< Joshua 9 >

1 Nísinsin yìí, nígbà tí gbogbo ọba tó wà ní ìwọ̀-oòrùn Jordani gbọ́ nípa nǹkan wọ̀nyí, àwọn náà tí ó wà ní orí òkè àti àwọn tí ó wà ní ẹsẹ̀ òkè, àti gbogbo àwọn tí ó wà ní agbègbè Òkun Ńlá títí ó fi dé Lebanoni (àwọn ọba Hiti, Amori, Kenaani, Peresi, Hifi àti Jebusi)
Na rĩrĩa athamaki othe arĩa maarĩ mwena wa ithũĩro wa Rũũĩ rwa Jorodani maiguire maũndũ macio, na arĩa maarĩ bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma, na arĩa maarĩ ituamba-ini ciikũrũko cia irĩma cia mwena wa ithũĩro, na kũu hũgũrũrũ-inĩ cia Iria rĩrĩa Inene guothe o nginya Lebanoni (nĩo athamaki a andũ a Ahiti, na Aamori, na Akaanani, na Aperizi, na Ahivi, na Ajebusi),
2 wọ́n sì kó ara wọn jọ láti bá Joṣua àti Israẹli jagun.
magĩcookanĩrĩra hamwe nĩguo mahũũrane na Joshua na Isiraeli.
3 Ṣùgbọ́n nígbà tí àwọn ènìyàn Gibeoni gbọ́ ohun tí Joṣua ṣe sí Jeriko àti Ai,
No rĩrĩ, rĩrĩa andũ a Gibeoni maaiguire ũrĩa Joshua ekĩte itũũra rĩa Jeriko o na rĩa Ai,
4 wọ́n dá ọgbọ́n ẹ̀tàn. Wọ́n lọ gẹ́gẹ́ bí aṣojú tí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ wọn kún fún ẹrù tí a fi àwọn àpò tó ti gbó dì, àti àwọn awọ ọtí wáìnì tó ti gbó tí a tún rán.
magĩĩka ũndũ wa wara. Magĩthiĩ marĩ ta andũ matũmĩtwo marĩ na ndigiri ciao ikuuithĩtio makũnia matarũkangu, na mondo ngũrũ mũno cia ndibei irĩ nduĩkangu na igatumwo.
5 Àwọn ọkùnrin náà sì wọ bàtà àti aṣọ tí ó ti gbó. Gbogbo oúnjẹ tí wọ́n pèsè fún ara wọn sì bu.
Nao arũme acio meekĩrĩte iraatũ ciarĩ ndarũku, ciarĩ na iraka, na makehumba nguo ngũrũ. Irio ciao ciothe iria meekuuĩire rĩĩgu ciarĩ nyũmũ na ikagĩa mbuu.
6 Wọ́n sì tọ Joṣua lọ ní ibùdó ní Gilgali, wọ́n sì sọ fún òun àti àwọn ọkùnrin Israẹli pé, “Ìlú òkèrè ní àwọn ti wá, ẹ ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wa.”
Nao magĩthiĩ kũrĩ Joshua kambĩ-inĩ o kũu Giligali, makĩmwĩra atĩrĩ we mwene hamwe na andũ a Isiraeli, “Tũũkĩte kuuma bũrũri wa kũraya mũno na gũkũ; tondũ ũcio gĩai kĩrĩkanĩro na ithuĩ.”
7 Àwọn ọkùnrin Israẹli sọ fún àwọn ará Hifi pé, “Ṣùgbọ́n bóyá tòsí wa ni ẹ ń gbé. Báwo ni a ó ṣe lè ṣe àdéhùn pẹ̀lú yín?”
Nao andũ a Isiraeli makĩĩra Ahivi acio atĩrĩ, “Hihi no gũkorwo mũtũũraga o gũkũ gũkuhĩ na ithuĩ, tũngĩhota atĩa kũgĩa kĩrĩkanĩro na inyuĩ?”
