< Luke 9 >

1 Ó sì pe àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ méjìlá jọ, ó sì fún wọn ní agbára àti àṣẹ lórí àwọn ẹ̀mí èṣù gbogbo, àti láti wo ààrùn sàn.
A zwoławszy Jezus dwunastu uczniów swoich, dał im moc i władzę nad wszystkimi dyjabły, i aby uzdrawiali choroby.
2 Ó sì rán wọn lọ wàásù ìjọba Ọlọ́run, àti láti mú àwọn ọlọkùnrùn láradá.
I rozesłał je, żeby kazali królestwo Boże, i uzdrawiali niemocne.
3 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹ má ṣe mú nǹkan lọ́wọ́ fún àjò yín, ọ̀pá, tàbí àpò tàbí àkàrà, tàbí owó, bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ̀yin má sì ṣe ní ẹ̀wù méjì.
Tedy rzekł do nich: Nie bierzcie nic na drogę, ani laski, ani taistry, ani chleba, ani pieniędzy, ani dwóch sukien miejcie.
4 Ní ilékílé tí ẹ̀yin bá sì wọ̀, níbẹ̀ ni kí ẹ̀yin gbé, láti ibẹ̀ ni kí ẹ̀yin sì ti jáde.
A do któregokolwiek domu wnijdziecie, tamże zostańcie, i stamtąd wynijdźcie.
5 Iye àwọn tí kò bá si gbà yín, nígbà tí ẹ̀yin bá jáde kúrò ní ìlú náà, ẹ gbọn eruku ẹsẹ̀ yín fún ẹ̀rí sí wọn.”
A którzybykolwiek was nie przyjęli, wychodząc z miasta onego, i proch z nóg waszych otrząśnijcie na świadectwo przeciwko nim.
6 Wọ́n sì lọ, wọ́n ń la ìletò kọjá wọ́n sì ń wàásù ìyìnrere, wọ́n sì ń mú ènìyàn láradá níbi gbogbo.
Wyszedłszy tedy, obchodzili wszystkie miasteczka, opowiadając Ewangieliję, a wszędzie chore uzdrawiając.
7 Herodu tetrarki gbọ́ nǹkan gbogbo èyí tí a ṣe láti ọ̀dọ̀ rẹ̀ wá: ó sì dààmú, nítorí tí àwọn ẹlòmíràn ń wí pé, Johanu ni ó jíǹde kúrò nínú òkú,
I usłyszał Herod, Tetrarcha, o wszystkiem, co się działo od niego, i był wątpliwym dla tego, że niektórzy powiadali, iż Jan zmartwychwstał.
8 Àwọn ẹlòmíràn sì wí pé Elijah ni ó farahàn; àwọn ẹlòmíràn sì wí pé, ọ̀kan nínú àwọn wòlíì àtijọ́ ni ó jíǹde.
A niektórzy zasię: Iż się Elijasz ukazał; a drudzy, iż prorok jeden z onych starych zmartwychwstał.
9 Herodu sì wí pé, “Johanu ni mo ti bẹ́ lórí, ṣùgbọ́n ta ni èyí tí èmi ń gbọ́ irú nǹkan wọ̀nyí sí?” Ó sì ń fẹ́ láti rí i.
Tedy rzekł Herod: Janamci ja ściął; któż wżdy ten jest, o którym ja takie rzeczy słyszę? i pragnął go widzieć.
10 Nígbà tí àwọn aposteli sì padà dé, wọ́n ròyìn ohun gbogbo fún un tí wọ́n ti ṣe. Ó sì mú wọn, lọ sí apá kan níbi tí a ń pè ní Betisaida.
A wróciwszy się Apostołowie, powiadali mu, cokolwiek czynili. A on wziąwszy je z sobą, ustąpił osobno na miejsce puste przy mieście, które zowią Betsaida.
11 Nígbà tí ọ̀pọ̀ ènìyàn sì mọ̀, wọ́n tẹ̀lé e: ó sì gbà wọ́n, ó sì sọ̀rọ̀ ìjọba Ọlọ́run fún wọn; àwọn tí ó fẹ́ ìmúláradá, ni ó sì mú láradá.
