< Jeremiah 9 >

1 Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
Naarĩ korwo mũtwe wakwa nĩ itherũkĩro rĩa maaĩ, namo maitho makwa nĩ gĩthima kĩa maithori! Ingĩrĩraga mũthenya na ũtukũ, ngĩrĩrĩra andũ akwa arĩa moragĩtwo.
2 Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
Naarĩ korwo ndĩ na nyũmba ya kũrarĩrĩrwo nĩ agendi kũu werũ-inĩ, nĩgeetha ndige andũ akwa, thiĩ ndĩmeherere; nĩ ũndũ othe nĩ itharia, othe nĩ gĩkundi kĩa andũ matangĩĩhokeka.
3 Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
“Mahacaga nĩmĩ ciao magacitua ta ũta wa gũikia ndeto cia maheeni. Ũhootani ũrĩa marĩ naguo bũrũri-inĩ, nduumanĩte na ũhoro wa ma. Moimaga rĩĩhia-inĩ rĩmwe magatoonya rĩĩhia-inĩ rĩrĩa rĩngĩ; na matinjũũĩ,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
4 “Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
“Mwĩhũgei arata anyu; mũndũ ndakehoke mũrũ wa nyina. Nĩgũkorwo mũrũ wa nyina na mũndũ nĩ mũheenania, na mũrata wa mũndũ nĩ mũcambania.
5 Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
Mũrata aheenagia mũratawe, na gũtirĩ mũndũ o na ũmwe waragia ũhoro wa ma. Maarutĩte nĩmĩ ciao kwaria ndeto cia maheeni; menogagia na mĩhangʼo o ya kwĩhia.
6 Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
Wee ũtũũraga ũrigiicĩirio nĩ maheeni, nao aheenania acio nĩmaregete kũmenyana na niĩ,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
7 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
Tondũ ũcio Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga ũũ: “Atĩrĩrĩ, nĩngamageria, na ndĩmatherie na mwaki, nĩ ũndũ-rĩ, nĩatĩa ũngĩ ingĩĩka nĩ ũndũ wa mehia ma andũ akwa?
8 Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
Nĩmĩ ciao itariĩ ta mĩguĩ ya kũũragana; no ndeto cia maheeni ciaragia. O mũndũ aaragĩria ũrĩa ũngĩ ndeto cia thayũ na kanua gake, no ngoro-inĩ yake-rĩ, aikaraga amwambĩire mũtego.”
9 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
Jehova ekũũria atĩrĩ, “Anga ndakĩaga kũmaherithia nĩ ũndũ wa maũndũ macio? Anga ndakĩaga kwĩrĩhĩria harĩ rũrĩrĩ ta rũrũ?”
10 Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
Nĩngũrĩra na ngirĩke nĩ ũndũ wa irĩma, o na njakaye nĩ ũndũ wa ũrĩithio wa werũ. Nĩgũkirĩte ihooru na gũkaaga mũndũ ũngĩtuĩkanĩria kuo, na mwanio wa ngʼombe ndũraiguĩka kuo. Nyoni cia rĩera-inĩ na nyamũ cia gĩthaka nĩciũrĩte, igeethiĩra.
11 “Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
“Ngaatua itũũra rĩa Jerusalemu hĩba ya mahiga, gũtuĩke kũndũ gwa gũtũũrwo nĩ mbwe; namo matũũra ma Juda nĩngamaharagania, kwage mũndũ o na ũmwe ũngĩtũũra kuo.”
12 Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
Rĩu-rĩ, nĩ mũndũ ũrĩkũ mũũgĩ ũngĩtaũkĩrwo nĩ ũhoro ũyũ? Nũũ hihi ũtaarĩtwo nĩ Jehova nĩguo atũtaarĩrie? Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte bũrũri ũyũ wanangwo na ũgakira ihooru, ũgatuĩka ta werũ mũtheri nginya gũkaaga mũndũ ũngĩtuĩkania kuo?
13 Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
Jehova ekuuga atĩrĩ, “Gĩtũmi nĩ tondũ nĩmatirikire watho wakwa ũrĩa ndaamaheire; matinjathĩkĩire, o na kana makarũmĩrĩra watho wakwa.
