< Mark 5 >

1 Wọ́n lọ sí apá kejì adágún ní ẹ̀bá ilẹ̀ àwọn ará Gadara.
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲙⲏⲣ ⳿ⲉ⳿ⲫⲓⲟⲙ ⳿ⲉ⳿ⲧⲭⲱⲣⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲄⲉⲣⲅⲉⲥⲉⲛⲟⲥ.
2 Bí Jesu sì ti ń ti inú ọkọ̀ ojú omi jáde. Ọkùnrin kan tí ó ní ẹ̀mí àìmọ́ jáde ti ibojì wá pàdé rẹ̀.
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲡⲓϫⲟⲓ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲙϩⲁⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⲉϥϧⲉⲛ ⲟⲩⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲕⲁⲑⲁⲣⲧⲟⲛ.
3 Ọkùnrin yìí ń gbé nínú ibojì, kò sí ẹni tí ó lè dè é mọ́, kódà ẹ̀wọ̀n kò le dè é.
ⲅ̅ⲫⲏ ⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ ⲡⲉϥⲙⲁ⳿ⲛϣⲱⲡⲓ ϣⲟⲡ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲙϩⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲕⲉϩⲁⲗⲩⲥⲓⲥ ⳿ⲙⲙⲟⲛ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⲡⲉ ⳿ⲉⲥⲟⲛϩϥ.
4 Nítorí pé nígbà púpọ̀ ni wọ́n ti ń fi ṣẹ́kẹ́ṣẹkẹ̀ dè é lọ́wọ́ àti ẹsẹ̀, tí ó sì ń já a dànù kúrò ni ẹsẹ̀ rẹ̀. Kò sí ẹnìkan tí ó ní agbára láti káwọ́ rẹ̀.
ⲇ̅ⲉⲑⲃⲉ ϫⲉ ⲛⲉ ⲁⲩⲥⲟⲛϩϥ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲥⲟⲡ ⳿ⲛϩⲁⲛⲡⲉⲇⲏⲥ ⲛⲉⲙ ϩⲁⲛϩⲁⲗⲩⲥⲓⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲥⲱⲗⲡ ⳿ⲛⲛⲓϩⲁⲗⲩⲥⲓⲥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲓⲧⲟⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲥⲉϧⲟⲙϧⲉⲙ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲡⲉⲇⲏⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ⳿ϣϫⲟⲙ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ϩⲗⲓ ⲉⲣⲇⲁⲙⲁⲍⲓⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
5 Tọ̀sán tòru láàrín àwọn ibojì àti ní àwọn òkè ni ó máa ń kígbe rara tí ó sì ń fi òkúta ya ara rẹ̀.
ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲥⲏⲟⲩ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲉϥⲭⲏ ϧⲉⲛ ⲛⲓ⳿ⲙϩⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲭⲏ ϧⲉⲛ ⲛⲓⲧⲱⲟⲩ ⲡⲉ ⲉϥⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲉϥϣⲱⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲛϩⲁⲛ⳿ⲱⲛⲓ.
6 Nígbà tí ó sì rí Jesu látòkèrè, ó sì sáré lọ láti pàdé rẹ̀. Ó sì wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲒⲏ̅ⲥ̅ ⲓⲥϫⲉⲛ ϩⲓ ⳿ⲫⲟⲩⲉⲓ ⲁϥϭⲟϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲟⲩⲱϣⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
7 Ó sì kígbe ní ohùn rara wí pé, “Kí ní ṣe tèmi tìrẹ, Jesu Ọmọ Ọlọ́run Ọ̀gá-ògo? Mo fi Ọlọ́run bẹ̀ ọ́ má ṣe dá mi lóró.”
ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲱϣ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛ⳿ⲥⲙⲏ ⲡⲉϫⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲁϧⲟⲕ ⲛⲉⲙⲏⲓ ϩⲱⲕ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ Ⲡ̇ϣⲏⲣⲓ ⳿ⲙⲪϯ ⲉⲧϭⲟⲥⲓ ϯⲧⲁⲣⲕⲟ ⳿ⲙⲙⲟⲕ ⳿ⲙⲪϯ ⳿ⲙⲡⲉⲣϯϭⲗⲁⲕ ⲛⲏⲓ.
8 Nítorí tí Ó wí fún un pé, “Jáde kúrò lára ọkùnrin náà, ìwọ ẹ̀mí àìmọ́!”
ⲏ̅ⲛⲁϥϫⲱ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲡⲉ ϫⲉ ⳿ⲁⲙⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲡⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲕⲁⲑⲁⲣⲧⲟⲛ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲣⲱⲙⲓ.
