< Job 34 >

1 Nígbà náà ni Elihu dáhùn, ó sì wí pé,
Nadto mówił Elihu, i rzekł:
2 “Ẹ̀yin ọlọ́gbọ́n ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ mi, kí ẹ sì fi etí sílẹ̀ sí mi ẹ̀yin tí ẹ ní ìmòye.
Słuchajcież, mądrzy! mów moich, a nauczeni posłuchajcie mię.
3 Nítorí pé etí a máa dán ọ̀rọ̀ wò, bí adùn ẹnu ti ń tọ́ oúnjẹ wò.
Bo ucho słów doświadcza, jako podniebienie smakuje pokarmu.
4 Ẹ jẹ́ kí a mọ òye ohun tí o tọ́ fún ara wa; ẹ jẹ́ kí a mọ ohun tí ó dára láàrín wa.
Obierzmy sobie sąd, a rozeznajmy między sobą, co jest dobrego.
5 “Nítorí pé Jobu wí pé, ‘Aláìlẹ́ṣẹ̀ ni èmi; Ọlọ́run sì ti gba ìdájọ́ mi lọ.
Ponieważ Ijob rzekł: Jestem sprawiedliwym, a Bóg odrzucił sprawę moję:
6 Èmi ha purọ́ sí ẹ̀tọ́ mi bí, bí mo tilẹ̀ jẹ́ aláìjẹ̀bi, ọfà rẹ̀ kò ní àwòtán ọgbẹ́.’
I mamże kłamać, mając sprawiedliwą? Bolesny jest postrzał mój bez przewinienia.
7 Ọkùnrin wo ni ó dàbí Jobu, tí ń mu ẹ̀gàn bí ẹní mú omi?
Któryż jest mąż taki, jako Ijob, coby pił pośmiewisko jako wodę?
8 Tí ń bá àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ kẹ́gbẹ́ tí ó sì ń bá àwọn ènìyàn búburú rìn.
A coby chodził w towarzystwie czyniących nieprawość; i przestawałby z ludźmi niepobożnymi?
9 Nítorí ó sá ti wí pé, ‘Èrè kan kò sí fún ènìyàn, tí yóò fi máa ṣe inú dídùn sí Ọlọ́run.’
Bo powiedział: Nie pomoże człowiekowi, choćby się podobał Bogu.
10 “Ǹjẹ́ nítorí náà, ẹ fetísílẹ̀ sí mi, ẹ fi etí sí mi ẹ̀yin ènìyàn amòye: Ó di èèwọ̀ fún Ọlọ́run ti ìbá fi hùwà búburú, àti fún Olódùmarè, tí yóò fi ṣe àìṣedéédéé!
Przetoż mię słuchajcie, mężowie rozumni! Niech będzie daleka niepobożność od Boga, i nieprawość od Wszechmocnego.
11 Nítorí pé ó ń sán fún ènìyàn fún gẹ́gẹ́ bi ohun tí a bá ṣe, yóò sì mú olúkúlùkù kí ó rí gẹ́gẹ́ bí ipa ọ̀nà rẹ̀.
Bo on według uczynku płaci człowiekowi, a według drogi jego każdemu nagradza.
12 Nítòótọ́ Ọlọ́run kì yóò hùwàkiwà; bẹ́ẹ̀ ni Olódùmarè kì yóò yí ìdájọ́ po.
A zgoła Bóg przewrotnie nie czyni, a Wszechmocny nie podwraca sądu.
13 Ta ni ó fi ìtọ́jú ayé lé e lọ́wọ́, tàbí ta ni ó fi gbogbo ayé lé e lọ́wọ́?
Któż go przełożył nad ziemią? a kto wystawił cały okrąg świata?
14 Bí ó bá gbé ayé rẹ̀ lé kìkì ara rẹ̀ tí ó sì gba ọkàn rẹ̀ àti ẹ̀mí rẹ̀ sọ́dọ̀ ara rẹ̀,
Jeźliby obrócił przeciwko niemu serce swoje, a ducha jego, i dech jego do siebie wziął:
15 gbogbo ènìyàn ni yóò parun pọ̀, ènìyàn a sì tún padà di erùpẹ̀.
Zginęłoby wszelkie ciało społu, a człowiekby się do prochu nawrócił.
16 “Ǹjẹ́ nísinsin yìí, bí ìwọ bá ní òye, gbọ́ èyí; fetísí ohùn ẹnu mi.
Maszli tedy rozum, słuchaj tego, a przyjmuj w uszy swe głos mowy mojej.
17 Ẹni tí ó kórìíra òtítọ́ ha le ṣe olórí bí? Ìwọ ó ha sì dá olóòótọ́ àti ẹni ńlá lẹ́bi?
Azaż ten, który ma w nienawiści sąd, panować może? azaż tego, który jest wielce sprawiedliwy, niepobożnym uczynisz?
18 O ha tọ́ láti wí fún ọba pé, ‘Ènìyàn búburú ní ìwọ,’ tàbí fún àwọn ọmọ-aládé pé, ‘Ìkà ni ẹ̀yin,’
Zaż potępisz tego, który może rzec królowi: O bezecny! a książętom: O niepobożny!
19 mélòó mélòó fún ẹni tí kì í ṣe ojúsàájú àwọn ọmọ-aládé tàbí tí kò kà ọlọ́rọ̀ sí ju tálákà lọ, nítorí pé iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni gbogbo wọn í ṣe?
Który nie ma względu na osoby książąt, i nie waży sobie więcej bogacza nad ubogiego; bo oni wszyscy są czynem rąk jego.
20 Ní ìṣẹ́jú kan ni wọn ó kú, àwọn ènìyàn á sì di yíyọ́ lẹ́nu láàrín ọ̀gànjọ́, wọn a sì kọjá lọ; a sì mú àwọn alágbára kúrò láìsí ọwọ́ ènìyàn níbẹ̀.
