àkàrà náà tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ọkùnrin.
ⲙ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲎ ⲈⲚⲀⲨⲞⲨⲰⲘ ⲚⲚⲒⲰⲒⲔ ⲚⲀⲨⲈⲢ ⲈⲚϢⲞ ⲚⲢⲰⲘⲒ.
45 Lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ lẹ́yìn èyí, Jesu pàṣẹ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti padà sínú ọkọ̀ kí wọn sì ṣáájú rékọjá sí Betisaida. Níbẹ̀ ni òun yóò ti wà pẹ̀lú wọn láìpẹ́. Nítorí òun fúnra a rẹ̀ yóò dúró sẹ́yìn láti rí i pé àwọn ènìyàn túká lọ ilé wọn.
ⲙ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤⲈⲢⲀⲚⲀⲄⲔⲀⲌⲒⲚ ⲚⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎ ⲦⲎⲤ ⲈⲀⲖⲎⲒ ⲈⲠⲒϪⲞⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲞⲨⲤⲰⲔ ϦⲀϪⲰϤ ⲈⲘⲎⲢ ⲈⲂⲎⲐⲤⲀⲒⲆⲀ ϢⲀⲦⲈϤⲬⲀ ⲠⲒⲘⲎ ϢⲈⲂⲞⲖ.
46 Lẹ́yìn náà, ó lọ sórí òkè láti lọ gbàdúrà.
ⲙ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲈⲢⲀⲠⲞⲦⲀⲌⲈⲤⲐⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲠⲒⲦⲰⲞⲨ ⲈⲈⲢⲠⲢⲞⲤⲈⲨⲬⲈⲤⲐⲈ.
47 Nígbà tí ó di alẹ́, ọkọ̀ wà láàrín Òkun, òun nìkan sì wà lórí ilẹ̀.
ⲙ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀ ⲢⲞⲨϨⲒ ϢⲰⲠⲒ ⲚⲀⲢⲈ ⲠⲒϪⲞⲒ ϦⲈⲚⲐⲘⲎϮ ⲘⲪⲒⲞⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲐⲞϤ ⲘⲘⲀⲨⲀⲦϤ ⲚⲀϤⲬⲎ ϨⲒ ⲠⲒⲬⲢⲞ.
48 Ó rí i wí pé àwọn ọmọ-ẹ̀yìn wà nínú wàhálà púpọ̀ ní wíwa ọkọ̀ náà nítorí ti ìjì líle ṣe ọwọ́ òdì sí wọn, nígbà tí ó sì dì ìwọ̀n ìṣọ́ kẹrin òru, ó tọ̀ wọ́n wá, ó ń rìn lórí omi Òkun, òun sì fẹ́ ré wọn kọjá,
ⲙ̅ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲈⲨⲦϨⲈⲘⲔⲎ ⲞⲨⲦ ϦⲈⲚⲠⲒϪⲒⲚⲤⲰⲔ ⲚⲀⲢⲈ ⲠⲒⲐⲎⲞⲨ ⲄⲀⲢ ]- ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϨⲢⲀⲨ ⲠⲈ ⲚϨⲢⲎⲒ ⲆⲈ ϦⲈⲚϮⲘⲀϨⲆ ⲚⲞⲨⲈⲢϢⲒ ⲚⲦⲈⲠⲒⲈϪⲰⲢϨ ⲀϤⲒ ϨⲀⲢⲰⲞⲨ ⲈϤⲘⲞϢⲒ ϨⲒϪⲈⲚ ⲪⲒⲞⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲞⲨⲰϢ ⲈⲤⲈⲚⲞⲨ ⲠⲈ.
49 ṣùgbọ́n nígbà tí wọ́n rí i tí ó ń rìn, wọ́n rò pé iwin ni. Wọ́n sì kígbe sókè lóhùn rara,
ⲙ̅ⲑ̅ⲚⲐⲰⲞⲨ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲈϤⲘⲞϢⲒ ϨⲒϪⲈⲚ ⲪⲒⲞⲘ ⲚⲀⲨⲘⲈⲨⲒ ϪⲈ ⲞⲨϨⲞⲢⲦϤ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ
50 nítorí gbogbo wọn ni ó rí i, tí ẹ̀rù sì bà wọ́n. Ṣùgbọ́n òun sọ̀rọ̀ sí wọn lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀ pé, “Ẹ mú ọkàn le! Èmi ni. Ẹ má bẹ̀rù.”