9 Jesu sì bi í léèrè pé, “Kí ni orúkọ rẹ?” Ẹ̀mí àìmọ́ náà sì dáhùn wí pé, “Ligioni, nítorí àwa pọ̀.”
ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϣⲓⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲡⲉ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ⲡⲉ ⲡⲉⲕⲣⲁⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲗⲉⲅⲉⲱⲛ ⲡⲉ ⲡⲁⲣⲁⲛ ϫⲉ ⲧⲉⲛⲉⲣ ⲟⲩⲙⲏϣ.
10 Nígbà náà ni ẹ̀mí àìmọ́ náà bẹ̀rẹ̀ sí í bẹ Jesu gidigidi, kí ó má ṣe rán àwọn jáde kúrò ní agbègbè náà.
ⲓ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲏϣ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ϣⲧⲉⲙⲟⲩⲟⲣⲡ ⲥⲁⲃⲟⲗ ⳿ⲛϯⲭⲱⲣⲁ.
11 Agbo ẹlẹ́dẹ̀ ńlá kan sì ń jẹ lẹ́bàá òkè.
ⲓ̅ⲁ̅ⲛⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩ⳿ⲁⲅⲉⲗⲏ ⲇⲉ ⳿ⲛⲣⲓⲣ ⲉⲥⲟϣ ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⲡⲉ ⲉⲥⲙⲟⲛⲓ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲡⲓⲧⲱⲟⲩ.
12 Àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà bẹ Jesu pé, “Rán wa lọ sínú àwọn ẹlẹ́dẹ̀ wọ̀n-ọn-nì kí àwa le è wọ inú wọn lọ.”
ⲓ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲡⲉ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲟⲩⲟⲣⲡⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲛ⳿ⲓⲣⲓⲣ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲛϣⲉ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ.
13 Jesu fún wọn láààyè, àwọn ẹ̀mí àìmọ́ náà sì jáde kúrò lára ọkùnrin náà, wọ́n sì wọ inú àwọn ẹlẹ́dẹ̀ náà lọ. Agbo ẹlẹ́dẹ̀ náà tí ó tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún méjì sì túká lọ́gán, wọ́n sì sáré lọ ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè rọ́ sínú Òkun, wọ́n sì ṣègbé.
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲟⲩⲁϩⲥⲁϩⲛⲓ ⲛⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲡ͞ⲛⲁ̅ ⳿ⲛ⳿ⲁⲕⲁⲑⲣⲧⲟⲛ ⲁⲩϣⲉⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲛⲓ⳿ⲉϣⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϩⲉⲓ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϫⲉ ϯ⳿ⲁⲅⲉⲗⲏ ϧⲁⲧⲉⲛ ⲡⲓϫⲁϫⲣⲓⲙ ⳿ⲉ⳿ⲫⲓⲟⲙ ⲉⲩⲉⲣ ϣⲟ ⲃ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲱϫϩ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲟⲙ.
14 Àwọn olùtọ́jú ẹran wọ̀nyí sì sálọ sí àwọn ìlú ńlá àti ìlú kéékèèké, wọ́n sì ń tan ìròyìn náà ká bí wọ́n ti ń sáré. Àwọn ènìyàn sì tú jáde láti fojú gán-án-ní ohun náà tí ó ṣẹlẹ̀.
ⲓ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏ⳿ⲉⲛⲁⲩ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⲁⲩⲫⲱⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϫⲟⲥ ϧⲉⲛ ϯⲃⲁⲕⲓ ⲛⲉⲙ ϧⲉⲛ ⳿ⲧⲕⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉⲛⲁⲩ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ.
15 Nígbà tí wọ́n péjọ sọ́dọ̀ Jesu, wọ́n rí ọkùnrin náà, ẹni tí ó ní ẹ̀mí èṣù, tí ó jókòó níbẹ̀, ó wọ aṣọ ìyè rẹ sì bọ̀ sípò, ẹ̀rù sì bà wọ́n.
ⲓ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲫⲏ⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ ⲛⲓⲇⲉⲙⲱⲛ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲉϥϩⲉⲙⲥⲓ ⳿ⲉⲣⲉ ⲛⲉϥ⳿ϩⲃⲱⲥ ⲧⲟⲓ ϩⲓⲱⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲣⲉ ⲡⲉϥϩⲏⲧ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲉⲣϩⲟϯ.
16 Àwọn tí ìṣẹ̀lẹ̀ yìí ṣojú wọn sì ń ròyìn rẹ̀ fún àwọn ènìyàn ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí ọkùnrin ẹlẹ́mìí àìmọ́, wọ́n si sọ nípa agbo ẹlẹ́dẹ̀ náà pẹ̀lú.
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲥⲁϫⲓ ϧⲁⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩⲛⲁⲩ ϫⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛⲁϣ ⳿ⲛⲣⲏϯ ⳿ⲙⲫⲏ⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ ⲛⲓⲇⲉⲙⲱⲛ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲛⲉⲙ ⲉⲑⲃⲉ ⲛ⳿ⲓⲣⲓⲣ.
17 Nígbà náà, àwọn èrò bẹ̀rẹ̀ sí ní bẹ Jesu pé kí ó fi agbègbè àwọn sílẹ̀.
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⳿ⲛϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲉϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗϧⲉⲛ ⲛⲟⲩⲑⲟϣ.
18 Bí Jesu ti ń wọ inú ọkọ̀ ojú omi lọ, ọkùnrin náà tí ó ti ní ẹ̀mí àìmọ́ tẹ́lẹ̀ bẹ̀ Ẹ́ pé kí òun lè bá a lọ.
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲁⲗⲏⲓ ⳿ⲉⲡⲓϫⲟⲓ ⲛⲁϥϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏ⳿ⲉⲛⲁϥⲟⲓ ⳿ⲛⲇⲉⲙⲱⲛ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲟϩⲓ ⲛⲉⲙⲁϥ.
19 Jesu kò gbà fún un, ṣùgbọ́n ó wí fún un pé, “Lọ sí ilé sí ọ̀dọ̀ àwọn ẹbí rẹ, kí o sì sọ fún wọn bí Ọlọ́run ti ṣe ohun ńlá fún ọ, àti bí ó sì ti ṣàánú fún ọ.”
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉϥⲭⲁϥ ⲁⲗⲗⲁ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⲙⲁϣⲉⲛⲁⲕ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲉⲕⲏⲓ ϩⲁ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉⲛⲟⲩⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲙⲁⲧⲁⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁ Ⲡ⳪ ⲁⲓⲧⲟⲩ ⲛⲁⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲛⲁⲓ ⲛⲁⲕ.
20 Nítorí náà, ọkùnrin yìí padà lọ, ó bẹ̀rẹ̀ sí ròyìn ní Dekapoli nípa ohun ńlá tí Jesu ṣe fún un. Ẹnu sì ya gbogbo ènìyàn.
ⲕ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϩⲱⲗ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⳿ⲛϩⲓⲱⲓϣ ϧⲉⲛ ϯⲙⲏϯ ⳿ⲙⲃⲁⲕⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲧⲁϥⲁⲓϥ ⲛⲁϥ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲡⲉ.
21 Nígbà tí Jesu sì ti inú ọkọ̀ rékọjá sí apá kejì Òkun, ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn péjọ yí i ká ní etí Òkun.
ⲕ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⲟⲛ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲉⲙⲏⲣ ϧⲉⲛ ⲡⲓϫⲟⲓ ⲁⲩⲑⲱⲟⲩϯ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲉϥⲟϣ ϩⲁⲣⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥⲭⲏ ⲡⲉ ϧⲁⲧⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲟⲙ.
22 Ọ̀kan nínú àwọn olórí Sinagọgu tí à ń pè ni Jairu wá sọ́dọ̀ Jesu, nígbà tí ó sì rí i, ó wólẹ̀ níwájú rẹ̀.
ⲕ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥ⳿ⲓ ϩⲁⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲁⲣⲭⲏⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲟⲥ ⳿ⲉⲡⲉϥⲣⲁⲛ ⲡⲉ Ⲓⲁⲓⲣⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲁϥϩⲓⲧϥ ϧⲁⲣⲁⲧⲟⲩ ⳿ⲛⲛⲉϥϭⲁⲗⲁⲩϫ.
23 Ó sì bẹ̀ ẹ́ gidigidi pé, “Ọmọbìnrin mi wà lójú ikú, mo bẹ̀ ọ́, wá fi ọwọ́ rẹ lé e, kí ara rẹ̀ lè dá, kí ó sì yè.”
ⲕ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲏϣ ⲉϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲧⲁϣⲉⲣⲓ ⲁⲥϧⲱⲛⲧ ⳿ⲉ⳿ⲫⲙⲟⲩ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲕ⳿ⲓ ⳿ⲛⲧⲉⲕⲭⲁ ⲧⲉⲕϫⲓϫ ⳿ⲉϫⲱⲥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉⲥⲛⲟϩⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉⲥⲱⲛϧ.
24 Jesu sì ń bá a lọ. Ọ̀pọ̀ ìjọ ènìyàn sì ń tọ̀ Ọ́ lẹ́yìn.
ⲕ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲉϥⲟϣ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϩⲟϫϩⲉϫ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲡⲉ.
25 Obìnrin kan sì wà láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn náà, tí ó ti ní ìsun ẹ̀jẹ̀ fún odidi ọdún méjìlá.
ⲕ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲓⲥ ⲟⲩ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲁⲥⲉⲣ ⲓ̅ⲃ̅ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⳿ⲉⲣⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲟⲩ⳿ⲥⲛⲟϥ ϧⲁⲣⲟⲥ.
26 Ẹni tí ojú rẹ̀ sì ti rí ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìpọ́njú lọ́dọ̀ ọ̀pọ̀ àwọn oníṣègùn, tí ó sì ti ná gbogbo ohun tí ó ní, síbẹ̀ kàkà kí ó san, ó ń burú sí i.
ⲕ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϭⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛϧⲓⲥⲓ ⳿ⲛⲧⲟⲧⲟⲩ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲏϣ ⳿ⲛⲥⲏⲓⲛⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϭⲉ ⲛⲉⲧⲉⲛⲧⲁⲥ ⲛⲓⲃⲉⲛ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉⲥϫⲉⲙϩⲏⲟⲩ ⳿ⲛ⳿ϩⲗⲓ ⲁⲗⲗⲁ ⲙⲁⲗⲗⲟⲛ ⲛⲁⲥ⳿ⲧϩⲟ ⳿ⲛϩⲟⲩ⳿ⲟ.
27 Nígbà tí ó sì gbúròó iṣẹ́ ìyanu tí Jesu ṣe, ìdí nìyìí tí ó fi wá sẹ́yìn rẹ̀, láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn, ó sì fọwọ́ kan aṣọ rẹ̀.
ⲕ̅ⲍ̅⳿ⲉⲧⲁⲥⲥⲱⲧⲉⲙ ⲉⲑⲃⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲁⲥ⳿ⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲏϣ ϩⲓⲫⲁϩⲟⲩ ⲁⲥϭⲓⲛⲉⲙ ⲡⲉϥ⳿ϩⲃⲟⲥ.
28 Nítorí ti ó rò ní ọkàn rẹ̀ pé, “Bí mo bá sá à lè fi ọwọ́ kan aṣọ rẹ̀, ara mi yóò dá.”
ⲕ̅ⲏ̅ⲛⲁⲥϫⲱ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲡⲉ ϫⲉ ⲕⲁⲛ ⲁⲓϣⲁⲛϭⲓⲛⲉⲙ ⲡⲉϥ⳿ϩⲃⲱⲥ ϯⲛⲁⲛⲟϩⲉⲙ.
29 Ìsun ẹ̀jẹ̀ rẹ̀ sì gbẹ lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, òun sì mọ̀ lára rẹ̀ pé, a mú òun láradá kúrò nínú ààrùn náà.
ⲕ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲟⲧⲥ ⲁⲥϣⲱⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ϯⲙⲟⲩⲙⲓ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲉⲥ⳿ⲥⲛⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥ⳿ⲉⲙⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲉⲥⲥⲱⲙⲁ ϫⲉ ⲁⲥⲟⲩϫⲁⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲁ ϯⲙⲁⲥⲧⲓⲅⲝ.
30 Lọ́gán, Jesu sì mọ̀ nínú ara rẹ̀ pé agbára jáde lára òun. Ó yípadà láàrín ọ̀pọ̀ ènìyàn, ó sì béèrè, “Ta ni ó fi ọwọ́ kan aṣọ mi?”
ⲗ̅ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ⲁϥ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛϫⲉ Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⳿ⲛ⳿ϧⲣⲏⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧϥ ⳿ⲉϯϫⲟⲙ ⳿ⲉⲧⲁⲥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲧⲁϥⲫⲟⲛϩϥ ⲇⲉ ϧⲉⲛ ⲡⲓⲙⲏϣ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ⲡⲉⲧⲁϥϭⲓⲛⲉⲙ ⲛⲁ⳿ϩⲃⲱⲥ.