Czego gdy się lud dowiedział, szedł za nim; a przyjąwszy je, mówił im o królestwie Bożem; a te, którzy uzdrowienia potrzebowali, uzdrawiał.
12 Nígbà tí ọjọ́ bẹ̀rẹ̀ sí rọlẹ̀, àwọn méjìlá wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Tú ìjọ ènìyàn ká, kí wọn lè lọ sí ìletò àti sí ìlú yíká, kí wọn lè wò, àti kí wọn lè wá oúnjẹ: nítorí ijù ni àwa sá wà níhìn-ín.”
A gdy się dzień począł skłaniać ku wieczorowi, przystąpiwszy oni dwunastu, rzekli mu: Rozpuść ten lud, aby odszedłszy do miasteczek okolicznych, i do wsi, i do gospód, znaleźli żywność; bośmy tu na miejscu pustem.
13 Ṣùgbọ́n ó wí fún wọn pé, “Ẹ fi oúnjẹ fún wọn jẹ!” Wọ́n sì wí fún un pé, “Àwa kò ní ju ìṣù àkàrà márùn-ún lọ, pẹ̀lú ẹja méjì: bí kò ṣe pé àwa lọ ra oúnjẹ fún gbogbo àwọn ènìyàn wọ̀nyí.”
Ale on rzekł do nich: Dajcież wy im jeść. A oni powiedzieli: Nie mamy więcej, tylko pięć chlebów i dwie ryby, oprócz żebyśmy szli, a kupili, na ten wszystek lud żywności.
14 Nítorí àwọn ọkùnrin náà tó ìwọ̀n ẹgbẹ̀rún márùn-ún ènìyàn. Ó sì wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé, “Kí wọ́n mú wọn jókòó lẹ́gbẹ̀ẹ̀gbẹ́, ní àràádọ́ta.”
Albowiem było mężów około pięciu tysięcy. I rzekł do uczniów swoich: Rozkażcie im usiąść w każdym rzędzie po pięćdziesiąt.
15 Wọ́n sì ṣe bẹ́ẹ̀, wọ́n sì mú gbogbo wọn jókòó.
I uczynili tak, i usiedli wszyscy.
16 Nígbà náà ni ó mú ìṣù àkàrà márùn-ún, àti ẹja méjì náà, nígbà tí ó gbé ojú sókè ọ̀run, ó súre sí i, ó sì bù ú, ó sì fi fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀, kí wọn gbé e kalẹ̀ níwájú àwọn ènìyàn.
A on wziąwszy onych pięć chlebów i one dwie ryby, wejrzawszy w niebo, błogosławił im, i łamał i dawał uczniom, aby kładli przed on lud.
17 Wọ́n sì jẹ, gbogbo wọn sì yó: wọ́n ṣa agbọ̀n méjìlá jọ nínú àjẹkù tí ó kù.
I jedli, i nasyceni są wszyscy; i zebrano, co im zbyło z ułomków, dwanaście koszów.
18 Ó sì ṣe, nígbà tí ó ku òun nìkan ó gbàdúrà, àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì wà lọ́dọ̀ rẹ̀: ó sì bi wọ́n pé, “Ta ni àwọn ènìyàn ń fi mí pè?”
I stało się, gdy się on sam osobno modlił, że z nim byli uczniowie; i pytał ich mówiąc: Kimże mię być powiadają ludzie?
19 Wọ́n sì dáhùn wí pé, “Johanu Onítẹ̀bọmi; ṣùgbọ́n ẹlòmíràn ní Elijah ni, àti àwọn ẹlòmíràn wí pé, ọ̀kan nínú àwọn wòlíì àtijọ́ ni ó jíǹde.”
A oni odpowiadając rzekli: Janem Chrzcicielem, a drudzy Elijaszem, a drudzy mówią, iż prorok niektóry z onych starych zmartwychwstał.
20 Ó sì bi wọ́n pé, “Ṣùgbọ́n ta ni ẹ̀yin ń fi èmi pè?” Peteru sì dáhùn, wí pe, “Kristi ti Ọlọ́run.”
