< Jeremiah 9 >

1 Háà! Orí ìbá jẹ́ orísun omi kí ojú mi sì jẹ́ orísun omijé! Èmi yóò sì sọkún tọ̀sán tòru nítorí ìparun àwọn ènìyàn mi.
De s-ar preface în ape, capul meu, și o fântână de lacrimi, ochii mei, ca să plâng zi și noapte pentru cei uciși ai fiicei poporului meu!
2 Háà, èmi ìbá ní ni aginjù ilé àgbàwọ̀ fún àwọn arìnrìn-àjò, kí n ba à lè fi àwọn ènìyàn mi sílẹ̀ kí n sì lọ kúrò lọ́dọ̀ wọn: nítorí gbogbo wọn jẹ́ panṣágà àjọ aláìṣòótọ́ ènìyàn.
De aș fi avut în pustie un loc de găzduire pentru călători; ca să las pe poporul meu și să plec de la ei! Pentru că ei toți sunt adulteri, o adunare de oameni perfizi.
3 Wọ́n ti pèsè ahọ́n wọn sílẹ̀ bí ọfà láti fi pa irọ́; kì í ṣe nípa òtítọ́ ni wọ́n fi borí ní ilẹ̀ náà. Wọ́n ń lọ láti inú ẹ̀ṣẹ̀ kan sí òmíràn; wọn kò sì náání mi, ní Olúwa wí.
Și ei își încordează limbile, arcul lor de minciuni; dar nu sunt viteji pentru adevărul de pe pământ, pentru că merg din rău în rău și nu mă cunosc, spune DOMNUL.
4 “Ṣọ́ra fún àwọn ọ̀rẹ́ rẹ; má ṣe gbẹ́kẹ̀lé àwọn arákùnrin rẹ. Nítorí pé oníkálùkù arákùnrin jẹ́ atannijẹ, oníkálùkù ọ̀rẹ́ sì jẹ́ abanijẹ́.
Luați bine seama, fiecare la aproapele său, și să nu vă încredeți în niciun frate, pentru că fiecare frate va piedica mult și fiecare prieten va umbla cu defăimări.
5 Ọ̀rẹ́ ń dalẹ̀ ọ̀rẹ́. Kò sì ṣí ẹni tó sọ òtítọ́, wọ́n ti kọ́ ahọ́n wọn láti máa purọ́. Wọ́n sọ ara wọn di onírẹ̀wẹ̀sì pẹ̀lú ẹ̀ṣẹ̀
Și fiecare va înșela pe aproapele său și nu va vorbi adevărul; și-au învățat limba să vorbească minciuni și se obosesc ca să facă nelegiuire.
6 Ó ń gbé ní àárín ẹ̀tàn; wọ́n kọ̀ láti mọ̀ mí nínú ẹ̀tàn wọn,” ni Olúwa wí.
Locuința ta este în mijlocul înșelăciunii; prin înșelăciune ei refuză să mă cunoască, spune DOMNUL.
7 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run Àwọn ọmọ-ogun wí: “Wò ó, èmi dán wọn wo; nítorí pé kí ni èmi tún le è ṣe? Nítorí ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn mi?
De aceea astfel spune DOMNUL oștirilor: Iată, îi voi topi și îi voi încerca, pentru că ce altceva aș putea face pentru fiica poporului meu?
8 Ahọ́n wọn dàbí ọfà olóró; ó ń sọ ẹ̀tàn. Oníkálùkù sì ń fi ẹnu rẹ̀ sọ̀rọ̀ àlàáfíà sí aládùúgbò rẹ̀, ní inú ọkàn rẹ̀, ó dẹ tàkúté sílẹ̀.
Limba lor este precum o săgeată trasă, vorbește înșelăciune; unul vorbește pașnic cu gura lui aproapelui său, dar în inima lui el își întinde cursa.
9 Èmi kì yóò ha fi ìyà jẹ wọ́n nítorí èyí?” ni Olúwa wí. “Èmi kì yóò ha gbẹ̀san ara mi lórí irú orílẹ̀-èdè yìí bí?”
Să nu îi cercetez eu pentru acestea? spune DOMNUL; să nu fie sufletul meu răzbunat pe o națiune ca aceasta?
