< Joshua 22 >

1 Joṣua sì pe àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase
Toho času povolav Jozue Rubenitských, Gáditských a polovice pokolení Manassesova,
2 ó sì sọ fún wọn pé, “Ẹ̀yin ti ṣe gbogbo èyí tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa pàṣẹ, ẹ sì ti ṣe ìgbọ́ràn sí ohun gbogbo tí mo pàṣẹ.
Řekl jim: Vy jste ostříhali všeho, což přikázal vám Mojžíš, služebník Hospodinův, a poslouchali jste hlasu mého ve všem, což jsem přikázal vám.
3 Ẹ kò fi àwọn arákùnrin yín sílẹ̀ láti ìgbà yí títí di òní, ṣùgbọ́n ẹ ti kíyèsára láti pa òfin Olúwa Ọlọ́run yín mọ́.
Neopustili jste bratří svých již za dlouhý čas až do dne tohoto, ale bedlivě jste ostříhali přikázaní Hospodina Boha vašeho.
4 Nísinsin yìí tí Olúwa Ọlọ́run yín ti fún àwọn arákùnrin yín ní ìsinmi gẹ́gẹ́ bí ó ti ṣèlérí, ẹ padà sí ilẹ̀ yín níbi tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin ní òdìkejì Jordani.
Nyní pak již odpočinutí dal Hospodin Bůh váš bratřím vašim, jakož mluvil jim; již tedy navraťte se a beřte se do stanů svých, do země vládařství svého, kteréž vám dal Mojžíš, služebník Hospodinův, před Jordánem.
5 Ṣùgbọ́n ẹ ṣọ́ra gidigidi láti pa àṣẹ àti òfin tí Mose ìránṣẹ́ Olúwa fi fún yin mọ́. Láti fẹ́ràn Olúwa Ọlọ́run yín, láti rìn nínú gbogbo ọ̀nà rẹ̀, láti gbọ́rọ̀ sí àṣẹ rẹ̀, láti dìímú ṣinṣin àti láti sìn ín pẹ̀lú gbogbo ọkàn yín àti gbogbo àyà yín.”
Toliko hleďte pilně zachovávati a plniti přikázaní a zákon, kterýž přikázal vám Mojžíš, služebník Hospodinův, a milovati Hospodina Boha svého a choditi po všech cestách jeho, a zachovávajíce přikázaní jeho, přídržeti se ho, a sloužiti jemu celým srdcem svým a celou duší svou.
6 Nígbà náà ni Joṣua súre fún wọn, ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn.
A požehnav jim Jozue, propustil je; i odešli do stanů svých.
7 (Mose ti fi ilẹ̀ fún ìdajì ẹ̀yà Manase ní Baṣani, Joṣua sì ti fún ìdajì ẹ̀yà yòókù ní ilẹ̀ ní ìwọ̀-oòrùn Jordani, pẹ̀lú àwọn arákùnrin wọn). Joṣua súre fún wọn ó sì jẹ́ kí wọn máa lọ sí ilẹ̀ wọn,
(Polovici pak pokolení Manassesova dal byl Mojžíš dědictví v Bázan, a druhé polovici jeho dal Jozue s bratřími jejich za Jordánem k západu.) A když je propouštěl Jozue do stanů jejich, požehnal jim,
8 Ó sì wí pé, “Ẹ padà sí ilẹ̀ ẹ yín pẹ̀lú ọrọ̀ púpọ̀ yín, pẹ̀lú agbo ẹran ọ̀sìn, pẹ̀lú fàdákà, wúrà, idẹ àti irin, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ aṣọ, kí ẹ sì pín ìkógun tí ẹ rí gbà láti ọ̀dọ̀ àwọn ọ̀tá yín pẹ̀lú àwọn arákùnrin yín.”
A mluvil k nim, řka: S bohatstvím velikým navracujete se do stanů svých a s dobytky velmi mnohými, s stříbrem a zlatem, s mědí a železem a rouchem velmi mnohým; rozděltež se loupeží nepřátel svých s bratřími svými.
9 Báyìí ni àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase fi àwọn ará Israẹli sílẹ̀ ní Ṣilo ní Kenaani láti padà sí Gileadi, ilẹ̀ wọn, èyí tí wọ́n ti gbà gẹ́gẹ́ bí àṣẹ Olúwa láti ẹnu Mose wá.
Tedy navracujíce se, odešli synové Rubenovi a synové Gádovi a polovice pokolení Manassesova od synů Izraelských z Sílo, jenž jest v zemi Kananejské, aby šli do země Galád, do země vládařství svého, v kteréž dědictví obdrželi, vedlé řeči Hospodinovy skrze Mojžíše.
