< Joshua 10 >

1 Ní báyìí tí Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu gbọ́ pé Joṣua ti gba Ai, tí ó sì ti pa wọ́n pátápátá; tí ó sì ṣe sí Ai àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Jeriko àti ọba rẹ̀, àti bí àwọn ènìyàn Gibeoni ti ṣe àdéhùn àlàáfíà pẹ̀lú Israẹli, tí wọ́n sì ń gbé nítòsí wọn.
Na rĩrĩa, Adoni-Zedeki mũthamaki wa Jerusalemu aiguire atĩ Joshua nĩarĩkĩtie gũtunyana itũũra rĩa Ai na akarĩananga o biũ, na ageeka Ai na mũthamaki warĩo o ta ũrĩa ekĩte itũũra rĩa Jeriko na mũthamaki warĩo, na atĩ andũ a Gibeoni nĩmagĩte kĩrĩkanĩro gĩa thayũ na Isiraeli na atĩ maatũũraga hakuhĩ nao-rĩ.
2 Ìbẹ̀rù sì mú òun àti àwọn ènìyàn rẹ̀ torí pé Gibeoni jẹ́ ìlú tí ó ṣe pàtàkì, bí ọ̀kan nínú àwọn ìlú ọba; ó tóbi ju Ai lọ, gbogbo ọkùnrin rẹ̀ ní ó jẹ́ jagunjagun.
Nake, we na andũ ake makĩmaka mũno nĩ ũndũ wa ũhoro ũcio, nĩgũkorwo Gibeoni rĩarĩ itũũra inene na rĩa bata, o ta rĩmwe rĩa matũũra marĩa maakoragwo marĩ ma ũthamaki; na rĩarĩ inene gũkĩra Ai, o na ningĩ andũ a rĩo othe maarĩ njamba cia ita.
3 Nítorí náà Adoni-Sedeki ọba Jerusalẹmu bẹ Hohamu ọba Hebroni, Piramu ọba Jarmatu, Jafia ọba Lakiṣi àti Debiri ọba Egloni. Wí pe,
Nĩ ũndũ ũcio Adoni-Zedeki mũthamaki wa Jerusalemu agĩtũmanĩra Hohamu mũthamaki wa Hebironi, na Piramu mũthamaki wa Jaramuthu, na Jafia mũthamaki wa Lakishi, o na Debiri mũthamaki wa Egiloni,
4 “Ẹ gòkè wá, kí ẹ sì ràn mi lọ́wọ́ láti kọlu Gibeoni, nítorí tí ó ti wà ní ìrẹ́pọ̀ pẹ̀lú Joṣua àti àwọn ará Israẹli.”
akĩmeera atĩrĩ, “Ambatai mũũke mũndeithie kũhũũra Gibeoni, nĩ ũndũ nĩmagĩte kĩrĩkanĩro gĩa thayũ na Joshua na andũ a Isiraeli.”
5 Àwọn ọba Amori márààrún, ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni, kó ara wọn jọ, wọ́n sì gòkè, àwọn àti gbogbo ogun wọn, wọ́n sì dojúkọ Gibeoni, wọ́n sì kọlù ú.
Nao athamaki acio atano a Aamori, nao nĩ athamaki a Jerusalemu, na Hebironi, na Jaramuthu, na Lakishi, na Egiloni, magĩcookanĩrĩra hamwe. Makĩambata na mbũtũ ciao ciothe cia ita, nao makĩamba hema ciao mangʼetheire itũũra rĩa Gibeoni, makĩrĩtharĩkĩra.
6 Àwọn ará Gibeoni sì ránṣẹ́ sí Joṣua ní ibùdó ní Gilgali pé, “Ẹ má ṣe fi ìránṣẹ́ yín sílẹ̀. Ẹ gòkè tọ̀ wà wá ní kánkán kí ẹ sì gbà wá là. Ẹ ràn wá lọ́wọ́, nítorí gbogbo àwọn ọba Amori tí ń gbé ní orílẹ̀-èdè òkè dojú ìjà kọ wá.”