10 Èmi yóò sì sọkún, pohùnréré ẹkún fún àwọn òkè àti ẹkún ìrora lórí pápá oko aginjù wọ̀n-ọn-nì. Nítorí wọ́n di ahoro, wọn kò sì kọjá ní ibẹ̀. A kò sì gbọ́ igbe ẹran ọ̀sìn. Àwọn ẹyẹ ojú ọ̀run sì ti sálọ, bẹ́ẹ̀ náà ni àwọn ẹranko sì ti lọ.
Pentru munți voi ridica plânset și bocet; și o plângere pentru locuințele pustiei, deoarece sunt arse de tot, încât nimeni nu poate trece prin ele; nici nu se poate auzi vocea vitelor; deopotrivă pasărea cerurilor și fiara au fugit; s-au dus.
11 “Èmi yóò sì sọ Jerusalẹmu di òkìtì àlàpà àti ihò àwọn ìkookò. Èmi ó sì sọ ìlú Juda di ahoro tí ẹnikẹ́ni kò sì ní le è gbé.”
Și eu voi face Ierusalimul ruine și o vizuină de dragoni; și voi face cetățile lui Iuda un pustiu, fără vreun locuitor.
12 Ta ni ẹni náà tí ó ní ọgbọ́n láti mòye nǹkan wọ̀nyí? Ta ni Olúwa ti sọ èyí fún, tí ó sì lè ṣàlàyé rẹ̀? Èéṣe tí ilẹ̀ náà fi ṣègbé bí aginjù, tí ẹnìkankan kò sì le là á kọjá?
Cine este omul înțelept, ca să înțeleagă aceasta? Și cui i-a vorbit gura DOMNULUI, ca să vestească aceasta, pentru ce a pierit țara și a ars ca o pustie, încât nimeni nu trece prin ea?
13 Olúwa sì wí pé, nítorí pé wọ́n ti kọ òfin mi sílẹ̀, èyí tí mo gbé kalẹ̀ níwájú wọn, wọn ṣe àìgbọ́ràn sí wọn, wọn kò sì rìn nínú òfin mi.
Și DOMNUL spune: Deoarece ei au părăsit legea mea pe care am pus-o înaintea lor, și nu au ascultat de vocea mea, nici nu au umblat în aceasta;
14 Dípò èyí, wọ́n ti tẹ̀lé agídí ọkàn wọn, wọ́n ti tẹ̀lé Baali gẹ́gẹ́ bí àwọn baba wọn ṣe kọ́ wọn.
Ci au umblat după închipuirea inimii lor proprii și după Baali precum i-au învățat părinții lor;
15 Nítorí náà, èyí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, “Wò ó, Èmi yóò mú kí àwọn ènìyàn wọ̀nyí jẹ oúnjẹ kíkorò àti láti mu omi májèlé.
De aceea astfel spune DOMNUL oștirilor, Dumnezeul lui Israel: Iată, voi hrăni acest popor cu pelin și le voi da să bea apă cu fiere.
16 Èmi yóò sì tú wọn ká láàrín àwọn orílẹ̀-èdè, nínú èyí tí àwọn tàbí àwọn baba wọn kò mọ̀. Èmi yóò sì lépa wọn pẹ̀lú idà títí èmi yóò fi pa wọ́n run.”
Îi voi împrăștia printre păgâni, pe care nici ei nici părinții lor nu i-au cunoscut; și voi trimite o sabie după ei, până îi voi fi mistuit.
17 Èyí sì ni ohun tí Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun wí: “Sá à wò ó nísinsin yìí! Ké sí obìnrin ti ń ṣọ̀fọ̀ nì kí ó wá; sì ránṣẹ́ pe àwọn tí ó mòye nínú wọn.
Astfel spune DOMNUL oștirilor: Luați aminte și chemați femeile care jelesc, și ele să vină; și trimiteți după femei iscusite, și ele să vină;
18 Jẹ́ kí wọn wá kíákíá, kí wọn wá pohùnréré ẹkún lé wa lórí títí ojú wa yóò fi sàn fún omijé tí omi yóò sì máa sàn àwọn ìpéǹpéjú wa.
