< Mark 2 >
1 Lẹ́yìn ọjọ́ mélòó kan, nígbà tí Jesu tún padà wọ Kapernaumu, òkìkí kàn pé ó ti wà nínú ilé.
A zasię przyszedł po kilku dniach do Kapernaum, i usłyszano, że jest w domu.
2 Láìpẹ́, ogunlọ́gọ̀ ènìyàn ti kún ilé tí ó dé sí tó bẹ́ẹ̀ tí inú ilé àti ẹ̀yìn ìlẹ̀kùn ní ìta kò gba ẹyọ ẹnìkan mọ́, ó sì wàásù ọ̀rọ̀ náà sí wọn.
A wnet zeszło się ich tak wiele, że się zmieścić nie mogli ani przede drzwiami; i opowiadał im słowo Boże.
3 Àwọn ọkùnrin kan wá, wọ́n gbé arọ tọ̀ ọ́ wá, ẹni tí ọkùnrin mẹ́rin gbé.
Tedy przyszli do niego niosący powietrzem ruszonego, którego czterej nieśli.
4 Nígbà tí wọn kò sì le dé ọ̀dọ̀ Jesu, nítorí ọ̀pọ̀ ènìyàn, wọ́n dá òrùlé ilé lu ní ọ̀gangan ibi tí Jesu wà. Wọ́n sì sọ ọkùnrin arọ náà kalẹ̀ ti òun ti àkéte rẹ̀ níwájú Jesu.
A gdy do niego przystąpić nie mogli dla ciżby, odarli dach, gdzie był Jezus, a przełamawszy go, spuścili po powrozach na dół łoże, na którem leżał powietrzem ruszony.
5 Nígbà tí Jesu sì rí ìgbàgbọ́ wọn, ó sọ fún arọ náà pé, “Ọmọ, a dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ rẹ jì ọ́.”
A widząc Jezus wiarę ich, rzekł powietrzem ruszonemu: Synu! odpuszczone są tobie grzechy twoje.
6 Ṣùgbọ́n díẹ̀ nínú àwọn olùkọ́ òfin tó jókòó níbẹ̀ sọ fún ara wọn pé,
A byli tam niektórzy z nauczonych w Piśmie, siedząc i myśląc w sercach swoich:
7 “Èéṣe ti ọkùnrin yìí fi sọ̀rọ̀ báyìí? Ó ń sọ̀rọ̀-òdì. Ta ni ó lè darí ẹ̀ṣẹ̀ ji ni bí ko ṣe Ọlọ́run nìkan?”
Czemuż ten takie mówi bluźnierstwa? któż może grzechy odpuszczać, tylko sam Bóg?
8 Lójúkan náà bí Jesu tí wòye nínú ọkàn rẹ̀ pé wọn ń gbèrò bẹ́ẹ̀ ní àárín ara wọn, ó wí fún wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yìn fi ń ro nǹkan wọ̀nyí nínú ọkàn yín?
A zaraz poznawszy Jezus duchem swym, iż tak w sobie myśleli, rzekł im: Czemuż tak myślicie w sercach waszych?
9 Èwo ni ó rọrùn jù láti wí fún arọ náà pé, ‘A dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ jì ọ,’ tàbí wí pé, ‘Dìde sì gbé àkéte rẹ, kí o sì máa rìn?’
Cóż łatwiejszego jest, rzec powietrzem ruszonemu: Odpuszczone są tobie grzechy, czyli rzec: Wstań i weźmij łoże twoje, a chodź?
10 Ṣùgbọ́n kí ẹ lè mọ̀ pé Ọmọ Ènìyàn ní agbára ní ayé láti dárí ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀ ji ni.” Ó wí fún ọkùnrin arọ náà pé,
Ale żebyście wiedzieli, iż Syn człowieczy ma moc na ziemi grzechy odpuszczać, rzekł powietrzem ruszonemu:
11 “Mo wí fún ọ, dìde, gbé àkéte rẹ kí ó sì máa lọ ilé rẹ.”