I rzekł im: A wy kim mię być powiadacie? A odpowiadając Piotr rzekł: Chrystusem, onym Bożym.
21 Ó sì kìlọ̀ fún wọn, pé, kí wọn má ṣe sọ èyí fún ẹnìkan.
Ale on przygroziwszy im, rozkazał, aby tego nikomu nie powiadali,
22 Ó sì wí pé, “Ọmọ ènìyàn yóò jìyà ohun púpọ̀, a ó sì kọ̀ ọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn alàgbà, olórí àlùfáà àti láti ọ̀dọ̀ àwọn akọ̀wé, a ó sì pa á, ní ọjọ́ kẹta a ó sì jí i dìde.”
Mówiąc: Że Syn człowieczy musi wiele cierpieć, a być odrzuconym od starszych ludu i od przedniejszych kapłanów i od nauczonych w Piśmie, i być zabitym, a trzeciego dnia zmartwychwstać.
23 Ó sì wí fún gbogbo wọn pé, “Bí ẹnìkan bá ń fẹ́ láti máa tọ̀ mí lẹ́yìn, kí ó sẹ́ ara rẹ̀, kí ó sì gbé àgbélébùú rẹ̀ ní ọjọ́ gbogbo, kí ó sì máa tọ̀ mí lẹ́yìn.
I mówił do wszystkich: Kto chce za mną iść, niech zaprze samego siebie, a niech bierze krzyż swój na każdy dzień, i naśladuje mię.
24 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá fẹ́ gba ọkàn rẹ̀ là, yóò sọ ọ́ nù: ṣùgbọ́n ẹnikẹ́ni tí ó bá sọ ọkàn rẹ̀ nù nítorí mi, òun náà ni yóò sì gbà á là.
Albowiem ktobykolwiek chciał zachować duszę swoję, straci ją; a ktobykolwiek stracił duszę swą dla mnie, ten ją zachowa.
25 Nítorí pé èrè kín ni fún ènìyàn, bí ó jèrè gbogbo ayé, tí ó sì sọ ara rẹ̀ nù tàbí kí ó fi ṣòfò.
Albowiem cóż pomoże człowiekowi, choćby wszystek świat pozyskał, gdyby samego siebie stracił, albo sobie uszkodził.
26 Nítorí ẹnikẹ́ni tí ó bá tijú mi, àti ọ̀rọ̀ mi, òun ni Ọmọ Ènìyàn yóò tijú rẹ̀ nígbà tí ó bá dé inú ògo tirẹ̀, àti ti baba rẹ̀, àti ti àwọn angẹli mímọ́.
Albowiem ktokolwiek by się wstydził za mię i za słowa moje, za tego się Syn człowieczy wstydzić będzie, gdy przyjdzie w chwale swej i w ojcowskiej i świętych Aniołów.
27 “Ṣùgbọ́n èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹlòmíràn dúró níhìn-ín yìí, tí kì yóò rí ikú, títí wọn ó fi rí ìjọba Ọlọ́run.”
Aleć wam powiadam prawdziwie: Są niektórzy z tych co tu stoją, którzy nie ukuszą śmierci, aż oglądają królestwo Boże.
28 Ó sì ṣe bí ìwọ̀n ọjọ́ mẹ́jọ lẹ́yìn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí, ó mú Peteru àti Johanu àti Jakọbu, ó gun orí òkè lọ láti lọ gbàdúrà.
I stało się po tych mowach, jakoby po ośmiu dniach, że wziąwszy z sobą Piotra i Jana i Jakóba, wstąpił na górę, aby się modlił.
29 Bí ó sì ti ń gbàdúrà, àwọ̀ ojú rẹ̀ yípadà, aṣọ rẹ̀ sì funfun gbòò,
A gdy się modlił, stał się inakszy kształt oblicza jego, i szaty jego stały się białe i świetne.
30 Sì kíyèsi i, àwọn ọkùnrin méjì, Mose àti Elijah, wọ́n ń bá a sọ̀rọ̀,
A oto dwaj mężowie rozmawiali z nim, a ci byli Mojżesz i Elijasz;
31 tí wọ́n fi ara hàn nínú ògo, wọ́n sì ń sọ̀rọ̀ ikú rẹ̀, tí òun yóò ṣe parí ní Jerusalẹmu.