Și să se grăbească ele și să înalțe un bocet pentru noi, ca din ochii noștri să curgă lacrimi și din pleoapele noastre să țâșnească ape.
19 A gbọ́ igbe ìpohùnréré ẹkún ní Sioni: ‘Àwa ti ṣègbé tó! A gbọdọ̀ fi ilẹ̀ wa sílẹ̀, nítorí pé àwọn ilé wa ti parun.’”
Fiindcă o voce de jale se aude din Sion: Cum suntem prădați! Suntem foarte încurcați, deoarece am părăsit țara, deoarece locuințele noastre ne-au lepădat.
20 Nísinsin yìí, ẹ̀yin obìnrin ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa; ṣí etí yín sí ọ̀rọ̀ ẹnu rẹ. Kọ́ àwọn ọmọbìnrin yín ní ìpohùnréré ẹkún, kí ẹ sì kọ́ ara yín ní arò.
Totuși ascultați cuvântul DOMNULUI, voi femeilor, și să primească urechea voastră cuvântul gurii lui și învățați-le pe fiicele voastre bocetul și fiecare, pe vecina ei, plângerea.
21 Ikú ti gba ojú fèrèsé wa wọlé ó sì ti wọ odi alágbára wa ó ti ké àwọn ọmọ kúrò ní àdúgbò àti àwọn ọ̀dọ́mọkùnrin kúrò ní gbọ̀ngàn ìta gbangba.
Pentru că moartea s-a urcat prin ferestrele noastre și a intrat în palatele noastre, pentru a-i stârpi pe copiii de afară și pe tinerii de pe străzi.
22 Sọ pé, “Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “‘Òkú àwọn ènìyàn yóò ṣubú bí ààtàn ní oko gbangba àti bí ìbùkúnwọ́ lẹ́yìn olùkórè láìsí ẹnìkankan láti kó wọn jọ.’”
Vorbește: Astfel spune DOMNUL: Chiar trupurile moarte ale oamenilor vor cădea ca balega pe câmpul deschis și ca snopul după secerător și nimeni nu le va aduna.
23 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Má ṣe jẹ́ kí ọlọ́gbọ́n yangàn nítorí agbára ọgbọ́n rẹ̀, tàbí alágbára nítorí agbára rẹ̀, tàbí ọlọ́rọ̀ nítorí ọrọ̀ rẹ̀.
Astfel spune DOMNUL: Să nu se laude înțeleptul cu înțelepciunea lui, nici cel puternic să nu se fălească cu puterea lui, bogatul să nu se fălească în bogățiile lui;
24 Ẹ jẹ́ kí ẹni tí ń ṣògo nípa èyí nì wí pé: òun ní òye, òun sì mọ̀ mí wí pé, Èmi ni Olúwa tí ń ṣe òtítọ́, ìdájọ́ àti òdodo ní ayé, nínú èyí ni mo ní inú dídùn sí,” Olúwa wí.
Ci cel ce se fălește să se fălească cu aceasta: că înțelege și că mă cunoaște, că eu sunt DOMNUL, care lucrez cu bunătate iubitoare, care fac judecată și dreptate pe pământ, pentru că în acestea mă desfătez, spune DOMNUL.
25 “Ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò fi ìyà jẹ gbogbo àwọn tí a kọ ilà fún nínú ara nìkan.
Iată, vin zilele, spune DOMNUL, că îi voi pedepsi pe toți cei circumciși împreună cu cei necircumciși;
26 Ejibiti, Juda, Edomu, Ammoni, Moabu àti gbogbo àwọn tí ń gbé ní ọ̀nà jíjìn réré ní aginjù. Nítorí pé gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè wọ̀nyí jẹ́ aláìkọlà gbogbo àwọn ará ilé Israẹli sì jẹ́ aláìkọlà ọkàn.”
Egiptul și Iuda și Edom și copiii lui Amon și Moab și toți cei din cele mai îndepărtate colțuri, care locuiesc în pustie, pentru că toate aceste națiuni sunt necircumcise și toată casa lui Israel este necircumcisă în inimă.

< Jeremiah 9 >