< Mark 5 >
1 Wọ́n lọ sí apá kejì adágún ní ẹ̀bá ilẹ̀ àwọn ará Gadara.
ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ⲈⲘⲎⲢ ⲈⲪⲒⲞⲘ ⲈⲦⲬⲰⲢⲀ ⲚⲦⲈⲚⲒⲄⲈⲢⲄⲈⲤⲎⲚⲞⲤ
2 Bí Jesu sì ti ń ti inú ọkọ̀ ojú omi jáde. Ọkùnrin kan tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́ jáde ti ibojì wá pàdé rẹ̀.
ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲠⲒϪⲞⲒ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈϨⲢⲀϤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲒⲘϨⲀⲨ ⲚϪⲈⲞⲨⲢⲰⲘⲒ ⲈϤϦⲈⲚ ⲞⲨⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲀⲢⲦⲞⲚ
3 Ọkùnrin yìí ń gbé nínú ibojì, kò sí ẹni tí ó lè dè é mọ́, kódà ẹ̀wọ̀n kò le dè é.
ⲅ̅ⲪⲎ ⲈⲚⲀⲢⲈ ⲠⲈϤⲘⲀⲚϢⲰⲠⲒ ϢⲞⲠ ϦⲈⲚⲚⲒⲘϨⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲞⲨⲆⲈ ϦⲈⲚⲚⲒⲔⲈϨⲀⲖⲨⲤⲒⲤ ⲘⲘⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲚϨⲖⲒ ⲠⲈ ⲈⲤⲞⲚϨϤ
4 Nítorí pé nígbà púpọ̀ ni wọ́n ti ń fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè é lọ́wọ́ àti ẹsẹ̀, tí ó sì ń já a dànù kúrò ni ẹsẹ̀ rẹ̀. Kò sí ẹnìkan tí ó ní agbára láti káwọ́ rẹ̀.
ⲇ̅ⲈⲐⲂⲈϪⲈ ⲚⲈⲀⲨⲤⲞⲚϨϤ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲚⲤⲞⲠ ⲚϨⲀⲚⲠⲈⲆⲎⲤ ⲚⲈⲘ ϨⲀⲚϨⲀⲖⲨⲤⲒⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈϤⲤⲰⲖⲠ ⲚⲚⲒϨⲀⲖⲨⲤⲒⲤ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲒⲦⲞⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲤⲈϦⲞⲘϦⲈⲘ ⲚϪⲈⲚⲒⲠⲈⲆⲎⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲈⲘⲘⲞⲚ ϢϪⲞⲘ ⲚⲦⲈϨⲖⲒ ⲈⲢⲆⲀⲘⲀⲌⲒⲚ ⲘⲘⲞϤ
5 Tọ̀sán tòru láàrín àwọn ibojì àti ní àwọn òkè ni ó máa ń kígbe rara tí ó sì ń fi òkúta ya ara rẹ̀.
ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲤⲎⲞⲨ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲘⲠⲒⲈϪⲰⲢϨ ⲚⲈⲘ ⲠⲒⲈϨⲞⲞⲨ ⲈϤⲬⲎ ϦⲈⲚⲚⲒⲘϨⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲬⲎ ϦⲈⲚⲚⲒⲦⲰⲞⲨ ⲠⲈ ⲈϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲈϤϢⲰⲦ ⲘⲘⲞϤ ⲚϨⲀⲚⲰⲚⲒ.
6 Nígbà tí ó sì rí Jesu látòkèrè, ó sì sáré lọ láti pàdé rẹ̀. Ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲒⲤϪⲈⲚ ϨⲒⲪⲞⲨⲈⲒ ⲀϤϬⲞϪⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲰϢⲦ ⲘⲘⲞϤ
7 Ó sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Kí ní ṣe tèmi tìrẹ, Jesu Ọmọ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo? Mo fi Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ má ṣe dá mi lóró.”
ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲰϢ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚⲤⲘⲎ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ϪⲈ ⲀϦⲞⲔ ⲚⲈⲘⲎⲒ ϨⲰⲔ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲠϢⲎⲢⲒ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲈⲦϬⲞⲤⲒ ϮⲦⲀⲢⲔⲞ ⲘⲘⲞⲔ ⲘⲪⲚⲞⲨϮ ⲘⲠⲈⲢϮϬⲖⲀⲔ ⲚⲎⲒ.