8 “Ìránṣẹ́ rẹ ní àwa í ṣe.” Wọ́n sọ fún Joṣua. Ṣùgbọ́n Joṣua béèrè, “Ta ni yín àti pé níbo ni ẹ̀yin ti wá?”
Nao magĩcookeria Joshua atĩrĩ, “Ithuĩ tũrĩ ndungata ciaku.” Ningĩ Joshua akĩmooria atĩrĩ, “Inyuĩ mũrĩ a, na muumĩte kũ?”
9 Wọ́n sì dáhùn pé, “Ní ilẹ̀ òkèèrè ní àwọn ìránṣẹ́ rẹ tí wá, nítorí orúkọ Olúwa Ọlọ́run rẹ. Nítorí tí àwa ti gbọ́ òkìkí rẹ àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe ní Ejibiti,
Nao makĩmũcookeria atĩrĩ, “Ithuĩ ndungata ciaku tuumĩte bũrũri wa kũraya mũno na gũkũ, tũũkĩte nĩ ũndũ wa ngumo ya Jehova Ngai wanyu. Nĩgũkorwo nĩtũiguĩte ũhoro wake: o na maũndũ mothe marĩa eekire bũrũri wa Misiri,
10 àti ohun gbogbo tí ó ti ṣe sí ọba àwọn Amori méjèèje tí ń bẹ ní òkè Jordani, sí Sihoni ọba Heṣboni, àti Ogu ọba Baṣani, tí wọ́n jẹ ọba ní Aṣtarotu.
na ũrĩa wothe eekire athamaki arĩa eerĩ a Aamori kũu irathĩro rĩa Rũũĩ rwa Jorodani, nao nĩ Sihoni mũthamaki wa Heshiboni, na Ogu mũthamaki wa Bashani, ũrĩa wathamakaga Ashitarothu.
11 Àwọn àgbàgbà wa àti gbogbo àwọn tí ń gbé ìlú wa sọ fún wa pé, ‘Ẹ mú oúnjẹ lọ́wọ́ fún ìrìnàjò yín, ẹ lọ pàdé wọn, kí ẹ sì sọ fún wọn pé, “Àwa ni ìránṣẹ́ yín, ẹ dá àdéhùn pẹ̀lú wa.”’
Nao athuuri atongoria aitũ na andũ arĩa othe matũũraga bũrũri witũ nĩmatwĩrire atĩrĩ, ‘Kuuai irio nĩ ũndũ wa rũgendo rwanyu, mũthiĩ mũcemanie na andũ acio, na mũmeere atĩrĩ, “Ithuĩ tũrĩ ndungata cianyu; gĩai kĩrĩkanĩro na ithuĩ.”’
12 Gbígbóná ní a mú oúnjẹ wa wá, nígbà tí a dì í ní ilé ní ọjọ́ tí à ń bọ̀ wá sọ́dọ̀ yín. Ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí ó ṣe gbẹ àti bí ó sì ṣe bu nísinsin yìí.
Irio ici ciitũ cia rĩĩgu ciarĩ hiũ mũthenya ũrĩa tuoimire gwitũ tũke kũrĩ inyuĩ. No rĩu ta kĩonei ũrĩa ciũmĩte na ikagĩa mbuu.
13 Àti ìgò wáìnì wọ̀nyí, tí àwa rọ kún tuntun ni, ṣùgbọ́n ẹ wò ó bí wọ́n ti sán. Aṣọ àti bàtà wa ni ó sì ti gbó nítorí ìrìnàjò ọ̀nà jíjìn.”
Nacio mondo ici ciarĩ njerũ tũgĩciyũria ndibei, no rĩu ta kĩonei ũrĩa ituĩkangĩte. Nacio nguo ciitũ na iraatũ nĩikũrĩte nĩ ũndũ wa rũgendo kũraiha mũno.”