Którzy pokazawszy się w sławie, powiadali o jego śmierci, którą miał podstąpić w Jeruzalemie.
32 Ṣùgbọ́n ojú Peteru àti ti àwọn tí ń bẹ lọ́dọ̀ rẹ̀ wúwo fún oorun. Nígbà tí wọ́n sì tají, wọ́n rí ògo rẹ̀, àti ti àwọn ọkùnrin méjèèjì tí ó bá a dúró.
A Piotr i ci, którzy byli z nim, obciążeni byli snem, a ocuciwszy się, ujrzeli chwałę jego i onych dwóch mężów, którzy z nim stali.
33 Ó sì ṣe, nígbà tí wọ́n lọ kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀, Peteru wí fún Jesu pé, “Olùkọ́, ó dára fún wa kí a máa gbé ìhín yìí, jẹ́ kí àwa pa àgọ́ mẹ́ta, ọ̀kan fún ìwọ, àti ọ̀kan fún Mose, àti ọ̀kan fún Elijah.” (Kò mọ èyí tí òun ń wí.)
I stało się, gdy oni odeszli od niego, rzekł Piotr do Jezusa: Mistrzu! dobrze nam tu być; przetoż uczyńmy trzy namioty, tobie jeden i Mojżeszowi jeden i Elijaszowi jeden; nie wiedząc, co mówił.
34 Bí ó ti ń sọ báyìí, ìkùùkuu kan wá, ó síji bò wọ́n: ẹ̀rù sì bà wọ́n nígbà tí wọ́n ń wọ inú ìkùùkuu lọ.
A gdy on to mówił, stał się obłok, i zacienił je; i bali się, gdy oni wchodzili w obłok.
35 Ohùn kan sì ti inú ìkùùkuu wá wí pé, “Èyí yìí ni àyànfẹ́ ọmọ mi: ẹ máa gbọ́ tirẹ̀.”
I stał się głos z obłoku mówiący: Ten jest Syn mój miły, tego słuchajcie.
36 Nígbà tí ohùn náà sì dákẹ́, Jesu nìkan ṣoṣo ni a rí. Wọ́n sì pa á mọ́, wọn kò sì sọ ohunkóhun tí wọ́n rí fún ẹnikẹ́ni ní ọjọ́ wọ̀nyí.
A gdy się stał on głos, znaleziony jest sam Jezus. A oni milczeli, i nie powiadali w one dni nikomu nic z tego, co widzieli.
37 Ó sì ṣe, ní ọjọ́ kejì, nígbà tí wọ́n sọ̀kalẹ̀ wá láti orí òkè, ọ̀pọ̀ àwọn ènìyàn wá pàdé rẹ̀.
I stało się nazajutrz, gdy oni zstąpili z góry, że mu lud wielki zabieżał.
38 Sì kíyèsi i, ọkùnrin kan nínú ìjọ ènìyàn kígbe sókè pé, “Olùkọ́ mo bẹ̀ ọ́, wo ọmọ mi: nítorí ọmọ mi kan ṣoṣo náà ni.
A oto mąż z onego ludu zawołał, mówiąc: Nauczycielu! proszę cię, wejrzyj na syna mego; boć jedynego mam.
39 Sì kíyèsi i, ẹ̀mí èṣù a máa mú un, a sì máa kígbe lójijì; a sì máa nà án tàntàn títí yóò fi yọ ìfófó lẹ́nu, a máa pa á lára, kì í tilẹ̀ ń fẹ́ fi í sílẹ̀ lọ.
A oto duch zły popada go, a zaraz krzyczy, a on rozdziera go, śliniącego się, a zaledwie odchodzi od niego, skruszywszy go.
40 Mo sì bẹ àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ láti lé e jáde: wọn kò sì lè ṣe é.”
I prosiłem uczniów twoich, aby go wygnali; ale nie mogli.
41 Jesu sì dáhùn pé, “Ìran aláìgbàgbọ́ àti àrékérekè, èmi ó ti bá yín gbé pẹ́ tó? Èmi yóò sì ti ṣe sùúrù fún yín pẹ́ tó? Fa ọmọ rẹ wá níhìn-ín yìí.”
