< Jeremiah 50 >

1 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa fi sẹ́nu wòlíì Jeremiah láti sọ fún ará ilẹ̀ Babeli:
La parole que Yahvé a prononcée sur Babylone, sur le pays des Chaldéens, par Jérémie, le prophète.
2 “Ẹ sọ ọ́ láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, ẹ sì kéde, kí ẹ sì gbé àsíá sókè, ẹ kéde rẹ̀ ẹ má sì ṣe bò ó, wí pé, ‘A kó Babeli, ojú tí Beli, a fọ́ Merodaki túútúú, ojú ti àwọn ère rẹ̀, a fọ́ àwọn òrìṣà rẹ̀ túútúú.’
« Déclarez parmi les nations et publiez, et établir une norme; publier, et ne pas dissimuler; disent: « Babylone a été prise, Bel est déçu, Merodach est consterné! Ses images sont déçues. Ses idoles sont consternées.
3 Àwọn ìlú ní apá àríwá yóò sì máa gbóguntì wọ́n. Gbogbo àwọn ènìyàn àti ẹranko ni yóò sá kúrò ní ìlú yìí.
Car une nation monte du nord contre elle, qui rendra sa terre désolée, et personne n'y habitera. Ils ont fui. Ils sont partis, l'homme et l'animal.
4 “Ní ọjọ́ wọ̀nyí àti ní àkókò náà,” ni Olúwa wí, “Àwọn ọmọ Israẹli yóò jùmọ̀ wá, àwọn, àti àwọn ọmọ Juda, wọn yóò lọ pẹ̀lú ẹkún láti ṣàfẹ́rí Olúwa Ọlọ́run wọn.
« En ces jours-là, et en ce temps-là, » dit Yahvé, « les enfants d'Israël viendront, eux et les enfants de Juda ensemble; ils poursuivront leur chemin en pleurant, et chercheront Yahvé leur Dieu.
5 Wọn ó máa béèrè ọ̀nà Sioni, ojú wọn yóò sì yí síhà ibẹ̀, wí pé ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a darapọ̀ mọ́ Olúwa ní májẹ̀mú ayérayé, tí a kì yóò gbàgbé.
Ils s'informeront sur Sion, le visage tourné vers elle, en disant: « Venez, joignez-vous à Yahvé par une alliance éternelle ». qui ne sera pas oublié.
6 “Àwọn ènìyàn mi ti jẹ́ àgùntàn tí ó sọnù, àwọn olùṣọ́-àgùntàn wọn ti jẹ́ kí wọn ṣìnà, wọ́n ti jẹ́ kí wọn rìn lórí òkè wọ́n ti lọ láti orí òkè ńlá dé òkè kékeré, wọn ti gbàgbé ibùsùn wọn.
Mon peuple est une brebis égarée. Leurs bergers les ont fait s'égarer. Ils les ont repoussés sur les montagnes. Ils sont passés de montagne en colline. Ils ont oublié leur lieu de repos.
7 Gbogbo àwọn tí ó rí wọn, ti pa wọ́n jẹ àwọn ọ̀tá wọ́n sì wí pé, ‘Àwa kò jẹ̀bi nítorí pé wọ́n ti ṣẹ̀ sí Olúwa ibùgbé òdodo àti ìrètí àwọn baba wọn.’
Tous ceux qui les ont trouvés les ont dévorés. Leurs adversaires ont dit: « Nous ne sommes pas coupables, parce qu'ils ont péché contre Yahvé, la demeure de la justice, Yahvé, l'espoir de leurs pères.
8 “Jáde kúrò ní Babeli, ẹ fi ilẹ̀ àwọn ará Kaldea sílẹ̀, kí ẹ sì jẹ́ bí òbúkọ níwájú agbo ẹran.
« Fuyez du milieu de Babylone! Sortez du pays des Chaldéens, et être comme les boucs devant les troupeaux.
9 Nítorí pé èmi yóò ru, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò gbé sókè sí Babeli àwọn orílẹ̀-èdè ńlá láti ilẹ̀ àríwá. Wọn yóò gba àyà wọn lẹ́gbẹ́ rẹ̀; láti àríwá wá, à ó sì mú ọ. Ọfà wọn yóò dàbí ọfà àwọn akọni akíkanjú tí wọn kì í wà lọ́wọ́ òfo.