31 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ wí fún un pé, “Ìwọ rí ọ̀pọ̀ ènìyàn tí ó rọ̀gbà yí ọ ká, ìwọ sì tún ń béèrè ẹni tí ó fi ọwọ́ kàn ọ́?”
ⲗ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲁϥ ⲡⲉ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ ϫⲉ ⳿ⲭⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲡⲓⲙⲏϣ ⲉϥϩⲟϫϩⲉϫ ⳿ⲙⲙⲟⲕ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲕϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ⲡⲉⲧⲁϥϭⲓⲛⲉⲙⲏⲓ.
32 Síbẹ̀, Jesu bẹ̀rẹ̀ sí wò yíká láti rí ẹni náà, tí ó fi ọwọ́ kan òun.
ⲗ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲟⲩϣⲧ ⲡⲉ ⳿ⲉⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲑⲏ⳿ⲉⲧⲁⲥⲉⲣ ⲫⲁⲓ.
33 Nígbà náà, obìnrin náà kún fún ìbẹ̀rù àti ìwárìrì nítorí ó ti mọ ohun tí ó ṣẹlẹ̀ lára òun. Ó sì kúnlẹ̀ níwájú rẹ̀, ó sì sọ gbogbo òtítọ́ fún un.
ⲗ̅ⲅ̅ϯ⳿ⲥϩⲓⲙⲓ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲁⲥⲉⲣϩⲟϯ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥ⳿ⲥⲑⲉⲣⲧⲉⲣ ⲉⲥ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲫⲏ⳿ⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲁⲥ⳿ⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϩⲓⲧⲥ ⳿ⲉ⳿ϧⲣⲏⲓ ϧⲁⲣⲁⲧϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϫⲉ ϯⲙⲉⲑⲙⲏⲓ ⲧⲏⲣⲥ ⲛⲁϥ.
34 Jesu sì wí fún un pé, “Ọmọbìnrin, ìgbàgbọ́ rẹ mú ọ láradá. Máa lọ ní àlàáfíà, ìwọ sì ti sàn nínú ààrùn rẹ.”
ⲗ̅ⲇ̅⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲧⲁϣⲉⲣⲓ ⲡⲉⲛⲁϩϯ ⲡⲉⲧⲁϥⲛⲁϩⲙⲓ ⲙⲁϣⲉⲛⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩϩⲓⲣⲏⲛⲏ ⲟⲩⲟϩ ϣⲱⲡⲓ ⲉⲩⲟⲩϫⲁⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗϩⲁ ⲧⲉⲙⲁⲥⲧⲓⲅⲝ.
35 Bí Jesu sì ti ń ba obìnrin náà sọ̀rọ̀, àwọn ìránṣẹ́ dé láti ilé Jairu olórí Sinagọgu wá, wọ́n wí fún un pé, ọmọbìnrin rẹ ti kú, àti pé kí wọn má ṣe yọ Jesu lẹ́nu láti wá, nítorí ó ti pẹ́ jù.
ⲗ̅ⲉ̅⳿ⲉⲧⲓ ⲉϥⲥⲁϫⲓ ⲁⲩ⳿ⲓ ϩⲁ ⲡⲓⲁⲣⲭⲏⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲟⲥ ⲉⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲁ ⲧⲉⲕϣⲉⲣⲓ ⲙⲟⲩ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⳿ⲕϯϧⲓⲥⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ.
36 Ṣùgbọ́n bi Jesu ti gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, ó wí fún Jairu pé, “Má bẹ̀rù, sá à gbàgbọ́ nìkan.”
ⲗ̅ⲋ̅Ⲓⲏ̅ⲥ̅ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲁϥⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲉⲧⲟⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲙⲡⲓⲁⲣⲭⲏⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲟⲥ ϫⲉ ⳿ⲙⲡⲉⲣⲉⲣϩⲟϯ ⲙⲟⲛⲟⲛ ⲛⲁϩϯ.
37 Nígbà náà, Jesu dá ọ̀pọ̀ ènìyàn náà dúró. Kò sì jẹ́ kí ẹnikẹ́ni tẹ̀lé òun lẹ́yìn lọ ilé Jairu, bí kò ṣe Peteru, Jakọbu àti Johanu arákùnrin Jakọbu.
ⲗ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉϥⲭⲁ ⳿ϩⲗⲓ ⲛⲉⲙⲁϥ ⲉϥⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛⲥⲱϥ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ⳿ⲉⲠⲉⲧⲣⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲓⲁⲕⲱⲃⲟⲥ ⲛⲉⲙ Ⲓⲱⲁⲛⲛⲏⲥ ⳿ⲡⲥⲟⲛ ⳿ⲛⲒⲁⲕⲱⲃⲟⲥ.
