< Joshua 7 >

1 Ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera, ẹ̀yà Juda, mú nínú wọn. Bẹ́ẹ̀ ni ìbínú Olúwa ru sí àwọn ará Israẹli.
Mais les enfants d'Israël commirent une infidélité à l'égard des choses consacrées, car Acan, fils de Carmi, fils de Zabdi, fils de Zérach, de la tribu de Juda, prit des choses consacrées. C'est pourquoi la colère de Yahvé s'enflamma contre les enfants d'Israël.
2 Joṣua rán àwọn ọkùnrin láti Jeriko lọ sí Ai, tí ó súnmọ́ Beti-Afeni ní ìlà-oòrùn Beteli, ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ gòkè lọ kí ẹ sì ṣe ayọ́lẹ̀wò.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn arákùnrin náà lọ, wọ́n sì yọ́ Ai wò.
Josué envoya des hommes de Jéricho à Aï, qui est à côté de Beth Aven, à l'est de Béthel, et leur parla ainsi: « Montez et explorez le pays. » Les hommes montèrent et découvrirent Aï.
3 Nígbà tí wọ́n padà sí ọ̀dọ̀ Joṣua, wọ́n wí pé, “Kì í ṣe gbogbo àwọn ènìyàn ni ó ni láti gòkè lọ bá Ai jà. Rán ẹgbẹ̀rún méjì tàbí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin láti gbà á, kí ó má ṣe dá gbogbo àwọn ènìyàn ní agara, nítorí ìba ọkùnrin díẹ̀ ní ó wà níbẹ̀.”
Ils revinrent vers Josué et lui dirent: « Que tout le peuple ne monte pas, mais que deux ou trois mille hommes environ montent et frappent Aï. Ne fais pas travailler tout le peuple, car il n'y en a qu'un petit nombre. »
4 Bẹ́ẹ̀ ní àwọn bí ẹgbẹ̀rún mẹ́ta ọkùnrin lọ; ṣùgbọ́n àwọn ọkùnrin Ai lé wọn sá.
Environ trois mille hommes du peuple montèrent et s'enfuirent devant les hommes d'Aï.
5 Àwọn ènìyàn Ai sì pa àwọn bí mẹ́rìndínlógójì nínú wọn. Wọ́n sì ń lépa àwọn ará Israẹli láti ibodè ìlú títí dé Ṣebarimu, wọ́n sì pa àwọn tí ń sọ̀kalẹ̀. Àyà àwọn ènìyàn náà sì já, ọkàn wọn sì pami.
Les gens d'Aï frappèrent environ trente-six hommes d'entre eux. Ils les poursuivirent depuis devant la porte jusqu'à Shebarim, et les frappèrent à la descente. Le cœur du peuple se fondit, et devint comme de l'eau.
6 Joṣua sì fa aṣọ rẹ̀ ya, ó sì dojúbolẹ̀ níwájú àpótí ẹ̀rí Olúwa títí di àṣálẹ́. Àwọn àgbà Israẹli sì ṣe bákan náà, wọ́n ku eruku sí orí wọn.
Josué déchira ses vêtements et tomba par terre, sur sa face, devant l'arche de Yahvé, jusqu'au soir, lui et les anciens d'Israël, et ils se mirent de la poussière sur la tête.
7 Joṣua sì wí pé, “Háà, Olúwa Olódùmarè, nítorí kín ni ìwọ ṣe mú àwọn ènìyàn yìí kọjá Jordani, láti fi wọ́n lé àwọn ará Amori lọ́wọ́, láti pa wọn run? Àwa ìbá mọ̀ kí a dúró ní òdìkejì Jordani?
Josué dit: « Hélas, Seigneur Yahvé, pourquoi as-tu fait passer le Jourdain à ce peuple, pour nous livrer entre les mains des Amoréens et nous faire périr? J'aurais voulu que nous soyons satisfaits et que nous vivions au-delà du Jourdain!
8 Olúwa, kín ni èmi yóò sọ nísinsin yìí tí Israẹli sì ti sá níwájú ọ̀tá a rẹ̀?
Oh, Seigneur, que dirai-je, après qu'Israël aura tourné le dos devant ses ennemis?
9 Àwọn Kenaani àti àwọn ènìyàn ìlú tí ó kù náà yóò gbọ́ èyí, wọn yóò sì yí wa ká, wọn yóò sì ké orúkọ wa kúrò ní ayé. Kí ni ìwọ ó ha ṣe fún orúkọ ńlá à rẹ?”