8 Nítorí tí Ó wí fún un pé, “Jáde kúrò lára ọkùnrin náà, ìwọ ẹ̀mí àìmọ́!”
ⲏ̅ⲚⲀϤϪⲰ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲤ ⲠⲈ ϪⲈ ⲀⲘⲞⲨ ⲈⲂⲞⲖ ⲠⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲀⲢⲦⲞⲚ ϦⲈⲚⲠⲒⲢⲰⲘⲒ.
9 Jesu sì bi í léèrè pé, “Kí ni orúkọ rẹ?” Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì dáhùn wí pé, “Ligioni, nítorí àwa pọ̀.”
ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϢⲒⲚⲒ ⲘⲘⲞϤ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ⲠⲈ ⲠⲈⲔⲢⲀⲚ ⲞⲨⲞϨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲖⲈⲄⲒⲰⲚ ⲠⲈ ⲠⲀⲢⲀⲚ ϪⲈ ⲦⲈⲚⲈⲢⲞⲨⲘⲎϢ
10 Nígbà náà ni ẹ̀mí àìmọ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí í bẹ Jesu gidigidi, kí ó má ṣe rán àwọn jáde kúrò ní agbègbè náà.
ⲓ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ⲚϨⲀⲚⲘⲎϢ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤϢⲦⲈⲘⲞⲨⲞⲢⲠ ⲤⲀⲂⲞⲖ ⲚϮⲬⲰⲢⲀ.
11 Agbo ẹlẹ́dẹ̀ ńlá kan sì ń jẹ lẹ́bàá òkè.
ⲓ̅ⲁ̅ⲚⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲀⲄⲈⲖⲎ ⲆⲈ ⲚⲢⲒⲢ ⲈⲤⲞϢ ⲘⲘⲀⲨ ⲠⲈ ⲈⲤⲘⲞⲚⲒ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲠⲒⲦⲰⲞⲨ
12 Àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà bẹ Jesu pé, “Rán wa lọ sínú àwọn ẹlẹ́dẹ̀ wọ̀n-ọn-nì kí àwa le è wọ inú wọn lọ.”
ⲓ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲞⲨⲞⲢⲠⲦⲈⲚ ⲈⲚⲒⲢⲒⲢ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲚϢⲈ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲢⲰⲞⲨ
13 Jesu fún wọn láààyè, àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà, wọ́n sì wọ inú àwọn ẹlẹ́dẹ̀ náà lọ. Agbo ẹlẹ́dẹ̀ náà tí ó tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì sì túká lọ́gán, wọ́n sì sáré lọ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè rọ́ sínú Òkun, wọ́n sì ṣègbé.
ⲓ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲞⲨⲀϨⲤⲀϨⲚⲒ ⲚⲰⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀⲨⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲚϪⲈⲚⲒⲠⲚⲈⲨⲘⲀⲚⲀⲔⲀⲐⲢⲦⲞⲚ ⲀⲨϢⲈ ⲚⲰⲞⲨ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲚⲒⲈϢⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϨⲈⲒ ⲈϦⲢⲎⲒ ⲚϪⲈϮⲀⲄⲈⲖⲎ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲠⲒϪⲀϪⲢⲒⲘ ⲈⲪⲒⲞⲘ ⲈⲨⲈⲢ ϢⲞ ⲤⲚⲀⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲰϪϨ ⲘⲘⲰⲞⲨ ϦⲈⲚⲪⲒⲞⲘ.
14 Àwọn olùtọ́jú ẹran wọ̀nyí sì sálọ sí àwọn ìlú ńlá àti ìlú kéékèèké, wọ́n sì ń tan ìròyìn náà ká bí wọ́n ti ń sáré. Àwọn ènìyàn sì tú jáde láti fojú gán-án-ní ohun náà tí ó ṣẹlẹ̀.
ⲓ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲎ ⲈⲚⲀⲨⲘⲞⲚⲒ ⲘⲘⲰⲞⲨ ⲀⲨⲪⲰⲦ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨϪⲞⲤ ϦⲈⲚϮⲂⲀⲔⲒ ⲚⲈⲘ ϦⲈⲚⲦⲔⲞⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲒ ⲈⲚⲀⲨ ϪⲈ ⲞⲨ ⲠⲈ ⲪⲎ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ.
