< Judges 1 >

1 Lẹ́yìn ikú Joṣua, ni orílẹ̀-èdè Israẹli béèrè lọ́wọ́ Olúwa pé, “Èwo nínú ẹ̀yà wa ni yóò kọ́kọ́ gòkè lọ bá àwọn ará Kenaani jagun fún wa?”
Après la mort de Josué, les enfants d'Israël demandèrent à Yahvé: « Qui montera pour nous le premier contre les Cananéens, pour les combattre? »
2 Olúwa sì dáhùn pé, “Juda ni yóò lọ; nítorí pé èmi ti fi ilẹ̀ náà lé e lọ́wọ́.”
Yahvé dit: « Juda montera. Voici, j'ai livré le pays entre ses mains. »
3 Nígbà náà ni àwọn olórí ẹ̀yà Juda béèrè ìrànlọ́wọ́ láti ọ̀dọ̀ àwọn ọmọ Simeoni arákùnrin wọn pé, “Ẹ wá bá wa gòkè lọ sí ilẹ̀ tí a ti fi fún wa, láti bá àwọn ará Kenaani jà kí a sì lé wọn kúrò, àwa pẹ̀lú yóò sì bá a yín lọ sí ilẹ̀ tiyín bákan náà láti ràn yín lọ́wọ́.” Àwọn ọmọ-ogun Simeoni sì bá àwọn ọmọ-ogun Juda lọ.
Juda dit à Siméon, son frère: « Monte avec moi dans mon lot, afin que nous combattions les Cananéens; et moi aussi, je monterai avec toi dans ton lot. » Siméon alla donc avec lui.
4 Nígbà tí àwọn ọmọ-ogun Juda sì kọlu wọ́n, Olúwa sì fi àwọn ará Kenaani àti àwọn ará Peresi lé wọn lọ́wọ́, wọ́n sì pa ẹgbẹ̀rún mẹ́wàá ọkùnrin ní Beseki.
Juda monta, et Yahvé livra entre leurs mains les Cananéens et les Phéréziens. Ils frappèrent dix mille hommes à Bézek.
5 Ní Beseki ni wọ́n ti rí Adoni-Beseki, wọ́n sì bá a jagun, wọ́n sì ṣẹ́gun àwọn ará Kenaani àti Peresi.
Ils trouvèrent Adoni-Bézek à Bézek, et ils lui livrèrent bataille. Ils battirent les Cananéens et les Phéréziens.
6 Ọba Adoni-Beseki sá àsálà, ṣùgbọ́n ogun Israẹli lépa rẹ̀ wọ́n sì bá a, wọ́n sì gé àwọn àtàǹpàkò ọwọ́ àti ẹsẹ̀ rẹ̀.
Mais Adoni-Bézek s'enfuit. Ils le poursuivirent, l'attrapèrent, et lui coupèrent les pouces et les gros orteils.
7 Nígbà náà ni Adoni-Beseki wí pé, “Àádọ́rin ọba ni èmi ti gé àtàǹpàkò wọn tí wọ́n sì ń ṣa èérún oúnjẹ jẹ lábẹ́ tábìlì mi. Báyìí Ọlọ́run ti san án fún mi gẹ́gẹ́ bí ohun tí mo ṣe sí wọn.” Wọ́n sì mú un wá sí Jerusalẹmu, ó sì kú síbẹ̀.
Adoni-Bézek dit: « Soixante-dix rois, qui ont eu les pouces et les gros orteils coupés, ont fait les poubelles sous ma table. Ce que j'ai fait, Dieu me l'a fait. » On le conduisit à Jérusalem, où il mourut.
8 Àwọn ológun Juda sì ṣẹ́gun Jerusalẹmu, wọ́n sì kó o, wọ́n sì fi ojú idà kọlù ú, wọ́n sì dáná sun ìlú náà.
Les fils de Juda combattirent contre Jérusalem, la prirent, la frappèrent du tranchant de l'épée et mirent le feu à la ville.
