< John 1 >
1 Ní àtètèkọ́ṣe ni Ọ̀rọ̀ wà, Ọ̀rọ̀ sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run, Ọlọ́run sì ni Ọ̀rọ̀ náà.
Na początku było Słowo, a ono Słowo było u Boga, a Bogiem było ono Słowo.
2 Òun ni ó sì wà pẹ̀lú Ọlọ́run ní àtètèkọ́ṣe.
To było na początku u Boga.
3 Nípasẹ̀ rẹ̀ ni a dá ohun gbogbo; lẹ́yìn rẹ̀ a kò sì dá ohun kan nínú ohun tí a ti dá.
Wszystkie rzeczy przez nie się stały, a bez niego nic się nie stało, co się stało.
4 Nínú rẹ̀ ni ìyè wà, ìyè yìí náà sì ni ìmọ́lẹ̀ aráyé,
W niem był żywot, a żywot był oną światłością ludzką.
5 ìmọ́lẹ̀ náà sì ń mọ́lẹ̀ nínú òkùnkùn, òkùnkùn kò sì borí rẹ̀.
A ta światłość w ciemnościach świeci, ale ciemności jej nie ogarnęły.
6 Ọkùnrin kan wà tí a rán láti ọ̀dọ̀ Ọlọ́run wá; orúkọ ẹni tí ń jẹ́ Johanu.
Był człowiek posłany od Boga, któremu imię było Jan.
7 Òun ni a sì rán fún ẹ̀rí, kí ó lè ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà, kí gbogbo ènìyàn kí ó lè gbàgbọ́ nípasẹ̀ rẹ̀.
Ten przyszedł na świadectwo, aby świadczył o tej światłości, aby przezeń wszyscy uwierzyli.
8 Òun fúnra rẹ̀ kì í ṣe ìmọ́lẹ̀ náà, ṣùgbọ́n a rán an wá láti ṣe ẹlẹ́rìí fún ìmọ́lẹ̀ náà.
Nie byłci on tą światłością, ale przyszedł, aby świadczył o tej światłości.
9 Ìmọ́lẹ̀ òtítọ́ ń bẹ tí ń tan ìmọ́lẹ̀ fún olúkúlùkù ènìyàn tí ó wá sí ayé.
Tenci był tą prawdziwą światłością, która oświeca każdego człowieka, przychodzącego na świat.
10 Òun sì wà ní ayé, àti pé, nípasẹ̀ rẹ̀ ni a sì ti dá ayé, ṣùgbọ́n ayé kò sì mọ̀ ọ́n.
Na świecie był, a świat przezeń uczyniony jest; ale go świat nie poznał.
11 Ó tọ àwọn tirẹ̀ wá, àwọn tirẹ̀ kò sì gbà á.
Do swej własności przyszedł, ale go właśni jego nie przyjęli.
12 Ṣùgbọ́n iye àwọn tí ó gbà á, àní àwọn náà tí ó gbà orúkọ rẹ̀ gbọ́, àwọn ni ó fi ẹ̀tọ́ fún láti di ọmọ Ọlọ́run.
Lecz którzykolwiek go przyjęli, dał im tę moc, aby się stali synami Bożymi, to jest tym, którzy wierzą w imię jego.
13 Àwọn ọmọ tí kì í ṣe nípa ẹ̀jẹ̀, tàbí nípa ti ìfẹ́ ara, bẹ́ẹ̀ ni kì í ṣe nípa ìfẹ́ ti ènìyàn, bí kò ṣe láti ọwọ́ Ọlọ́run.
Którzy nie z krwi, ani z woli ciała, ani z woli męża, ale z Boga narodzeni są.
14 Ọ̀rọ̀ náà sì di ara, òun sì ń bá wa gbé. Àwa sì ti rí ògo rẹ̀, àní ògo ọmọ rẹ kan ṣoṣo, tí ó ti ọ̀dọ̀ Baba wá, ó kún fún oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́.
A to Słowo ciałem się stało, i mieszkało między nami, i widzieliśmy chwałę jego, chwałę jako jednorodzonego od Ojca, pełne łaski i prawdy.
15 Johanu sì jẹ́rìí nípa rẹ̀, ó kígbe, ó sì wí pé, “Èyí ni ẹni tí mo sọ̀rọ̀ rẹ̀ pé, ‘Ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi pọ̀jù mí lọ, nítorí òun ti wà ṣáájú mi.’”
Jan świadczył o nim, i wołał, mówiąc: Tenci był, o którymem powiadał: Który po mnie przyszedłszy, uprzedził mię; bo pierwej był niż ja.