Nagle umierają; a o północy wzruszony bywa naród, i przemija, a mocarz zniesiony bywa bez ręki ludzkiej.
21 “Nítorí pé ojú rẹ̀ ń bẹ ní ipa ọ̀nà ènìyàn, òun sì rí ìrìn rẹ̀ gbogbo.
Oczy bowiem jego nad drogami człowieczemi, a on widzi wszystkie kroki jego.
22 Kò sí ibi òkùnkùn, tàbí òjìji ikú, níbi tí àwọn oníṣẹ́ ẹ̀ṣẹ̀ yóò gbé sá pamọ́ sí.
Niemasz ciemności, ani cienia śmierci, kędyby się skryli ci, którzy czynią nieprawość.
23 Nítorí pé òun kò pẹ́ àti kíyèsi ẹnìkan, kí òun kí ó sì mú lọ sínú ìdájọ́ níwájú Ọlọ́run.
Bo na nikogo nie wkłada więcej, tak, żeby miał wchodzić w sąd z Bogiem.
24 Òun ó sì fọ́ àwọn alágbára túútúú láìní ìwádìí, a sì fi ẹlòmíràn dípò wọn,
Pociera bardzo wiele mocarzów, a inszych miasto nich wystawia.
25 nítorí pé ó mọ iṣẹ́ wọn, ó sì yí wọn po ní òru, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n di ìtẹ̀mọ́lẹ̀.
Przeto, iż zna sprawy ich, obraca im dzień w noc, aby byli potarci.
26 Ó kọlù wọ́n nítorí ìwà búburú wọn níbi tí àwọn ẹlòmíràn ti lè rí i,
Poraża ich jako niepobożnych na miejscu jawnem.
27 nítorí pé wọ́n padà pẹ̀yìndà sí i, wọn kò sì fiyèsí ipa ọ̀nà rẹ̀ gbogbo,
Przeto, iż odstąpili od niego, a żadnych dróg jego zrozumieć nie chcieli:
28 kí wọn kí ó sì mú igbe ẹkún àwọn tálákà lọ dé ọ̀dọ̀ rẹ̀, òun sì gbọ́ igbe ẹkún aláìní.
Aby przywiódł na nich wołanie znędzniałych, a pokazał, że wysłuchuje wołanie ubogich.
29 Ṣùgbọ́n nígbà tí ó bá dákẹ́ síbẹ̀, ta ni yóò dá lẹ́bi? Nígbà tí ó bá pa ojú rẹ̀ mọ́, ta ni yóò lè rí i? Bẹ́ẹ̀ ni ó ṣe si orílẹ̀-èdè tàbí sí ènìyàn kan ṣoṣo;
Gdy on sprawi pokój, któż go wzruszy? także, gdy skryje oblicze, któż go ujrzy? A to czyni tak całemu narodowi, jako każdemu człowiekowi,
30 kí aláìwà bi Ọlọ́run kí ó má bá à jẹ ọba kí wọn kí ó má di ìdẹwò fún ènìyàn.
Aby dalej nie panował człowiek obłudny na upadek ludzki.
31 “Nítorí pé ẹnìkan ha lè wí fún Ọlọ́run pé, èmi jẹ̀bi, èmi kò sì ní ṣẹ̀ mọ́?
Zaprawdę miałbyś mówić do Boga: Przepuść; poniosę, a nie będę się wzbraniał.
32 Èyí tí èmi kò rí ìwọ fi kọ́ mi bi mo bá sì dẹ́ṣẹ̀ èmi kì yóò ṣe bẹ́ẹ̀ mọ́.
Nadto jeźlibym czego nie baczył, ty mię naucz; jeźlim nieprawość popełnił, nie uczynię tego więcej.
33 Ǹjẹ́ bí ti inú rẹ̀ ni ki òun ó san ẹ̀ṣẹ̀ padà? Ǹjẹ́ òun yóò san án padà bí ìwọ bá kọ̀ ọ́ láti jẹ́wọ́, ìwọ gbọdọ̀ yan, kì í ṣe èmi. Nítorí náà sọ ohun tí o mọ̀, pẹ̀lúpẹ̀lú ohun tí ìwọ mọ̀, sọ ọ́!
Izali według zdania twego będziesz płacił, żeć się to nie podoba, a żeś ty owo obrał, a nie on? Ale wieszli co lepszego, powiedz.
34 “Àwọn ènìyàn amòye yóò wí fún mi, àti pẹ̀lúpẹ̀lú ẹnikẹ́ni tí í ṣe ọlọ́gbọ́n tí ó sì gbọ́ mi pé,
Mężowie rozumni toż rzeką ze mną, a człowiek mądry przypadnie na to,
35 ‘Jobu ti fi àìmọ̀ sọ̀rọ̀, ọ̀rọ̀ rẹ̀ sì ṣe aláìgbọ́n.’
Że Ijob nie mówi mądrze, a słowa jego nie są roztropne.
36 Ìfẹ́ mi ni kí a dán Jobu wò dé òpin, nítorí ìdáhùn rẹ̀ dàbí i ti ènìyàn búburú.
Boże, Ojcze mój! niech będzie Ijob doskonale doświadczony, przeto, iż nam odpowiada, jako ludziom złym.
37 Nítorí pe ó fi ìṣọ̀tẹ̀ kún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀; ó pàtẹ́wọ́ ní àárín wa, ó sì sọ ọ̀rọ̀ odi púpọ̀ sí Ọlọ́run.”
Bo przestępstwa przyczynia do grzechu swego; chlubi się między nami, i mówi bardzo wiele przeciwko Bogu.

< Job 34 >