< Joshua 23 >

1 Lẹ́yìn ọjọ́ pípẹ́, nígbà tí Olúwa sì ti fún Israẹli ní ìsinmi kúrò ní ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn tí ó yí wọn ká, nígbà náà Joṣua sì ti di arúgbó.
I stalo se po mnohých dnech, když dal Hospodin odpočinutí Izraelovi ode všech nepřátel jejich vůkol, a Jozue se sstaral a sešel věkem,
2 Ó sì pe gbogbo Israẹli jọ: àgbàgbà wọn, olórí wọn, adájọ́ àti àwọn ìjòyè, ó sì sọ fún wọn pé, “Èmi ti pọ̀ ní ọdún èmi ti di arúgbó.
Že povolav Jozue všeho Izraele, starších jeho i předních jeho soudců i správců jeho, řekl jim: Já jsem se sstaral a sešel věkem.
3 Ẹ̀yin tìkára yín sì ti rí ohun gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín ti ṣe sí gbogbo orílẹ̀-èdè wọ̀nyí nítorí yín, Olúwa Ọlọ́run yín ni ó jà fún yín.
A vy jste viděli všecko to, co jest učinil Hospodin Bůh váš všechněm národům těm před oblíčejem vaším; nebo Hospodin Bůh váš onť bojoval za vás.
4 Ẹ rántí bí mo ṣe pín ogún ìní fún àwọn ẹ̀yà yín ní ilẹ̀ orílẹ̀-èdè gbogbo tí ó kù; àwọn orílẹ̀-èdè tí mo ti ṣẹ́gun ní àárín Jordani àti Òkun Ńlá ní ìwọ̀-oòrùn.
Pohleďte, losem rozdělil jsem vám ty národy pozůstalé v dědictví po pokoleních vašich od Jordánu, i všecky národy, kteréž jsem vyplénil až k moři velikému na západ slunce.
5 Olúwa Ọlọ́run yín fúnra rẹ̀ yóò lé wọn jáde kúrò ní ọ̀nà yín, yóò sì tì wọ́n jáde ní iwájú yín, ẹ̀yin yóò sì gba ilẹ̀ ìní wọn, gẹ́gẹ́ bí Olúwa Ọlọ́run ti ṣe ìlérí fún yín.
Hospodin pak Bůh váš onť je vyžene od tváři vaší, a vypudí je před oblíčejem vaším, a vy dědičně obdržíte zemi jejich, jakož mluvil vám Hospodin Bůh váš.
6 “Ẹ jẹ́ alágbára gidigidi, kí ẹ sì ṣọ́ra láti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun tí a kọ sí inú ìwé òfin Mose, láìyí padà sí ọ̀tún tàbí sí òsì.
Protož zmužile se mějte, abyste ostříhali a činili všecko, což psáno jest v knize zákona Mojžíšova, a neodstupovali od něho na pravo ani na levo.
7 Ẹ má ṣe ní àjọṣepọ̀ pẹ̀lú àwọn orílẹ̀-èdè tí ó ṣẹ́kù láàrín yín; ẹ má ṣe pe orúkọ òrìṣà wọn tàbí kí ẹ fi wọ́n búra. Ẹ kò gbọdọ̀ sìn wọ́n tàbí ki ẹ tẹríba fún wọn.
Nesměšujte se s těmi národy, kteříž pozůstávají s vámi, a jména bohů jejich nepřipomínejte, ani skrze ně přisahejte, aniž jim služte, ani se jim klanějte.
8 Ṣùgbọ́n ẹ di Olúwa Ọlọ́run yín mú ṣinṣin gẹ́gẹ́ bí ẹ ti ń ṣe tẹ́lẹ̀ títí di àkókò yìí.
Ale přídržte se Hospodina Boha svého, jakož jste činili až do tohoto dne.
9 “Olúwa ti lé àwọn orílẹ̀-èdè ńlá àti alágbára kúrò níwájú yín; títí di òní yìí kò sí ẹnìkan tí ó le dojúkọ yín.