10 Nígbà tí wọ́n wá dé Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ilẹ̀ Kenaani, àwọn ẹ̀yà Reubeni, ẹ̀yà Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ ńlá tí ó tóbi kan ní ẹ̀bá Jordani.
A přišedše ku pomezí při Jordánu, kteréž jest v zemi Kananejské, i vzdělali tu synové Rubenovi, a synové Gádovi, a polovice pokolení Manassesova oltář nad Jordánem, oltář veliký ku podivení.
11 Nígbà tí àwọn ọmọ Israẹli gbọ́ pé àwọn ọmọ Reubeni, àti àwọn ọmọ Gadi àti ìlàjì ẹ̀yà Manase mọ pẹpẹ kan dojúkọ ilẹ̀ Kenaani ní Geliloti ní ẹ̀bá Jordani ní ìhà kejì àwọn ọmọ Israẹli,
Uslyšeli pak synové Izraelští, že praveno bylo: Aj, vystavěli synové Rubenovi a synové Gádovi, a polovice pokolení Manassesova oltář naproti zemi Kananejské, při pomezi u Jordánu, kdež přešli synové Izraelští.
12 gbogbo àjọ Israẹli péjọ ní Ṣilo láti lọ bá wọn jagun.
Uslyševše, pravím, synové Izraelští, sešlo se všecko množství jejich do Sílo, aby táhli proti nim k boji.
13 Àwọn ọmọ Israẹli rán Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà, sí ilẹ̀ Gileadi, sí Reubeni, sí Gadi àti sí ìdajì ẹ̀yà Manase.
I poslali synové Izraelští k synům Rubenovým a k synům Gádovým a ku polovici pokolení Manassesova do země Galád Fínesa, syna Eleazara kněze,
14 Pẹ̀lú rẹ̀ wọ́n rán àwọn ọkùnrin olóyè mẹ́wàá, ẹnìkan fún ẹ̀yà Israẹli kọ̀ọ̀kan, olórí ọ̀kọ̀ọ̀kan tiwọn jẹ́ olórí ìdílé láàrín àwọn ọmọ Israẹli.
A deset knížat s ním, po jednom knížeti z každého domu otcovského, ze všech pokolení Izraelských. (Každý pak z nich byl přední v domě otců svých v tisících Izraele.)
15 Nígbà tí wọ́n lọ sí Gileadi—sí Reubeni, Gadi àti ìdajì ẹ̀yà Manase—wọ́n sì sọ fún wọn pé,
Ti přišli k synům Rubenovým a k synům Gádovým a ku polovici pokolení Manassesova do země Galád, a mluvili s nimi, řkouce:
16 “Gbogbo àjọ ènìyàn Olúwa wí pe, ‘A fẹ́ mọ ìdí tí ẹ fi sẹ̀ sí Ọlọ́run Israẹli nípa yíyí padà kúrò lọ́dọ̀ rẹ̀ tí ẹ sì kọ́ pẹpẹ ìṣọ̀tẹ̀ ní ìlòdì sí Olúwa?
Toto praví všecko shromáždění Hospodinovo: Jaké jest to přestoupení, jímž jste přestoupili proti Bohu Izraelskému, odvrátivše se dnes, abyste nešli za Hospodinem, vzdělavše sobě oltář, abyste se protivili dnes Hospodinu?
17 Ẹ̀ṣẹ̀ Peori kò ha tó fún wa bí? Títí di òní yìí àwa kò tí ì wẹ ara wa mọ́ kúrò nínú ẹ̀ṣẹ̀ náà, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé àjàkálẹ̀-ààrùn ti jà láàrín ènìyàn Olúwa!
Ještě-liž se nám malá zdá nepravost modly Fegor, od níž nejsme očištěni až do dnes, pročež byla rána v shromáždění Hospodinovu,
18 Ṣé ẹ tún wá ń padà kúrò lẹ́yìn Olúwa ni báyìí? “‘Tí ẹ̀yin bá ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa ní òní, ní ọ̀la ní òun o bínú sí gbogbo ìpéjọpọ̀ Israẹli.
Že vy přes to odvracujete se dnes, abyste nešli za Hospodinem? I stane se, poněvadž vy dnes odporujete Hospodinu, že on zítra na všecko shromáždění Izraelské rozhěvá se.
19 Bí ilẹ̀ ìní yín bá di àìmọ́, ẹ wá sí orí ilẹ̀ ìní Olúwa, ní ibi tí àgọ́ Olúwa dúró sí, kí ẹ sì pín ilẹ̀ náà pẹ̀lú wa. Ṣùgbọ́n kí ẹ má ṣe ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa tàbí sí wa nípa mímọ pẹpẹ fún ara yín, lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa.