Nao andũ a Gibeoni magĩtũmanĩra Joshua o kũu Giligali kambĩ-inĩ yake, makĩmwĩra atĩrĩ, “Ndũgatiganĩrie ndungata ciaku. Ambata, ũũke gũkũ narua nĩguo ũtũhonokie! Tũteithie nĩ ũndũ athamaki othe a Aamori arĩa matũũraga bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma nĩmacookanĩrĩire matũũkĩrĩre.”
7 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua gòkè lọ láti Gilgali pẹ̀lú gbogbo ogun rẹ̀, àti akọni nínú àwọn ọmọ-ogun rẹ̀.
Nĩ ũndũ ũcio Joshua akĩambata akiuma Giligali arĩ na ita rĩake rĩothe hamwe na njamba ciake cia ita iria irĩ hinya.
8 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Má ṣe bẹ̀rù wọn, Mo ti fi wọ́n lé ọ lọ́wọ́. Kò sí ẹnikẹ́ni nínú wọn ti yóò lè dojúkọ ọ́.”
Nake Jehova akĩĩra Joshua atĩrĩ, “Ndũkametigĩre, nĩ ũndũ nĩndĩmaneanĩte moko-inĩ maku. Gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wao ũkũhota gũgwĩtiiria.”
9 Lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n ti wọ́de ogun ní gbogbo òru náà láti Gilgali, Joṣua sì yọ sí wọn lójijì.
Thuutha wa gũthiĩ ũtukũ wothe kuuma Giligali, Joshua akĩmahithũkĩra o rĩmwe.
10 Olúwa mú kí wọn dààmú níwájú àwọn Israẹli, wọ́n sì pa wọ́n ní ìpakúpa ní Gibeoni. Israẹli sì lépa wọn ní ọ̀nà tí ó lọ sí Beti-Horoni, ó sì pa wọ́n dé Aseka, àti Makkeda.
Nake Jehova akĩmarehere kĩrigiicano mbere ya Isiraeli, nao makĩmatooria o biũ kũu Gibeoni. Ningĩ andũ a Isiraeli makĩmatengʼeria na njĩra ĩrĩa yathiĩte yambatĩte nginya Bethi-Horoni, magĩthiĩ makĩmooragaga o nginya Azeka na Makeda.
11 Bí wọ́n sì tí ń sá ní iwájú Israẹli ní gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ ní ọ̀nà láti Beti-Horoni títí dé Aseka, Olúwa rọ yìnyín ńlá sí wọn láti ọ̀run wá, àwọn tí ó ti ipa yìnyín kú sì pọ̀ ju àwọn tí àwọn ará Israẹli fi idà pa lọ.
Hĩndĩ ĩyo moragĩra andũ a Isiraeli maikũrũkĩte kuuma Bethi-Horoni marorete Azeka-rĩ, Jehova akĩmagũithĩria mahiga manene ma mbura kuuma igũrũ, nao andũ aingĩ makĩũragwo nĩ mahiga macio ma mbura o na gũkĩra arĩa mooragĩtwo nĩ andũ a Isiraeli na rũhiũ rwa njora.
12 Ní ọjọ́ tí Olúwa fi àwọn ọmọ Amori lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sọ fún Olúwa níwájú àwọn ará Israẹli, “Ìwọ oòrùn, dúró jẹ́ẹ́ ní orí Gibeoni, Ìwọ òṣùpá, dúró jẹ́ẹ́ lórí àfonífojì Aijaloni.”
Mũthenya ũrĩa Jehova aaneanire Aamori kũrĩ a Isiraeli-rĩ, Joshua akĩarĩria Jehova, andũ a Isiraeli makĩiguaga, akĩmwĩra atĩrĩ: “We riũa-rĩ, rũgama o ũguo wĩhaande igũrũ rĩa Gibeoni, O nawe mweri-rĩ, rũgama o ro ũguo wĩhaande igũrũ rĩa Gĩtuamba kĩa Aijaloni.”
13 Bẹ́ẹ̀ ni oòrùn náà sì dúró jẹ́ẹ́, òṣùpá náà sì dúró, títí tí ìlú náà fi gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá rẹ̀, gẹ́gẹ́ bí a ti kọ́ nínú ìwé Jaṣari. Oòrùn sì dúró ní agbede-méjì ọ̀run, kò sì wọ̀ ní ìwọ̀n odindi ọjọ́ kan.
