< Mark 3 >

1 Nígbà tí Jesu wá sí Sinagọgu. Sì kíyèsi i ọkùnrin kan wà níbẹ̀, tí ọwọ́ rẹ̀ kan rọ.
Wszedł zasię do bóżnicy, a był tam człowiek, który miał rękę uschłą.
2 Àwọn kan nínú wọn sì ń wa ọ̀nà láti fi ẹ̀sùn kan Jesu. Nítorí náà, wọ́n ń ṣọ́ Ọ bí yóò mú un láradá ní ọjọ́ ìsinmi.
I podstrzegali go, jeźliby go w sabat uzdrowił, aby go oskarżyli.
3 Jesu wí fún ọkùnrin tí ọwọ́ rẹ̀ rọ náà pé, “Dìde dúró ní iwájú ìjọ ènìyàn.”
I rzekł onemu człowiekowi, który miał rękę uschłą: Wystąp w pośrodek.
4 Nígbà náà ni Jesu béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Ǹjẹ́ ó bá òfin mu ní ọjọ́ ìsinmi bóyá láti ṣe rere, tàbí láti ṣe búburú! Láti gbà ẹ̀mí là, tàbí pa á run?” Ṣùgbọ́n wọ́n dákẹ́ láìfèsì.
I rzekł do nich: Godzili się w sabat dobrze czynić, czyli źle czynić? człowieka zachować, czyli zabić? a oni milczeli.
5 Nígbà tí ó sì wo gbogbo wọn yíká pẹ̀lú ìbínú, ọkàn rẹ̀ sì bàjẹ́ nítorí líle àyà wọn, ó sọ fún ọkùnrin náà pé, “Na ọwọ́ rẹ jáde.” Ó nà án jáde, ọwọ́ náà sì bọ̀ sípò padà pátápátá.
Tedy spojrzawszy po nich z gniewem i zasmuciwszy się nad zatwardzeniem serca ich, rzekł onemu człowiekowi: Wyciągnij rękę twoję! i wyciągnął; i przywrócona jest ręka jego do zdrowia jako i druga.
6 Lójúkan náà, àwọn Farisi jáde lọ, láti bá àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Herodu gbìmọ̀ pọ̀, bí wọn yóò ṣe pa Jesu.
Tedy wyszedłszy Faryzeuszowie, uczynili wnet radę z Herodyjany przeciwko niemu, jakoby go stracili.
7 Jesu pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ yẹra kúrò níbẹ̀ lọ sí etí Òkun. Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn láti Galili àti Judea sì tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.
Ale Jezus z uczniami swymi ustąpił nad morze, a wielkie mnóstwo szło za nim z Galilei i z ziemi Judzkiej,
8 Nígbà tí wọ́n gbọ́ ìròyìn iṣẹ́ ìyanu tí ó ṣe, ọ̀pọ̀ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá láti Judea, Jerusalẹmu àti Idumea, àti láti apá kejì odò Jordani àti láti ìhà Tire àti Sidoni.
I z Jeruzalemu, i z Idumei, i zza Jordanu, i z tych, którzy mieszkali około Tyru i Sydonu, wielkie mnóstwo, słysząc, jak wielkie rzeczy czynił, przyszli do niego.
9 Nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, Jesu sọ fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ láti ṣètò ọkọ̀ ojú omi kékeré kan sílẹ̀ fún un láti lọ, láti lé àwọn èrò sẹ́yìn.
I rozkazał uczniom swoim, aby łódkę mieli zawsze w pogotowiu, dla ludu, aby go nie cisnęli.
10 Nítorí tí ó mú ọ̀pọ̀ ènìyàn láradá, ọ̀pọ̀lọpọ̀ àwọn aláìsàn ló bí ara wọn lù ú láti fi ọwọ́ kàn án.
Albowiem ich wiele uzdrawiał, tak iż nań padali, aby się go dotykali, którzykolwiek choroby mieli.
