< Mark 4 >

1 Jesu sì tún bẹ̀rẹ̀ sí ń kọ́ni létí Òkun, àwọn ìjọ ènìyàn tí ó yí i ká pọ̀ jọjọ tó bẹ́ẹ̀ tí ó fi bọ́ sínú ọkọ̀ ojú omi, tí ó sì jókòó nínú rẹ̀ lẹ́gbẹ̀ẹ́ Òkun, nígbà tí àwọn ènìyàn sì wà ní ilẹ̀ létí Òkun.
ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲁⲗⲓⲛ ⲁϥⲉⲣϩⲏⲧⲥ ⳿ⲛϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲉ⳿ⲥⲕⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲟⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲑⲱⲟⲩϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲙⲏϣ ⲉϥⲟϣ ϩⲱⲥⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲁⲗⲏⲓ ⳿ⲉ⳿ⲡϫⲟⲓ ⳿ⲛⲧⲉϥϩⲉⲙⲥⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲟⲙ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲣⲉ ⲡⲓⲙⲏϣ ⲧⲏⲣϥ ϧⲁⲧⲉⲛ ⳿ⲫⲓⲟⲙ ϩⲓ ⲡⲓ⳿ⲭⲣⲟ.
2 Ó bẹ̀rẹ̀ sí í fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀ nínú ẹ̀kọ́ rẹ̀ pé,
ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲛϩⲁⲛⲙⲏϣ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲧⲉϥ⳿ⲥⲃⲱ.
3 “Ẹ fi etí sílẹ̀! Ní ọjọ́ kan, afúnrúgbìn kan jáde lọ láti lọ fúnrúgbìn rẹ̀.
ⲅ̅ϫⲉ ⲥⲱⲧⲉⲙ ϩⲏⲡⲡⲉ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲣⲉϥⲥⲓϯ ⳿ⲉⲥⲓϯ.
4 Bí ó ti ń fúnrúgbìn, díẹ̀ bọ́ sí ẹ̀bá ọ̀nà, àwọn ẹyẹ sì wá, wọ́n sì ṣà á jẹ.
ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⳿ⲡϫⲓⲛ⳿ⲑⲣⲉϥⲥⲓϯ ⲟⲩⲁⲓ ⲙⲉⲛ ⲁϥϩⲉⲓ ⳿ⲉ⳿ⲥⲕⲉⲛ ⲡⲓⲙⲱⲓⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓϩⲁⲗⲁϯ ⲁⲩⲟⲩⲟⲙϥ.
5 Díẹ̀ bọ́ sórí ilẹ̀ àpáta, níbi tí erùpẹ̀ ko sí púpọ̀. Láìpẹ́ ọjọ́, ó hu jáde.
ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⲁϥϩⲉⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓⲙⲁ⳿ⲙⲡⲉⲧⲣⲁ ⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲛⲕⲁϩⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ⲁϥⲣⲱⲧ ⲉⲑⲃⲉ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲉϥ ϣⲱⲕ ⳿ⲛⲕⲁϩⲓ.
6 Ṣùgbọ́n nígbà tí oòrùn mú gangan, ó jóná, nítorí tí kò ní gbòǹgbò, ó gbẹ.
ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲟⲧⲉ ⳿ⲉⲧⲁϥϣⲁⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲫⲣⲏ ⲁϥⲉⲣⲕⲁⲩⲙⲁ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲑⲃⲉ ϫⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲉϥ ⲛⲟⲩⲛⲓ ⲁϥϣⲱⲟⲩ⳿ⲓ.
7 Àwọn irúgbìn mìíràn sì bọ́ sáàrín ẹ̀gún, nígbà tí ẹ̀gún sì dàgbàsókè, ó fún wọn pa, tó bẹ́ẹ̀ tí àwọn irúgbìn náà kò le so èso.
ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⲁϥϩⲉⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲛⲓⲥⲟⲩⲣⲓ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓⲥⲟⲩⲣⲓ ⲁⲩⲟϫϩϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲡⲉϥϯⲟⲩⲧⲁϩ.
8 Ṣùgbọ́n òmíràn bọ́ sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, o sì so èso lọ́pọ̀lọ́pọ̀, òmíràn ọgbọọgbọ̀n, òmíràn ọgọọgọ́ta, àti òmíràn ọgọọgọ́rùn-ún.”
ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲕⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲁⲩϩⲉⲓ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲟⲩⲕⲁϩⲓ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩϯ ⲟⲩⲧⲁϩ ⲉϥⲛⲏⲟⲩ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⲁϥⲉⲣⲉⲩⲑⲉⲛⲓⲛ ⲟⲩⲟϩ ⲟⲩⲁⲓ ⲁϥⲉⲛ ⲗ̅ ⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⲝ̅ ⲕⲉⲟⲩⲁⲓ ⲣ̅.
9 Jesu sì wí pé, “Ẹni tí ó bá ní etí láti fi gbọ́, kí ó gbọ́.”
ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲙⲁϣϫ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⲙⲁⲣⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ.
10 Nígbà tí ó ku òun nìkan pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjìlá àti àwọn mìíràn, wọ́n bi í léèrè wí pé, “Kí ni ìtumọ̀ òwe rẹ̀?”
ⲓ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧϥ ⲛⲁⲩϯϩⲟ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲏⲉⲧⲕⲱϯ ⳿ⲉⲣⲟϥ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ ⲓ̅ⲃ̅ ⲉⲑⲃⲉ ⲛⲓⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ.
11 Ó sì dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin ni a gbà láààyè láti mọ ohun ìjìnlẹ̀ nípa ìjọba Ọlọ́run. Èyí tí ó pamọ́ sí àwọn tí ó wà lẹ́yìn agbo ìjọba náà.
ⲓ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϥϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉⲧⲉ ⲥⲧⲟⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲉ⳿ⲉⲙⲓ ⳿ⲛⲛⲓⲙⲩⲥⲧⲏⲣⲓⲟⲛ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⲛⲏⲇⲉ ⳿ⲛⲑⲱⲟⲩ ⲉⲧⲥⲁⲃⲟⲗ ϣⲁⲣⲉ ⳿ⲡⲧⲏⲣϥ ϣⲱⲡⲓ ⲛⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ϩⲁⲛⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ.
12 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ wí pé, “‘wọn yóò rí i, wọn yóò sì gbọ́, kì yóò yé wọn, bẹ́ẹ̀ ni wọn kì yóò sì yípadà sí Ọlọ́run. Tàbí kí a dárí ẹ̀ṣẹ̀ jì wọ́n!’”
ⲓ̅ⲃ̅ϩⲓⲛⲁ ⲉⲩⲛⲁⲩ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲛⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩ⳿ϣⲧⲉⲙⲛⲁⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲉⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩ⳿ϣⲧⲉⲙⲕⲁϯ ⲙⲏ ⲡⲟⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲕⲟⲧⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲭⲱ ⲛⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ.
13 Ṣùgbọ́n Jesu wí fún wọn pé, “Bí òwe tí ó rọrùn yìí kò bá yé e yín? Báwo ni ẹ̀yin yóò ṣe mọ ìtumọ̀ àwọn mìíràn tí mo ń sọ fún un yín?
ⲓ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ⳿ⲉⲧⲁⲓⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲱⲥ ⲛⲓⲕⲉⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁⲥⲟⲩ⳿ⲱⲛⲟⲩ.
14 Afúnrúgbìn ń fúnrúgbìn ọ̀rọ̀ náà.
ⲓ̅ⲇ̅ⲫⲏⲉⲧⲥⲓϯ ⲁϥⲥⲓϯ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ.
15 Àwọn èso tó bọ́ sí ojú ọ̀nà, ni àwọn ọlọ́kàn líle tí wọ́n gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run, lójúkan náà èṣù wá ó sì mú kí wọn gbàgbé ohun tí wọ́n ti gbọ́.
ⲓ̅ⲉ̅ⲛⲁⲓ ⲇⲉ ⲛⲉ ⲛⲏⲉⲧϩⲓ ⳿ⲉ⳿ⲥⲕⲉⲛ ⲡⲓⲙⲱⲓⲧ ⲡⲓⲙⲁ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲓϯ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ⲇⲉ ϣⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⳿ⲡⲥⲁⲧⲁⲛⲁⲥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲱⲗⲓ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲁⲧϥ ⳿ⲛϧⲣⲏⲓ ϧⲉⲛ ⲡⲟⲩϩⲏⲧ.