Tedy Jezus odpowiadając rzekł: O rodzaju niewierny i przewrotny! dokądże z wami będę, i dokądże was cierpieć będę? Przywiedź tu syna twego.
42 Bí ó sì ti ń bọ̀, ẹ̀mí èṣù náà gbé e ṣánlẹ̀, ó sì nà án tàntàn. Jesu sì bá ẹ̀mí àìmọ́ náà wí, ó sì mú ọmọ náà láradá, ó sì fà á lé baba rẹ̀ lọ́wọ́.
A wtem, gdy on przychodził, rozdarł go dyjabeł i roztargał; ale Jezus zgromił ducha nieczystego i uzdrowił młodzieńca, i oddał go ojcu jego.
43 Ẹnu sì ya gbogbo wọn sí iṣẹ́ títóbi Ọlọ́run, ṣùgbọ́n nígbà tí hà sì ń ṣe gbogbo wọn sí ohun gbogbo tí Jesu ṣe, ó wí fún àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ pé,
I zdumieli się wszyscy nad wielmożnością Bożą. A gdy się wszyscy dziwowali wszystkim rzeczom, które czynił Jezus, rzekł do uczniów swoich:
44 “Ẹ jẹ́ kí ọ̀rọ̀ wọ̀nyí wọ̀ yín létí, nítorí a ó fi Ọmọ Ènìyàn lé àwọn ènìyàn lọ́wọ́.”
Składajcie wy do uszów waszych słowa te: albowiem Syn człowieczy ma być wydany w ręce ludzkie.
45 Ṣùgbọ́n ọ̀rọ̀ náà kò yé wọn, ó sì ṣú wọn lójú, bẹ́ẹ̀ ni wọn kò sì mọ̀ ọ́n: ẹ̀rù sì ń bà wọ́n láti béèrè ìdí ọ̀rọ̀ náà.
Lecz oni nie rozumieli słowa tego, i było zakryte od nich, że go pojąć nie mogli, i nie śmieli go pytać o to słowo.
46 Iyàn kan sì dìde láàrín wọn, ní ti ẹni tí yóò ṣe olórí nínú wọn.
I wszczęła się gadka między nimi, kto by z nich był największym.
47 Nígbà tí Jesu sì mọ èrò ọkàn wọn, ó mú ọmọdé kan, ó gbé e jókòó lọ́dọ̀ rẹ̀.
A Jezus widząc myśl serca ich, wziąwszy dziecię, postawił je podle siebie,
48 Ó sì wí fún wọn pé, “Ẹnikẹ́ni tí ó bá gba ọmọdé yìí nítorí orúkọ mi, ó gbà mí: àti ẹnikẹ́ni tí ó bá gbà mí, ó gba ẹni tí ó rán mi: nítorí ẹni tí ó bá kéré jù nínú gbogbo yín, òun náà ni yóò pọ̀jù.”
I rzekł im: Ktobykolwiek przyjął to dzieciątko w imieniu mojem, mnie przyjmuje; a ktobykolwiek mnie przyjął, przyjmuje onego, który mię posłał: albowiem kto jest najmniejszy między wszystkimi wami, tenci będzie wielkim.
49 Johanu sì dáhùn ó sì wí fún un pé, “Olùkọ́, àwa rí ẹnìkan ó ń fi orúkọ rẹ lé àwọn ẹ̀mí èṣù jáde; àwa sì dá a lẹ́kun, nítorí tí kò bá wa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn.”
A Jan odpowiadając, rzekł: Mistrzu! widzieliśmy niektórego w imieniu twojem dyjabły wyganiającego, i zabranialiśmy mu, przeto że za tobą z nami nie chodzi.
50 Jesu sì wí fún un, pé, “Má ṣe dá a lẹ́kun mọ́: nítorí ẹni tí kò bá lòdì sí i yín, ó wà fún yín.”
I rzekł do niego Jezus: Nie zabraniajcie mu; bo kto nie jest przeciwko nam, za nami jest.
