< Job 36 >

1 Elihu sì tún sọ̀rọ̀ wí pé,
Do tego przydał Elihu, i rzekł:
2 “Fún mi láyè díẹ̀ èmi ó sì fihàn ọ́, nítorí ọ̀rọ̀ sísọ ní ó kún fún Ọlọ́run.
Poczekaj mię maluczko, a ukażęć; bo jeszcze mam, cobym za Bogiem mówił.
3 Èmi ó mú ìmọ̀ mi ti ọ̀nà jíjìn wá, èmi ó sì fi òdodo fún Ẹlẹ́dàá mi.
Zacznę umiejętność moję z daleka, a Stworzycielowi memu przywłaszczę sprawiedliwość.
4 Rí i dájú pé ọ̀rọ̀ mi kì yóò ṣèké nítòótọ́; ẹni tí ó pé ní ìmọ̀ wà pẹ̀lú rẹ̀.
Boć zaprawdę bez kłamstwa będą mowy moje, a mąż doskonały w umiejętności jest przed tobą.
5 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni alágbára, òun kò i sì gàn ènìyàn; ó ní agbára ní ipá àti òye.
Oto Bóg mocny jest, a nie odrzuca nikogo; on jest mocny w sile serca.
6 Òun kì í dá ẹ̀mí ènìyàn búburú sí, ṣùgbọ́n ó fi òtítọ́ fún àwọn tálákà.
Nie żywi niepobożnego, a u sądu ubogim dopomaga.
7 Òun kì í mú ojú rẹ̀ kúrò lára olódodo, ṣùgbọ́n àwọn ọba ni wọ́n wà lórí ìtẹ́; àní ó fi ìdí wọn múlẹ̀ láéláé, a sì gbé wọn lékè.
Nie odwraca od sprawiedliwego oczów swoich; ale z królmi na stolicy sadza ich na wieki, i bywają wywyższeni.
8 Bí ó bá sì dè wọ́n nínú àbà, tí a sì fi okùn ìpọ́njú dè wọ́n,
A jeźliby byli okowani w pęta, albo uwikłani powrozami utrapienia:
9 nígbà náà ni ó ń sọ àwọn ohun tí wọn ti ṣe fún wọn, wí pé wọ́n ti ṣẹ̀ pẹ̀lú ìgbéraga wọn.
Tedy przez to im oznajmuje sprawy ich, i przestępstwa ich, że się zmocniły;
10 Ó sí wọn létí pẹ̀lú sí ọ̀nà ẹ̀kọ́, ó sì pàṣẹ kí wọn kí ó padà kúrò nínú àìṣedédé.
I otwiera im ucho, aby przyjęli karanie, a mówi, aby się nawrócili od nieprawości.
11 Bí wọ́n bá gbàgbọ́ tí wọ́n sì sìn ín, wọn ó lo ọjọ́ wọn ní ìrọ̀rùn, àti ọdún wọn nínú afẹ́.
Jeźli będą posłuszni, a będą mu służyć, dokończą dni swoich w dobrem, a lat swych w rozkoszach.
12 Ṣùgbọ́n, bí wọn kò bá gbàgbọ́, wọ́n ó ti ọwọ́ idà ṣègbé, wọ́n á sì kú láìní òye.
Ale jeźli nie usłuchają, od miecza zejdą, a pomrą bez umiejętności.
13 “Ṣùgbọ́n àwọn àgàbàgebè ní ayé kó ìbínú jọ; wọn kò kígbe fún ìrànlọ́wọ́ nígbà tí ó bá wọ́n wí.
Bo ludzie obłudnego serca obalają na się gniew, a nie wołają, kiedy ich wiąże.
14 Nígbà náà ni ọkàn wọn yóò kú ní èwe, ní àárín àwọn ọkùnrin alágbèrè ojúbọ òrìṣà.
Umrze w młodości dusza ich, a żywot ich między nierządnikami.
15 Òun gba òtòṣì nínú ìpọ́njú wọn, a sì sọ̀rọ̀ sí wọn ní etí nínú ìnira wọn.
Wyrwie utrapionego z utrapienia jego, a otworzy w uciśnieniu ucho jego.
16 “Bẹ́ẹ̀ ni pẹ̀lúpẹ̀lú ó fa wọn yọ láti inú ìhágágá sí ibi gbòòrò, sí ibi tí ó ní ààyè tí kò ní wàhálà nínú rẹ̀, ohun tí a sì gbé kalẹ̀ ní tábìlì rẹ̀ jẹ́ kìkì ọ̀rá oúnjẹ tí ó fẹ́.
Takby i ciebie wyrwał z miejsca ciasnego na przestronne, gdzie niemasz ucisku, a spokojny stół twój byłby pełen tłustości.