16 Bákan náà, àwọn tí ó bọ́ sórí àpáta, ni àwọn ènìyàn tí wọ́n fi ayọ̀ gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run.
ⲓ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲓ ⲟⲛ ⳿ⲙⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲡⲉ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲁⲧⲟⲩ ϩⲓϫⲉⲛ ⲛⲓⲙⲁ⳿ⲙⲡⲉⲧⲣⲁ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲁⲩϣⲁⲛⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲁϫⲓ ϣⲁⲩϭⲓⲧϥ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲣⲁϣⲓ.
17 Ṣùgbọ́n kò ni gbòǹgbò tí ó jinlẹ̀ ní ọkàn wọn. Ṣùgbọ́n wọ́n á wà fún ìgbà díẹ̀, lẹ́yìn náà nígbà ti wàhálà tàbí inúnibíni bá dìde nítorí ọ̀rọ̀ náà, lójúkan náà, wọ́n á kọsẹ̀.
ⲓ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲛⲟⲩⲛⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⲁⲗⲗⲁ ϩⲁⲛ⳿ⲡⲣⲟⲥ ⲟⲩⲥⲏⲟⲩ ⲛⲉ ⳿ⲓⲧⲁ ⳿ⲁⲣⲉϣⲁⲛ ⲟⲩϩⲟϫϩⲉϫ ϣⲱⲡⲓ ⲓⲉ ⲟⲩⲇⲓⲱⲅⲙⲟⲥ ⲉⲑⲃⲉ ⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⲥⲁⲧⲟⲧⲟⲩ ϣⲁⲩⲉⲣ⳿ⲥⲕⲁⲛⲇⲁⲗⲓⲍⲉⲥⲑⲉ.
18 Àwọn tí ó bọ́ sáàrín ẹ̀gún ni àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ náà, tí wọn sì gbà á.
ⲓ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ϩⲁⲛⲕⲉⲟⲩⲟⲛ ⲛⲉ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲁⲧⲟⲩ ϩⲓϫⲉⲛ ⲛⲓⲥⲟⲩⲣⲓ ⲛⲁⲓ ⲛⲉ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲁϫⲓ.
19 Ṣùgbọ́n láìpẹ́ jọjọ, àwọn adùn ayé àti inú dídùn, ọrọ̀ àti ìjàkadì fún àṣeyọrí àti ìfẹ́ àwọn ohun mèremère ayé, gba ọkàn wọn, wọ́n sì fún ọ̀rọ̀ náà pa ní ọkàn wọn. Ọ̀rọ̀ náà sì jẹ́ aláìléso. (aiōn g165)
ⲓ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓⲣⲱⲟⲩϣ ⳿ⲛⲧⲉ ⲡⲁⲓ⳿⳿ⲉⲛⲉϩ ⲛⲉⲙ ϯ⳿ⲁⲡⲁⲧⲏ ⳿ⲛⲧⲉ ϯⲙⲉⲧⲣⲁⲙⲁ⳿ⲟ ⲛⲉⲙ ⲛⲓ⳿ⲉⲡⲓⲑⲩⲙⲓ⳿ⲁ ⳿ⲛⲧⲉ ⲛⲓⲕⲉⲥⲱϫⲡ ⲉⲩⲙⲟϣⲓ ⳿ⲛϧⲏⲧⲟⲩ ⲥⲉⲱϫϩ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁϥⲉⲣⲁⲧⲟⲩⲧⲁϩ. (aiōn g165)
20 Ṣùgbọ́n àwọn tí ó bọ́ sí ilẹ̀ ọlọ́ràá, ní àwọn tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Ọlọ́run tí wọ́n sì gbà á lóòtítọ́, wọ́n sì mú èso púpọ̀ jáde fún Ọlọ́run ní ọgbọọgbọ̀n, ọgọọgọ́ta, àti òmíràn ọgọọgọ́rùn-ún, gẹ́gẹ́ bí a ti gbìn ín sí ọkàn wọn.”
ⲕ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲏ ϩⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲥⲁⲧⲟⲩ ⳿ⲉϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⲉⲑⲛⲁⲛⲉϥ ⲛⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲁⲩϣⲁⲛⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲡⲓⲥⲁϫⲓ ϣⲁⲩϣⲟⲡϥ ⳿ⲉⲣⲱⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁⲩϯ ⲟⲩⲧⲁϩ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲗ̅ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲝ̅ ⲟⲩⲁⲓ ⳿ⲛⲣ̅.