Car voici que je vais susciter et fais monter contre Babylone une troupe de grandes nations du pays du nord; et ils se rangent en bataille contre elle. Elle sera prise à partir de là. Leurs flèches seront comme celles d'un homme puissant et expert. Aucun d'entre eux ne reviendra en vain.
10 A ó dààmú Babeli, gbogbo àwọn tó dààmú rẹ yóò sì mú ìfẹ́ wọn ṣẹ,” ni Olúwa wí.
La Chaldée sera une proie. Tous ceux qui s'en prennent à elle seront satisfaits », dit Yahvé.
11 “Nítorí pé inú yín dùn nítorí pé ẹ̀yìn yọ̀, ẹ̀yìn olè tí ó jí ìní mi, nítorí tí ẹ̀yìn fi ayọ̀ fò bí ẹgbọrọ abo màlúù sí koríko tútù, ẹ sì ń yan bí akọ ẹṣin.
« Parce que vous êtes heureux, parce que vous vous réjouissez, O vous qui pillez mon héritage, car tu es dévergondée comme une génisse qui foule le grain, et hennir comme des chevaux forts,
12 Ojú yóò ti ìyá rẹ, ẹni tí ó bí ọ yóò sì gba ìtìjú. Òun ni yóò jẹ́ kékeré jù nínú àwọn orílẹ̀-èdè, ilẹ̀ aṣálẹ̀ àti aginjù tí kò lọ́ràá.
votre mère sera totalement déçue. Celle qui t'a porté sera confondue. Voici qu'elle sera la plus petite des nations, un désert, une terre aride, et un désert.
13 Nítorí ìbínú Olúwa, kì yóò ní olùgbé; ẹnikẹ́ni kò sì ní gbé inú rẹ̀. Gbogbo àwọn tí ó bá kọjá ni Babeli yóò fi ṣe yẹ̀yẹ́ nítorí ọgbẹ́ rẹ̀.
A cause de la colère de Yahvé, elle ne sera pas habitée, mais elle sera totalement désolée. Tous ceux qui passeront par Babylone seront étonnés, et siffler sur tous ses fléaux.
14 “Dúró sí ààyè rẹ ìwọ Babeli àti gbogbo ẹ̀yin tí ẹ n ta ọfà náà. Ẹ ta ọfà náà sí i, nítorí ó ti ṣẹ̀ sí Olúwa.
Mettez-vous en ordre de bataille contre Babylone tout autour, vous tous qui courbez l'arc; lui tirer dessus. N'épargnez aucune flèche, car elle a péché contre Yahvé.
15 Kígbe mọ́ ọn ní gbogbo ọ̀nà! Ó tẹríba, òpó rẹ̀ sì yẹ̀, níwọ̀n ìgbà tí ó ti jẹ́ wí pé èyí ni ìgbẹ̀san Olúwa, gbẹ̀san lára rẹ̀. Ṣe sí i gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí àwọn ẹlòmíràn.
Criez contre elle tout autour. Elle s'est soumise. Ses remparts sont tombés. Ses murs ont été abattus, car c'est la vengeance de Yahvé. Se venger d'elle. Comme elle l'a fait, faites-lui.
16 Ké afúnrúgbìn kúrò ní Babeli, àti ẹni tí ń di dòjé mú ní igà ìkórè! Nítorí idà àwọn aninilára jẹ́ kí oníkálùkù padà sí ọ̀dọ̀ àwọn ènìyàn rẹ̀, kí oníkálùkù sì sá padà sí ilẹ̀ rẹ̀.
Coupez le semeur de Babylone, et celui qui manie la faucille au moment de la moisson. Par peur de l'épée oppressante, ils retourneront chacun à leur propre peuple, et ils fuiront chacun dans leur pays.
17 “Israẹli jẹ́ àgùntàn tí ó ṣìnà kiri, kìnnìún sì ti lé e lọ. Níṣàájú ọba Asiria pa á jẹ, àti níkẹyìn yìí Nebukadnessari ọba Babeli fa egungun rẹ̀ ya.”
« Israël est une brebis traquée. Les lions l'ont chassé. D'abord, le roi d'Assyrie l'a dévoré, et enfin, Nebuchadnezzar, roi de Babylone, a brisé ses os. »
18 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Alágbára, Ọlọ́run Israẹli wí, “Ǹ ó fi ìyà jẹ ọba Babeli àti ilẹ̀ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí mo ti ṣe fìyà jẹ ọba, Asiria.
C'est pourquoi Yahvé des armées, le Dieu d'Israël, dit: « Voici, je vais punir le roi de Babylone et son pays, comme j'ai puni le roi d'Assyrie.
