< Job 29 >

1 Pẹ̀lúpẹ̀lú, Jobu sì tún tẹ̀síwájú nínú ọ̀rọ̀ rẹ̀, ó sì wí pé,
Mai mult, Iov și-a continuat parabola și a spus:
2 “Háà! ìbá ṣe pé èmi wà bí ìgbà oṣù tí ó kọjá, bí ọjọ́ tí Ọlọ́run pa mí mọ́,
O, de aș fi ca în lunile trecute, ca în zilele când Dumnezeu mă păstra;
3 nígbà tí fìtílà rẹ tàn sí mi ní orí, àti nípa ìmọ́lẹ̀ rẹ̀ èmi rìn nínú òkùnkùn já.
Când candela lui strălucea peste capul meu și când prin lumina lui umblam prin întuneric;
4 Bí mo ti rí nígbà ọ̀dọ́ mi, nígbà tí ọ̀rẹ́ Ọlọ́run tímọ́tímọ́ bùkún ilé mi,
Cum eram în zilele tinereții mele, când taina lui Dumnezeu era peste cortul meu;
5 nígbà tí Olódùmarè wà pẹ̀lú mi, nígbà tí àwọn ọmọ mi wà yí mi ká;
Când cel Atotputernic mai era cu mine, când copiii mei erau în jurul meu;
6 nígbà tí èmi fi òrí-àmọ́ n wẹ ìṣísẹ̀ mi, àti tí àpáta ń tú ìṣàn òróró jáde fún mi wá.
Când îmi spălam pașii cu unt și stânca îmi revărsa râuri de untdelemn;
7 “Nígbà tí mo jáde la àárín ìlú lọ sí ẹnu ibodè, nígbà tí mo tẹ́ ìtẹ́ mi ní ìgboro,
Când ieșeam la poartă, trecând prin cetate, când îmi pregăteam scaunul meu în stradă!
8 nígbà náà ni àwọn ọmọkùnrin rí mi, wọ́n sì sá pamọ́, àwọn àgbà dìde dúró ní ẹsẹ̀ wọn,
Tinerii mă vedeau și se ascundeau; și bătrânii se ridicau și stăteau în picioare.
9 àwọn ọmọ-aládé dákẹ́ ọ̀rọ̀ sísọ, wọn a sì fi ọwọ́ wọn lé ẹnu.
Prinții își opreau vorbirea și își puneau mâna la gura.
10 Àwọn ọlọ́lá dákẹ́, ahọ́n wọn sì lẹ̀ mọ́ èrìgì ẹnu wọn.
Nobilii își rețineau vocea și limba li se lipea de cerul gurii.
11 Nígbà tí etí gbọ́, ó sì súre fún mi, àti nígbà tí ojú sì rí mi, ó jẹ́rìí mi,
Când urechea mă auzea, mă binecuvânta; și când ochiul mă vedea, îmi aducea mărturie;
12 nítorí mo gbà tálákà tí n fẹ́ ìrànlọ́wọ́, àti aláìní baba tí kò sí olùrànlọ́wọ́ fún un.
Pentru că am eliberat pe cel sărac care striga și pe cel fără tată și pe cel ce nu avea pe nimeni să îl ajute.
13 Ẹni tí ó ń kìlọ̀ súre fún mi, èmi sì mú àyà opó kọrin fún ayọ̀.
Binecuvântarea celui ce era gata să piară venea peste mine și făceam inima văduvei să cânte de bucurie.
14 Èmi sì mú òdodo wọ̀ bí aṣọ, ẹ̀tọ́ mi dàbí aṣọ ìgúnwà àti adé ọba.
Mă îmbrăcam cu dreptate și ea mă înveșmânta; judecata mea era ca o robă și o diademă.
15 Mo ṣe ojú fún afọ́jú mo sì ṣe ẹsẹ̀ fún amúnkùn ún.
Eram ochi celui orb și picioare pentru șchiop.
16 Mo ṣe baba fún tálákà; mo ṣe ìwádìí ọ̀ràn àjèjì tí èmi kò mọ̀ rí.
[Eram] tată celor săraci; și cauza pe care nu o cunoșteam, am cercetat-o în amănunțime.
17 Mo sì ká eyín ẹ̀rẹ̀kẹ́ ènìyàn búburú, mo sì já ohun ọdẹ náà kúrò ní eyín rẹ̀.
Și am frânt fălcile celui stricat și am smuls prada din dinții lui.
18 “Nígbà náà ni mo rò pé, ‘Èmi yóò kú nínú ilé mi, èmi yóò sì mú ọjọ́ mi pọ̀ sí i bí iyanrìn.
Atunci am spus: Voi muri în cuibul meu și voi înmulți zilele mele precum nisipul.
19 Gbòǹgbò mi yóò ta kan omi, ìrì yóò sì sẹ̀ ní gbogbo òru sí ara ẹ̀ka mi.
Rădăcina mea era întinsă lângă ape și roua se așeza toată noaptea pe ramura mea.
20 Ògo mi yóò wà ní ọ̀tún ní ọ̀dọ̀ mi, ọrun mi sì padà di tuntun ní ọwọ́ mi.’
Gloria mea era proaspătă în mine și arcul meu era înnoit în mâna mea.
21 “Èmi ni ènìyàn ń dẹtí sílẹ̀ sí, wọn a sì dúró, wọn a sì dákẹ́ rọ́rọ́ ní ìmọ̀ràn mi.
Mă ascultau oamenii și așteptau și tăceau la sfatul meu.
22 Lẹ́yìn ọ̀rọ̀ mi, wọn kò tún sọ̀rọ̀ mọ́; ọ̀rọ̀ mi wọ̀ wọ́n ní etí ṣinṣin.
După cuvântarea mea nu mai vorbeau; și vorbirea mea picura peste ei.
23 Wọn a sì dúró dè mí bí ẹni wí pé wọ́n dúró fún ọ̀wọ́ òjò; wọn a sì mu nínú ọ̀rọ̀ mi bí ẹní mu nínú òjò àrọ̀kúrò.
Și mă așteptau ca pe ploaie; și își deschideau larg gura ca după ploaia târzie.
24 Èmi sì rẹ́rìn-ín sí wọn nígbà tí wọn kò bá gbà á gbọ́; ìmọ́lẹ̀ ojú mi jẹ́ iyebíye sí wọn.
[Dacă] râdeam de ei, nu credeau; și lumina înfățișării mele nu o doborau.
25 Mo la ọ̀nà sílẹ̀ fún wọn, mo sì jókòó bí olóyè wọn. Mo jókòó bí ọba ní àárín ológun rẹ, mo sì rí bí ẹni tí ń tu ẹni tí ń ṣọ̀fọ̀ nínú.
Le alegeam calea și ședeam drept mai mare conducător și locuiam ca un împărat în armată, ca unul care mângâie pe cei ce jelesc.

< Job 29 >