21 Ó sì wí fún wọn pé, “A ha lè gbé fìtílà wá láti fi sábẹ́ òsùwọ̀n tàbí sábẹ́ àkéte? Rárá o, ki a ṣe pe a o gbé e ka orí ọ̀pá fìtílà?
ⲕ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⲙⲏⲧⲓ ϣⲁⲩϭⲉⲣⲉ ⲟⲩϧⲏⲃⲥ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉⲭⲁϥ ϧⲁ ⲡⲓⲙⲉⲛⲧ ⲓⲉ ϧⲁ ⲡⲓϭⲗⲟϫ ⲟⲩⲭⲓ ϩⲓⲛⲁ ⳿ⲛⲥⲉⲭⲁϥ ϩⲓϫⲉⲛ ϯⲗⲩⲭⲛⲓ⳿ⲁ.
22 Gbogbo ohun tí ó pamọ́ nísinsin yìí yóò hàn ní gbangba ní ọjọ́ kan, bẹ́ẹ̀ ni kò sí ohun tí ó wà ní ìkọ̀kọ̀, bí kò ṣe pé kí ó le yọ sí gbangba.
ⲕ̅ⲃ̅ⲟⲩ ⲅⲁⲣ ⳿ⲙⲙⲟⲛ ⲡⲉⲧϩⲏⲡ ⲁϥ⳿ϣⲧⲉⲙⲟⲩⲱⲛϩ ⳿ⲉⲃⲟⲗ ⲟⲩⲇⲉ ⳿ⲙⲡⲁϥϣⲱⲡⲓ ⲉϥϩⲏⲡ ⳿ⲉⲃⲏⲗ ϫⲉ ⳿ⲛⲧⲉϥ⳿ⲓ ⲉϥⲟⲩⲱⲛϩ.
23 Bí ẹnikẹ́ni bá ní etí láti fi gbọ́, kí ó gbọ́.”
ⲕ̅ⲅ̅ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛ ⲙⲁϣϫ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⳿ⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⲙⲁⲣⲉϥⲥⲱⲧⲉⲙ.
24 Ó sì tún tẹ̀síwájú pé, “Ẹ máa kíyèsi ohun tí ẹ bà gbọ́ dáradára, nítorí òsùwọ̀n tí ẹ̀yin bá fi wọ́n náà ni a ó fi wọ́n fún un yín àti jù bẹ́ẹ̀ lọ.
ⲕ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⲛⲱⲟⲩ ⲟⲛ ϫⲉ ⳿ⲁⲛⲁⲩ ϫⲉ ⲟⲩ ⲡⲉ ⲧⲉⲧⲉⲛⲥⲱⲧⲉⲙ ⳿ⲉⲣⲟϥ ϧⲉⲛ ⲡⲓϣⲓ ⳿ⲉⲧⲉⲧⲉⲛⲛⲁϣⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲉⲩⲛⲁϣⲓ ⲛⲱⲧⲉⲛ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲧⲟⲩϩⲟ ⲛⲱⲧⲉⲛ ϧⲁ ⲛⲏⲉⲧⲥⲱⲧⲉⲙ.
25 Nítorí ẹni tí ó bá ní, òun ni a ó tún fi fún sí i àti lọ́wọ́ ẹni tí kò bá ní, ni a ó ti gba èyí náà tí ó ní.”
ⲕ̅ⲉ̅ⲫⲏ ⲅⲁⲣ ⳿ⲉⲧⲉ ⲟⲩⲟⲛⲧⲁϥ ⲉⲩ⳿ⲉϯ ⲛⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⳿ⲙⲙⲟⲛⲧⲁϥ ⲟⲩⲟϩ ⲫⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ ϣⲁⲩⲟⲗϥ ⳿ⲛⲧⲟⲧϥ.
26 Ó sì tún sọ èyí pé, “Èyí ni a lè fi ìjọba Ọlọ́run wé. Ọkùnrin kan ń fúnrúgbìn sí ilẹ̀.