14 Àwọn ọkùnrin Israẹli sì yẹ oúnjẹ wọn wò, wọn kò sì wádìí ní ọwọ́ Olúwa.
Nao andũ a Isiraeli makĩrora irio imwe cia andũ acio, no matiigana kũhooya kĩrĩra kuuma harĩ Jehova.
15 Nígbà náà ni Joṣua ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú wọn láti dá wọn sí, àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn fi ọwọ́ sí àdéhùn náà nípa ṣíṣe ìbúra.
Nake Joshua akĩgĩa kĩrĩkanĩro gĩa thayũ nao atĩ areke matũũre muoyo, nao atongoria a kĩũngano kĩu kĩa andũ a Isiraeli magĩĩkĩra ũhoro ũcio hinya na mwĩhĩtwa.
16 Ní ẹ̀yìn ọjọ́ mẹ́ta tí wọ́n ti ṣe àdéhùn pẹ̀lú àwọn ará Gibeoni, àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé aládùúgbò wọn ni wọ́n, tí ń gbé ní tòsí wọn.
Mĩthenya ĩtatũ thuutha wa kũgĩa na kĩrĩkanĩro kĩu na andũ acio a Gibeoni, andũ a Isiraeli makĩigua atĩ andũ acio maahakanĩte nao, na maatũũraga o hakuhĩ nao.
17 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn ọmọ Israẹli jáde, wọ́n sì dé ìlú wọn ní ọjọ́ kẹta: Gibeoni, Kefira, Beeroti àti Kiriati-Jearimu.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli makiumagara, na mũthenya wa gatatũ magĩkinya matũũra-inĩ mao manene, na nĩmo: Gibeoni, na Kefira, na Beerothu, na Kiriathu-Jearimu.
18 Ṣùgbọ́n àwọn ọmọ Israẹli kò si kọlù wọ́n, nítorí pé àwọn àgbàgbà ìjọ ènìyàn ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli. Gbogbo ènìyàn sì kùn sí àwọn àgbàgbà náà,
No andũ a Isiraeli matiigana kũmahũũra, nĩ ũndũ atongoria a kĩũngano kĩao nĩmehĩtĩte na mwĩhĩtwa makĩgwetaga rĩĩtwa rĩa Jehova Ngai wa Isiraeli. Nakĩo kĩũngano kĩu gĩothe gĩkĩnuguna nĩ ũndũ wa atongoria acio,
19 ṣùgbọ́n gbogbo àwọn olórí dáhùn pé, “Àwa ti búra fún wọn ní orúkọ Olúwa Ọlọ́run Israẹli, a kò sì lè fọwọ́ kàn wọ́n nísinsin yìí.
no atongoria acio othe makĩmacookeria atĩrĩ, “Nĩtwĩhĩtĩte na mwĩhĩtwa tũkĩgwetaga rĩĩtwa rĩa Jehova Ngai wa Isiraeli, na tondũ ũcio tũtingĩmahutia.
20 Èyí ní àwa yóò ṣe sí wọn, àwa yóò dá wọn sí, kí ìbínú kí ó má ba à wá sórí wa, nítorí ìbúra tí a búra fún wọn.”
Ũrĩa tũngĩmeeka nĩ atĩrĩ: Nĩ tũkũreka matũũre muoyo, nĩgeetha tũtikanacookererwo nĩ marakara nĩ ũndũ wa kuuna mwĩhĩtwa ũrĩa twehĩtire nĩ ũndũ wao.”
21 Wọ́n tẹ̀síwájú, “Ẹ dá wọn sí, ṣùgbọ́n ẹ jẹ́ kí wọn jẹ́ gégigégi àti apọnmi fún gbogbo ìlú.” Àwọn àgbàgbà náà sì mú ìlérí wọn ṣẹ fún wọn.