11 Ìgbàkúgbà tí àwọn tí ó ni ẹ̀mí àìmọ́ bá ti fojú ri, wọ́n á wólẹ̀ níwájú rẹ̀. Wọn a sì kígbe lóhùn rara wí pé, “Ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run.”
A duchowie nieczyści, gdy go ujrzeli, upadali przed nim i wołali, mówiąc: Ty jesteś Syn Boży!
12 Ṣùgbọ́n ó kìlọ̀ fún wọn gidigidi, kí wọn má ṣe fi òun hàn.
Ale ich on srodze gromił, żeby go nie objawiali.
13 Jesu gun orí òkè lọ, ó sì pe àwọn kan tí ó yàn láti wà pẹ̀lú rẹ̀, wọ́n sì tọ̀ ọ́ wá.
I wstąpił na górę, a wezwał do siebie tych, których sam chciał, i przyszli do niego.
14 Ó yan àwọn méjìlá, kí wọn kí ó lè wà pẹ̀lú rẹ̀, àti kí ó lè rán wọn lọ láti wàásù
I postanowił ich dwanaście, aby z nim byli, a iżby je wysłał kazać Ewangieliję:
15 àti láti lágbára láti lé àwọn ẹ̀mí Èṣù jáde.
I żeby mieli moc uzdrawiać choroby i wyganiać dyjabły:
16 Wọ̀nyí ni àwọn méjìlá náà tí ó yàn: Simoni (ẹni ti ó sọ àpèlé rẹ̀ ní Peteru),
Szymona, któremu imię dał Piotr;
17 Jakọbu ọmọ Sebede àti Johanu arákùnrin rẹ̀ (àwọn ẹni tí Jesu sọ àpèlé wọ́n ní Boanaji, èyí tí ó túmọ̀ sí “àwọn ọmọ àrá”).
I Jakóba, syna Zebedeuszowego, i Jana, brata Jakóbowego, (którym dał imię Boanerges, to jest: synowie gromu);
18 Àti Anderu, Filipi, Bartolomeu, Matiu, Tomasi, Jakọbu ọmọ Alfeu, Taddeu, Simoni tí ń jẹ́ Sealoti
I Andrzeja, i Filipa, i Bartłomieja, i Mateusza, i Tomasza, i Jakóba, syna Alfeuszowego, i Tadeusza, i Szymona Kananejczyka;
19 àti Judasi Iskariotu, ẹni tí ó fi í hàn níkẹyìn.
I Judasza Iszkaryjota, który go też wydał.
20 Nígbà náà ni Jesu sì wọ inú ilé kan, àwọn èrò sì tún kórajọ, tó bẹ́ẹ̀ tí Òun àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ kò rí ààyè láti jẹun.
I przyszli do domu. I zgromadził się znowu lud, tak iż nie mogli ani chleba jeść.
21 Nígbà tí àwọn ẹbí rẹ̀ gbọ́ èyí, wọ́n wá láti mú un lọ ilé, nítorí tí wọn wí pé, “Orí rẹ̀ ti dàrú.”
A gdy o tem usłyszeli jego powinni, przyszli, aby go pojmali; bo mówili, że odszedł od rozumu.
22 Àwọn olùkọ́ni ní òfin sọ̀kalẹ̀ wá láti Jerusalẹmu, wọ́n sì wí pé, “Ó ni Beelsebulu, olórí àwọn ẹ̀mí èṣù, ni ó sì fi ń lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde!”
A nauczeni w Piśmie, którzy byli przyszli z Jeruzalemu, mówili: Iż ma Beelzebuba, a iż przez książęcia dyjabelskiego wygania dyjabły.
23 Jesu pè wọ́n, ó sì fi òwe bá wọn sọ̀rọ̀: “Báwo ni Èṣù ṣe lè lé èṣù jáde?
I wezwawszy ich, mówił do nich w podobieństwach: Jakoż może szatan szatana wyganiać?
