< Jeremiah 5 >

1 “Lọ sókè àti sódò àwọn òpópó Jerusalẹmu, wò yíká, kí o sì mọ̀, kí o sì wá kiri. Bí o bá le è rí ẹnìkan, tí ó jẹ́ olóòtítọ́ àti olódodo, n ó dáríjì ìlú yìí.
Alergați încoace și încolo pe străzile Ierusalimului și vedeți acum și aflați și căutați în piețele lui, dacă puteți găsi un om, dacă este vreunul care face judecată, care caută adevărul; și îl voi ierta.
2 Bí wọ́n tilẹ̀ wí pé, ‘Bí Olúwa ti ń bẹ,’ síbẹ̀ wọ́n búra èké.”
Și deși ei spun: DOMNUL trăiește; cu siguranță ei jură fals.
3 Olúwa, ojú rẹ kò ha wà lára òtítọ́? Ìwọ lù wọ́n, kò dùn wọ́n; ìwọ bá wọn wí, wọ́n kọ̀ láti yípadà. Wọ́n mú ojú wọn le ju òkúta lọ, wọ́n sì kọ̀ láti yípadà.
DOAMNE, nu sunt ochii tăi asupra adevărului? tu i-ai lovit, dar ei nu sunt mâhniți; i-ai mistuit, dar ei au refuzat să primească disciplinarea; și-au făcut fețele mai tari decât o stâncă, au refuzat să se întoarcă.
4 Èmi sì rò pé, “Tálákà ni àwọn yìí; wọn jẹ́ aṣiwèrè, nítorí pé wọn kò mọ ọ̀nà Olúwa, àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.
De aceea eu am spus: Într-adevăr, aceștia sunt săraci și sunt nebuni, pentru că nu cunosc calea DOMNULUI, nici judecata Dumnezeului lor.
5 Nítorí náà, èmi yóò tọ àwọn adarí lọ, n ó sì bá wọn sọ̀rọ̀; ó dájú wí pé wọ́n mọ ọ̀nà Olúwa àti ohun tí Ọlọ́run wọn ń fẹ́.” Ṣùgbọ́n pẹ̀lú ìfìmọ̀ṣọ̀kan, wọ́n ti ba àjàgà jẹ́, wọ́n sì ti já ìdè.
Mă voi duce la oamenii însemnați și le voi vorbi, pentru că ei au cunoscut calea DOMNULUI și judecata Dumnezeului lor; dar aceștia au rupt cu totul jugul și au rupt legăturile.
6 Nítorí náà, kìnnìún láti inú igbó yóò kọlù wọ́n, ìkookò aginjù yóò sì pa wọ́n run, ẹkùn yóò máa ṣe ibùba sí ẹ̀bá ìlú yín ẹnikẹ́ni tí ó bá jáde ni yóò fàya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, nítorí àìgbọ́ràn yín pọ, ìpadàsẹ́yìn wọn sì pọ̀.
Pentru aceea, un leu din pădure îi va ucide și un lup al înserărilor îi va prăda, un leopard va pândi cetățile lor; oricine iese de acolo va fi sfâșiat în bucăți; deoarece fărădelegile lor sunt multe și decăderile lor sunt înmulțite.
7 “Kí ni ṣe tí èmi ó ṣe dáríjì ọ́? Àwọn ọmọ rẹ ti kọ̀ mí sílẹ̀ àti pé wọ́n ti fi ọlọ́run tí kì í ṣe Ọlọ́run búra. Mo pèsè fún gbogbo àìní wọn, síbẹ̀ wọ́n tún ń ṣe panṣágà wọ́n sì kórajọ sí ilé àwọn alágbèrè.
Cum să te iert pentru aceasta? Copiii tăi m-au părăsit și au jurat pe cei care nu sunt dumnezei; când eu i-am hrănit pe deplin, atunci au comis adulter și s-au adunat în cete la casele curvelor.
8 Wọ́n jẹ́ akọ ẹṣin tí a bọ́ yó, tí ó lágbára, wọ́n sì ń sọkún sí aya arákùnrin wọn.
Ei au fost precum cai hrăniți dimineața; fiecare a nechezat după soția aproapelui său.
9 Èmi kì yóò ha ṣe ìbẹ̀wò nítorí nǹkan wọ̀nyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gba ẹ̀san fúnra mi lára irú orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Să nu cercetez eu pentru aceste lucruri? spune DOMNUL; și să nu fie sufletul meu răzbunat pe o națiune ca aceasta?
10 “Lọ sí ọgbà àjàrà rẹ̀, kí ẹ sì pa wọ́n run, ẹ má ṣe pa wọ́n run pátápátá. Ya ẹ̀ka rẹ̀ kúrò, nítorí àwọn ènìyàn wọ̀nyí kì í ṣe ti Olúwa.