O na ningĩ makĩmeera atĩrĩ, “Rekei matũũre muoyo, no matuĩke a kuunaga ngũ na a gũtahagĩra kĩrĩndĩ gĩkĩ gĩothe gĩa Isiraeli maaĩ.” Nĩ ũndũ ũcio atongoria makĩiga kĩrĩko kĩao kũrĩ andũ acio a Gibeoni.
22 Nígbà náà ni Joṣua pe àwọn ọmọ Gibeoni jọ pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi tàn wá wí pe, ‘Àwa gbé ní ibi tí ó jìnnà sí yín,’ nígbà tí ó jẹ́ pé tòsí wa ní ẹ̀yin ń gbé?
Ningĩ Joshua agĩĩta andũ acio a Gibeoni akĩmooria atĩrĩ, “Nĩ kĩĩ gĩatũmire mũtũheenie rĩrĩa mwoigire atĩrĩ, ‘Tũtũũraga kũndũ kũraya mũno na inyuĩ,’ o rĩrĩa mũtũũraga o gũkũ gũkuhĩ na ithuĩ?
23 Nísinsin yìí, ẹ̀yin di ẹni ègún, ẹ̀yin kò sì ní kúrò ní gégigégi àti apọnmi fún ilé Ọlọ́run mi.”
Tondũ ũcio nĩmwagwatwo nĩ kĩrumi, na inyuĩ mũtigatiga gũtuĩka ndungata cia kuuna ngũ na gũtahagĩra nyũmba ya Ngai wakwa maaĩ.”
24 Wọ́n sì dá Joṣua lóhùn pé, “Nítorí tí a sọ fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ dájúṣáká bí Olúwa Ọlọ́run rẹ ti pàṣẹ fún Mose ìránṣẹ́ rẹ̀, láti fún yín ní gbogbo ilẹ̀ náà, kí ó sì pa gbogbo olùgbé ilẹ̀ náà run kúrò ní iwájú yín. Nítorí náà, àwa bẹ̀rù ẹ̀mí wa nítorí yín, èyí sì ni ìdí tí a fi ṣe bẹ́ẹ̀.
Nao magĩcookeria Joshua makĩmwĩra atĩrĩ, “Ithuĩ ndungata ciaku nĩtwerirwo o wega ũrĩa Jehova Ngai waku aathire ndungata yake Musa akamũhe bũrũri ũyũ wothe, na atĩ aniine andũ othe arĩa matũũraga kuo mehere mbere yanyu. Nĩ ũndũ ũcio tũgĩĩtigĩra mũno, tweciria ũrĩa mũngĩtũũraga, na nĩkĩo twekire ũndũ ũcio.
25 Nísinsin yìí, àwa wà ní ọwọ́ yín. Ohunkóhun tí ẹ bá rò pé ó yẹ ó si tọ́ lójú yín ní kí ẹ fi wá ṣe.”
Na rĩrĩ, rĩu tũrĩ moko-inĩ maku. Twĩke ũndũ ũrĩa wothe ũkuona ũrĩ mwega na wa kĩhooto.”
26 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua sì gbà wọ́n là kúrò ní ọwọ́ àwọn ọmọ Israẹli. Wọn kò sì pa wọ́n.
Nĩ ũndũ ũcio Joshua akĩmahonokia kuuma kũrĩ andũ a Isiraeli, na matiamoragire.
27 Ní ọjọ́ náà ni ó sọ àwọn Gibeoni di aṣẹ́gi àti apọnmi fún àwọn ará ìlú àti fún pẹpẹ Olúwa ní ibi tí Olúwa yóò yàn. Báyìí ni wọ́n wà títí di òní yìí.
Mũthenya o ro ũcio Joshua agĩtua andũ acio a Gibeoni oini a ngũ na atahĩri mũingĩ wa Isiraeli maaĩ, o na atahĩri kĩgongona kĩa Jehova maaĩ o harĩa hothe Jehova angĩathuurire. Ũguo nĩguo matũire nginya ũmũthĩ.

< Joshua 9 >