15 Nígbà tí wọ́n péjọ sọ́dọ̀ Jesu, wọ́n rí ọkùnrin náà, ẹni tí ó ní ẹ̀mí èṣù, tí ó jókòó níbẹ̀, ó wọ aṣọ ìyè rẹ sì bọ̀ sípò, ẹ̀rù sì bà wọ́n.
ⲓ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲒ ϨⲀ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲀⲨⲚⲀⲨ ⲈⲪⲎ ⲈⲚⲀⲢⲈ ⲚⲒⲆⲈⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲈϤϨⲈⲘⲤⲒ ⲈⲢⲈ ⲚⲈϤϨⲂⲰⲤ ⲦⲞⲒ ϨⲒⲰⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲢⲈ ⲠⲈϤϨⲎⲦ ⲘⲘⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲈⲢϨⲞϮ.
16 Àwọn tí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ṣojú wọn sì ń ròyìn rẹ̀ fún àwọn ènìyàn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí ọkùnrin ẹlẹ́mìí àìmọ́, wọ́n si sọ nípa agbo ẹlẹ́dẹ̀ náà pẹ̀lú.
ⲓ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲤⲀϪⲒ ϦⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚϪⲈⲚⲎ ⲈⲦⲀⲨⲚⲀⲨ ϪⲈ ⲈⲦⲀⲤϢⲰⲠⲒ ⲚⲀϢ ⲚⲢⲎϮ ⲘⲪⲎ ⲈⲚⲀⲢⲈ ⲚⲒⲆⲈⲘⲰⲚ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲚⲈⲘ ⲈⲐⲂⲈ ⲚⲒⲢⲒⲢ
17 Nígbà náà, àwọn èrò bẹ̀rẹ̀ sí ní bẹ Jesu pé kí ó fi agbègbè àwọn sílẹ̀.
ⲓ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲚϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ϪⲈ ⲚⲦⲈϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈⲂⲞⲖ ϦⲈⲚⲚⲞⲨⲐⲞϢ
18 Bí Jesu ti ń wọ inú ọkọ̀ ojú omi lọ, ọkùnrin náà tí ó ti ní ẹ̀mí àìmọ́ tẹ́lẹ̀ bẹ̀ Ẹ́ pé kí òun lè bá a lọ.
ⲓ̅ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲀⲖⲎⲒ ⲈⲠⲒϪⲞⲒ ⲚⲀϤϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲪⲎ ⲈⲚⲀϤⲞⲒ ⲚⲆⲈⲘⲰⲚ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϤⲞϨⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ
19 Jesu kò gbà fún un, ṣùgbọ́n ó wí fún un pé, “Lọ sí ilé sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ, kí o sì sọ fún wọn bí Ọlọ́run ti ṣe ohun ńlá fún ọ, àti bí ó sì ti ṣàánú fún ọ.”
ⲓ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈϤⲬⲀϤ ⲀⲖⲖⲀ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀϤ ϪⲈ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲀⲔ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲈⲔⲎⲒ ϨⲀ ⲚⲎ ⲈⲦⲈⲚⲞⲨⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲀⲦⲀⲘⲰⲞⲨ ⲈⲚⲎ ⲈⲦⲀ ⲠϬⲞⲒⲤ ⲀⲒⲦⲞⲨ ⲚⲀⲔ ⲈⲀϤⲚⲀⲒ ⲚⲀⲔ
20 Nítorí náà, ọkùnrin yìí padà lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ròyìn ní Dekapoli nípa ohun ńlá tí Jesu ṣe fún un. Ẹnu sì ya gbogbo ènìyàn.
ⲕ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϨⲰⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲈⲢϨⲎⲦⲤ ⲚϨⲒⲰⲒϢ ϦⲈⲚⲐⲘⲎϮ ⲚϮⲂⲀⲔⲒ ⲘⲠⲈⲦⲀϤⲀⲒϤ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲦⲎⲢⲞⲨ ⲠⲈ
21 Nígbà tí Jesu sì ti inú ọkọ̀ rékọjá sí apá kejì Òkun, ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn péjọ yí i ká ní etí Òkun.