16 Nítorí láti inú ẹ̀kúnrẹ́rẹ́ oore-ọ̀fẹ́ rẹ̀ ni gbogbo wa sì ti gba ìbùkún kún ìbùkún.
A z pełności jego myśmy wszyscy wzięli i łaskę za łaskę.
17 Nítorí pé nípasẹ̀ Mose ni a ti fi òfin fún ni ṣùgbọ́n òun; oore-ọ̀fẹ́ àti òtítọ́ láti ipasẹ̀ Jesu Kristi wá.
Albowiem zakon przez Mojżesza jest dany, a łaska i prawda przez Jezusa Chrystusa stała się.
18 Kò sí ẹni tí ó rí Ọlọ́run rí, bí kò ṣe òun nìkan, àní ọmọ rẹ̀ kan ṣoṣo, ẹni tí òun pàápàá jẹ́ Ọlọ́run, tí ó sì wà ní ìbáṣepọ̀ tí ó súnmọ́ jùlọ pẹ̀lú baba, òun náà ni ó sì fi í hàn.
Boga nikt nigdy nie widział: on jednorodzony syn, który jest w łonie ojcowskiem, ten nam opowiedział.
19 Èyí sì ni ẹ̀rí Johanu, nígbà tí àwọn Júù rán àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi láti Jerusalẹmu wá láti béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ ẹni tí òun ń ṣe.
A toć jest świadectwo Janowe, gdy posłali Żydzi z Jeruzalemu kapłany i Lewity, aby go pytali: Ty ktoś jest?
20 Òun kò sì kùnà láti jẹ́wọ́, ṣùgbọ́n òun jẹ́wọ́ wọ́ọ́rọ́wọ́ pé, “Èmi kì í ṣe Kristi náà.”
I wyznał, a nie zaprzał, a wyznał, żem ja nie jest Chrystus.
21 Wọ́n sì bi í léèrè pé, “Ta ha ni ìwọ? Elijah ni ìwọ bí?” Ó sì wí pé, “Èmi kọ́.” “Ìwọ ni wòlíì náà bí?” Ó sì dáhùn pé, “Bẹ́ẹ̀ kọ́.”
I pytali go: Cóżeś tedy? Elijasześ ty? A on rzekł: Nie jestem. A oni: Prorokiemeś ty? i odpowiedział: Nie jestem.
22 Ní ìparí wọ́n wí fún un pé, “Ta ni ìwọ í ṣe? Fún wa ní ìdáhùn kí àwa kí ó lè mú èsì padà tọ àwọn tí ó rán wa wá lọ. Kí ni ìwọ wí nípa ti ara rẹ?”
Rzekli mu tedy: Któżeś jest, żebyśmy odpowiedź dali tym, którzy nas posłali? Cóż wżdy powiadasz o sobie?
23 Johanu sì fi ọ̀rọ̀ wòlíì Isaiah fún wọn ní èsì pé, “Èmi ni ohùn ẹni tí ń kígbe ní ijù, ‘Ẹ ṣe ọ̀nà Olúwa ní títọ́.’”
Rzekł: Jam jest głos wołającego na puszczy: Prostujcie drogę Pańską, jako powiedział Izajasz prorok.
24 Ọ̀kan nínú àwọn Farisi tí a rán
A ci, którzy byli posłani, byli z Faryzeuszów.
25 bi í léèrè pé, “Èéṣe tí ìwọ fi ń bamitiisi nígbà náà, bí ìwọ kì í bá ṣe Kristi, tàbí Elijah, tàbí wòlíì náà?”
I pytali go i rzekli mu: Czemuż tedy chrzcisz, jeźliżeś ty nie jest Chrystus, ani Elijasz, ani prorok?
26 Johanu dá wọn lóhùn, wí pé, “Èmi ń fi omi bamitiisi, ẹnìkan dúró láàrín yín, ẹni tí ẹ̀yin kò mọ̀,
Odpowiedział im Jan, mówiąc: Jać chrzczę wodą; ale w pośrodku was stoi, którego wy nie znacie.
27 Òun náà ni ẹni tí ń bọ̀ lẹ́yìn mi, okùn bàtà ẹni tí èmi kò tó láti tú.”
Tenci jest, który po mnie przyszedłszy, uprzedził mię, któremum ja nie jest godzien, żebym rozwiązał rzemyk obuwia jego.
28 Àwọn nǹkan wọ̀nyí ni ó ṣẹlẹ̀ ní Betani ní òdìkejì odò Jordani, níbi tí Johanu ti ń fi omi bamitiisi.