Jestližeť jest nečistá země vládařství vašeho, přejděte do země vládařství Hospodinova, v níž přebývá stánek Hospodinův, a dědictví vezměte mezi námi; toliko proti Hospodinu se nepostavujte, a nebuďte odporní nám, stavějíce sobě oltář mimo oltář Hospodina Boha našeho.
20 Nígbà tí Akani ọmọ Sera ṣe àìṣòótọ́ nípa ohun ìyàsọ́tọ̀, ǹjẹ́ ìbínú kò wá sí orí gbogbo àjọ ènìyàn Israẹli nítorí rẹ̀ bí? Òun nìkan kọ́ ni ó kú fún ẹ̀ṣẹ̀ ẹ rẹ̀.’”
Zdali Achan syn Záre nedopustil se přestoupení při věci proklaté? A přišlo rozhněvání na všecko shromáždění Izraelské, a on sám jeden zhřešiv, nezahynul pro svou nepravost sám.
21 Nígbà náà ni Reubeni, Gadi àti ẹ̀yà Manase sọ nínú ìdáhùn wọn fún àwọn olórí Israẹli pé.
I odpověděli synové Rubenovi a synové Gádovi a polovice pokolení Manassesova, a mluvili s knížaty tisíců Izraelských:
22 Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run! Olúwa Ọlọ́run àwọn ọlọ́run, Òun mọ̀, jẹ́ kí Israẹli pẹ̀lú kí ó mọ̀! Bí èyí bá wà ní ìṣọ̀tẹ̀ tàbí àìgbọ́ràn sí Olúwa, ẹ má ṣe gbà wa ní òní yìí.
Silný Bůh Hospodin, silný Bůh Hospodin, onť ví, ano sám Izrael pozná, žeť jsme ne z zpoury a všetečnosti proti Hospodinu to učinili, jináč nezachovávejž nás ani dne tohoto.
23 Bí àwa bá ti mọ pẹpẹ wa láti yí padà kúrò ní ọ̀dọ̀ Olúwa àti láti rú ẹbọ sísun àti ẹbọ oúnjẹ jíjẹ, tàbí ẹbọ àlàáfíà ní orí rẹ, kí Olúwa fún ara rẹ̀ gba ẹ̀san.
Jistě žeť jsme nestavěli sobě oltáře k tomu, abychom se odvrátiti měli a nejíti za Hospodinem, ani k obětování na něm zápalů a obětí suchých, a k obětování na něm obětí pokojných, sic jináč Hospodin sám ať to vyhledává.
24 “Bẹ́ẹ̀ kọ́! Àwa ṣe èyí ní ìbẹ̀rù pé ní ọjọ́ tí àwọn ọmọ yín yóò wí fún wa pé, ‘Kí ni ẹ̀yin ní ṣe pẹ̀lú Olúwa, Ọlọ́run Israẹli?
Anobrž raději obávajíce se té věci, učinili jsme to, myslíce: Potom mluviti budou synové vaši synům našim, řkouce: Co vám do Hospodina Boha Izraelského?
25 Olúwa ti fi Jordani ṣe ààlà láàrín àwa àti ẹ̀yin—àwọn ọmọ Reubeni àti àwọn ọmọ Gadi! Ẹ kò ni ní ìpín nínú Olúwa.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ yín lè mú kí àwọn ọmọ wa dẹ́kun láti máa bẹ̀rù Olúwa.
Poněvadž meze položil Hospodin mezi námi a vámi, ó synové Rubenovi a synové Gádovi, Jordán tento, nemáte vy dílu v Hospodinu. I odvrátí synové vaši syny naše od bázně Hospodinovy.
26 “Nítorí èyí ni àwa ṣe wí pé, ‘Ẹ jẹ́ kí àwa múra láti mọ pẹpẹ kan, ṣùgbọ́n kì í ṣe fún ẹbọ sísun, tàbí fún àwọn ìrúbọ.’
Protož jsme řekli: Přičiňme se a vzdělejme oltář, ne pro zápaly a oběti,
27 Ní ọ̀nà mìíràn, yóò jẹ́ ẹ̀rí kan láàrín àwa àti ẹ̀yin àti àwọn ìran tí ń bọ̀, pé àwa yóò jọ́sìn fún Olúwa ní ibi mímọ́ rẹ̀ pẹ̀lú ẹbọ sísun wa, ẹbọ àti ọrẹ àlàáfíà. Nígbà náà ni ẹ̀yìn ọ̀la, àwọn ọmọ yín kò ní lè sọ fún tiwa pé, ‘Ẹ kò ní ìpín nínú ti Olúwa.’