19 Ṣùgbọ́n, èmi yóò mú Israẹli padà wá pápá oko tútù rẹ̀ òun yóò sì máa bọ́ ara rẹ̀ lórí Karmeli àti Baṣani, a ó sì tẹ́ ọkàn rẹ̀ lọ́rùn ní òkè Efraimu àti ní Gileadi.
Je ramènerai Israël dans son pâturage, et il se nourrira de Carmel et de Bashan. Son âme sera satisfaite sur les collines d'Ephraïm et en Galaad.
20 Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “À ó wá àìṣedéédéé ẹ̀ṣẹ̀ Israẹli, ṣùgbọ́n a ki yóò rí ohun; àti ẹ̀ṣẹ̀ Juda ni a ki yóò sì rí mọ kankan nítorí èmi yóò dáríjì àwọn tí ó ṣẹ́kù tí mo dá sí.
En ces jours-là, et en ce temps-là, dit Yahvé, « l'iniquité d'Israël sera recherchée, et il n'y en aura pas, aussi les péchés de Juda, et ils ne seront pas trouvés; car je pardonnerai à ceux que j'ai laissés comme restes.
21 “Kọlu ilẹ̀ Merataimu àti àwọn tí ó ń gbé ní Pekodi. Lépa rẹ pa, kí o sì parun pátápátá,” ni Olúwa wí, “Ṣe gbogbo ohun tí mo pàṣẹ fún ọ.
« Monte contre le pays de Merathaim, même contre elle, et contre les habitants de Pekod. Tuez et détruisez tout après eux, dit Yahvé, « et faites tout ce que je vous ai ordonné.
22 Ariwo ogun wà ní ilẹ̀ náà ìrọ́kẹ̀kẹ̀ ìparun ńlá.
Un bruit de bataille retentit dans le pays, et de grande destruction.
23 Báwo ni ó ṣe fọ́, tí ó sì pín yẹ́lẹyẹ̀lẹ tó, lọ́wọ́ òòlù gbogbo ayé! Báwo ní Babeli ti di ahoro ni àárín àwọn orílẹ̀-èdè.
Comme le marteau de toute la terre est écarté et brisé! Comme Babylone est devenue une désolation parmi les nations!
24 Mo dẹ pàkúté sílẹ̀ fún ọ ìwọ Babeli, kí o sì tó mọ ohun tí ó ń ṣẹlẹ̀, o ti kó sínú rẹ̀. A mú ọ nítorí pé o tako Olúwa.
Je vous ai tendu un piège, et vous êtes aussi pris, Babylone, et vous n'étiez pas au courant. Vous êtes trouvé, et aussi pris, parce que vous avez combattu contre Yahvé.
25 Olúwa ti kó àwọn ohun èlò ìjà rẹ̀ jáde, nítorí pé Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun ti ṣiṣẹ́ ní ilẹ̀ Babeli.
Yahvé a ouvert son arsenal, et a sorti les armes de son indignation; car le Seigneur, Yahvé des Armées, a une œuvre à accomplir dans le pays des Chaldéens.
26 Ẹ wá sórí rẹ̀ láti òpin gbogbo, sí ilé ìṣúra rẹ̀ sílẹ̀, ẹ kó o jọ bí òkìtì ọkà, kí ẹ sì yà á sọ́tọ̀ fún ìparun, ẹ má ṣe fí yòókù sílẹ̀ fún un.
Venez contre elle depuis la frontière la plus éloignée. Ouvrez ses entrepôts. Jetez-la en tas. Détruisez-la complètement. Qu'il ne reste rien d'elle.
27 Pa gbogbo àwọn akọ màlúù rẹ, jẹ́ kí a kó wọn lọ ibi tí a ó ti pa wọ́n! Ègbé ní fún wọn! Nítorí ọjọ́ wọn dé, àkókò ìbẹ̀wò wọn.
Tuez tous ses taureaux. Laissez-les aller à l'abattoir. Malheur à eux! Car leur jour est venu, le moment de leur visite.
28 Gbọ́ ohùn àwọn tí ó sálọ, tí ó sì sálà láti Babeli wá, sì sọ ní Sioni, bí Olúwa Ọlọ́run wa ti gbẹ̀san, ẹ̀san fún tẹmpili rẹ̀.
Écoutez ceux qui fuient et s'échappent du pays de Babylone, pour annoncer dans Sion la vengeance de Yahvé notre Dieu, la vengeance de son temple.