ⲛ̅ⲚⲈ ⲀⲨⲚⲀⲨ ⲄⲀⲢ ⲈⲢⲞϤ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϢⲐⲞⲢⲦⲈⲢ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤⲤⲀϪⲒ ⲚⲈⲘⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ϪⲈⲘⲚⲞⲘϮ ⲀⲚⲞⲔ ⲠⲈ ⲘⲠⲈⲢⲈⲢϨⲞϮ
51 Nígbà náà ni ó gòkè sínú ọkọ̀ pẹ̀lú wọn, ìjì líle náà sì dáwọ́ dúró. Ẹ̀rù sì bà wọ́n rékọjá gidigidi, ẹnu sì yà wọ́n.
ⲛ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲀⲖⲎⲒ ⲈⲠⲒϪⲞⲒ ϨⲀⲢⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϨⲈⲢⲒ ⲚϪⲈⲠⲒⲐⲎⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲦⲰⲘⲦ ⲈⲘⲀϢⲰ ⲠⲈ ⲚϦⲢⲎⲒ ⲚϦⲎⲦⲞⲨ
52 Wọn kò sá tó ni òye iṣẹ́ ìyanu ti ìṣù àkàrà, nítorí ti ọkàn wọn yigbì.
ⲛ̅ⲃ̅ⲞⲨ ⲄⲀⲢ ⲘⲠⲞⲨⲔⲀϮ ⲈϪⲈⲚ ⲚⲒⲰⲒⲔ ⲀⲖⲖⲀ ⲚⲀⲢⲈ ⲠⲞⲨϨⲎⲦ ⲐⲎⲘ ⲠⲈ
53 Lẹ́yìn tí wọ́n la Òkun náà kọjá, wọ́n gúnlẹ̀ sí Genesareti. Wọ́n sì so ọkọ̀ sí èbúté.
ⲛ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲈⲢϪⲒⲚⲒⲞⲢ ⲈⲘⲎⲢ ⲀⲨⲒ ⲈⲄⲈⲚⲚⲎ ⲤⲀⲢⲈⲐ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲘⲞⲚⲒ
54 Wọ́n jáde kúrò nínú ọkọ̀. Àwọn ènìyàn tó wà níbẹ̀ rí Jesu, wọ́n sì dá a mọ̀ ọ́n.
ⲛ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈϨⲢⲎⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒ ⲠⲒϪⲞⲒ ⲀⲨⲤⲞⲨⲰⲚϤ ⲤⲀⲦⲞⲦⲞⲨ
55 Wéré, wọ́n ròyìn dídé rẹ̀, gbogbo àwọn ènìyàn sáré gbé gbogbo àwọn aláìsàn lórí àkéte wọn wá pàdé rẹ̀.
ⲛ̅ⲉ̅ⲀⲨϬⲞϪⲒ ϦⲈⲚϮⲬⲰⲢⲀ ⲦⲎⲢⲤ ⲈⲦⲈⲘⲘⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲘϤⲀⲒ ⲚⲚⲎ ⲈⲦⲦϨⲈⲘⲔⲎ ⲞⲨⲦ ϨⲒ ϨⲀⲚϬⲖⲞϪ ⲈⲠⲒⲘⲀ ⲈϢⲀⲨⲤⲰⲦⲈⲘ ϪⲈ ϤⲈⲘⲘⲀⲨ.
56 Ní ibi gbogbo tí ó sì dé, yálà ní abúlé, ìlú ńlá tàbí àrọ́ko, ń ṣe ni wọ́n ń kó àwọn aláìsàn pàdé rẹ̀ ní àárín ọjà. Wọ́n sì ń bẹ̀ ẹ́ kí ó jẹ́ kí wọn fi ọwọ́ kan etí aṣọ rẹ̀, gbogbo àwọn tí wọ́n sì fi ọwọ́ kàn án ni a mú láradá.
ⲛ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲠⲒⲘⲀ ⲈϢⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲚⲒϮⲘⲒ ⲒⲈ ⲚⲒⲂⲀⲔⲒ ⲒⲈ ⲚⲒⲒⲞϨⲒ ⲚⲀⲨⲬⲰ ⲚⲚⲎ ⲈⲦϢⲰⲚⲒ ϨⲒ ⲚⲒⲀⲄⲞⲢⲀ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ϨⲒⲚⲀ ⲔⲀⲚ ⲚⲦⲞⲨϬⲒ ⲚⲈⲘ ⲠⲒϢⲦⲀϮ ⲚⲦⲈⲚⲈϤϨⲂⲰⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲞⲚ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈϢⲀⲨϬⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ϢⲀⲨⲞⲨϪⲀⲒ.

< Mark 6 >