Ale aby byl svědkem mezi námi a vámi, a mezi potomky našimi po nás, k vykonávání služby Hospodinu před ním zápaly našimi, a obětmi našimi a pokojnými obětmi našimi, a aby neřekli potom synové vaši synům našim: Nemáte dílu v Hospodinu.
28 “Àwa sì wí pé, ‘Tí wọ́n bá tilẹ̀ sọ èyí fún wa, tàbí sí àwọn ọmọ wa, a ó dáhùn pé, “Ẹ wo àpẹẹrẹ pẹpẹ Olúwa, èyí tí àwọn baba wa mọ, kì í ṣe fún ẹbọ sísun àti ẹbọ ṣùgbọ́n fún ẹ̀rí láàrín àwa àti ẹ̀yin.”’
Protož jsme řekli: Jestliže by potom mluvili nám neb potomkům našim, tedy odpovíme: Vizte podobenství oltáře Hospodinova, kterýž učinili otcové naši, ne pro zápaly ani oběti, ale aby byl na svědectví mezi námi a vámi.
29 “Kí Ọlọ́run má jẹ́ kí àwa kí ó ṣọ̀tẹ̀ sí Olúwa, kí àwa sì yípadà kúrò ní ọ̀dọ̀ rẹ ní òní nípa mímọ pẹpẹ ẹbọ sísun, ọrẹ oúnjẹ jíjẹ àti ẹbọ lẹ́yìn pẹpẹ Olúwa Ọlọ́run wa tí ó dúró níwájú àgọ́ rẹ̀.”
Odstup to od nás, abychom odporovati měli Hospodinu, a odvraceti se dnes a nejíti za Hospodinem, stavějíce oltář k zápalům, k obětem suchým a jiným obětem, mimo oltář Hospodina Boha našeho, kterýž jest před stánkem jeho.
30 Nígbà tí Finehasi àlùfáà àti àwọn olórí ìjọ ènìyàn, àwọn olórí ìdílé Israẹli gbọ́ ohun tí Reubeni, Gadi àti Manase ti sọ, ó dùn mọ́ wọn.
Uslyšev pak Fínes kněz a knížata shromáždění a přední z tisíců Izraelských, kteříž s ním byli, slova, kteráž mluvili synové Rubenovi a synové Gádovi a synové Manassesovi, líbilo se jim.
31 Finehasi ọmọ Eleasari, àlùfáà wí fún Reubeni, Gadi àti Manase pé, “Ní òní ni àwa mọ̀ pé Olúwa wà pẹ̀lú wa, nítorí tí ẹ̀yin kò hùwà àìṣòótọ́ sí Olúwa ní orí ọ̀rọ̀ yí nísinsin yìí, ẹ̀yin ti yọ àwọn ará Israẹli kúrò ní ọwọ́ Olúwa”.
I řekl Fínes, syn Eleazara kněze, synům Rubenovým a synům Gádovým, i synům Manassesovým: Nyní jsme poznali, že u prostřed nás jest Hospodin, a že jste se nedopustili proti Hospodinu přestoupení toho, a tak vysvobodili jste syny Izraelské z ruky Hospodinovy.
32 Nígbà náà ni Finehasi ọmọ Eleasari àlùfáà àti àwọn olórí padà sí Kenaani láti ibi ìpàdé wọn pẹ̀lú àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ní Gileadi, wọ́n sì mú ìròyìn tọ àwọn ọmọ Israẹli lọ.
Tedy navrátil se Fínes, syn Eleazara kněze, i ta knížata od synů Rubenových a od synů Gádových z země Galád do země Kananejské k synům Izraelským a oznámili jim tu věc.
33 Inú wọn sì dùn láti gbọ́ ìròyìn náà, wọ́n sì yin Ọlọ́run. Wọn kò sì sọ̀rọ̀ mọ́ nípa lílọ bá wọn jagun láti run ilẹ̀ tí àwọn ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi ń gbé.
I líbilo se to synům Izraelským, a dobrořečili Boha synové Izraelští, a již více nemluvili o to, aby táhli proti nim k boji a zkazili zemi, v kteréž synové Rubenovi a synové Gádovi bydlili.
34 Ẹ̀yà Reubeni àti ẹ̀yà Gadi sì fún pẹpẹ náà ní orúkọ yìí, “Ẹ̀rí láàrín wa pé Olúwa ni Ọlọ́run.”
Nazvali pak synové Rubenovi a synové Gádovi oltář ten Ed, řkouce: Nebo svědkem bude mezi námi, že Hospodin jest Bůh.

< Joshua 22 >