< Lamentations 4 >

1 Báwo ni wúrà ṣe sọ ògo dídán rẹ̀ nù, wúrà dídára di àìdán! Òkúta ibi mímọ́ wá túká sí oríta gbogbo òpópó.
Hwɛ sɛnea sikakɔkɔɔ ayera ne hyerɛn no ni Sikakɔkɔɔ ankasa na ho abiri saa! Wɔatoto aboɔdemmo kronkron apete wɔ abɔnten biara so.
2 Báwo ni àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin Sioni tí ó ṣe iyebíye, tí wọ́n fi wúrà dídára ṣe wá dàbí ìkòkò amọ̀ lásán iṣẹ́ ọwọ́ amọ̀kòkò!
Hwɛ sɛnea Sion mmabarima a wodi mu na anka wɔsom bo sɛ sikakɔkɔɔ no ayɛ, mprempren wɔfa wɔn sɛ dɔte nkuku, ɔnwemfo nsa ano adwuma!
3 Àwọn ajáko pèsè ọmú wọn fún ìtọ́jú àwọn ọmọ wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn mi wá láì lọ́kàn bí ògòǹgò ní aginjù.
Mpo adompo yi wɔn nufu ma wɔn mma num, nanso me nkurɔfo ayɛ atirimɔdenfo sɛ sohori a ɔwɔ sare so.
4 Nítorí òǹgbẹ, ahọ́n àwọn ọmọ ọwọ́ lẹ̀ mọ́ òkè ẹnu wọn; àwọn ọmọdé bẹ̀bẹ̀ fún oúnjẹ, ṣùgbọ́n kò sí ẹni tí ó fi fún wọn.
Osukɔm nti, akokoaa tɛkrɛma fam ne dodo mu; mmofra no srɛ aduan, nanso obiara mfa mma wɔn.
5 Àwọn tí ó ń jẹ ohun dáradára di òtòṣì ní òpópó. Àwọn tí a fi aṣọ dáradára wọ̀ ni wọ́n sùn ní orí òkìtì eérú.
Wɔn a na anka wodi nnuan pa no ohia buruburoo aka wɔn wɔ mmɔnten so. Wɔn a wɔde sirikyi tetew wɔn no mprempren wɔdeda nso a wɔaboa ano so.
6 Ìjìyà àwọn ènìyàn mi tóbi ju ti Sodomu lọ, tí a sí ní ipò ní òjijì láìsí ọwọ́ láti ràn án lọ́wọ́.
Me nkurɔfo asotwe so sen Sodom a wotuu wɔn mpofirim no, a wɔannya ɔboafo biara de.
7 Ọmọ ọba ọkùnrin wọn mọ́ ju òjò-dídì, wọ́n sì funfun ju wàrà lọ wọ́n ni ìtọ́jú bí iyùn pupa, ìrísí wọn dàbí safire.
Na wɔn ahenemma ho twa sen sukyerɛmma, na wɔnan sen nufusu, na wɔn nipadua no bere, na ɛwɔ ahoɔden te sɛ abohemaa, na wɔte sɛ hoabo.
8 Ṣùgbọ́n nísinsin yìí wọ́n dúdú ju èédú; wọn kò sì dá wọn mọ̀ ní òpópó. Ara wọn hun mọ́ egungun; ó sì gbẹ bí igi gbígbẹ.
Nanso mprempren de, wobiri sen wusiw bɔtɔ; na wonhu wɔn yiye wɔ mmɔnten so. Wɔn were atwintwam wɔ wɔn nnompe so; ho awo wosee sɛ abaa.
9 Àwọn tí ó kù nípasẹ̀ idà sàn ju àwọn tí ìyàn pa; tí ó wọ àkísà ebi, tí ó ń ṣòfò fún àìní oúnjẹ láti inú pápá.
Wɔn a wɔtotɔɔ wɔ afoa ano no ye koraa sen wɔn a ɔkɔm kunkum wɔn; ɔkɔm tware wɔn ma wowuwu, esiane aduan a enni mfuw so nti.
10 Pẹ̀lú ọwọ́ àwọn obìnrin aláàánú ni wọ́n ṣe ọmọ wọn jẹ tí ó di oúnjẹ fún wọn nígbà tí a pa àwọn ènìyàn mi run.
Mmea a wɔwɔ ayamhyehye de wɔn nsa anoa wɔn ankasa mma, ayɛ wɔn aduan, bere a wɔsɛee me nkurɔfo no.
11 Olúwa ti fi ihò kíkún fún ìbínú rẹ̀; ó sì tú ìbínú gbígbóná rẹ̀ jáde. Ó da iná ní Sioni tí ó jó ìpìlẹ̀ rẹ̀ run.
Awurade ada nʼabufuwhyew nyinaa adi; wahwie nʼabufuw a ano yɛ den no. Ɔsɔɔ ogya ano wɔ Sion ma ɛhyew ne fapem.
12 Àwọn ọba ayé kò gbàgbọ́, tàbí àwọn ènìyàn ayé, wí pé àwọn ọ̀tá àti aninilára le wọ odi ìlú Jerusalẹmu.
Asase so ahemfo annye anni, wiase mu nnipa nso annye anni sɛ atamfo betumi ahyɛn Yerusalem apon mu.