Car les Cananéens et tous les habitants du pays l'apprendront, ils nous entoureront et retrancheront notre nom de la terre. Que feras-tu pour ton grand nom? »
10 Olúwa sì sọ fún Joṣua pé, “Dìde! Kín ni ìwọ ń ṣe tí ó fi dojúbolẹ̀?
Yahvé dit à Josué: « Lève-toi! Pourquoi es-tu tombé sur ta face comme cela?
11 Israẹli ti ṣẹ̀, wọ́n sì ti ba májẹ̀mú mi jẹ́, èyí tí mo pàṣẹ fún wọn pé kí wọn pamọ́. Wọ́n ti mú nínú ohun ìyàsọ́tọ̀, wọ́n ti jí, wọ́n pa irọ́, wọ́n ti fi wọ́n sí ara ohun ìní wọn.
Israël a péché. Ils ont même transgressé l'alliance que je leur avais prescrite. Ils ont même pris des choses consacrées, ils ont volé, ils ont trompé. Ils ont même mis cela parmi leurs propres affaires.
12 Ìdí nì èyí tí àwọn ará Israẹli kò fi lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá wọn; wọ́n yí ẹ̀yìn wọn padà, wọ́n sì sálọ níwájú ọ̀tá a wọn nítorí pé àwọn gan an ti di ẹni ìparun. Èmi kì yóò wà pẹ̀lú u yín mọ́, bí kò ṣe pé ẹ̀yin pa ohun ìyàsọ́tọ̀ run kúrò ní àárín yín.
C'est pourquoi les enfants d'Israël ne peuvent pas se tenir debout devant leurs ennemis. Ils tournent le dos devant leurs ennemis, parce qu'ils se sont dévoués pour la destruction. Je ne serai plus avec vous, à moins que vous ne détruisiez les choses consacrées du milieu de vous.
13 “Lọ, ya àwọn ènìyàn náà sí mímọ́. Sọ fún wọn pé, ‘Ẹ ya ara yín sí mímọ́ fún ọ̀la, nítorí báyìí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, ohun ìyàsọ́tọ̀ kan ń bẹ ní àárín yín, Israẹli. Ẹ̀yin kì yóò lè dúró níwájú àwọn ọ̀tá a yín títí ẹ̀yin yóò fi mú kúrò.
Levez-vous! Sanctifiez le peuple, et dites: « Sanctifiez-vous pour demain, car Yahvé, le Dieu d'Israël, dit: « Il y a parmi toi, Israël, une chose dévouée. Tu ne pourras pas tenir devant tes ennemis tant que tu n'auras pas ôté du milieu de toi cette chose dévouée. »
14 “‘Ní òwúrọ̀, kí ẹ mú ará yín wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan. Ẹ̀yà tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní agbo ilé kọ̀ọ̀kan, agbo ilé tí Olúwa bá mú yóò wá sí iwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, ìdílé tí Olúwa bá sì mú yóò wá sí iwájú ní ẹni kọ̀ọ̀kan.
Dès le matin, on vous fera approcher par vos tribus. La tribu choisie par Yahvé s'approchera par familles. La famille choisie par l'Éternel s'approchera des ménages. Le foyer choisi par l'Éternel s'approchera de l'homme par l'homme.
15 Ẹnikẹ́ni tí a bá ká mọ́ pẹ̀lú ohun ìyàsọ́tọ̀ náà, a ó fi iná pa á run, pẹ̀lú gbogbo ohun tí ó ní. Ó ti ba májẹ̀mú Olúwa jẹ́, ó sì ti ṣe nǹkan ìtìjú ní Israẹli!’”
Celui qui aura pris la chose dévouée sera brûlé au feu, lui et tout ce qui lui appartient, parce qu'il a transgressé l'alliance de Yahvé et parce qu'il a commis une infamie en Israël.'"
16 Ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, Joṣua mú Israẹli wá síwájú ní ẹ̀yà kọ̀ọ̀kan, a sì mú ẹ̀yà Juda.
Josué se leva de bon matin et fit approcher Israël selon ses tribus. Il choisit la tribu de Juda.
17 Àwọn agbo ilé e Juda wá sí iwájú, ó sì mú agbo ilé Sera. Ó sì mú agbo ilé Sera wá síwájú ní ìdílé kọ̀ọ̀kan, a sì mú ìdílé Sabdi.
Il fit approcher la famille de Juda, et il choisit la famille des Zérachites. Il fit approcher la famille des Zérachites homme par homme, et Zabdi fut choisi.
18 Joṣua sì mú ìdílé Simri wá síwájú ní ọkùnrin kọ̀ọ̀kan, a sì mú Akani ọmọ Karmi, ọmọ Sabdi, ọmọ Sera ti ẹ̀yà Juda.
Il fit approcher sa famille homme par homme, et Akan, fils de Carmi, fils de Zabdi, fils de Zérah, de la tribu de Juda, fut choisi.