9 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni àwọn ogun Juda sọ̀kalẹ̀ lọ láti bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé ní àwọn ìlú orí òkè ní gúúsù àti ní pẹ̀tẹ́lẹ̀ òkè lápá ìwọ̀-oòrùn Juda jagun.
Après cela, les fils de Juda descendirent pour combattre les Cananéens qui habitaient dans la montagne, dans le midi et dans la plaine.
10 Ogun Juda sì tún ṣígun tọ ará Kenaani tí ń gbé Hebroni (tí orúkọ rẹ̀ ń jẹ́ Kiriati-Arba) ó sì ṣẹ́gun Ṣeṣai, Ahimani àti Talmai.
Juda marcha contre les Cananéens qui habitaient à Hébron. (Le nom d'Hébron était auparavant Kiriath Arba.) Ils frappèrent Sheshai, Ahiman et Talmai.
11 Láti ibẹ̀, wọ́n sì wọ́de ogun láti ibẹ̀ lọ bá àwọn ènìyàn tí ń gbé ní Debiri (tí à ń pè ní Kiriati-Seferi nígbà kan rí).
De là, il alla contre les habitants de Debir. (Le nom de Debir était auparavant Kiriath Sepher.)
12 Kalebu sì wí pé, “Èmi yóò fi ọmọbìnrin mi Aksa fún ọkùnrin tí ó bá kọlu Kiriati-Seferi, tí ó sì gbà á ní ìgbéyàwó.”
Caleb dit: « Je donnerai ma fille Acsa pour femme à l'homme qui frappera Kiriath Sepher et la prendra. »
13 Otnieli ọmọ Kenasi, àbúrò Kalebu sì gbà á, báyìí ni Kalebu sì fi ọmọbìnrin rẹ̀ Aksa fún un ní ìyàwó.
Othniel, fils de Kenaz, frère cadet de Caleb, la prit, et il lui donna pour femme sa fille Acsa.
14 Ní ọjọ́ kan, nígbà tí Aksa lọ sí ọ̀dọ̀ Otnieli, ó rọ̀ ọ́ kí ó béèrè ilẹ̀ oko lọ́wọ́ baba rẹ̀. Nígbà náà ni Aksa sọ̀kalẹ̀ ní orí kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀, Kalebu sì béèrè pé, “Kí ni kí èmi ṣe fún ọ?”
Quand elle arriva, elle lui demanda de demander un champ à son père. Elle descendit de son âne; et Caleb lui dit: « Que veux-tu? »
15 Aksa sì dáhùn pé, “Mo ń fẹ́ kí o ṣe ojúrere kan fún mi, nígbà ti o ti fún mi ní ilẹ̀ ní gúúsù, fún mi ní ìsun omi náà pẹ̀lú.” Kalebu sì fún un ní ìsun òkè àti ìsun ìsàlẹ̀.
Elle lui dit: « Donne-moi une bénédiction; puisque tu m'as établie dans le pays du Midi, donne-moi aussi des sources d'eau. » Et Caleb lui donna les sources supérieures et les sources inférieures.
16 Àwọn ìran Keni tí wọ́n jẹ́ àna Mose bá àwọn ọmọ Juda gòkè láti ìlú ọ̀pẹ lọ sí aginjù Juda ní gúúsù Aradi; wọ́n sì lọ, orílẹ̀-èdè méjèèjì sì jùmọ̀ ń gbé pọ̀ láti ìgbà náà.
Les fils du Kénite, beau-frère de Moïse, montèrent de la ville des palmiers avec les fils de Juda dans le désert de Juda, qui est au sud d'Arad, et ils allèrent habiter avec le peuple.
17 Ó sì ṣe, àwọn ológun Juda tẹ̀lé àwọn ológun Simeoni arákùnrin wọn, wọ́n sì lọ bá àwọn ará Kenaani tí ń gbé Sefati jagun, wọ́n sì run ìlú náà pátápátá, ní báyìí àwa yóò pe ìlú náà ní Horma (Horma èyí tí ń jẹ́ ìparun).
Juda partit avec Siméon, son frère, et ils frappèrent les Cananéens qui habitaient Zéphath, et la détruisirent par interdit. Le nom de la ville fut appelé Horma.