24 Bí ìjọba kan bá yapa sí ara rẹ̀, ìjọba náà yóò wó lulẹ̀.
A jeźliże królestwo samo w sobie będzie rozdzielone, nie może się ostać ono królestwo.
25 Bákan náà, bí ilé kan bá sì yapa sí ara rẹ, ilé náà kí yóò le è dúró.
I dom, jeźliby sam przeciwko sobie był rozdzielony, nie będzie się mógł ostać on dom.
26 Bí Èṣù bá sì dìde sí ara rẹ̀, tí ó sì yapa, òun kí yóò le è dúró ṣùgbọ́n òpin rẹ̀ yóò dé.
Takci, jeźli szatan powstał sam przeciwko sobie i jest rozdzielony, nie może się ostać, ale koniec bierze.
27 Kò sí ẹni tí ó le wọ ilé ọkùnrin alágbára kan lọ, kí ó sì kó o ní ẹrù lọ, bí kò ṣe pé ó kọ́kọ́ de ọkùnrin alágbára náà ní okùn, nígbà náà ni yóò lè kó ẹrù ní ilé rẹ̀.
Nikt nie może sprzętu mocarzowego, wszedłszy do domu jego, rozchwycić, jeźliby pierwej mocarza onego nie związał; a potem dom jego splądruje.
28 Lóòótọ́ ní mo wí fún yín, gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ ni a ó dáríjì àwọn ọmọ ènìyàn, àti gbogbo ọ̀rọ̀-òdì.
Zaprawdę powiadam wam, że wszystkie grzechy synom ludzkim będą odpuszczone, i bluźnierstwa, któremibykolwiek bluźnili;
29 Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá sọ̀rọ̀-òdì sí Ẹ̀mí Mímọ́, kì yóò rí ìdáríjì títí ayé, ṣùgbọ́n ó wà nínú ewu ẹ̀bi àìnípẹ̀kun.” (aiōn g165, aiōnios g166)
Ale kto bluźni przeciwko Duchowi Świętemu, nie ma odpuszczenia na wieki, ale winien jest sądu wiecznego. (aiōn g165, aiōnios g166)
30 Òun sọ eléyìí fún wọn, nítorí tí wọ́n sọ pé, “Nípa agbára ẹ̀mí àìmọ́ ló ń ṣe àwọn iṣẹ́ ìyanu rẹ̀.”
Bo mówili: Ma ducha nieczystego.
31 Nígbà náà ni àwọn arákùnrin rẹ̀ àti ìyá wá, wọ́n dúró lóde, wọ́n sì ránṣẹ́ sí i, wọ́n ń pè é.
Przyszli tedy bracia i matka jego, a stojąc przed domem, posłali do niego, i kazali go zawołać.
32 Àwọn ènìyàn tí wọ́n jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ sì wí fún un pé, “Ìyá àti àwọn arákùnrin rẹ wà lóde.”
A lud siedział około niego, i rzekli mu: Oto matka twoja i bracia twoi szukają cię przed domem.
33 Ṣùgbọ́n ó dá wọn lóhùn wí pé, “Ta ni í ṣe ìyá mi tàbí àwọn arákùnrin mi?”
Ale im on odpowiedział, mówiąc: Któż jest matka moja, i bracia moi?
34 Ó sì wò gbogbo àwọn tí ó jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀ yíká, ó sì wí pé, “Àwọn wọ̀nyí ni ìyá mi àti àwọn arákùnrin mi.
A spojrzawszy wokoło po tych, którzy koło niego siedzieli, rzekł: Oto matka moja, i bracia moi!
35 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá ń ṣe ìfẹ́ Ọlọ́run, òun ni arákùnrin mi àti arábìnrin mi àti ìyá mi.”
Albowiem ktobykolwiek czynił wolę Bożą, ten jest brat mój, i siostra moja, i matka moja.

< Mark 3 >