19 Nígbà náà ní Joṣua sọ fún Akani pé, “Ọmọ mi fi ògo fún Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, kí o sì fi ìyìn fún un. Sọ fún mi ohun tí ìwọ ti ṣe, má ṣe fi pamọ́ fún mi.”
Josué dit à Acan: « Mon fils, rends gloire à Yahvé, le Dieu d'Israël, et confesse-toi à lui. Dis-moi maintenant ce que tu as fait! Ne me le cache pas! »
20 Akani sì dáhùn pé, “Òtítọ́ ni! Mo ti ṣẹ̀ sí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli. Nǹkan tí mo ṣe nìyìí,
Acan prit la parole devant Josué et dit: « J'ai vraiment péché contre Yahvé, le Dieu d'Israël, et voici ce que j'ai fait.
21 nígbà tí mo rí ẹ̀wù Babeli kan tí ó dára nínú ìkógun, àti igba ṣékélì fàdákà àti odindi wúrà olóṣùnwọ́n àádọ́ta ṣékélì, mo ṣe ojúkòkòrò wọn mo sì mú wọn. Mo fi wọ́n pamọ́ ní abẹ́ àgọ́ mi àti fàdákà ní abẹ́ rẹ̀.”
Lorsque j'ai vu parmi le butin une belle robe babylonienne, deux cents sicles d'argent, et un coin d'or pesant cinquante sicles, je les ai convoités et je les ai pris. Voici qu'ils sont cachés dans le sol, au milieu de ma tente, avec l'argent en dessous. »
22 Bẹ́ẹ̀ ni Joṣua ran àwọn òjíṣẹ́, wọ́n sì sáré wọ inú àgọ́ náà, ó sì wà níbẹ̀, a sì fi pamọ́ nínú àgọ́ ọ rẹ̀, àti fàdákà ní abẹ́ ẹ rẹ̀.
Josué envoya des messagers, et ils coururent à la tente. Et voici, il était caché dans sa tente, avec l'argent en dessous.
23 Wọ́n sì mú àwọn nǹkan náà jáde láti inú àgọ́ rẹ̀, wọ́n mú wọn wá fún Joṣua àti gbogbo àwọn ọmọ Israẹli, wọ́n sì fi wọ́n lélẹ̀ níwájú Olúwa.
Ils les prirent au milieu de la tente et les apportèrent à Josué et à tous les enfants d'Israël. Ils les déposèrent devant Yahvé.
24 Nígbà náà ni Joṣua pẹ̀lú gbogbo Israẹli, mú Akani ọmọ Sera, fàdákà, ẹ̀wù àti wúrà tí a dà, àwọn ọmọ rẹ̀ ọkùnrin àti obìnrin, màlúù rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ àti àgùntàn àgọ́ rẹ̀ àti gbogbo ohun tí ó ni, wọ́n sì kó wọn lọ sí ibi àfonífojì Akori.
Josué, et tout Israël avec lui, prit Acan, fils de Zérach, l'argent, la robe, le coin d'or, ses fils, ses filles, son bétail, ses ânes, ses brebis, sa tente et tout ce qui lui appartenait, et ils les firent monter dans la vallée d'Acor.
25 Joṣua sì wí pé, “Èéṣe tí ìwọ mú wàhálà yìí wá sí orí wa? Olúwa yóò mú ìpọ́njú wá sí orí ìwọ náà lónìí.” Nígbà náà ni gbogbo Israẹli sọ ọ́ ní òkúta pa, lẹ́yìn ìgbà tí wọ́n sọ àwọn tókù ní òkúta pa tán, wọ́n sì jó wọn níná.
Josué dit: « Pourquoi nous avez-vous inquiétés? C'est Yahvé qui va te troubler aujourd'hui. » Tout Israël le lapida, et ils les brûlèrent au feu et les lapidèrent.
26 Wọ́n sì kó òkìtì òkúta ńlá lé Akani lórí títí di òní yìí. Nígbà náà ní Olúwa sì yí ìbínú gbígbóná rẹ̀ padà. Nítorí náà ni a ṣe ń pe orúkọ ibẹ̀ ní àfonífojì Akori láti ìgbà náà.
Ils élevèrent au-dessus de lui un grand monceau de pierres qui subsiste encore aujourd'hui. Yahvé se détourna de l'ardeur de sa colère. C'est pourquoi le nom de ce lieu a été appelé jusqu'à ce jour « vallée d'Acor ».

< Joshua 7 >