29 “Pe ọ̀pọ̀lọpọ̀ ènìyàn, àní gbogbo tafàtafà, sórí Babeli, ẹ dó tí ì yíkákiri, ma jẹ́ ki ẹnikẹ́ni sálà. Sán fún un gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ rẹ̀ gẹ́gẹ́ bi gbogbo èyí tí ó ti ṣe, ẹ ṣe bẹ́ẹ̀ sí i, nítorí tí ó ti gbéraga sí Olúwa, sí Ẹni Mímọ́ Israẹli.
« Convoquez les archers contre Babylone, tous ceux qui tendent l'arc. Encampement contre elle tout autour. Que rien ne s'échappe. Remboursez-la en fonction de son travail. Selon tout ce qu'elle a fait, faites-lui; car elle s'est enflammée contre Yahvé, contre le Saint d'Israël.
30 Nítorí náà, àwọn ọmọkùnrin rẹ̀ yóò ṣubú ní ìgboro, a ó sì pa àwọn ológun lẹ́nu mọ́,” ní Olúwa wí.
C'est pourquoi ses jeunes gens tomberont dans ses rues. Tous ses hommes de guerre seront réduits au silence en ce jour-là, dit Yahvé.
31 “Wò ó, èmi yóò dojú kọ ọ́ ìwọ agbéraga,” ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun wí, “nítorí ọjọ́ rẹ ti dé, àkókò tí èmi ó bẹ̀ ọ wò.
« Voici, j'en veux à toi, orgueilleux, dit le Seigneur, Yahvé des armées; « car ton jour est venu, le moment où je vous rendrai visite.
32 Onígbèéraga yóò kọsẹ̀, yóò sì ṣubú, kì yóò sì ṣí ẹni tí yóò gbé dìde. Èmi yóò tan iná ní ìlú náà, èyí tí yóò sì jo run.”
L'orgueilleux trébuche et tombe, et personne ne le relèvera. Je vais allumer un feu dans ses villes, et il dévorera tous ceux qui sont autour de lui. »
33 Èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun sọ: “A pọ́n àwọn ènìyàn Israẹli lójú àti àwọn ènìyàn Juda pẹ̀lú. Gbogbo àwọn tí ó kó wọn nígbèkùn dì wọn mú ṣinṣin wọn kò sì jẹ́ kí ó sá àsálà.
Yahvé des armées dit: « Les enfants d'Israël et les enfants de Juda sont opprimés ensemble. Tous ceux qui les ont fait prisonniers les retiennent. Ils refusent de les laisser partir.
34 Síbẹ̀, Olùràpadà wọn, Alágbára, Olúwa Ọlọ́run Alágbára ni orúkọ rẹ̀. Yóò sì gbe ìjà wọn jà, kí ó ba à lè mú wọn wá sinmi ní ilẹ̀ náà; ṣùgbọ́n kò sí ìsinmi fún àwọn tí ó ń gbé Babeli.
Leur rédempteur est fort. Yahvé des Armées est son nom. Il va plaider leur cause de manière approfondie, pour qu'il donne du repos à la terre, et de troubler les habitants de Babylone.
35 “Idà lórí àwọn Babeli!” ni Olúwa wí, “lòdì sí àwọn tó ń gbé ní Babeli, àwọn aláṣẹ àti àwọn amòye ọkùnrin.
« L'épée est sur les Chaldéens, dit Yahvé, « et sur les habitants de Babylone, sur ses princes, et sur ses sages.
36 Idà lórí àwọn wòlíì èké wọn yóò di òmùgọ̀! Idà lórí àwọn jagunjagun, wọn yóò sì kún fún ẹ̀rù.
L'épée est sur les vantards, et ils deviendront des imbéciles. Une épée est sur ses hommes puissants, et ils seront consternés.
37 Idà lórí àwọn kẹ̀kẹ́-ẹṣin rẹ̀ àti àwọn àjèjì nínú ẹgbẹ́ rẹ̀. Wọn yóò di obìnrin. Idà lórí àwọn ohun ìṣúra rẹ̀!
L'épée est sur leurs chevaux, sur leurs chars, et sur toutes les personnes mixtes qui se trouvent au milieu d'elle; et ils deviendront comme des femmes. Une épée est sur ses trésors, et ils seront volés.