Nĩ ũndũ ũcio riũa rĩkĩrũgama o ro ũguo, naguo mweri ũkĩrũgama, o nginya rĩrĩa rũrĩrĩ rũu rwerĩhĩirie harĩ thũ ciao, o ta ũrĩa kwandĩkĩtwo Ibuku-inĩ rĩa Jasharu. Riũa rĩarũgamire o kũu matu-inĩ gatagatĩ na rĩkĩamba gũtiga gũthũa handũ ha mũthenya mũgima.
14 Kò sí ọjọ́ tí o dàbí rẹ̀ ṣáájú tàbí ní ẹ̀yìn rẹ̀, ọjọ́ tí Olúwa gbọ́ ohùn ènìyàn. Dájúdájú Olúwa jà fún Israẹli!
Gũtirĩ kwagĩa mũthenya ũngĩ ta ũcio mbere ĩyo kana thuutha ũcio, mũthenya ũrĩa Jehova aacookirie mahooya ta macio. Ti-itherũ Jehova nĩwe warũagĩrĩra andũ a Isiraeli!
15 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli padà sí ibùdó ní Gilgali.
Nake Joshua agĩcooka hamwe na andũ othe a Isiraeli kambĩ-inĩ kũu Giligali.
16 Ní báyìí àwọn ọba Amori márùn-ún ti sálọ, wọ́n sì fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta kan ní Makkeda,
Na rĩrĩ, athamaki acio atano nĩmoorĩte na magathiĩ makehitha thĩinĩ wa ngurunga kũu Makeda.
17 nígbà tí wọ́n sọ fún Joṣua pé, a ti rí àwọn ọba márààrún, ti ó fi ara pamọ́ nínú ihò àpáta ní Makkeda,
Rĩrĩa Joshua eerirwo atĩ athamaki acio nĩmonetwo mehithĩte ngurunga-inĩ kũu Makeda,
18 ó sì wí pé, “Ẹ yí òkúta ńlá dí ẹnu ihò àpáta náà, kí ẹ sì yan àwọn ọkùnrin sí ibẹ̀ láti ṣọ́ ọ.
akiuga atĩrĩ, “Garagariai mahiga manene mũhinge mũromo wa ngurunga ĩyo na mũige arangĩri ho.
19 Ṣùgbọ́n, ẹ má ṣe dúró! Ẹ lépa àwọn ọ̀tá yín, ẹ kọlù wọ́n láti ẹ̀yìn, kí ẹ má ṣe jẹ́ kí wọn kí ó dé ìlú wọn, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín tí fi wọ́n lé yín lọ́wọ́.”
No inyuĩ mũtigatithie. Tengʼeriai thũ cianyu, mũcitharĩkĩre mũcirutĩtie na thuutha, na mũtikareke itoonye matũũra macio manene, nĩgũkorwo Jehova Ngai wanyu nĩacineanĩte moko-inĩ manyu.”
20 Bẹ́ẹ̀ ní Joṣua àti àwọn ọmọ Israẹli pa wọ́n ní ìpakúpa wọ́n sì pa gbogbo ọmọ-ogun àwọn ọba márààrún run, àyàfi àwọn díẹ̀ tí wọ́n tiraka láti dé ìlú olódi wọn.
Nĩ ũndũ ũcio Joshua hamwe na andũ a Isiraeli makĩmaniina biũ, hakuhĩ kwage mũndũ o na ũmwe ũgũtigara, no anini arĩa maatigarire nĩmahotire kũũrĩra matũũra mao manene marĩa maarĩ mairigĩre.
21 Gbogbo àwọn ọmọ-ogun sì padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua ní ibùdó ogun ní Makkeda ní àlàáfíà, kò sí àwọn tí ó dábàá láti tún kọlu Israẹli.
Mbũtũ yothe ya ita ĩgĩgĩcooka kambĩ kũrĩ Joshua o kũu Makeda na thayũ, na gũtirĩ mũndũ o na ũmwe wacookire kwaria kiugo gĩa gũũkĩrĩra andũ a Isiraeli.