ⲕ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲞⲚ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲈⲘⲎⲢ ϦⲈⲚⲠⲒϪⲞⲒ ⲀⲨⲐⲰⲞⲨϮ ⲚϪⲈⲞⲨⲘⲎϢ ⲈϤⲞϢ ϨⲀⲢⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤⲬⲎ ⲠⲈ ϦⲀⲦⲈⲚ ⲪⲒⲞⲘ
22 Ọ̀kan nínú àwọn olórí Sinagọgu tí à ń pè ni Jairu wá sọ́dọ̀ Jesu, nígbà tí ó sì rí i, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
ⲕ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤⲒ ϨⲀⲢⲞϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲀⲒ ⲚⲦⲈⲚⲒⲀⲢⲬⲎⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲞⲤ ⲈⲠⲈϤⲢⲀⲚ ⲠⲈ ⲒⲀⲒⲢⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲚⲀⲨ ⲈⲢⲞϤ ⲀϤϨⲒⲦϤ ϦⲀⲢⲀⲦⲞⲨ ⲚⲚⲈϤϬⲀⲖⲀⲨϪ
23 Ó sì bẹ̀ ẹ́ gidigidi pé, “Ọmọbìnrin mi wà lójú ikú, mo bẹ̀ ọ́, wá fi ọwọ́ rẹ lé e, kí ara rẹ̀ lè dá, kí ó sì yè.”
ⲕ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϮϨⲞ ⲈⲢⲞϤ ⲚϨⲀⲚⲘⲎϢ ⲈϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲦⲀϢⲈⲢⲒ ⲀⲤϦⲰⲚⲦ ⲈⲪⲘⲞⲨ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲔⲒ ⲚⲦⲈⲔⲬⲀ ⲦⲈⲔϪⲒϪ ⲈϪⲰⲤ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈⲤⲚⲞϨⲈⲘ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲦⲈⲤⲰⲚϦ
24 Jesu sì ń bá a lọ. Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì ń tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
ⲕ̅ⲇ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ ⲚϪⲈⲞⲨⲘⲎϢ ⲈϤⲞϢ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϨⲞϪϨⲈϪ ⲘⲘⲞϤ ⲠⲈ.
25 Obìnrin kan sì wà láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, tí ó ti ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún odidi ọdún méjìlá.
ⲕ̅ⲉ̅ⲞⲨⲞϨ ⲒⲤ ⲞⲨⲤϨⲒⲘⲒ ⲀⲤⲈⲢ ⲒⲂ ⲚⲢⲞⲘⲠⲒ ⲈⲢⲈ ⲞⲨⲞⲚ ⲞⲨⲤⲚⲞϤ ϦⲀⲢⲞⲤ.
26 Ẹni tí ojú rẹ̀ sì ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú lọ́dọ̀ ọ̀pọ̀ àwọn oníṣègùn, tí ó sì ti ná gbogbo ohun tí ó ní, síbẹ̀ kàkà kí ó san, ó ń burú sí i.
ⲕ̅ⲋ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϬⲒ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ ⲚϦⲒⲤⲒ ⲚⲦⲞⲦⲞⲨ ⲚⲚⲒⲘⲎϢ ⲚⲤⲎⲒⲚⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϬⲈ ⲚⲈⲦⲈⲚⲦⲀⲤ ⲚⲒⲂⲈⲚ ⲈⲂⲞⲖ ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈⲤϪⲈⲘϨⲎⲞⲨ ⲚϨⲖⲒ ⲀⲖⲖⲀ ⲘⲀⲖⲖⲞⲚ ⲀⲤⲦϨⲞ ⲚϨⲞⲨⲞ.
27 Nígbà tí ó sì gbúròó iṣẹ́ ìyanu tí Jesu ṣe, ìdí nìyìí tí ó fi wá sẹ́yìn rẹ̀, láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn, ó sì fọwọ́ kan aṣọ rẹ̀.
