< Lamentations 5 >

1 Rántí, Olúwa, ohun tí ó ṣẹlẹ̀ sí wa; wò ó, kí o sì rí ìtìjú wa.
Souviens-toi, Yahvé, de ce qui nous est arrivé. Regardez, et voyez notre reproche.
2 Àwọn ohun ìní wa ti di ti àlejò, ilé wa ti di ti àjèjì.
Notre héritage a été livré à des étrangers, nos maisons aux étrangers.
3 Àwa ti di aláìní òbí àti aláìní baba, àwọn ìyá wa ti di opó.
Nous sommes orphelins et sans père. Nos mères sont comme des veuves.
4 A gbọdọ̀ ra omi tí à ń mu; igi wa di títà fún wa.
Nous devons payer pour avoir de l'eau à boire. Notre bois nous est vendu.
5 Àwọn tí ó ń lé wa súnmọ́ wa; àárẹ̀ mú wa àwa kò sì rí ìsinmi.
Nos poursuivants sont à nos trousses. Nous sommes fatigués, et nous n'avons pas de repos.
6 Àwa jọ̀wọ́ ara wa fún Ejibiti àti Asiria láti rí oúnjẹ tó tó jẹ.
Nous avons donné nos mains aux Égyptiens, et aux Assyriens, de se contenter de pain.
7 Àwọn baba wa ti ṣẹ̀, wọn kò sì ṣí mọ́, àwa sì ń ru ìjìyà ẹ̀ṣẹ̀ wọn.
Nos pères ont péché, et ils ne sont plus. Nous avons porté leurs iniquités.
8 Àwọn ẹrú ń jẹ ọba lórí wa, kò sì ṣí ẹni tí yóò gbà wá lọ́wọ́ wọn.
Les serviteurs nous gouvernent. Il n'y a personne pour nous délivrer de leur main.
9 Àwa ń rí oúnjẹ wa nínú ewu ẹ̀mí wa nítorí idà tí ó wà ní aginjù.
Nous obtenons notre pain au péril de notre vie, à cause de l'épée dans le désert.
10 Ẹran-ara wa gbóná bí ààrò, ebi sì yó wa bí àárẹ̀.
Notre peau est noire comme un four, à cause de la chaleur brûlante de la famine.
11 Wọ́n ti fipá bá àwọn obìnrin wa lòpọ̀ ní Sioni, àti àwọn wúńdíá ti o wa ní ìlú Juda.
Ils ont violé les femmes de Sion, les vierges dans les villes de Juda.
12 Àwọn ọmọ ọbakùnrin ti di síso sókè ní ọwọ́ wọn; kò sí ìbọ̀wọ̀ fún àgbàgbà mọ́.
Les princes ont été pendus par leurs mains. Les visages des anciens n'ont pas été honorés.
13 Àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin wa ru òkúta; àwọn ọmọkùnrin sì ń ṣàárẹ̀ lábẹ́ ẹrù igi.
Les jeunes hommes portent des meules. Les enfants ont trébuché sous des charges de bois.
14 Àwọn àgbàgbà ti lọ kúrò ní ẹnu-bodè ìlú; àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin sì dákẹ́ orin wọn.
Les anciens se sont retirés de la porte, et les jeunes hommes de leur musique.
15 Ayọ̀ ti ṣáko ní ọkàn wa; ọ̀fọ̀ sì ti dúró bí ijó fún wa.
La joie de notre cœur a cessé. Notre danse se transforme en deuil.
16 Adé ti ṣí kúrò ní orí wa ègbé ni fún wa, nítorí a ti ṣẹ̀.
La couronne est tombée de notre tête. Malheur à nous, car nous avons péché!
17 Nítorí èyí, àárẹ̀ mú ọkàn wa, nítorí èyí, ojú wa sì ṣú.
A cause de cela, notre cœur est défaillant. Pour ces choses, nos yeux sont faibles:
18 Fún òkè Sioni tí ó ti di ahoro lórí rẹ̀ àwọn kọ̀lọ̀kọ̀lọ̀ sì ń rìn kiri.
pour la montagne de Sion, qui est désolée. Les renards marchent dessus.
19 Ìwọ, Olúwa, jẹ ọba títí láé; ìjọba rẹ dúró láti ìran kan dé ìran mìíràn.
Toi, Yahvé, tu demeures à jamais. Ton trône est de génération en génération.
20 Kí ló dé tí o ń gbàgbé wa ní gbogbo ìgbà? Kí ló dé tí o fi kọ̀ wá sílẹ̀ fún ọjọ́ pípẹ́?
Pourquoi nous oublies-tu à jamais? et nous a abandonnés pendant si longtemps?
21 Mú wa padà sí ọ̀dọ̀ rẹ, Olúwa, kí àwa kí ó le padà; mú ọjọ́ wa di tuntun bí ìgbàanì,
Tourne-nous vers toi, Yahvé, et nous nous tournerons vers toi. Renouvelez nos jours comme autrefois.
22 àyàfi tí o bá ti kọ̀ wá sílẹ̀ pátápátá tí ìbínú rẹ sí wa sì kọjá ìwọ̀n.
Mais vous nous avez complètement rejetés. Vous êtes très en colère contre nous.

< Lamentations 5 >