< Jeremiah 35 >

1 Ọ̀rọ̀ tí ó tọ Jeremiah wá láti ọ̀dọ̀ Olúwa ní ọjọ́ Jehoiakimu ọmọ Josiah ọba Juda wí pé:
The word that was maad of the Lord to Jeremye, in the daies of Joachym, sone of Josie,
2 “Lọ sí ilé àwọn ọmọ Rekabu, kí o sì bá wọn sọ̀rọ̀, kí o sì mú wọn wá sí ilé Olúwa, sí ọ̀kan nínú iyàrá wọ̀n-ọn-nì, kí o sì fún wọn ní ọtí wáìnì mu.”
kyng of Juda, and seide, Go thou to the hous of Recabitis, and speke thou to hem; and thou schalt brynge hem in to the hous of the Lord, in to o chaumbre of tresouris, and thou schalt yyue to hem to drynke wyn.
3 Nígbà náà ni mo mu Jaaṣaniah ọmọ Jeremiah, ọmọ Habasiniah àti àwọn arákùnrin rẹ̀; àti gbogbo àwọn ọmọ rẹ̀, àti gbogbo ilé àwọn ọmọ Rekabu.
And Y took Jeconye, the sone of Jeremye, sone of Absanye, and hise britheren, and alle the sones of hym, and al the hous of Recabitis.
4 Mo sì mú wọn wá sí ilé Olúwa sínú iyàrá Hanani ọmọ Igdaliah, ènìyàn Ọlọ́run, tí ó wà lẹ́bàá yàrá àwọn ìjòyè, tí ó wà ní òkè yàrá Maaseiah, ọmọ Ṣallumu olùtọ́jú ẹnu-ọ̀nà.
And Y ledde hem in to the hous of the Lord, to the treserie of the sones of Eman, sone of Godolie, the man of God; which treserie was bisidis the treserie of princes, aboue the tresour of Maasie, sone of Sellum, that was kepere of the vestiarie.
5 Mo sì gbé ìkòkò tí ó kún fún ọtí wáìnì pẹ̀lú ago ka iwájú àwọn ọmọ Rekabu. Mo sì wí fún wọn pé, “Mu ọtí wáìnì.”
And Y settide bifore the sones of the hous of Recabitis pecis, and grete cowpis ful of wyn; and Y seide to hem, Drinke ye wyn.
6 Ṣùgbọ́n wọ́n wí pé, “Àwa kì yóò mu ọtí wáìnì nítorí Jonadabu ọmọ Rekabu, baba wa pàṣẹ fún wa pé: ‘Ẹ̀yin kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì ẹ̀yin àti àwọn ọmọ yín láéláé.
And thei answeriden, We schulen not drinke wyn; for whi Jonadab, oure fadir, the sone of Recab, comaundide to vs, and seide, Ye schulen not drinke wyn, ye and youre sones, `til in to withouten ende;
7 Bẹ́ẹ̀ ni, ẹ̀yin kò gbọdọ̀ kọ́ ilé tàbí kí ẹ fúnrúgbìn, tàbí kí ẹ gbin ọgbà àjàrà. Bẹ́ẹ̀ ni ẹ̀yin kò gbọdọ̀ ní ọ̀kankan nínú àwọn ohun wọ̀nyí, ṣùgbọ́n ní gbogbo ọjọ́ yín ni ẹ̀yin ó máa gbé inú àgọ́; kí ẹ̀yin kí ó lè wá ní ọjọ́ púpọ̀ ní ilẹ̀ náà; níbi tí ẹ̀yin ti ń ṣe àtìpó.’
and ye schulen not bilde an hous, and ye schulen not sowe seed, and ye schulen not plaunte vynes, nether schulen haue, but ye schulen dwelle in tabernaclis in alle youre daies, that ye lyue many daies on the face of erthe, in which ye goen in pilgrymage.
8 Báyìí ni àwa gba ohùn Jehonadabu ọmọ Rekabu baba wa gbọ́ nínú gbogbo èyí tí ó pàṣẹ fún wa, kí a má mu ọtí wáìnì ní gbogbo ọjọ́ ayé wa; àwa, àwọn aya wa, àwọn ọmọkùnrin wa, àti àwọn ọmọbìnrin wa.
Therfor we obeieden to the vois of Jonadab, oure fadir, the sone of Recab, in alle thingis whiche he comaundide to vs; so that we drunken not wyn in alle oure dayes, we, and oure wymmen, oure sones, and douytris;
9 Àti kí a má kọ́ ilé láti gbé; bẹ́ẹ̀ ni àwa kò ní ọgbà àjàrà tàbí oko, tàbí ohun ọ̀gbìn.
and we bildiden not housis to dwelle, and we hadden not a vyner, and a feeld, and seed;
10 Ṣùgbọ́n àwa ń gbé inú àgọ́, a sì gbọ́rọ̀, a sì ṣe gẹ́gẹ́ bí gbogbo èyí tí Jonadabu baba wa pàṣẹ fún wa.
but we dwelliden in tabernaclis, and weren obeiynge, and diden bi alle thingis, whiche Jonadab, oure fadir, comaundide to vs.