Tobie mówię: Wstań, a weźmij łoże twoje, a idź do domu twego.
12 Lójúkan náà, ọkùnrin náà fò sókè fún ayọ̀. Ó gbé àkéte rẹ̀. Ó sì jáde lọ lójú gbogbo wọn. Èyí sì ya gbogbo wọn lẹ́nu tó bẹ́ẹ̀ tí wọ́n sì yin Ọlọ́run lógo wí pé, “Àwa kò rí irú èyí rí!”
A on zarazem wstał, i wziąwszy łoże swoje, wyszedł przed wszystkimi, tak iż się wszyscy zdumiewali i chwalili Boga, mówiąc: Nigdyśmy nic takiego nie widzieli.
13 Nígbà náà, Jesu tún jáde lọ sí etí Òkun. Ọ̀pọ̀ ènìyàn sì tọ̀ ọ́ wá, ó sì bẹ̀rẹ̀ sí ní kọ́ wọn.
I wyszedł zasię nad morze, a wszystek lud przychodził do niego, i nauczał je.
14 Bí ó ti ń rin etí Òkun lọ sókè, ó rí Lefi ọmọ Alfeu tí ó jókòó nínú àgọ́ níbi tí ó ti ń gba owó orí, Jesu sì wí fún un pé, “Tẹ̀lé mi,” Lefi dìde, ó sì ń tẹ̀lé e.
A idąc mimo cła, ujrzał Lewiego, syna Alfeuszowego, siedzącego na cle, i rzekł mu: Pójdź za mną! a on wstawszy szedł za nim.
15 Ó sì ṣe, bí ó sì ti jókòó ti oúnjẹ ni ilé Lefi, ọ̀pọ̀ àwọn agbowó òde àti ẹlẹ́ṣẹ̀ wá bá Jesu jókòó pẹ̀lú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, nítorí tiwọn pọ̀ tiwọn tẹ̀lé e.
I stało się, gdy Jezus siedział za stołem w domu jego, że wiele celników i grzeszników wespół siedziało z Jezusem i z uczniami jego; bo ich wiele było, i chodzili za nim.
16 Nígbà tí àwọn olùkọ́ òfin àti àwọn Farisi rí ì tí ó ń bá àwọn agbowó òde àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ jẹun, wọn wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Èétirí tí ó fi ń bá àwọn agbowó òde àti ẹlẹ́ṣẹ̀ jẹun?”
A nauczeni w Piśmie i Faryzeuszowie widząc go, że jadł z celnikami i z grzesznikami, mówili do uczniów jego: Cóż jest, iż z celnikami i z grzesznikami je i pije?
17 Nígbà tí Jesu gbọ́, ó sọ fún wọn wí pé, “Àwọn tí ara wọ́n dá kò wa oníṣègùn, bí ko ṣe àwọn tí ara wọn kò dá. Èmi kò wá láti sọ fún àwọn ènìyàn rere láti ronúpìwàdà, bí kò ṣe àwọn ènìyàn ẹlẹ́ṣẹ̀.”
A usłyszawszy to Jezus, rzekł im: Nie potrzebują zdrowi lekarza, ale ci, co się źle mają; nie przyszedłem, wzywać sprawiedliwych, ale grzesznych do pokuty.
18 Àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti àwọn Farisi a máa gbààwẹ̀. Àwọn ènìyàn kan sì wá, wọ́n sì bi í pé, “Èéṣe tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Johanu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn Farisi fi ń gbààwẹ̀, ṣùgbọ́n àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ kò gbààwẹ̀?”
A uczniowie Janowi i Faryzejscy pościli, a przyszedłszy mówili do niego: Czemuż uczniowie Janowi i Faryzejscy poszczą, a twoi uczniowie nie poszczą?