38 Nígbà tí wọ́n dé ibẹ̀, Jesu rí i pé gbogbo nǹkan ti dàrú. Ilé kún fún àwọn tí ń sọkún, àti àwọn tí ń pohùnréré ẹkún.
ⲗ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ⲡⲏⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲁⲣⲭⲏⲥⲩⲛⲁⲅⲱⲅⲟⲥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲉⲩ⳿ϣⲑⲉⲣⲑⲱⲣ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩⲣⲓⲙⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩ⳿ϣⲗⲏⲗⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛⲟⲩⲙⲏϣ.
39 Ó wọ inú ilé lọ, o sì bá àwọn ènìyàn sọ̀rọ̀, ó béèrè pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń sọkún tí ẹ sì ń pohùnréré ẹkún? Ọmọbìnrin náà kò kú, ó sùn lásán ni.”
ⲗ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲉⲑⲃⲉ ⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ϣⲧⲉⲣⲑⲱⲣ ⲟⲩⲟϩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲣⲓⲙⲓ ⳿ⲙⲡⲉⲥⲙⲟⲩ ⳿ⲛϫⲉ ϯ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲁⲗⲗⲁ ⲁⲥⲉⲛⲕⲟⲧ.
40 Wọ́n sì fi í rẹ́rìn-ín. Ṣùgbọ́n ó sọ fún gbogbo wọn láti bọ́ síta, ó mú baba àti ìyá ọmọ náà, àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ mẹ́ta. Ó sì wọ inú yàrá tí ọmọbìnrin náà gbé dùbúlẹ̀ sí.
ⲙ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲥⲱⲃⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲡⲉ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲇⲉ ⳿ⲉⲧⲁϥϩⲓ ⳿ⲡⲧⲏⲣϥ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲁϥ⳿ⲱⲗⲓ ⲛⲉⲙⲁϥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲓⲱⲧ ⳿ⲛϯ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⲧⲉⲥⲙⲁⲩ ⲛⲉⲙ ⲛⲏⲉⲑⲛⲉⲙⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϣⲉⲛⲁϥ ⳿ⲉϧⲟⲩⲛ ⳿ⲉⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲛⲁⲣⲉ ϯ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲭⲏ ⳿ⲙⲙⲟϥ.
41 Ó gbá a ní ọwọ́ mú, ó sì wí pé, “Talita kuumi” (tí ó túmọ̀ sí “Ọmọdébìnrin, dìde dúró!”).
ⲙ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥ⳿ⲁⲙⲟⲛⲓ ⳿ⲛ⳿ⲧϫⲓϫ ⳿ⲛϯ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲁⲥ ϫⲉ ⲧⲁⲗⲓⲑⲁ ⲕⲟⲩⲙⲓ ⳿ⲉⲧⲉ ⲫⲁⲓ ⲡⲉ ϫⲉ ϯ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲉⲓϫⲉⲣⲟ ⲧⲱⲟⲩⲛⲓ.
42 Lẹ́sẹ̀kan náà, ọmọbìnrin náà sì dìde. Ó sì ń rìn, ẹ̀rù sì bà wọ́n, ẹnu sì ya àwọn òbí rẹ̀ gidigidi.
ⲙ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲟⲧⲥ ⲁⲥⲧⲱⲛⲥ ⳿ⲛϫⲉ ϯ⳿ⲁⲗⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥⲙⲟϣⲓ ⲛⲁⲥϧⲉⲛ ⲓ̅ⲃ̅ ⲅⲁⲣ ⳿ⲛⲣⲟⲙⲡⲓ ⲡⲉ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩⲉⲣ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ ⲥⲁⲧⲟⲧⲟⲩ ⲡⲉ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛ⳿ϣⲫⲏⲣⲓ.
43 Jesu sì kìlọ̀ fún wọn gidigidi pé kí wọn má ṣe sọ ohun tí ó ti ṣẹlẹ̀. Ó sì wí fún wọn kí wọn fún ọmọbìnrin náà ní oúnjẹ.
ⲙ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϩⲟⲛϩⲉⲛ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲏϣ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲧⲉ⳿ϣⲧⲉⲙ ⳿ϩⲗⲓ ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲉⲫⲁⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥϫⲟⲥ ⳿ⲛⲧⲟⲩϯⲟⲩⲱⲙ ⲛⲁⲥ

< Mark 5 >