ⲕ̅ⲍ̅ⲈⲦⲀⲤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲆⲈ ⲈⲐⲂⲈ ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲀⲤⲒ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲎϢ ϨⲒⲪⲀϨⲞⲨ ⲀⲤϬⲒ ⲚⲈⲘ ⲠⲈϤϨⲂⲞⲤ
28 Nítorí ti ó rò ní ọkàn rẹ̀ pé, “Bí mo bá sá à lè fi ọwọ́ kan aṣọ rẹ̀, ara mi yóò dá.”
ⲕ̅ⲏ̅ⲚⲀⲤϪⲰ ⲄⲀⲢ ⲘⲘⲞⲤ ⲠⲈ ϪⲈ ⲔⲀⲚ ⲀⲒϢⲀⲚϬ ⲒⲚⲈⲘ ⲚⲈϤϨⲂⲰⲤ ϮⲚⲀⲚⲞϨⲈⲘ.
29 Ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì gbẹ lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, òun sì mọ̀ lára rẹ̀ pé, a mú òun láradá kúrò nínú ààrùn náà.
ⲕ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦⲤ ⲀⲤϢⲰⲞⲨⲒ ⲚϪⲈϮⲘⲞⲨⲘⲒ ⲚⲦⲈⲠⲈⲤⲤⲚⲞϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤⲈⲘⲒ ϦⲈⲚⲠⲈⲤⲤⲰⲘⲀ ϪⲈ ⲀⲤⲞⲨϪⲀⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀ ϮⲘⲀⲤⲦⲒⲄⲜ
30 Lọ́gán, Jesu sì mọ̀ nínú ara rẹ̀ pé agbára jáde lára òun. Ó yípadà láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn, ó sì béèrè, “Ta ni ó fi ọwọ́ kan aṣọ mi?”
ⲗ̅ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦϤ ⲀϤⲈⲘⲒ ⲚϪⲈⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲚϦⲢⲎ ⲒⲚϦⲎⲦϤ ⲈϮϪⲞⲘ ⲈⲦⲀⲤⲒ ⲈⲂⲞⲖ ⲘⲘⲞϤ ⲈⲦⲀϤⲪⲞⲚϨϤ ϦⲈⲚⲠⲒⲘⲎϢ ⲚⲀϤϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ⲠⲈⲦⲀϤϬⲒ ⲚⲈⲘ ⲚⲀϨⲂⲰⲤ
31 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ rí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó rọ̀gbà yí ọ ká, ìwọ sì tún ń béèrè ẹni tí ó fi ọwọ́ kàn ọ́?”
ⲗ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ⲚⲀϤ ⲚϪⲈⲚⲈϤⲘⲀⲐⲎ ⲦⲎⲤ ϪⲈ ⲬⲚⲀⲨ ⲈⲠⲒⲘⲎϢ ⲈϤϨⲞϪϨⲈϪ ⲘⲘⲞⲔ ⲞⲨⲞϨ ⲔϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲚⲒⲘ ⲠⲈⲦⲀϤϬⲒ ⲚⲈⲘⲎⲒ.
32 Síbẹ̀, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí wò yíká láti rí ẹni náà, tí ó fi ọwọ́ kan òun.
ⲗ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀϤϪⲞⲨϢⲦ ⲠⲈ ⲈⲚⲀⲨ ⲈⲐⲎ ⲈⲦⲀⲤⲈⲢ ⲪⲀⲒ
33 Nígbà náà, obìnrin náà kún fún ìbẹ̀rù àti ìwárìrì nítorí ó ti mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ lára òun. Ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì sọ gbogbo òtítọ́ fún un.
ⲗ̅ⲅ̅ϮⲤϨⲒⲘⲒ ⲆⲈ ⲈⲦⲀⲤⲈⲢϨⲞϮ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤⲤⲐⲈⲢⲦⲈⲢ ⲈⲤⲈⲘⲒ ⲈⲪⲎ ⲈⲦⲀϤϢⲰⲠⲒ ⲘⲘⲞⲤ ⲀⲤⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϨⲒⲦⲤ ⲈϦⲢⲎⲒ ϦⲀⲢⲀⲦϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤϪⲈ ϮⲘⲈⲐⲘⲎⲒ ⲦⲎⲢⲤ ⲚⲀϤ
34 Jesu sì wí fún un pé, “Ọmọbìnrin, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá. Máa lọ ní àlàáfíà, ìwọ sì ti sàn nínú ààrùn rẹ.”
