< Jeremiah 5 >

1 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
“Ta ambatai na mũikũrũke barabara-inĩ ciothe cia Jerusalemu, mũrore na mũcarie, na mũtuĩrie ihaaro-inĩ ciakuo. Hihi mwahota kuona mũndũ o na ũmwe wĩkaga maũndũ ma kĩhooto kana akarũmbũiya ũhoro wa ma; muona mũndũ ta ũcio, nĩngarekera itũũra rĩa Jerusalemu.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
O na gũtuĩka nĩmehĩtaga makoigaga atĩrĩ, ‘Ti-itherũ o ta ũrĩa Jehova atũũraga muoyo,’ kwĩhĩta kwao no kwa maheeni.”
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
Wee Jehova, githĩ maitho maku ti ũhoro ũrĩa wa ma macaragia? Wamaringire iringa, no matiigana kũigua ruo; wamahehenjire, no makĩrega ũtaarani ũcio. Momirie ithiithi ciao gũkĩra ihiga, makĩrega kwĩrira.
4 Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
Ngĩĩciiria atĩrĩ: “Aya nĩ andũ athĩĩni; nĩ andũ akĩĩgu, nĩgũkorwo matiũĩ njĩra ya Jehova, kana makamenya ũrĩa Ngai wao endaga.
5 Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
Nĩ ũndũ ũcio nĩngũthiĩ kũrĩ atongoria ngaaranĩrie nao; ti-itherũ acio nĩmoĩ njĩra ya Jehova, na makamenya ũrĩa Ngai wao endaga.” No rĩrĩ, othe marĩ hamwe, nĩmoinangĩte icooki rĩao rĩa ngingo, na magatua mĩkwa.
6 Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
Nĩ ũndũ wa ũguo-rĩ, mũrũũthi nĩũkoima mũtitũ-inĩ ũmatharĩkĩre, na njũũi yume werũ-inĩ ĩmatambuurange, nayo ngarĩ ĩmooherie njĩra-inĩ cia matũũra mao, nĩguo ĩtambuurange mũndũ wothe ũrĩa ũngĩgeria kuuma nja, nĩ ũndũ ũremi ũcio wao nĩũingĩhĩte mũno, na ũhoro wao wa gũcooka na thuutha nĩ mũingĩ.
7 “Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
“Ngũmũrekera nĩkĩ? Ciana cianyu nĩciindirikĩte, na ikeehĩta ikĩgwetaga marĩĩtwa ma ngai cia tũhũ. Niĩ ndaamaheaga o kĩrĩa gĩothe mabataragio nĩkĩo, no-o no gũtharia maatharagia, makahatĩkana nĩguo matoonye nyũmba cia maraya.
8 Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
Mahũũnĩte magatuĩka ta mbarathi cia njamba cikĩĩrirĩria cia mĩgoma, o ũmwe wao akeriragĩria mũtumia wa mũndũ ũrĩa ũngĩ.
9 Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Githĩ ndikĩagĩrĩirwo nĩkũmaherithia nĩ ũndũ wa maũndũ macio?” ũguo nĩguo Jehova ekuuga. “Githĩ ndikĩagĩrĩirwo nĩ kwĩrĩhĩria harĩ rũrĩrĩ ta rũu?
10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
“Tuĩkanĩriai mĩgũnda yao ya mĩthabibũ mũmĩharaganie, no mũtikamĩanange biũ. Hũrũrai honge ciayo, nĩgũkorwo andũ aya ti a Jehova.
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
Andũ a nyũmba ya Isiraeli na andũ a nyũmba ya Juda nĩmagĩte wĩhokeku harĩ niĩ biũ,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
Nĩmaheenanĩtie ũhoro wĩgiĩ Jehova; moigĩte atĩrĩ, “Ndarĩ ũndũ egwĩka! Gũtirĩ ũũru tũkuona; tũtikoona tũtharĩkĩirwo na rũhiũ rwa njora kana tuone ngʼaragu.
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
Anabii nĩ a tũhũ ta rũhuho, nakĩo kiugo kĩa Jehova gĩtirĩ thĩinĩ wao; nĩ ũndũ ũcio-rĩ, ũguo moigĩte nĩguo mageekwo.”
14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
Nĩ ũndũ ũcio, Jehova Ngai Mwene-Hinya-Wothe ekuuga atĩrĩ: “Tondũ wa andũ acio kwaria ndeto ta icio, ndũmĩrĩri yakwa ĩrĩa ngwĩkĩra kanua-inĩ gaku ngaamĩtua ta mwaki, nao andũ aya ndĩmatue ta ngũ, mwaki ũcio ũmacine ũmaniine.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
Atĩrĩrĩ, inyuĩ andũ a nyũmba ya Isiraeli,” ũũ nĩguo Jehova ekũmwĩra, “nĩngũtũma mũũkĩrĩrwo nĩ rũrĩrĩ ruumĩte kũndũ kũraya: naruo nĩ rũrĩrĩ rũtũũrĩte kuuma o tene, andũ mũtangĩmenya rũthiomi rwao, o na kana mũigue mwarĩrie wao.