19 Jesu dáhùn wí pé, “Báwo ni àwọn àlejò ọkọ ìyàwó yóò ṣe máa gbààwẹ̀ nígbà tí ọkọ ìyàwó ṣì wà lọ́dọ̀ wọn?
I rzekł im Jezus: Izali mogą synowie łożnicy małżeńskiej pościć, póki z nimi jest oblubieniec? Póki z sobą oblubieńca mają, nie mogą pościć.
20 Ṣùgbọ́n láìpẹ́ ọjọ́, a ó gba ọkọ ìyàwó kúrò lọ́dọ̀ wọn. Nígbà náà wọn yóò gbààwẹ̀ ni ọjọ́ wọ̀nyí.”
Ale przyjdą dni, gdy od nich odjęty będzie oblubieniec, a tedy będą pościć w one dni.
21 “Kò sí ẹni tí ń fi ìrépé aṣọ tuntun lẹ ògbólógbòó ẹ̀wù, bí ó ba ṣe bẹ́ẹ̀, èyí tuntun tí a fi lẹ̀ ẹ́ yóò fàya kúrò lára ògbólógbòó, yíya rẹ̀ yóò sí burú púpọ̀ jù.
A żaden nie wprawuje łaty sukna nowego w szatę wiotchą, inaczej ona jego łata nowa ujmuje nieco od wiotchej szaty, i stawa się gorsze rozdarcie.
22 Kò sì sí ẹni tí ń fi ọtí wáìnì tuntun sínú ìgò wáìnì ògbólógbòó. Bí a bá ṣe bẹ́ẹ̀, ọtí wáìnì náà yóò fa ìgò náà ya, ọtí wáìnì a sì dàànù, bákan náà ni ìgò náà, ṣùgbọ́n ọtí wáìnì tuntun ni a n fi sínú ìgò wáìnì tuntun.”
I żaden nie leje wina młodego w stare statki; bo inaczej wino młode rozsadza statki, i wycieka wino, a statki się psują; ale wino nowe ma być wlewane w statki nowe.
23 Ó sì ṣe ni ọjọ́ ìsinmi, bí Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ ti ń kọjá lọ láàrín oko ọkà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ bẹ̀rẹ̀ sí í ya ìpẹ́ ọkà.
I stało się, że szedł Jezus w sabat przez zboża, i poczęli uczniowie jego idąc rwać kłosy.
24 Díẹ̀ nínú àwọn Farisi wí fún Jesu pé, “Wò ó, èéṣe tiwọn fi ń ṣe èyí ti kò yẹ ni ọjọ́ ìsinmi.”
Ale Faryzeuszowie mówili do niego: Oto czemu ci czynią w sabat, czego się nie godzi czynić?
25 Ó dá wọn lóhùn pé, “Ẹ̀yin kò ti ka ohun tí Dafidi ṣe, nígbà tí ó ṣe aláìní, tí ebi sì ń pa á, òun àti àwọn tí ó wà lọ́dọ̀ rẹ̀?
A on im rzekł: Nigdyście nie czytali, co uczynił Dawid, gdy niedostatek cierpiał, a łaknął, sam i ci, którzy z nim byli?
26 Bí ó tí wọ ilé Ọlọ́run lọ ni ọjọ́ Abiatari olórí àlùfáà, tí ó sì jẹ àkàrà ìfihàn ti kò tọ́ fún un láti jẹ bí kò ṣe fún àwọn àlùfáà, ó sì tún fi fún àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀.”
Jako wszedł do domu Bożego za Abijatara, kapłana najwyższego, i jadł chleby pokładne, (których się nie godziło jeść, tylko kapłanom), a dał i tym, którzy z nim byli.
27 Ó sì wí fún wọ́n pé, a dá ọjọ́ ìsinmi fún ènìyàn, “Ṣùgbọ́n a kò dá ènìyàn fún ọjọ́ ìsinmi.
Dotego rzekł im: Sabat dla człowieka uczyniony, a nie człowiek dla sabatu.
28 Nítorí náà Ọmọ Ènìyàn ni Olúwa ọjọ́ ìsinmi pẹ̀lú.”
Dlatego Syn człowieczy jest Panem i sabatu.