ⲗ̅ⲇ̅ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀⲤ ϪⲈ ⲦⲀϢⲈⲢⲒ ⲠⲈⲚⲀϨϮ ⲠⲈⲦⲀϤⲚⲀϨⲘⲒ ⲘⲀϢⲈ ⲚⲈϦⲈⲚⲞⲨϨⲒⲢⲎ ⲚⲎ ⲞⲨⲞϨ ϢⲰⲠⲒ ⲈⲞⲨⲞⲨϪⲀⲒ ⲈⲂⲞⲖ ϨⲀ ⲦⲈⲘⲀⲤⲦⲒⲄⲜ.
35 Bí Jesu sì ti ń ba obìnrin náà sọ̀rọ̀, àwọn ìránṣẹ́ dé láti ilé Jairu olórí Sinagọgu wá, wọ́n wí fún un pé, ọmọbìnrin rẹ ti kú, àti pé kí wọn má ṣe yọ Jesu lẹ́nu láti wá, nítorí ó ti pẹ́ jù.
ⲗ̅ⲉ̅ⲈⲦⲒ ⲈϤⲤⲀϪⲒ ⲀⲨⲒ ϨⲀ ⲠⲒⲀⲢⲬⲎⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲞⲤ ⲈⲨϪⲰ ⲘⲘⲞⲤ ϪⲈ ⲀⲦⲈⲔϢⲈⲢⲒ ⲘⲞⲨ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲈⲔϮϦⲒⲤⲒ ⲘⲠⲒⲢⲈϤϮⲤⲂⲰ
36 Ṣùgbọ́n bi Jesu ti gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, ó wí fún Jairu pé, “Má bẹ̀rù, sá à gbàgbọ́ nìkan.”
ⲗ̅ⲋ̅ⲒⲎⲤⲞⲨⲤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤⲤⲰⲦⲈⲘ ⲈⲠⲒⲤⲀϪⲒ ⲈⲦⲞⲨϪⲰ ⲘⲘⲞϤ ⲠⲈϪⲀϤ ⲘⲠⲒⲀⲢⲬⲎⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲞⲤ ϪⲈ ⲘⲠⲈⲢⲈⲢϨⲞϮ ⲘⲞⲚⲞⲚ ⲚⲀϨϮ
37 Nígbà náà, Jesu dá ọ̀pọ̀ ènìyàn náà dúró. Kò sì jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tẹ̀lé òun lẹ́yìn lọ ilé Jairu, bí kò ṣe Peteru, Jakọbu àti Johanu arákùnrin Jakọbu.
ⲗ̅ⲍ̅ⲞⲨⲞϨ ⲘⲠⲈϤⲬⲀ ϨⲖⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲈϤⲘⲞϢⲒ ⲚⲤⲰϤ ⲈⲂⲎⲖ ⲈⲠⲈⲦⲢⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲒⲀⲔⲰⲂⲞⲤ ⲚⲈⲘ ⲒⲰⲀⲚⲚⲎⲤ ⲠⲤⲞⲚ ⲚⲒⲀⲔⲰⲂⲞⲤ
38 Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, Jesu rí i pé gbogbo nǹkan ti dàrú. Ilé kún fún àwọn tí ń sọkún, àti àwọn tí ń pohùnréré ẹkún.
ⲗ̅ⲏ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲒ ⲈⲠⲎⲒ ⲘⲠⲒⲀⲢⲬⲎⲤⲨⲚⲀⲄⲰⲄⲞⲤ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲨⲚⲀⲨ ⲈⲢⲰⲞⲨ ⲈⲨϢⲐⲈⲢⲐⲰⲢ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨⲢⲒⲘⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲈⲨϢⲖⲎⲖⲞⲨⲒ ⲚⲞⲨⲘⲎϢ.
39 Ó wọ inú ilé lọ, o sì bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀, ó béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń sọkún tí ẹ sì ń pohùnréré ẹkún? Ọmọbìnrin náà kò kú, ó sùn lásán ni.”