ⲕ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲡⲉ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲣⲱⲙⲓ ⲉϥϩⲓⲟⲩ⳿ⲓ ⳿ⲙⲡⲉϥ⳿ϫⲣⲟϫ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ.
27 Lóru àti ní ọ̀sán, bóyá ó sùn tàbí ó dìde, irúgbìn náà hu jáde, ó sì dàgbà, òun kò sì mọ̀ bí ó ti ṣẹlẹ̀.
ⲕ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲉⲛⲕⲟⲧ ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲧⲉϥⲧⲱⲛϥ ⳿ⲙⲡⲓ⳿ⲉϫⲱⲣϩ ⲛⲉⲙ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁⲣⲉ ⲡⲓ⳿ϫⲣⲟϫ ⲑⲏⲛⲓ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁϥϣⲓ⳿ⲏ ϩⲱⲥ ⳿ⲛ⳿ϥ⳿ⲉⲙⲓ ⲁⲛ ⳿ⲛⲑⲟϥ.
28 Nítorí tí ilẹ̀ kọ́kọ́ hù èso jáde fún ara rẹ̀, ó mú èéhù ewé jáde, èyí tí ó tẹ̀lé e ní orí ọkà, ní ìparí, ọkà náà gbó.
ⲕ̅ⲏ̅ϣⲁⲣⲉ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⳿ⲙⲙⲁⲩⲁⲧϥ ϯⲟⲩⲧⲁϩ ⳿ⲛϣⲟⲣⲡ ⳿ⲛⲟⲩⲥⲓⲙ ⳿ⲓⲧⲁ ⲟⲩϧⲉⲙⲥ ⳿ⲓⲧⲁ ϣⲁϥⲙⲟϩ ⳿ⲛϫⲉ ⲫⲏⲉⲧ ϧⲉⲛ ⲡⲓϧⲉⲙⲥ.
29 Nígbà tí èso bá gbó tán, lẹ́sẹ̀kẹsẹ̀, òun a tẹ dòjé bọ inú ọkà náà, ó sì kórè rẹ̀.”
ⲕ̅ⲑ̅⳿ⲉϣⲱⲡ ⲇⲉ ⲁϥϣⲁⲛⲫⲟϩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲟⲩⲧⲁϩ ⲥⲁⲧⲟⲧϥ ϣⲁϥⲟⲩⲱⲣⲡ ⳿ⲙⲡⲓⲟⲥϧ ϫⲉ ⲟⲩⲏⲓ ⲅⲁⲣ ⲁϥ⳿ⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲱⲥϧ.
30 Jesu sì tún wí pé, “Kí ni kí èmi fi ìjọba Ọlọ́run wé? Òwe wo ni kí èmi fi ṣe àkàwé rẹ̀?
ⲗ̅ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁϥϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ϫⲉ ⲁⲛⲛⲁⲧⲉⲛⲑⲱⲛ ϯⲙⲉⲧⲟⲩⲣⲟ ⳿ⲛⲧⲉ Ⲫϯ ⳿ⲉⲟⲩ ⲓⲉ ⲁⲛⲛⲁⲭⲁⲥ ϧⲉⲛ ⲁϣ ⳿ⲙⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ.
31 Ó dàbí èso hóró musitadi kan, lóòótọ́, ó jọ ọ̀kan nínú àwọn èso tí ó kéré jùlọ ti a gbìn sínú ilẹ̀.
ⲗ̅ⲁ̅ⲁⲥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲛⲟⲩⲛⲁⲫⲣⲓ ⳿ⲛϣⲉⲗⲧⲁⲙ ⲑⲏ⳿ⲉⲧⲉ ⲁⲩϣⲁⲛⲥⲁⲧⲥ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ ⳿ⲉⲟⲩⲕⲟⲩϫⲓ ⲧⲉ ⳿ⲉⲛⲓ⳿ϫⲣⲟϫ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲛⲏⲉⲧ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓⲕⲁϩⲓ.
32 Síbẹ̀, nígbà tí a gbìn ín, ó dàgbàsókè, ó gbilẹ̀, ó sì di títóbi ju gbogbo ewéko inú ọgbà yòókù lọ. Ó sì yọ ẹ̀ka ńlá níbi tí àwọn ẹyẹ ọ̀run lè kọ́ ìtẹ́ wọn sí, kí wọn sì rí ìdáàbòbò.”