I budeť, že jakož jest vyhnal Hospodin od tváři vaší národy veliké a silné, aniž ostál kdo před oblíčejem vaším až do tohoto dne:
10 Ọ̀kan nínú yín lé ẹgbẹ̀rún ọ̀tá, nítorí tí Olúwa Ọlọ́run yín jà fún yín gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣe ìlérí.
Tak jeden z vás honiti bude tisíc, nebo Hospodin Bůh váš onť bojuje za vás, jakož mluvil vám.
11 Bẹ́ẹ̀ ni kí ẹ ṣọ́ra gidigidi láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín.
Toho tedy nejpilnější buďte, abyste milovali Hospodina Boha svého.
12 “Ṣùgbọ́n bí ẹ bá yí padà, tí ẹ sì gba ìmọ̀ pọ̀ pẹ̀lú àwọn tó ṣẹ́kù lára àwọn orílẹ̀-èdè tí ó kù láàrín yín, tí ẹ sì ń fọmọ fún ara yín ní ìyàwó, tí ẹ sì bá wọn ní àjọṣepọ̀.
Nebo jestliže předce se odvrátíte, a připojíte se k těm pozůstalým národům, k těm, kteříž zůstávají mezi vámi, a vejdete s nimi v příbuzenství a smísíte se s nimi a oni s vámi:
13 Nígbà náà ni ẹ ó mọ̀ dájú pé Olúwa Ọlọ́run yín kì yóò lé àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jáde mọ́ kúrò níwájú yín. Dípò èyí, wọn yóò jẹ́ ìkẹ́kùn àti tàkúté fún un yín, pàṣán ní ẹ̀yin yín àti ẹ̀gún ní ojú yín, títí ẹ ó fi ṣègbé kúrò ní ilẹ̀ dáradára yí, èyí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fi fún yín.
Tedy jistotně vězte, že Hospodin Bůh váš nebude více vyháněti všech národů těch od tváři vaší, ale budou vám osídlem a úrazem i bičem na bocích vašich, a trním v očích vašich, dokudž nezahynete z země této výborné, kterouž vám dal Hospodin Bůh váš.
14 “Nísinsin yìí èmi ti fẹ́ máa lọ sí ibi tí àwọn àgbà ń rè. Ẹ mọ̀ pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti àyà yín pé, kò sí ohun kan tí ó kùnà nínú àwọn ìlérí rere gbogbo tí Olúwa Ọlọ́run yín fi fún un yín. Gbogbo ìlérí tó ti ṣe kò sí ọ̀kan tí ó kùnà.
A hle, já nyní odcházím podlé způsobu všech lidí, poznejtež tedy vším srdcem svým a celou duší svou, že nepochybilo ani jedno slovo ze všech slov nejlepších, kteráž mluvil Hospodin Bůh váš o vás; všecko se naplnilo vám, ani jediné slovo z nich nepominulo.
15 Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí ìlérí dáradára gbogbo ti Olúwa Ọlọ́run yín ti wá sí ìmúṣẹ, bẹ́ẹ̀ ni Olúwa yóò mú ibi gbogbo tí ó ti kìlọ̀ wá sí orí yín, títí yóò fi pa yín run kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.
Jakož tedy naplnilo se vám dnes každé slovo dobré, kteréž mluvil k vám Hospodin Bůh váš, takť uvede na vás každé slovo zlé, dokudž nevyhladí vás z země této výborné, kterouž dal vám Hospodin Bůh váš,
16 Bí ẹ bá sẹ̀ sí májẹ̀mú Olúwa Ọlọ́run yín, èyí tí ó pàṣẹ fún un yín, tí ẹ bá sì lọ tí ẹ sì sin àwọn òrìṣà tí ẹ sì tẹ orí ba fún wọn, ìbínú gbígbóná Olúwa yóò wá sórí i yín, ẹ̀yin yóò sì ṣègbé kíákíá kúrò ní ilẹ̀ dáradára tí ó ti fi fún un yín.”
Jestliže přestoupíte smlouvu Hospodina Boha svého, kterouž přikázal vám, a jdouce, sloužiti budete bohům cizím, a klaněti se jim. I rozhěvá se prchlivost Hospodinova na vás, a zahynete rychle z země této výborné, kterouž vám dal.

< Joshua 23 >