14 Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
Handũ ha ũguo, o maarũmĩrĩire ũremi wa ngoro ciao, na makarũmĩrĩra Mabaali, o ta ũrĩa maithe mao maamonereirie.”
15 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, Jehova Mwene-Hinya-Wothe, o we Ngai wa Isiraeli ekuuga ũũ: “Atĩrĩrĩ, nĩngũtũma andũ aya marĩe irio ndũrũ, na manyue maaĩ marĩ na thumu.
16 Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
Nĩngũmahurunja ndũrĩrĩ-inĩ iria o ene matooĩ, o na kana maithe mao, njooke ndĩmaingatithie na rũhiũ rwa njora nginya ndĩmaniine biũ.”
17 Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
Jehova Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ: “Mwĩcũraniei rĩu! Ĩtai atumia arĩa marĩraga makĩgirĩkaga moke; tũmanĩrai atumia arĩa oogĩ mũno thĩinĩ wao moke.
18 Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
Nĩmeerwo moke narua, matũrĩrĩre nginya maitho maitũ maiyũre maithori, nacio imone cia maitho maitũ inyũrũrũkie maithori ta tũrũũĩ.
19 A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
Mũgambo wa andũ maragirĩka nĩũraiguuo kuuma Zayuni: ‘Hĩ, kaĩ rĩu tũrĩ aanange-ĩ! Kaĩ nĩtũconorithĩtio mũno-ĩ! No nginya tuume bũrũri witũ, tondũ nyũmba ciitũ nĩcimomoretwo.’”
20 Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
No rĩrĩ, inyuĩ atumia aya, ta thikĩrĩriai kiugo kĩa Jehova; hingũrai matũ manyu mũigue ciugo cia kanua gake. Oniai airĩtu anyu kũgirĩka; o mũndũ nĩarute ũrĩa ũngĩ gũcakaya.
21 Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
Gĩkuũ kĩambatĩte gĩgaatoonyera ndirica-inĩ ciitũ, na gĩgatoonya nyũmba ciitũ iria ciirigĩirwo na hinya, nĩkĩniinĩte ciana ciitũ kũu barabara-inĩ cia itũũra, o na aanake aitũ makaniinwo kuuma kũu ihaaro-inĩ.
22 Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
Meere ũũ, “Jehova ekuuga atĩrĩ: “‘Ciimba cia andũ nĩikaragana ta rũrua rũrĩ mũgũnda, na ta itira iria itinĩtio igatigwo na thuutha nĩ mũgethi, itarĩ na mũndũ wa gũcicookanĩrĩria.’”
23 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
Jehova ekuuga atĩrĩ: “Mũndũ ũrĩa mũũgĩ-rĩ, nĩatige kwĩgaatha nĩ ũndũ wa ũũgĩ wake, kana mũndũ ũrĩa ũrĩ na hinya egaathe nĩ ũndũ wa hinya ũrĩa arĩ naguo, o na kana gĩtonga kĩĩgathe nĩ ũndũ wa ũtonga wakĩo,
24 Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
no rĩrĩ, mũndũ ũrĩa ũkwĩgaatha, nĩegaathe nĩ ũndũ wa ũhoro ũyũ: atĩ we nĩataũkĩirwo na akamenya atĩ niĩ nĩ niĩ Jehova, ũrĩa wĩkaga maũndũ ma ũtugi, na ngatuanĩra ciira kĩhooto na ngarũmia ũthingu gũkũ thĩ, nĩ ũndũ maũndũ macio nĩmo ngenagio nĩmo,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
25 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
Jehova ekuuga atĩrĩ, “Matukũ nĩmagooka rĩrĩa ngaaherithia andũ othe arĩa maruĩte o mĩĩrĩ yao iiki,
26 Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”
nao nĩ andũ a bũrũri wa Misiri, na a Juda, na a Edomu, na a Amoni, na a Moabi, na arĩa othe matũũraga werũ-inĩ kũndũ kũraya. Nĩgũkorwo andũ a ndũrĩrĩ ici ciothe ti aruu kũna, o na andũ a nyũmba yothe ya Isiraeli matiruĩte ngoro.”

< Jeremiah 9 >