ⲗ̅ⲃ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉϣⲱⲡ ⳿ⲛⲧⲟⲩⲥⲁⲧⲥ ϣⲁⲥ⳿ⲓ ⳿ⲉ⳿ϩⲣⲏⲓ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⲉⲥⲟⲓ ⳿ⲛⲛⲓϣϯ ⳿ⲉⲛⲓⲟⲩ⳿ⲟϯ ⲧⲏⲣⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ϣⲁⲥ⳿⳿ⲓⲣⲓ ⳿ⲛϩⲁⲛⲛⲓϣϯ ⳿ⲛϫⲁⲗ ϩⲱⲥⲧⲉ ⳿ⲛⲧⲟⲩϫⲉⲙϫⲟⲙ ⳿ⲛϫⲉ ⲛⲓϩⲁⲗⲁϯ ⳿ⲛⲧⲉ ⳿ⲧⲫⲉ ⳿ⲉⲟⲩⲱϩ ϧⲁ ⲧⲉⲥϧⲏⲓⲃⲓ.
33 Òun lo ọ̀pọ̀ irú òwe wọ̀nyí láti fi kọ́ àwọn ènìyàn, gẹ́gẹ́ bí wọ́n bá ti ń fẹ́ láti ní òye tó.
ⲗ̅ⲅ̅ⲟⲩⲟϩ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲙⲏϣ ⳿ⲙⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⲡⲁⲓⲣⲏϯ ⲛⲁϥⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲡⲉ ⳿ⲙⲡⲓⲥⲁϫⲓ ⲕⲁⲧⲁ⳿ⲫⲣⲏϯ ⳿ⲉⲛⲁⲩ⳿ϣϫⲉⲙϫⲟⲙ ⳿ⲛⲥⲱⲧⲉⲙ.
34 Kìkì òwe ni Jesu fi ń kọ́ àwọn ènìyàn ní ẹ̀kọ́ ìta gbangba rẹ̀. Ṣùgbọ́n lẹ́yìn èyí, nígbà tí ó bá sì wà pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, òun a sì sọ ìtumọ̀ ohun gbogbo.
ⲗ̅ⲇ̅ⲟⲩⲟϩ ⲭⲱⲣⲓⲥ ⲡⲁⲣⲁⲃⲟⲗⲏ ⲛⲁϥⲥⲁϫⲓ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ⲁⲛ ⲡⲉ ⲥⲁ⳿ⲡⲥⲁ ⲇⲉ ⲛⲁϥⲃⲱⲗ ⳿ⲙ⳿ⲡⲧⲏⲣϥ ⳿⳿ⲉⲛⲉϥⲙⲁⲑⲏⲧⲏⲥ.
35 Nígbà tí alẹ́ lẹ́, Jesu wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Ẹ jẹ́ kí a rékọjá sí apá kejì.”
ⲗ̅ⲉ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϧⲉⲛ ⲡⲓ⳿ⲉϩⲟⲟⲩ ⳿ⲉⲧⲉ⳿ⲙⲙⲁⲩ ⳿ⲉⲧⲁ ⲣⲟⲩϩⲓ ϣⲱⲡⲓ ϫⲉ ⲙⲁⲣⲉⲛⲥⲓⲛⲓ ⳿ⲉⲙⲏⲣ.
36 Nígbà tí wọn ti tú ìjọ ká, wọ́n sì gbà á sínú ọkọ̀ ojú omi gẹ́gẹ́ bí ó ti wà. Àwọn ọkọ̀ ojú omi kékeré mìíràn sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀.
ⲗ̅ⲋ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁⲩⲭⲁ ⲡⲓⲙⲏϣ ⳿ⲛⲥⲱⲟⲩ ⲁⲩⲟⲗϥ ⲛⲉⲙⲱⲟⲩ ϩⲱϥ ϩⲓ ⲡⲓϫⲟⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲣⲉ ϩⲁⲛⲕⲉ⳿ⲉϫⲏⲟⲩ ⲛⲉⲙⲁϥ.
37 Ìjì líle ńlá kan sì dìde, omi sì ń bù sínú ọkọ̀, tó bẹ́ẹ̀ tí ọkọ̀ fi bẹ̀rẹ̀ sí í kún fún omi, ó sì fẹ́rẹ rì.