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
Mathiaka ma mĩguĩ yao matariĩ ta mbĩrĩra iria ĩtathikĩtwo; othe nĩ njamba irĩ hinya.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
Nao nĩmakaarĩa na maniine magetha manyu o na irio cianyu, na marĩe na maniine aanake na airĩtu anyu; nĩmakaarĩa ndũũru cianyu cia mbũri na cia ngʼombe maciniine, ningĩ marĩe mĩthabibũ na mĩkũyũ yanyu. Nĩmakananga matũũra marĩa mairigĩre na rũhiũ rwa njora, o macio mwĩhokaga.
18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
“No rĩrĩ, o na matukũ-inĩ macio, ndigakwananga ngũniine biũ,” ũguo nĩguo Jehova ekuuga.
19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
“Na rĩrĩa andũ makooria atĩrĩ, ‘Nĩ kĩĩ gĩtũmĩte Jehova Ngai witũ atwĩke maũndũ maya mothe?’ Ũkamacookeria, ũmeere atĩrĩ: ‘O ta ũrĩa inyuĩ mwandirikire na mũgĩtungatĩra ngai cia kũngĩ mũrĩ bũrũri-inĩ wanyu-rĩ, ũguo noguo mũgaatungatagĩra andũ a kũngĩ mũrĩ bũrũri ũtarĩ wanyu.’
20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
“Anĩrĩra ũhoro ũyũ kũrĩ andũ a nyũmba ya Jakubu, na ũũhunjie kũu Juda, uuge atĩrĩ:
21 Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
Ta thikĩrĩriai inyuĩ andũ aya akĩĩgu na mũtarĩ mbuguĩro, o inyuĩ mũrĩ na maitho na mũtionaga, na mũrĩ na matũ na mũtiiguaga:
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
Githĩ inyuĩ mũtiagĩrĩirwo nĩkũnjĩtigĩra?” ũguo nĩguo Jehova ekuuga. “Githĩ inyuĩ mũtiagĩrĩirwo nĩkũinaina mũrĩ mbere yakwa? Ndaatũmire mũthanga ũtuĩke mũhaka wa iria rĩrĩa inene, ngĩũtua rũirigo rwa gũtũũra, rũtangĩagararwo nĩ iria rĩu. Makũmbĩ ma maaĩ no moyane, no matingĩrũtooria, no mahũyũke, no matingĩrwagarara.
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
No andũ aya-rĩ, marĩ ngoro cia rũngʼathio na nemi; nĩmahĩtĩtie njĩra na makoora.
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
Nao matingĩĩra atĩrĩ, ‘Nĩtwĩtigĩrei Jehova Ngai witũ, ũrĩa ũheanaga mbura ya kũmeria hĩĩra, na ya gũkũria irio o kĩmera gĩakinya, o we ũrĩa ũtũheaga mwĩhoko wa kũgetha mahinda maakinya.’
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
Mahĩtia manyu nĩmo matũmĩte mũraihĩrĩrio nĩ maũndũ macio; mehia manyu matũmĩte mwage maũndũ marĩa mega.
26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
“Thĩinĩ wa andũ akwa-rĩ, nĩ kũrĩ andũ aaganu arĩa maikaraga moheirie ta andũ arĩa mategaga nyoni, na ta andũ arĩa mambaga mĩtego ya kũgwatia andũ.
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
O ta ũrĩa gĩkerenge kĩiyũraga nyoni, ũguo nĩguo nyũmba ciao ciyũrĩte ũheenania; matongete na makagĩa na hinya,
28 wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
ningĩ manorete na makanyoroka mwĩrĩ. Waganu wao nĩũingĩhĩte mũno; maticiiragĩrĩra mwana wa ndigwa nĩguo ahootane ciira-inĩ, na matirũagĩrĩra kĩhooto kĩa mũndũ mũkĩa.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Githĩ ndikĩagĩrĩirwo nĩkũmaherithia nĩ ũndũ wa maũndũ macio?” ũguo nĩguo Jehova ekuuga. “Githĩ ndikĩagĩrĩirwo nĩ kwĩrĩhĩria harĩ rũrĩrĩ ta rũrũ?
30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
“Ũndũ mũũru mũno na wa kũmakania nĩwĩkĩkĩte bũrũri-inĩ ũyũ:
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?
Anabii marathaga mohoro ma maheeni, nao athĩnjĩri-Ngai magaathana ũrĩa mekwenda, nao andũ akwa ũguo nĩguo mendaga. No inyuĩ-rĩ, kĩrĩkĩrĩro-inĩ kĩa maũndũ macio mũgeeka atĩa?

< Jeremiah 5 >