11 Ó sì ṣe, nígbà tí Nebukadnessari ọba Babeli gòkè wá sí ilẹ̀ náà; àwa wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lọ sí Jerusalẹmu, nítorí ìbẹ̀rù ogun àwọn ara Siria.’ Bẹ́ẹ̀ ni àwa sì ń gbé Jerusalẹmu.”
But whanne Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, hadde stied to this lond, we seiden, Come ye, and entre we in to Jerusalem, fro the face of the oost of Caldeis, and fro the face of the oost of Sirie; and we dwelliden in Jerusalem.
12 Nígbà yìí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tọ Jeremiah wá wí pé:
And the word of the Lord was maad to Jeremye,
13 “Báyìí ní Olúwa àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé, lọ, kí o sì sọ fún àwọn ọkùnrin Juda, àti àwọn olùgbé Jerusalẹmu pé, ‘Ẹ̀yin kì yóò ha gba ẹ̀kọ́ láti fetí sí ọ̀rọ̀ mi,’ ni Olúwa wí.
and seide, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Go thou, and seie to the men of Juda, and to the dwelleris of Jerusalem, Whether ye schulen not take techyng, that ye obeie to my wordis, seith the Lord?
14 ‘Ọ̀rọ̀ Jehonadabu ọmọ Rekabu tí ó pàṣẹ fún àwọn ọmọ rẹ̀ pé wọn kò gbọdọ̀ mu ọtí wáìnì, ni a mú ṣẹ, wọn kò sì mu ọtí wáìnì títí di òní yìí, nítorí tí wọ́n gba òfin baba wọn. Èmi sì ti ń sọ̀rọ̀ fún un yín, ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
The wordis of Jonadab, sone of Rechab, hadden the maistrie, whiche he comaundide to hise sones, that thei schulden not drynke wyn; and thei drynken not, `til to this dai; for thei obeieden to the comaundement of her fadir; but Y spak to you, and Y roos ful eerli, and spake, and ye obeieden not to me.
15 Èmi rán gbogbo àwọn ìránṣẹ́ àti àwọn wòlíì mí sí yín pẹ̀lú wí pé, “Ẹ yípadà nísinsin yìí kúrò ní ọ̀nà búburú yín, kí ẹ sì tún ìṣe yín ṣe sí rere. Kí ẹ ma sì ṣe bọ òrìṣà tàbí sìn wọ́n; ẹ̀yin ó sì máa gbé ní ilẹ̀ náà tí mo fi fún un yín àti fún àwọn baba ńlá yín.” Ṣùgbọ́n ẹ̀yin kò fetí sí mi.
And Y sente to you alle my seruauntis profetis, and Y roos ful eerli, and Y sente, and seide, Be ye conuertid, ech man fro his worste weye, and make ye good youre studies, and nyle ye sue alien goddis, nether worschipe ye hem, and ye schulen dwelle in the lond, which Y yaf to you, and to youre fadris; and ye bowiden not youre eere, nether herden me.
16 Nítòótọ́, àwọn ọmọ Jehonadabu ọmọ Rekabu pa òfin baba wọn mọ́ tí ó pàṣẹ fún wọn, ṣùgbọ́n àwọn ènìyàn wọ̀nyí kò pa òfin mi mọ́.’
Therfor the sones of Jonadab, sone of Recab, maden stidfast the comaundement of her fadir, which he comaundide to hem; but this puple obeiede not to me.
17 “Nítorí náà, báyìí ni, Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí, ‘Fetísílẹ̀! Èmi ó mú gbogbo ohun búburú tí èmi ti sọ wá sórí Juda, àti sórí gbogbo olùgbé Jerusalẹmu nítorí èmi ti bá wọn sọ̀rọ̀: Ṣùgbọ́n wọn kò sì dáhùn.’”
Therfor the Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Lo! Y schal bringe on Juda, and on alle the dwelleris of Jerusalem, al the turment which Y spak ayens hem; for Y spak to hem, and thei herden not; Y clepide hem, and thei answeriden not to me.
18 Nígbà náà ni Jeremiah wí fún ìdílé Rekabu pé, “Báyìí ni Olúwa Ọlọ́run àwọn ọmọ-ogun Ọlọ́run Israẹli wí pé: ‘Nítorí tí ẹ̀yin gba òfin Jehonadabu baba yín, tí ẹ sì pa gbogbo rẹ̀ mọ́, tí ẹ sì ṣe gẹ́gẹ́ bí èyí tí ó pàṣẹ fún un yín.’
Forsothe Jeremye seide to the hous of Recabitis, The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, For that that ye obeieden to the comaundement of Jonadab, youre fadir, and kepten alle hise comaundementis, and diden alle thingis, whiche he comaundide to you;
19 Nítorí náà, báyìí ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun, Ọlọ́run Israẹli wí, pé: ‘Jonadabu ọmọ Rekabu kì yóò fẹ́ ọkùnrin kan kù láti sìn mí.’”
therfor the Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, A man of the generacioun of Jonadab, sone of Recab, schal not faile stondynge in my siyt in alle daies.

< Jeremiah 35 >