38 Ilẹ̀ gbígbẹ lórí omi rẹ̀; yóò sì gbẹ. Nítorí pé ó jẹ́ ilẹ̀ àwọn ère, àwọn ère tí yóò ya òmùgọ̀ pẹ̀lú ẹ̀rù.
La sécheresse est sur ses eaux, et ils seront desséchés; car c'est un pays d'images gravées, et ils sont fous des idoles.
39 “Nítorí náà àwọn ẹranko ijù pẹ̀lú ọ̀wàwà ni yóò máa gbé ibẹ̀, abo ògòǹgò yóò sì máa gbé inú rẹ̀, a kì yóò sì gbé inú rẹ̀ mọ́, láéláé, bẹ́ẹ̀ ni a kì yóò ṣàtìpó nínú rẹ̀ láti ìrandíran.
C'est pourquoi les animaux sauvages du désert avec les loups y habiteront. Les autruches y habiteront. Elle ne sera plus habitée à jamais, Elle ne sera pas non plus vécue de génération en génération.
40 Gẹ́gẹ́ bí Olúwa ti gba ìjọba Sodomu àti Gomorra pẹ̀lú àwọn ìlú agbègbè wọn,” ni Olúwa wí, “torí náà kò sí ẹnikẹ́ni tí yóò gbé ibẹ̀; ènìyàn ki yóò gbé nínú rè.
Comme lorsque Dieu a renversé Sodome, Gomorrhe et ses villes voisines, dit Yahvé, « pour que personne n'y habite, aucun fils de l'homme n'y vivra.
41 “Wò ó! Ọ̀wọ́ ọmọ-ogun láti ìhà àríwá; orílẹ̀-èdè ńlá àti àwọn ọba púpọ̀ ni à ń gbé dìde láti òpin ilẹ̀ ayé.
« Voici qu'un peuple vient du nord. Une grande nation et de nombreux rois seront suscités des extrémités de la terre.
42 Wọ́n sì di ìhámọ́ra ọ̀kọ̀ àti ọrun, wọ́n burú wọn kò sì ní àánú. Wọ́n n ké bí i rírú omi bí wọ́n ti ṣe ń gun ẹṣin wọn lọ. Wọ́n wá bí àkójọpọ̀ ogun láti kọlù ọ́, ìwọ ọmọbìnrin Babeli.
Ils prennent l'arc et la lance. Ils sont cruels, et n'ont aucune pitié. Leur voix gronde comme la mer. Ils montent à cheval, tout le monde dans le tableau, comme un homme à la bataille, contre toi, fille de Babylone.
43 Ọba Babeli ti gbọ́ ìròyìn nípa wọn, ọwọ́ wọn sì rọ, ìrora mú wọn bí obìnrin tí ó ń rọbí.
Le roi de Babylone a entendu parler d'eux, et ses mains deviennent faibles. Anguish s'est emparé de lui, des douleurs comme celles d'une femme en travail.
44 Bí i kìnnìún ni òun ó gòkè wá láti igbó Jordani sí orí ilẹ̀ ọlọ́ràá, Èmi ó lé Babeli kúrò ní ilẹ̀ rẹ̀ ní kíákíá. Ta ni àyànfẹ́ náà tí èmi ó yàn sórí rẹ̀? Ta ló dàbí mi, ta ni ó sì pé mi ṣe ẹlẹ́rìí? Ta ni olùṣọ́-àgùntàn náà tí yóò le dúró níwájú mi?”
Voici que l'ennemi surgit comme un lion. des fourrés du Jourdain contre la forte habitation; car je les ferai fuir soudainement. Celui qui sera choisi, Je le nommerai à ce poste, car qui est comme moi? Qui me fixera une heure? Qui est le berger qui peut se tenir devant moi? »
45 Nítorí náà, gbọ́ ohun tí Olúwa sọ nípa Babeli, ẹni tí ó gbìmọ̀ lòdì sí Babeli: n ó sì pa agbo ẹran wọn run.
C'est pourquoi, écoutez le conseil de Yahvé qu'il a pris contre Babylone; et ses objectifs qu'il s'est proposé contre le pays des Chaldéens: Ils vont sûrement les traîner loin, même les petits du troupeau. Il fera de leur habitation une désolation.
46 Ní ohùn igbe ńlá pé; a kò Babeli, ilẹ̀ ayé yóò mì tìtì, a sì gbọ́ igbe náà láàrín àwọn orílẹ̀-èdè.
La terre tremble au bruit de la prise de Babylone. Le cri est entendu parmi les nations.

< Jeremiah 50 >