18 Àwọn ogun Juda sì ṣẹ́gun Gasa àti àwọn agbègbè rẹ̀, Aṣkeloni àti Ekroni pẹ̀lú àwọn ìlú tí ó yí ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ká.
Juda prit aussi Gaza et son territoire, Ashkelon et son territoire, et Ekron et son territoire.
19 Olúwa sì wà pẹ̀lú ẹ̀yà Juda, wọ́n gba ilẹ̀ òkè, ṣùgbọ́n wọn kò le lé àwọn ènìyàn tí ó wà ní pẹ̀tẹ́lẹ̀, nítorí wọ́n ní kẹ̀kẹ́ ogun onírin.
L'Éternel fut avec Juda, et il chassa les habitants de la montagne, car il ne put chasser les habitants de la vallée, parce qu'ils avaient des chars de fer.
20 Gẹ́gẹ́ bí Mose ti ṣèlérí, wọ́n fún Kalebu ní Hebroni, ó sì lé àwọn tí ń gbé ibẹ̀ kúrò; àwọn náà ni ìran àwọn ọmọ Anaki mẹ́ta.
On donna Hébron à Caleb, comme Moïse l'avait dit, et il en chassa les trois fils d'Anak.
21 Àwọn ẹ̀yà Benjamini ni wọn kò le lé àwọn Jebusi tí wọ́n ń gbé Jerusalẹmu, nítorí náà wọ́n ń gbé àárín àwọn Israẹli títí di òní.
Les fils de Benjamin ne chassèrent pas les Jébusiens qui habitaient Jérusalem, mais les Jébusiens habitent avec les fils de Benjamin à Jérusalem jusqu'à ce jour.
22 Àwọn ẹ̀yà Josẹfu sì bá Beteli jagun, Olúwa síwájú pẹ̀lú wọn.
La maison de Joseph monta aussi contre Béthel, et l'Éternel fut avec eux.
23 Nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu rán àwọn ènìyàn láti lọ yọ́ Beteli wò (orúkọ ìlú náà tẹ́lẹ̀ rí ni Lusi).
La maison de Joseph envoya espionner Béthel.
24 Àwọn ayọ́lẹ̀wò náà rí ọkùnrin kan tí ń jáde láti inú ìlú náà wá, wọ́n sì wí fún un pé, “Fi ọ̀nà àtiwọ ìlú yìí hàn wá, àwa ó sì dá ẹ̀mí rẹ sí, a ó sì ṣe àánú fún ọ.”
Les observateurs virent un homme sortir de la ville et ils lui dirent: « Montre-nous l'entrée de la ville, et nous te traiterons avec bienveillance. »
25 Ó sì fi ọ̀nà ìlú náà hàn wọ́n, wọ́n sì fi ojú idà kọlu ìlú náà, ṣùgbọ́n wọ́n dá ọkùnrin náà àti gbogbo ìdílé rẹ̀ si.
Il leur montra l'entrée de la ville, et ils frappèrent la ville du tranchant de l'épée; mais ils laissèrent partir l'homme et toute sa famille.
26 Ọkùnrin náà sí lọ sí ilẹ̀ àwọn ará Hiti, ó sì tẹ ìlú kan dó, ó sì pe orúkọ rẹ̀ ní Lusi, èyí sì ni orúkọ rẹ̀ títí di òní.
L'homme alla dans le pays des Hittites, bâtit une ville et l'appela Luz, nom qu'elle porte encore aujourd'hui.
27 Ṣùgbọ́n Manase kò lé àwọn ará Beti-Ṣeani àti ìlú rẹ̀ wọ̀n-ọn-nì jáde, tàbí àwọn ará Taanaki àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Dori àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Ibleamu àti àwọn ìgbèríko rẹ̀, tàbí àwọn ará Megido àti àwọn ìgbèríko tí ó yí i ká, torí pé àwọn ará Kenaani ti pinnu láti máa gbé ìlú náà.