22 Joṣua sì wí pe, “Ẹ ṣí ẹnu ihò náà, kí ẹ sì mú àwọn ọba márààrún jáde wá fún mi.”
Joshua agĩcooka akiuga atĩrĩ, “Hingũrai mũromo wa ngurunga-inĩ na mũndehere athamaki acio atano.”
23 Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n sì mú àwọn ọba márààrún náà kúrò nínú ihò àpáta, àwọn ọba Jerusalẹmu, Hebroni, Jarmatu, Lakiṣi àti Egloni.
Nĩ ũndũ ũcio magĩĩka o ũguo, makĩruta athamaki acio atano kuuma ngurunga-inĩ, na nĩo athamaki a Jerusalemu, na Hebironi, na Jaramuthu, na Lakishi o na Egiloni.
24 Nígbà tí wọ́n mú àwọn ọba náà tọ Joṣua wá, ó pe gbogbo àwọn ọkùnrin Israẹli, ó sì sọ fún àwọn olórí ọmọ-ogun tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ pé, “Ẹ súnmọ́ bí, kí ẹ sì fi ẹsẹ̀ yín lé ọrùn àwọn ọba wọ̀nyí.” Bẹ́ẹ̀ ni wọ́n wá sí iwájú, wọ́n sì gbé ẹsẹ̀ lé ọrùn wọn.
Athamaki acio marĩkia kũrehwo harĩ Joshua, agĩĩta andũ othe a Isiraeli na akĩĩra anene a ita arĩa mathiĩte nake atĩrĩ, “Ũkai haha, mũkinye athamaki aya ngingo.” Nĩ ũndũ ũcio makiumĩra, magĩkinya athamaki acio ngingo.
25 Joṣua sì sọ fún wọn pé, “Ẹ má ṣe bẹ̀rù, ẹ má sì ṣe fòyà. Ẹ ṣe gírí, kí ẹ sì mú àyà le. Báyìí ni Olúwa yóò ṣe sí gbogbo àwọn ọ̀tá yín, tí ẹ̀yin yóò bá jà.”
Joshua akĩmeera atĩrĩ, “Mũtigetigĩre kana mũkue ngoro. Gĩai na hinya na mũũmĩrĩrie. Ũũ nĩguo Jehova arĩĩkaga thũ cianyu ciothe iria mũrĩrũaga nacio.”
26 Nígbà náà ni Joṣua kọlù wọ́n, ó sì pa àwọn ọba márààrún náà, ó sì so wọ́n rọ̀ ní orí igi ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ márùn-ún, wọ́n sì fi wọ́n sí orí igi títí di ìrọ̀lẹ́.
Nake Joshua akĩringa athamaki acio akĩmooraga, agĩcooka akĩmacuuria igũrũ rĩa mĩtĩ ĩtano, nao magĩtinda macunjurĩte mĩtĩ-inĩ ĩyo nginya hwaĩ-inĩ.
27 Nígbà tí oòrùn wọ̀, Joṣua pàṣẹ, wọ́n sì sọ̀ wọ́n kalẹ̀ kúrò ní orí igi, wọ́n sì gbé wọn jù sí inú ihò àpáta ní ibi tí wọ́n sá pamọ́ sí. Wọ́n sì fi òkúta ńlá dí ẹnu ihò náà, tí ó sì wà níbẹ̀ di òní yìí.
Riũa rĩgĩthũa-rĩ, Joshua agĩathana, nayo mĩĩrĩ ya andũ acio ĩgĩcuurũrio kuuma mĩtĩ-inĩ, ĩgĩikio ngurunga ĩrĩa meehithĩte; na hau mũromo-inĩ wa ngurunga ĩyo hakĩigwo mahiga manene mũno, namo matũire ho o na ũmũthĩ.
28 Ní ọjọ́ náà Joṣua gba Makkeda. Ó sì fi ojú idà kọlu ìlú náà àti ọba rẹ̀, ó sì run gbogbo wọn pátápátá, kò fi ẹnìkan sílẹ̀. Ó sì ṣe sí ọba Makkeda gẹ́gẹ́ bí o ti ṣe sí ọba Jeriko.