ⲗ̅ⲑ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲒ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲰⲞⲨ ϪⲈ ⲈⲐⲂⲈⲞⲨ ⲦⲈⲦⲈⲚϢⲦⲈⲢⲐⲰⲢ ⲞⲨⲞϨ ⲦⲈⲦⲈⲚⲢⲒⲘⲒ ⲘⲠⲈⲤⲘⲞⲨ ⲚϪⲈϮⲀⲖⲞⲨ ⲀⲖⲖⲀ ⲀⲤⲚⲔⲞⲦ
40 Wọ́n sì fi í rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n ó sọ fún gbogbo wọn láti bọ́ síta, ó mú baba àti ìyá ọmọ náà, àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ mẹ́ta. Ó sì wọ inú yàrá tí ọmọbìnrin náà gbé dùbúlẹ̀ sí.
ⲙ̅ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲤⲰⲂⲒ ⲘⲘⲞϤ ⲚⲐⲞϤ ⲆⲈ ⲈⲦⲀϤϨⲒ ⲠⲦⲎⲢϤ ⲈⲂⲞⲖ ⲀϤⲰⲖⲒ ⲚⲈⲘⲀϤ ⲘⲪⲒⲰⲦ ⲚϮⲀⲖⲞⲨ ⲚⲈⲘ ⲦⲈⲤⲘⲀⲨ ⲚⲈⲘ ⲚⲎ ⲈⲐⲚⲈⲘⲀϤ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϢⲈ ⲚⲀϤ ⲈϦⲞⲨⲚ ⲈⲠⲒⲘⲀ ⲈⲚⲀⲢⲈ ϮⲀⲖⲞⲨ ⲬⲎ ⲘⲘⲞϤ.
41 Ó gbá a ní ọwọ́ mú, ó sì wí pé, “Talita kuumi” (tí ó túmọ̀ sí “Ọmọdébìnrin, dìde dúró!”).
ⲙ̅ⲁ̅ⲞⲨⲞϨ ⲈⲦⲀϤⲀⲘⲞⲚⲒ ⲚⲦϪⲒϪ ⲚϮⲀⲖⲞⲨ ⲠⲈϪⲀϤ ⲚⲀⲤ ϪⲈ ⲦⲀⲖⲒⲐⲀ ⲔⲞⲨⲘ ⲈⲦⲈ ⲪⲀⲒ ⲠⲈ ϪⲈ ϮⲀⲖⲞⲨ ⲀⲒϪⲈ ⲈⲢⲞ ⲦⲰⲚⲒ
42 Lẹ́sẹ̀kan náà, ọmọbìnrin náà sì dìde. Ó sì ń rìn, ẹ̀rù sì bà wọ́n, ẹnu sì ya àwọn òbí rẹ̀ gidigidi.
ⲙ̅ⲃ̅ⲞⲨⲞϨ ⲤⲀⲦⲞⲦⲤ ⲀⲤⲦⲰⲚⲤ ⲚϪⲈϮⲀⲖⲞⲨ ⲞⲨⲞϨ ⲀⲤⲘⲞϢⲒ ⲚⲀⲤϦⲈⲚ ⲒⲂ ⲄⲀⲢ ⲚⲢⲞⲘⲠⲒ ⲠⲈ ⲞⲨⲞϨ ⲚⲀⲨⲈⲢϢⲪⲎⲢⲒ ⲤⲀⲦⲞⲦⲞⲨ ⲠⲈ ϦⲈⲚⲞⲨⲚⲒϢϮ ⲚϢⲪⲎⲢⲒ
43 Jesu sì kìlọ̀ fún wọn gidigidi pé kí wọn má ṣe sọ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Ó sì wí fún wọn kí wọn fún ọmọbìnrin náà ní oúnjẹ.
ⲙ̅ⲅ̅ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϨⲞⲚϨⲈⲚ ⲚⲰⲞⲨ ⲚϨⲀⲚⲘⲎϢ ϨⲒⲚⲀ ⲚⲦⲈϢⲦⲈⲘ ϨⲖⲒ ⲈⲘⲒ ⲈⲪⲀⲒ ⲞⲨⲞϨ ⲀϤϪⲞⲤ ⲚⲦⲞⲨϮⲞⲨⲰⲘ ⲚⲀⲤ.