51 Nígbà tí ọjọ́ àti gbà á sókè ń súnmọ́, ó pinnu láti lọ sí Jerusalẹmu.
I stało się, gdy się wypełniły dni, aby był wzięty w górę, że się on na to udał, aby szedł do Jeruzalemu.
52 Ó sì rán àwọn ìránṣẹ́ lọ sí iwájú rẹ̀. Nígbà tí wọ́n sì lọ wọ́n wọ ìletò kan tí í ṣe ti ará Samaria láti pèsè sílẹ̀ dè é.
Tedy posłał posły przed sobą; którzy weszli do miasteczka Samarytańskiego, aby mu nagotowali gospodę.
53 Wọn kò sì gbà á, nítorí pé ó ń lọ sí Jerusalẹmu.
Lecz oni go nie przyjęli, przeto że oblicze jego obrócone było do Jeruzalemu.
54 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ Jakọbu àti Johanu sì rí i, wọ́n ní, “Olúwa wa, jẹ́ kí a pe iná láti ọ̀run wá, kí a sì pa wọ́n run, bí Elijah ti ṣe?”
A widząc to uczniowie jego, Jakób i Jan, rzekli: Panie! chceszże, iż rzeczemy, aby ogień zstąpił z nieba i spalił je, jako i Elijasz uczynił?
55 Ṣùgbọ́n Jesu yípadà, ó sì bá wọn wí.
Ale Jezus obróciwszy się, zgromił je, i rzekł: Nie wiecie wy, jakiego jesteście ducha.
56 Lẹ́yìn náà Jesu àti àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀ sì lọ sí ìletò mìíràn.
Albowiem Syn człowieczy nie przyszedł, zatracać dusz ludzkich, ale zachować. I szli do inszego miasteczka.
57 Bí wọ́n ti ń lọ lọ́nà, ọkùnrin kan wí fún un pé, “Olúwa, Èmi ń fẹ́ láti máa tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ní ibikíbi tí ìwọ bá ń lọ.”
I stało się, gdy oni szli, że w drodze rzekł niektóry do niego: Pójdę za tobą, gdziekolwiek pójdziesz, Panie!
58 Jesu sì wí fún un pé, “Àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ ní ihò, àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ní ìtẹ́; ṣùgbọ́n Ọmọ Ènìyàn kò ní ibi tí yóò fi orí rẹ̀ lé.”
A Jezus mu rzekł: Liszki mają jamy, i ptaszki niebieskie gniazda; ale Syn człowieczy nie ma, gdzie by głowę skłonił.
59 Ó sì wí fún ẹlòmíràn pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.” Ṣùgbọ́n èyí wí fún un pé, “Olúwa, jẹ́ kí èmi lọ sìnkú baba mi ná.”
I rzekł do drugiego: Pójdź za mną! Ale on rzekł: Panie! dopuść mi pierwej odejść i pogrześć ojca mego.
60 Jesu sì wí fún un pé, “Jẹ́ kí àwọn òkú máa sìnkú ara wọn, ṣùgbọ́n ìwọ lọ kí o sì máa wàásù ìjọba Ọlọ́run.”
Ale mu Jezus rzekł: Niechaj umarli grzebią umarłych swoich; a ty poszedłszy, opowiadaj królestwo Boże.
61 Ẹlòmíràn sì wí fún un pé, “Olúwa, èmi yóò tọ̀ ọ́ lẹ́yìn ṣùgbọ́n jẹ́ kí n kọ́kọ́ lọ dágbére fún àwọn ará ilé mi.”
Rzekł też i drugi: Pójdę za tobą, Panie! ale mi pierwej dopuść pożegnać się z tymi, którzy są w domu moim.
62 Jesu sì wí fún un pé, “Kò sí ẹni, tí ó fi ọwọ́ rẹ̀ lé ohun èlò ìtulẹ̀, tí ó sì wo ẹ̀yìn, tí ó yẹ fún ìjọba Ọlọ́run.”
Rzekł do niego Jezus: Żaden, który by przyłożył rękę swoję do pługa, a oglądałby się nazad, nie jest sposobny do królestwa Bożego.

< Luke 9 >