Urcați-vă pe zidurile lui și distrugeți; dar să nu mistuiți deplin; luați-i crenelurile, pentru că ele nu sunt ale DOMNULUI.
11 Ilé Israẹli àti ilé Juda ti jẹ́ aláìṣòdodo sí mi,” ni Olúwa wí.
Căci casa lui Israel și casa lui Iuda s-au purtat foarte perfid împotriva mea, spune DOMNUL.
12 Wọ́n ti pa irọ́ mọ́ Olúwa; wọ́n wí pé, “Òun kì yóò ṣe ohun kan! Ibi kan kì yóò sì tọ̀ wá wá; àwa kì yóò sì rí idà tàbí ìyàn.
Ei au negat pe DOMNUL și au spus: Nu este el; nici nu va veni răul asupra noastră; nici nu vom vedea sabie sau foamete;
13 Àwọn wòlíì wá dàbí afẹ́fẹ́, ọ̀rọ̀ kò sí nínú wọn. Nítorí náà, jẹ́ kí ohun tí wọ́n bá sọ ṣẹlẹ̀ sí wọn.”
Iar profeții vor deveni vânt și cuvântul nu este în ei; astfel li se va face.
14 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa Ọlọ́run Alágbára wí: “Nítorí tí àwọn ènìyàn ti sọ àwọn ọ̀rọ̀ wọ̀nyí; Èmi yóò sọ ọ̀rọ̀ mi lẹ́nu wọn di iná, àti àwọn ènìyàn wọ̀nyí di igi tí yóò jórun.
Pentru aceea astfel spune DOMNUL Dumnezeul oștirilor: Deoarece voi vorbiți acest cuvânt, iată, voi face cuvintele mele în gura ta să fie foc și pe acest popor să fie lemne, și îi va mistui.
15 Háà, ẹ̀yin ilé Israẹli,” ni Olúwa wí, “Èmi yóò mú kí orílẹ̀-èdè láti ọ̀nà jíjìn dìde sí i yín Orílẹ̀-èdè àtijọ́ àti alágbára nì àwọn ènìyàn tí ìwọ kò mọ èdè rẹ̀, tí ọ̀rọ̀ rẹ̀ kò sì yé ọ.
Iată, casă a lui Israel, de departe voi aduce o națiune asupra voastră, spune DOMNUL; aceasta este o națiune puternică, este o națiune străveche, o națiune a cărei limbă nu o cunoști, nici nu înțelegi ce spun ei.
16 Apó-ọfà rẹ sì dàbí isà òkú tí a ṣí gbogbo wọn sì jẹ́ akọni ènìyàn.
Tolba lor este un mormânt deschis, ei sunt toți războinici.
17 Wọn yóò jẹ ìkórè rẹ àti oúnjẹ rẹ, àwọn ọmọ rẹ ọkùnrin àti obìnrin, wọn yóò sì jẹ agbo àti ẹran rẹ, wọn yóò jẹ àjàrà àti igi ọ̀pọ̀tọ́ rẹ. Pẹ̀lú idà ni wọn ó run ìlú tí ìwọ gbẹ́kẹ̀lé.
Și ei îți vor mânca secerișul și pâinea, pe care fiii tăi și fiicele tale ar trebui să le mănânce; îți vor mânca turmele și cirezile; îți vor mânca viile și smochinii; ei îți vor sărăci cu sabia cetățile tale întărite, în care te încrezi.
18 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì,” ni Olúwa wí, “Èmi kì yóò pa yín run pátápátá.
Totuși în acele zile, spune DOMNUL, nu vă voi mistui deplin.
19 Àti pé, nígbà tí àwọn ènìyàn bá sì béèrè wí pé, ‘Kí ni ìdí rẹ̀ tí Olúwa Ọlọ́run wa fi ṣe gbogbo èyí sí wa?’ Ìwọ yóò sì sọ fún wọn wí pé, ‘Ẹ̀yin ti kọ̀ mí sílẹ̀, ẹ sì ń sin ọlọ́run àjèjì ní ilẹ̀ yín. Nísinsin yìí, ẹ̀yin yóò máa sin àjèjì ní ilẹ̀ tí kì í ṣe tiyín.’
Și se va întâmpla, când veți spune: Pentru ce ne face DOMNUL Dumnezeul nostru toate acestea? atunci să le răspundeți: La fel cum voi m-ați părăsit și ați servit unor dumnezei străini în țara voastră, tot astfel veți servi unor străini într-o țară care nu este a voastră.
20 “Kéde èyí fún ilé Jakọbu, kí ẹ sì polongo rẹ̀ ní Juda.