To się stało w Betabarze za Jordanem, gdzie Jan chrzcił.
29 Ní ọjọ́ kejì, Johanu rí Jesu tí ó ń bọ̀ wá sí ọ̀dọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé, “Wò ó, Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run, ẹni tí ó kó ẹ̀ṣẹ̀ ayé lọ!
A nazajutrz ujrzał Jan Jezusa idącego do siebie, i rzekł: Oto Baranek Boży, który gładzi grzech świata.
30 Èyí ni ẹni tí mo ń sọ nígbà tí mo wí pé, ‘Ọkùnrin kan tí ń bọ̀ wá lẹ́yìn mi, tí ó pọ̀jù mí lọ, nítorí tí ó ti wà ṣáájú mi.’
Tenci jest, o którymem powiadał, że idzie za mną mąż, który mię uprzedził; bo pierwej był niż ja.
31 Èmi gan an kò sì mọ̀ ọ́n, ṣùgbọ́n ìdí tí mo fi wá ń fi omi ṣe ìtẹ̀bọmi ni kí a lè fi í hàn fún Israẹli.”
A jam go nie znał; ale aby był objawiony Izraelowi, dlategom ja przyszedł, chrzcząc wodą.
32 Nígbà náà ni Johanu jẹ́rìí sí i pé, “Mo rí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ láti ọ̀run wá bí àdàbà, tí ó sì bà lé e.
I świadczył Jan, mówiąc: Widziałem Ducha zstępującego jako gołębicę z nieba, i został na nim.
33 Èmi kì bá tí mọ̀ ọ́n, bí kò ṣe pé ẹni tí ó rán mi láti fi omi bamitiisi sọ fún mi pé, ‘Ọkùnrin tí ìwọ rí tí Ẹ̀mí sọ̀kalẹ̀ tí ó bà lé lórí ni ẹni tí yóò fi Ẹ̀mí Mímọ́ bamitiisi.’
A jam go nie znał; ale który mię posłał chrzcić wodą, ten mi rzekł: Na kogo byś ujrzał Ducha zstępującego i zostającego na nim, tenci jest, który chrzci Duchem Świętym.
34 Èmi ti rí i, mo sì jẹ́rìí pé, èyí ni Ọmọ Ọlọ́run.”
A jam widział i świadczył, że ten jest Syn Boży.
35 Ní ọjọ́ kejì, Johanu dúró pẹ̀lú méjì nínú àwọn ọmọ-ẹ̀yìn rẹ̀.
Nazajutrz zasię stał Jan i dwaj z uczniów jego.
36 Nígbà tí ó sì rí Jesu bí ó ti ń kọjá lọ, ó wí pé, “Wò ó Ọ̀dọ́-àgùntàn Ọlọ́run!”
A ujrzawszy Jezusa chodzącego, rzekł: Oto Baranek Boży.
37 Nígbà tí àwọn ọmọ-ẹ̀yìn méjì náà sì gbọ́ ohun tí ó wí yìí, wọ́n bẹ̀rẹ̀ sì í tọ Jesu lẹ́yìn.
I słyszeli go oni dwaj uczniowie mówiącego, i szli za Jezusem.
38 Nígbà náà ni Jesu yípadà, ó rí i pé wọ́n ń tọ òun lẹ́yìn, ó sì béèrè pé, “Kí ni ẹ̀yin ń wá?” Wọ́n wí fún un pé, “Rabbi” (ìtumọ̀ èyí tí í ṣe Olùkọ́ni), “Níbo ni ìwọ ń gbé?”
A obróciwszy się Jezus i ujrzawszy je za sobą idące, rzekł do nich: Czego szukacie? A oni mu rzekli: Rabbi! (co się wykłada: Mistrzu), gdzie mieszkasz?
39 Ó wí fún wọn pé, “Ẹ wá wò ó, ẹ̀yin yóò sì rí i.” Wọ́n sì wá, wọ́n sì rí ibi tí ó ń gbé, wọ́n sì wà ní ọ̀dọ̀ rẹ̀ ní gbogbo ọjọ́ náà. Ó jẹ́ ìwọ̀n wákàtí kẹwàá ọjọ́.
Rzekł im: Pójdźcie, a oglądajcie. I szli i widzieli, gdzie mieszkał, a zostali przy nim onego dnia; bo było około dziesiątej godziny.
40 Anderu arákùnrin Simoni Peteru jẹ́ ọ̀kan nínú àwọn méjì tí ó gbọ́ ọ̀rọ̀ Johanu, tí ó sì tọ Jesu lẹ́yìn.
A był Andrzej, brat Szymona Piotra, jeden z onych dwóch, którzy to słyszeli od Jana, i szli byli za nim.