Mũthenya ũcio, Joshua agĩtunyana itũũra rĩa Makeda; akĩniina mũthamaki na itũũra rĩu na rũhiũ rwa njora, na akĩniina andũ othe arĩa maarĩ thĩinĩ warĩo biũ. Ndaatigirie mũndũ o na ũmwe arĩ muoyo; na agĩĩka mũthamaki wa Makeda o ta ũrĩa eekire mũthamaki wa Jeriko.
29 Nígbà náà ní Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Makkeda lọ sí Libina wọ́n sì kọlù ú.
Ningĩ Joshua na Isiraeli rĩothe arĩa maarĩ hamwe nake makiuma kũu Makeda magĩthiĩ nginya itũũra rĩa Libina na makĩrĩtharĩkĩra.
30 Olúwa sì fi ìlú náà àti ọba rẹ̀ lé Israẹli lọ́wọ́. Ìlú náà àti gbogbo àwọn ènìyàn ibẹ̀ ni Joṣua fi idà pa. Kò fi ẹnìkan sílẹ̀ ní ibẹ̀: Ó sì ṣe sí ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí ọba Jeriko.
Nake Jehova akĩneana itũũra rĩu o narĩo na mũthamaki warĩo moko-inĩ ma andũ a Isiraeli. Nake Joshua akĩniina itũũra rĩu na andũ arĩa maarĩ kuo na rũhiũ rwa njora. Ndaigana gũtigia mũndũ o na ũmwe thĩinĩ warĩo arĩ muoyo. Nake agĩĩka mũthamaki warĩo o ta ũrĩa eekire mũthamaki wa Jeriko.
31 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo ará Israẹli, tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Libina lọ sí Lakiṣi; ó sì dó tì í, ó sì kọlù ú.
Ningĩ Joshua na Isiraeli othe arĩa maarĩ hamwe nake makiuma kũu Libina magĩthiĩ nginya Lakishi; makĩrĩngʼethera, makĩrĩtharĩkĩra.
32 Olúwa sì fi Lakiṣi lé Israẹli lọ́wọ́, Joṣua sì gbà á ní ọjọ́ kejì. Ìlú náà àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀ ní ó fi idà pa gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe sí Libina.
Nake Jehova akĩneana Lakishi kũrĩ Isiraeli, nake Joshua akĩrĩtunyana mũthenya wa keerĩ. Itũũra rĩu akĩrĩniina na rũhiũ rwa njora o hamwe na andũ othe arĩa maarĩ thĩinĩ warĩo, o ta ũrĩa eekire Libina.
33 Ní àkókò yìí, Horamu ọba Geseri gòkè láti ran Lakiṣi lọ́wọ́, ṣùgbọ́n Joṣua ṣẹ́gun rẹ̀ àti àwọn ọmọ-ogun rẹ̀ títí ti kò fi ku ẹnìkan sílẹ̀.
O hĩndĩ ĩyo, nake Horamu mũthamaki wa Gezeri nĩokĩte gũteithia Lakishi, no Joshua akĩmũhoota hamwe na mbũtũ yake, o nginya gũkĩaga mũndũ watigarire muoyo.
34 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ kọjá láti Lakiṣi lọ sí Egloni; wọ́n sì dó tì í, wọ́n sì kọlù ú.
Ningĩ Joshua na Isiraeli othe arĩa maarĩ hamwe nake makiuma kũu Lakishi magĩthiĩ nginya Egiloni; makĩrĩngʼethera makĩrĩtharĩkĩra.
35 Wọ́n gbà á ní ọjọ́ náà, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì run gbogbo ènìyàn ibẹ̀ pátápátá, gẹ́gẹ́ bí wọ́n ti ṣe sí Lakiṣi.
Nao magĩtunyana itũũra rĩu mũthenya o ro ũcio, na makĩrĩniina biũ na rũhiũ rwa njora, na makĩniina andũ othe arĩa maarĩ thĩinĩ warĩo, o ta ũrĩa meekĩte Lakishi.
36 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli ṣí láti Egloni lọ sí Hebroni, wọ́n sì kọlù ú.
Ningĩ Joshua na Isiraeli othe arĩa maarĩ hamwe nake, makĩambata kuuma Egiloni magĩthiĩ nginya Hebironi, makĩrĩtharĩkĩra.