13 Èyí ṣẹlẹ̀ nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn wòlíì àti àìṣedéédéé àwọn olórí àlùfáà, tí ó ta ẹ̀jẹ̀ àwọn olódodo sílẹ̀ láàrín rẹ̀.
Nanso esii, nʼadiyifo no bɔne ne nʼasɔfo amumɔyɛ nti, wɔn na wohwiee atreneefo mogya guu wɔ kuropɔn no mu.
14 Nísinsin yìí wọ́n ń rìn kiri ní òpópó bí ọkùnrin tí ó fọ́jú. Ẹ̀jẹ̀ ara wọn sọ wọ́n di àbàwọ́n tí kò sẹ́ni tó láyà láti fọwọ́ kan aṣọ wọn.
Afei wɔkeka wɔ mmɔnten so te sɛ nnipa a wɔn ani afura. Mogya a ama wɔn ho agu fi no nti obiara suro sɛ ɔde ne ho bɛka wɔn ntade.
15 “Lọ kúrò! Ẹ̀yin di aláìmọ́!” ni àwọn ènìyàn ń kígbe sí wọn. “Ẹ lọ! Ẹ lọ! Ẹ má ṣe fọwọ́ kàn wá!” Àwọn ènìyàn láàrín orílẹ̀-èdè wí pé, “Wọn kì yóò tẹ̀dó síbí mọ́.”
Nnipa teɛteɛɛ mu gu wɔn so se, “Mumfi ha nkɔ! Mo ho ntew!” “Monkɔ, monkɔ! Mommfa mo ho nka yɛn.” Sɛ woguan kɔnenam a amanaman no mu nnipa ka se, “Wɔrentumi ntena ha bio.”
16 Olúwa ti tú wọn ká fúnra rẹ̀; kò sí bojútó wọn mọ́. Kò sí ọ̀wọ̀ fún olórí àlùfáà mọ́, àti àánú fún àwọn àgbàgbà.
Awurade ankasa abɔ wɔn ahwete; nʼani nni wɔn so bio. Wɔmmfa nidi mma asɔfo, na wɔn ani nsɔ mpanyimfo.
17 Síwájú sí i, ojú wa kùnà fún wíwo ìrànlọ́wọ́ asán; láti orí ìṣọ́ wa ni à ń wò fún orílẹ̀-èdè tí kò le gbà wá là.
Nea ɛka ho bio, yɛn ani anni ammoa yɛn, yɛpɛɛ sɛ yebenya mmoa, nanso ɛyɛɛ ɔkwa; yefi yɛn abantenten so de yɛn ani too ɔman a wɔrentumi nnye yɛn so.
18 Wọ́n ń ṣọ́ wa kiri, àwa kò sì le rìn ní òpópó wa mọ́. Òpin wa ti súnmọ́, ọjọ́ wa sì níye nítorí òpin wa ti dé.
Nnipa dii yɛn ntɛntɛnso wɔ yɛn anammɔntu mu, enti yɛantumi annantew yɛn mmɔnten so. Yɛn awiei bɛnee, na wɔkan yɛn nna, efisɛ na yɛn awiei adu so.
19 Àwọn tí ń lé wa yára ju idì ojú ọ̀run lọ; wọ́n lé wa ní gbogbo orí òkè wọ́n sì gẹ̀gùn dè wá ní aginjù.
Yɛn ataafo ho yɛ hare sen akɔre a wɔwɔ wim; wɔtaa yɛn faa mmepɔw so na wɔtɛw yɛn wɔ sare so.
20 Ẹni àmì òróró Olúwa, èémí ìyè wa, ni wọ́n fi tàkúté wọn mú. Àwa rò pé lábẹ́ òjìji rẹ̀ ni àwa yóò máa gbé láàrín orílẹ̀-èdè gbogbo.
Nea Awurade asra no ngo, yɛn nkwa home ankasa no, kɔtɔɔ wɔn mfiri mu. Yegye dii sɛ ne nwini ase, yebenya nkwa wɔ amanaman no mu.
21 Ẹ yọ̀ kí inú yín sì dùn, ẹ̀yin ọmọbìnrin Edomu, ẹ̀yin tó ń gbé ní ilẹ̀ Usi. Ṣùgbọ́n, a ó gbé ago náà kọjá sọ́dọ̀ rẹ pẹ̀lú; ìwọ yóò yó bí ọ̀mùtí, ìwọ yóò sì rìn ní ìhòhò.
Di ahurusi na ma wʼani nnye, Edom Babea, wo a wote Us asase so. Wɔde kuruwa no bɛma wo nso bi; wobɛbow na wɔabɔ wo adagyaw.
22 Ìwọ ọmọbìnrin Sioni, ìjìyà rẹ yóò dópin; kò ní mú ìgbèkùn rẹ pẹ́ mọ́. Ṣùgbọ́n, ìwọ ọmọbìnrin Edomu, yóò jẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ ní yà yóò sì fi àìṣedéédéé rẹ hàn kedere.
Ɔbabea Sion, wʼasotwe bɛba awiei; ɔremma wo nkɔ so ntena nnommum mu. Nanso Ɔbabea Edom, obetua wo bɔne so ka na wada wʼamumɔyɛ adi.

< Lamentations 4 >