41 Ohun àkọ́kọ́ tí Anderu ṣe ni láti wá Simoni arákùnrin rẹ̀, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí Messia” (ẹni tí ṣe Kristi).
Ten najpierw znalazł Szymona, brata swego własnego, i rzekł mu: Znaleźliśmy Mesyjasza, co się wykłada Chrystus.
42 Ó sì mú un wá sọ́dọ̀ Jesu. Jesu sì wò ó, ó wí pé, “Ìwọ ni Simoni ọmọ Jona: Kefa ni a ó sì máa pè ọ” (ìtumọ̀ èyí tí ṣe Peteru).
I przywiódł go do Jezusa. A wejrzawszy nań Jezus, rzekł: Tyś jest Szymon, syn Jonasza; ty będziesz nazwany Kiefas, co się wykłada Piotr.
43 Ní ọjọ́ kejì Jesu ń fẹ́ jáde lọ sí Galili, ó sì rí Filipi, ó sì wí fún un pé, “Máa tọ̀ mí lẹ́yìn.”
A nazajutrz chciał Jezus wynijść do Galilei, i znalazł Filipa i rzekł mu: Pójdź za mną.
44 Filipi gẹ́gẹ́ bí i Anderu àti Peteru, jẹ́ ará ìlú Betisaida.
A Filip był z Betsaidy, z miasta Andrzejowego i Piotrowego.
45 Filipi rí Natanaeli, ó sì wí fún un pé, “Àwa ti rí ẹni náà tí Mose kọ nípa rẹ̀ nínú òfin àti ẹni tí àwọn wòlíì ti kọ̀wé rẹ̀, Jesu ti Nasareti, ọmọ Josẹfu.”
Filip znalazł Natanaela i rzekł mu: Znaleźliśmy onego, o którym pisał Mojżesz w zakonie i prorocy, Jezusa, syna Józefowego, z Nazaretu.
46 Natanaeli béèrè pé, “Nasareti? Ohun rere kan ha lè ti ibẹ̀ jáde?” Filipi wí fún un pé, “Wá wò ó.”
I rzekł mu Natanael: Możesz z Nazaretu być co dobrego? Rzekł mu Filip: Pójdź, a oglądaj!
47 Jesu rí Natanaeli ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ rẹ̀, ó sì wí nípa rẹ̀ pé, “Èyí ni ọmọ Israẹli tòótọ́, nínú ẹni tí ẹ̀tàn kò sí.”
Ujrzawszy tedy Jezus Natanaela idącego do siebie, rzekł o nim: Oto prawdziwie Izraelczyk, w którym nie masz zdrady.
48 Natanaeli béèrè pé, “Báwo ni ìwọ ti ṣe mọ̀ mí?” Jesu sì dáhùn pé, “Èmi rí ọ nígbà tí ìwọ wà lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́ kí Filipi tó pè ọ́.”
Rzekł mu Natanael: Skądże mię znasz? Odpowiedział Jezus i rzekł mu: Pierwej niż cię Filip zawołał, gdyś był pod figowem drzewem, widziałem cię.
49 Nígbà náà ni Natanaeli sọ ọ́ gbangba pé, “Rabbi, ìwọ ni Ọmọ Ọlọ́run; Ìwọ ni ọba Israẹli.”
Odpowiedział Natanael i rzekł mu: Mistrzu! tyś jest on Syn Boży, tyś jest on król Izraelski.
50 Jesu sì wí fún un pé, “Ìwọ gbàgbọ́ nítorí mo wí fún ọ pé mo rí ọ lábẹ́ igi ọ̀pọ̀tọ́. Ìwọ ó rí ohun tí ó pọ̀jù ìwọ̀nyí lọ.”
Odpowiedział Jezus i rzekł mu: Iżem ci powiedział: Widziałem cię pod figowem drzewem, wierzysz; większe rzeczy nad te ujrzysz.
51 Nígbà náà ni ó fi kún un pé, “Èmi wí fún yín nítòótọ́, ẹ̀yin yóò rí ọ̀run ṣí sílẹ̀, àwọn angẹli Ọlọ́run yóò sì máa gòkè, wọ́n ó sì máa sọ̀kalẹ̀ sórí Ọmọ Ènìyàn.”
I rzekł mu: Zaprawdę, zaprawdę powiadam wam: Od tego czasu ujrzycie niebo otworzone i Anioły Boże wstępujące i zstępujące na Syna człowieczego.