ⲗ̅ⲍ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲁ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛⲑⲏⲟⲩ ϣⲱⲡⲓ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲓϫⲟⲗ ⲛⲁⲩϩⲓ ⳿ⲙⲙⲱⲟⲩ ⳿ⲉⲡⲓϫⲟⲓ ϩⲱⲥⲧⲉ ϩⲏⲇⲏ ⳿ⲛⲧⲉϥⲙⲟϩ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓϫⲟⲓ.
38 Jesu ti sùn lọ lẹ́yìn ọkọ̀, ó gbé orí lé ìrọ̀rí. Wọ́n sì jí i lóhùn rara wí pé, “Olùkọ́ni, tàbí ìwọ kò tilẹ̀ bìkítà pé gbogbo wa fẹ́ rì?”
ⲗ̅ⲏ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲛⲑⲟϥ ⲛⲁϥⲉⲛⲕⲟⲧ ϩⲓⲫⲁϩⲟⲩ ϩⲓϫⲉⲛ ⲡⲓ⳿ϣϣⲟⲧ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲛⲉϩⲥⲓ ⳿ⲙⲙⲟϥ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲱⲟⲩ ⲛⲁϥ ϫⲉ ⳿ⲫⲣⲉϥϯ⳿ⲥⲃⲱ ⳿ⲥⲉⲣⲙⲉⲗⲓⲛ ⲛⲁⲕ ⲁⲛ ϫⲉ ⲧⲉⲛⲛⲁⲧⲁⲕⲟ.
39 Ó dìde, ó bá ìjì líle náà wí, ó sì wí fún òkun pé, “Dákẹ́! Jẹ́ẹ́!” Ìjì náà sì dá, ìparọ́rọ́ ńlá sì wà.
ⲗ̅ⲑ̅ⲟⲩⲟϩ ⳿ⲉⲧⲁϥⲧⲱⲛϥ ⲁϥⲉⲣ⳿ⲉⲡⲓⲧⲓⲙⲁⲛ ⳿ⲙⲡⲓⲑⲏⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⳿ⲙ⳿ⲫⲓⲟⲙ ϫⲉ ⲭⲁⲣⲱⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲑⲱⲙ ⳿ⲛⲣⲱⲕ ⲟⲩⲟϩ ⲁϥⲕⲏⲛ ⳿ⲛϫⲉ ⲡⲓⲑⲏⲟⲩ ⲟⲩⲟϩ ⲁⲥϣⲱⲡⲓ ⳿ⲛϫⲉ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛϫⲁⲙⲏ.
40 Lẹ́yìn náà, ó béèrè lọ́wọ́ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ń ṣojo bẹ́ẹ̀? Tàbí ẹ̀yin kò ì tí ì ní ìgbàgbọ́ síbẹ̀síbẹ̀?”
ⲙ̅ⲟⲩⲟϩ ⲡⲉϫⲁϥ ⲛⲱⲟⲩ ϫⲉ ⳿ⲁϧⲱⲧⲉⲛ ⲧⲉⲧⲉⲛⲉⲣϩⲟϯ ⳿ⲙⲡⲁⲧⲉ ⲛⲁϩϯ ϣⲱⲡⲓ ϧⲉⲛ ⲑⲏⲛⲟⲩ.
41 Ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi, wọ́n sì wí fún ara wọn pé, “Irú ọkùnrin wo ni èyí, tí ìjì àti Òkun ń gbọ́ tirẹ̀!”
ⲙ̅ⲁ̅ⲟⲩⲟϩ ⲁⲩⲉⲣϩⲟϯ ϧⲉⲛ ⲟⲩⲛⲓϣϯ ⳿ⲛϩⲟϯ ⲟⲩⲟϩ ⲛⲁⲩϫⲱ ⳿ⲙⲙⲟⲥ ⳿ⲛⲛⲟⲩ⳿ⲉⲣⲏⲟⲩ ϫⲉ ⲛⲓⲙ ϩⲁⲣⲁ ⲡⲉ ⲫⲁⲓ ϫⲉ ⲛⲓⲑⲏⲟⲩ ⲛⲉⲙ ⳿ⲫⲓⲟⲙ ⲥⲉⲥⲱⲧⲉⲙ ⲛⲁϥ

< Mark 4 >