Vestiți aceasta casei lui Iacob și faceți să se audă aceasta în Iuda, spunând:
21 Gbọ́ èyí, ẹ̀yin aṣiwèrè àti aláìlọ́gbọ́n ènìyàn, tí ó lójú ti kò fi ríran tí ó létí ti kò fi gbọ́rọ̀.
Ascultați acum aceasta, voi popor nebun și fără înțelegere; care aveți ochi și nu vedeți, care aveți urechi și nu auziți;
22 Kò ha yẹ kí ẹ bẹ̀rù mi?” ni Olúwa wí. “Kò ha yẹ kí ẹ̀yin ó wárìrì níwájú mi bí? Mo fi yanrìn pààlà òkun, èyí tí kò le è rékọjá rẹ̀ láéláé. Ìjì lè jà, kò le è borí rẹ̀; wọ́n le è bú, wọn kò le è rékọjá rẹ̀.
Nu vă temeți de mine? Spune DOMNUL; nu tremurați în prezența mea, cel care am pus nisipul drept graniță mării printr-o hotărâre veșnică, încât aceasta nu poate trece peste ea; și deși valurile ei se aruncă, totuși nu o pot învinge; deși răcnesc, totuși nu pot trece peste ea?
23 Ṣùgbọ́n, àwọn ènìyàn wọ̀nyí ní ọkàn líle àti ọkàn ọ̀tẹ̀, wọ́n ti yípadà, wọ́n sì ti lọ.
Dar acest popor are o inimă îndărătnică și răzvrătită; ei s-au abătut și au plecat.
24 Wọn kò sọ fún ara wọn pé, ‘Ẹ jẹ́ ká a bẹ̀rù Olúwa Ọlọ́run wa, ẹni tí ó fún wa ní òjò àkọ́rọ̀ àti àrọ̀kúrò òjò ní ìgbà rẹ̀, tí ó fi wá lọ́kàn balẹ̀ nípa ìkórè ọ̀sẹ̀ déédé.’
Nici nu spun ei în inima lor: Să ne temem acum de DOMNUL Dumnezeul nostru, care dă ploaie deopotrivă timpurie și târzie, la timpul său; el ne păstrează săptămânile rânduite ale secerișului.
25 Àìṣedéédéé yín mú gbogbo nǹkan wọ̀nyí kúrò, ẹ̀ṣẹ̀ yín sì mú kí a fi nǹkan rere dù yín.
Nelegiuirile voastre au îndepărtat aceste lucruri și păcatele voastre au oprit lucrurile bune de la voi.
26 “Láàrín ènìyàn mi ni ìkà ènìyàn wà tí ó wà ní ibùba bí ẹni tí ó ń dẹ ẹyẹ, àti bí àwọn tí ó ń dẹ pàkúté láti mú ènìyàn.
Pentru că în poporul meu se găsesc oameni stricați; ei stau la pândă, precum cel care pune curse; ei pun o capcană, ei prind oameni.
27 Bí àgò tí ó kún fún ẹyẹ, ilé wọn sì kún fún ẹ̀tàn; wọ́n ti di ọlọ́lá àti alágbára,
Precum o colivie plină de păsări, astfel casele lor sunt pline de înșelăciune; de aceea au devenit mari și s-au îmbogățit.
28 wọ́n sanra wọ́n sì ń dán. Ìwà búburú wọn kò sì lópin; wọn kò bẹ̀bẹ̀ fún ẹjọ́ àwọn aláìní baba láti borí rẹ̀. Wọn kò jà fún ẹ̀tọ́ àwọn tálákà.
S-au îngrășat și strălucesc; da, întrec faptele celor stricați; cauza celui fără tată, această cauză ei nu o judecă, totuși ei prosperă; și dreptul celor nevoiași ei nu îl judecă.
29 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n fún èyí bí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò wá gbẹ̀san ara mi lára orílẹ̀-èdè bí èyí bí?
Să nu cercetez eu pentru aceste lucruri? spune DOMNUL, să nu fie sufletul meu răzbunat pe o națiune ca aceasta?
30 “Nǹkan ìbànújẹ́ àti ohun ìtara ti ṣẹlẹ̀ ní ilẹ̀ náà.
Un lucru uimitor și groaznic este comis în țară;
31 Àwọn wòlíì ń sọ àsọtẹ́lẹ̀ èké, àwọn àlùfáà sì ń ṣe àkóso pẹ̀lú àṣẹ ara wọn, àwọn ènìyàn mi sì ní ìfẹ́ sí èyí, kí ni ẹ̀yin yóò ṣe ní òpin?
Profeții profețesc fals și preoții stăpânesc prin mijloacele lor și poporul meu iubește aceasta; și ce veți face la sfârșit?

< Jeremiah 5 >