17 Ṣùgbọ́n ìwọ kún fún ìdájọ́ àwọn búburú; ìdájọ́ àti òtítọ́ dì ọ́ mú.
Aleś ty sąd niepobożnego zasłużył, przetoż prawo i sąd będą cię trzymać.
18 Nítorí ìbínú ń bẹ, ṣọ́ra kí òtítọ́ rẹ máa bá a tàn ọ; láti jẹ́ kí títóbi rẹ mú ọ ṣìnà.
Zaisteć gniew Boży jest nad tobą; patrzże, aby cię nie poraził plagą wielką, tak, żeby cię nie wybawił żaden okup.
19 Ọrọ̀ rẹ pọ̀ tó, tí wàhálà kì yóò fi dé bá ọ bí? Tàbí ipa agbára rẹ?
Izali sobie będzie ważył bogactwa twoje? Zaiste ani złota, ani jakiejkolwiek siły, albo potęgi twojej.
20 Má ṣe ìfẹ́ òru, nígbà tí a ń ké àwọn orílẹ̀-èdè kúrò ní ipò wọn.
Nie kwapże się tedy ku nocy, w którą zstępują narody na miejsca swoje.
21 Máa ṣọ́ra kí ìwọ ki ó má yí ara rẹ̀ padà sí búburú, nítorí èyí tí ìwọ rò pé ó dára jù ìpọ́njú lọ.
Strzeż, abyś się nie oglądał na nieprawość, obierając ją sobie nad utrapienia.
22 “Kíyèsi i, Ọlọ́run ni gbéga nípa agbára rẹ̀; ta ni jẹ́ olùkọ́ni bí rẹ̀?
Oto Bóg jest najwyższy w mocy swojej, któż tak nauczyć może jako on?
23 Ta ni ó là ọ̀nà iṣẹ́ rẹ̀ sílẹ̀ fún un, tàbí ta ni ó lè wí pé ìwọ ti ń ṣe àìṣedéédéé?
Któż mu wymierzył drogę jego? albo kto mu rzecze: Uczyniłeś nieprawość?
24 Rántí kí ìwọ kí ó gbé iṣẹ́ rẹ̀ ga, ti ènìyàn ni yín nínú orin.
Pamiętajże, abyś wysławiał sprawę jego, której się przypatrują ludzie.
25 Olúkúlùkù ènìyàn a máa rí i; ẹni ikú a máa wò ó ní òkèrè.
Wszyscy ludzie widzą ją, a człowiek przypatruje się jej z daleka.
26 Kíyèsi i, Ọlọ́run tóbi, àwa kò sì mọ̀ bí ó ti ní òye tó, bẹ́ẹ̀ ni a kò lè wádìí iye ọdún rẹ̀ rí.
Oto Bóg jest wielki, a poznać go nie możemy, ani liczba lat jego dościgniona być może.
27 “Nítorí pé òun ni ó fa ìkán omi òjò sílẹ̀, kí wọn kí ó kán bí òjò ní ìkùùkuu rẹ̀,
Bo on wyciąga krople wód, które wylewają z obłoków jego deszcz,
28 tí àwọsánmọ̀ ń rọ̀ ìrì rẹ̀ sílẹ̀, tí ó sì fi ń sẹ̀ lọ́pọ̀lọ́pọ̀ lórí ènìyàn.
Który spuszczają obłoki, a spuszczają na wiele ludzi.
29 Pẹ̀lúpẹ̀lú ǹjẹ́ ẹnikẹ́ni lè ní ìmọ̀ ìtànká àwọsánmọ̀, tàbí ariwo àrá láti àgọ́ rẹ̀?
(Nadto, któż zrozumie rozciągnienie obłoków, i grzmot namiotu jego.
30 Kíyèsi i, ó tan ìmọ́lẹ̀ yí ara rẹ̀ ká ó sì bo ìsàlẹ̀ òkun mọ́lẹ̀.
Jako rozciąga nad nim światłość swoję, a głębokości morskie okrywa?
31 Nítorí pé nípa wọn ní ń ṣe dájọ́ àwọn orílẹ̀-èdè ènìyàn; ó sí ń pèsè oúnjẹ ní ọ̀pọ̀lọpọ̀.
Bo przez te rzeczy sądzi narody, i daje pokarm w hojności.
32 Ó fi ìmọ́lẹ̀ bo ọwọ́ rẹ̀ méjèèjì ó sì rán an sí ẹni olódì.
Obłokami nakrywa światłość, i rozkazuje jej ukrywać się za obłok następujący.)
33 Ariwo àrá rẹ̀ fi ìjì hàn ní; ọ̀wọ́ ẹran pẹ̀lú wí pé, ó súnmọ́ etílé!
Daje o nim znać szum jego, także i bydło i para w górę wstępująca.

< Job 36 >