Manassé ne chassa pas les habitants de Beth Shean et de ses villes, ni de Taanach et de ses villes, ni les habitants de Dor et de ses villes, ni les habitants d'Ibleam et de ses villes, ni les habitants de Megiddo et de ses villes; mais les Cananéens demeurèrent dans ce pays.
28 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli di alágbára, wọ́n mú àwọn ará Kenaani sìn bí i ẹrú, ṣùgbọ́n wọn kò fi agbára lé wọn jáde kúrò ní ilẹ̀ náà.
Lorsqu'Israël fut devenu fort, il mit les Cananéens au travail forcé et ne les chassa pas complètement.
29 Efraimu náà kò lé àwọn ará Kenaani tí ó ń gbé Geseri jáde, ṣùgbọ́n àwọn ará Kenaani sì ń gbé láàrín àwọn ẹ̀yà Efraimu.
Ephraïm ne chassa pas les Cananéens qui habitaient à Guézer, mais les Cananéens habitèrent à Guézer au milieu d'eux.
30 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn Sebuluni kò lé àwọn ará Kenaani tí ń gbé Kitironi jáde tàbí àwọn ará Nahalali, ṣùgbọ́n wọ́n sọ wọ́n di ẹrú. Wọ́n sì ń sin àwọn ará Sebuluni.
Zabulon ne chassa pas les habitants de Kitron ni ceux de Nahalol, mais les Cananéens habitèrent parmi eux et furent soumis au travail forcé.
31 Bẹ́ẹ̀ ni Aṣeri kò lé àwọn tí ń gbé ní Akko tàbí ní Sidoni tàbí ní Ahlabu tàbí ní Aksibu tàbí ní Helba tàbí ní Afiki tàbí ní Rehobu.
Asher ne chassa pas les habitants d'Acco, ni ceux de Sidon, ni ceux d'Ahlab, ni ceux d'Achzib, ni ceux d'Helba, ni ceux d'Aphik, ni ceux de Rehob;
32 Ṣùgbọ́n nítorí àwọn ará Aṣeri ń gbé láàrín àwọn ará Kenaani tí wọ́n ni ilẹ̀ náà.
mais les Asher habitèrent parmi les Cananéens, habitants du pays, car ils ne les chassèrent pas.
33 Àwọn ẹ̀yà Naftali pẹ̀lú kò lé àwọn ará Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati jáde; ṣùgbọ́n àwọn ẹ̀yà Naftali náà ń gbé àárín àwọn ará Kenaani tí ó ti ní ilẹ̀ náà rí, ṣùgbọ́n àwọn tí ń gbé Beti-Ṣemeṣi àti Beti-Anati ń sìn ìsìn tipátipá.
Nephtali ne chassa pas les habitants de Beth Shemesh ni ceux de Beth Anath, mais il habita au milieu des Cananéens, habitants du pays. Néanmoins, les habitants de Beth Shemesh et de Beth Anath furent soumis au travail forcé.
34 Àwọn ará Amori fi agbára dá àwọn ẹ̀yà Dani dúró sí àwọn ìlú orí òkè, wọn kò sì jẹ́ kí wọn sọ̀kalẹ̀ wá sí pẹ̀tẹ́lẹ̀.
Les Amorrhéens forcèrent les enfants de Dan à aller dans la montagne, car ils ne leur permirent pas de descendre dans la vallée;
35 Àwọn ará Amori ti pinnu láti dúró lórí òkè Heresi àti òkè Aijaloni àti ti Ṣaalbimu, ṣùgbọ́n nígbà tí ẹ̀yà Josẹfu di alágbára wọ́n borí Amori wọ́n sì mú wọn sìn.
mais les Amorrhéens habitèrent au mont Hérès, à Aijalon et à Shaalbim. Mais la main de la maison de Joseph l'emporta, de sorte qu'ils furent soumis au travail forcé.
36 Ààlà àwọn ará Amori sì bẹ̀rẹ̀ láti ìgòkè Akrabbimu kọjá lọ sí Sela àti síwájú sí i.
La frontière des Amoréens s'étendait depuis la montée d'Akrabbim, depuis le rocher et vers le haut.

< Judges 1 >