37 Wọ́n gba ìlú náà, wọ́n sì ti idà bọ̀ ọ́, pẹ̀lú ọba rẹ̀, gbogbo ìletò wọn àti gbogbo ènìyàn ibẹ̀. Wọn kò dá ẹnìkan sí. Gẹ́gẹ́ bí ti Egloni, wọ́n run un pátápátá àti gbogbo ènìyàn inú rẹ̀.
Magĩtunyana itũũra rĩu, na makĩrĩniina na rũhiũ rwa njora hamwe na mũthamaki warĩo, na tũtũũra twarĩo, na arĩa othe maarĩ thĩinĩ watuo. Matiatigirie mũndũ o na ũmwe arĩ muoyo. Nao makĩrĩananga biũ hamwe na arĩa othe maarĩ thĩinĩ warĩo, o ta ũrĩa meekĩte Egiloni.
38 Nígbà náà ni Joṣua àti gbogbo Israẹli tí ó wà pẹ̀lú rẹ̀ yí padà, wọ́n sì kọlu Debiri.
Ningĩ Joshua na Isiraeli othe arĩa maarĩ nake makĩhũndũka, magĩtharĩkĩra Debiri.
39 Wọ́n gba ìlú náà, ọba rẹ̀ àti gbogbo ìlú wọn, wọ́n sì fi idà pa wọ́n. Gbogbo ènìyàn inú rẹ̀ ni wọ́n parun pátápátá. Wọn kò sì dá ẹnìkankan sí. Wọ́n ṣe sí Debiri àti ọba rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí wọn ti ṣe sí Libina àti ọba rẹ̀ àti sí Hebroni.
Magĩtunyana itũũra rĩu, na mũthamaki warĩo, na tũtũũra twarĩo, makĩmaniina na rũhiũ rwa njora. Makĩananga arĩa maarĩ thĩinĩ warĩo biũ. Matiatigirie mũndũ o na ũmwe arĩ muoyo. Nao magĩĩka Debiri na mũthamaki warĩo o ta ũrĩa meekĩte Libina na mũthamaki warĩo, na noguo meekĩte Hebironi.
40 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ṣẹ́gun gbogbo agbègbè náà, ìlú òkè, gúúsù, ìlú ẹsẹ̀ òkè ti ìhà ìwọ̀-oòrùn àti gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè pẹ̀lú gbogbo ọba, wọn kò dá ẹnìkankan sí. Ó pa gbogbo ohun alààyè run pátápátá, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run Israẹli, ti pàṣẹ.
Nĩ ũndũ ũcio Joshua agĩtooria mwena ũcio wothe, naguo bũrũri ũrĩa ũrĩ irĩma, o na Negevu, na ituamba-inĩ cia irĩma cia mwena wa ithũĩro, o na kũu ciikũrũko-inĩ cia irĩma, hamwe na athamaki othe akuo. Ndaatigirie mũndũ o na ũmwe arĩ muoyo. Nĩanangire arĩa othe maarĩ na mĩhũmũ, o ta ũrĩa Jehova, Ngai wa Isiraeli aathanĩte.
41 Joṣua sì ṣẹ́gun wọn láti Kadeṣi-Barnea sí Gasa àti láti gbogbo agbègbè Goṣeni lọ sí Gibeoni.
Joshua akĩmatooria kuuma Kadeshi-Barinea nginya Gaza na kuuma mwena ũcio wothe wa Gosheni nginya Gibeoni.
42 Gbogbo àwọn ọba wọ̀nyí àti ilẹ̀ wọn ní Joṣua ṣẹ́gun ní ìwọ́de ogun ẹ̀ẹ̀kan, nítorí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, jà fún Israẹli.
Athamaki acio othe hamwe na mabũrũri mao-rĩ, Joshua aamahootire na itharĩkĩra rĩmwe, nĩ ũndũ Jehova, Ngai wa Isiraeli nĩwe warũagĩrĩra Isiraeli.
43 Nígbà náà ni Joṣua padà sí ibùdó ní Gilgali pẹ̀lú gbogbo Israẹli.
Nake Joshua agĩcooka hamwe na andũ othe a Isiraeli kambĩ-inĩ kũu Giligali.

< Joshua 10 >