< Jeremiah 31 >

1 “Nígbà náà, Èmi yóò jẹ́ Ọlọ́run fún gbogbo ìdílé ìran Israẹli, àwọn náà yóò sì jẹ́ ènìyàn mi,” ni Olúwa wí.
In that tyme, seith the Lord, Y schal be God to alle the kynredis of Israel; and thei schulen be in to a puple to me.
2 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àwọn ènìyàn tí ó sá àsálà lọ́wọ́ idà yóò rí ojúrere Olúwa ní aṣálẹ̀, Èmi yóò sì fi ìsinmi fún Israẹli.”
The Lord seith these thingis, The puple that was left of swerd, foond grace in desert; Israel schal go to his reste.
3 Olúwa ti fi ara rẹ̀ hàn wá ní ìgbà kan rí, ó wí pé: “Èmi ti nífẹ̀ẹ́ yín pẹ̀lú ìfẹ́ àìlópin; mo ti fi ìfẹ́ ńlá fà yín,
Fer the Lord apperide to me, and in euerlastynge charite Y louede thee; therfor Y doynge merci drow thee.
4 Èmi yóò tún gbé e yín sókè, àní a ó tún gbé e yín ró ìwọ wúńdíá ilẹ̀ Israẹli. Àní ẹ ó tún tún ohun èlò orin yín gbé, ẹ ó sì jáde síta pẹ̀lú ijó àti ayọ̀.
And eft Y schal bilde thee, and thou, virgyn Israel, schalt be bildid; yit thou schalt be ourned with thi tympans, and schalt go out in the cumpenye of pleieris.
5 Ẹ ó tún gbin ọgbà àjàrà ní orí òkè Samaria; àwọn àgbẹ̀ yóò sì máa gbádùn èso oko wọn.
Yit thou schalt plaunte vynes in the hillis of Samarie; men plauntynge schulen plaunte, and til the tyme come, thei schulen not gadere grapis.
6 Ọjọ́ kan máa wà tí àwọn olùṣọ́ yóò kígbe jáde lórí òkè Efraimu wí pé, ‘Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a gòkè lọ sí Sioni, ní ọ̀dọ̀ Olúwa Ọlọ́run wa.’”
For whi a dai schal be, wherynne keperis schulen crye in the hil of Samarie, and in the hil of Effraym, Rise ye, and stie we in to Sion, to oure Lord God.
7 Èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ wí pé: “Ẹ fi ayọ̀ kọrin sí Jakọbu; ẹ hó sí olórí àwọn orílẹ̀-èdè gbogbo. Jẹ́ kí wọ́n gbọ́ ìyìn rẹ kí o sì wí pé, ‘Olúwa, gba àwọn ènìyàn rẹ là; àwọn tí ó ṣẹ́kù ní Israẹli.’
For the Lord seith these thingis, Jacob, make ye ful out ioye in gladnesse, and neye ye ayens the heed of hethene men; sowne ye, synge ye, and seie ye, Lord, saue thi puple, the residues of Israel.
8 Wò ó, Èmi yóò mú wọn wá láti ilẹ̀ àríwá; èmi yóò kó gbogbo wọn jọ láti òpin ayé. Lára wọn ni yóò jẹ́ afọ́jú àti arọ, aboyún àti obìnrin tí ń rọbí, ọ̀pọ̀ ènìyàn yóò wá.
Lo! Y schal brynge hem fro the loond of the north, and Y schal gadere hem fro the fertheste partis of erthe; among whiche schulen be a blynd man, and crokid, and a womman with childe, and trauelynge of child togidere, a greet cumpeny of hem that schulen turne ayen hidur.
9 Wọn yóò wá pẹ̀lú ẹkún, wọn yóò gbàdúrà bí Èmi yóò ṣe mú wọn padà. Èmi yóò jẹ́ atọ́nà fún wọn ní ẹ̀bá odò omi; ní ọ̀nà tí ó tẹ́jú tí wọn kì yóò le ṣubú, nítorí èmi ni baba Israẹli, Efraimu sì ni àkọ́bí ọkùnrin mi.
Thei schulen come in wepyng, and Y schal brynge hem ayen in merci; and Y schal brynge hem bi the strondis of watris in a riytful weie, thei schulen not spurne therynne; for Y am maad a fadir to Israel, and Effraym is my gendrid sone.
10 “Ẹ gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa ẹ̀yin orílẹ̀-èdè ẹ kéde rẹ̀ ní erékùṣù jíjìn; ‘Ẹni tí ó bá tú Israẹli ká yóò kójọ, yóò sì ṣọ́ agbo rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí olùṣọ́-àgùntàn.’
Ye hethene men, here ye the word of the Lord, and telle ye in ylis that ben fer, and seie, He that scateride Israel, schal gadere it, and schal kepe it, as a scheepherde kepith his floc.
11 Nítorí Olúwa ti tú Jakọbu sílẹ̀, o sì rà á padà ní ọwọ́ àwọn tí ó lágbára jù ú lọ.
For the Lord ayenbouyte Jacob, and delyuerede hym fro the hond of the myytiere.
12 Wọn yóò wá, wọn ó sì hó ìhó ayọ̀ lórí òkè Sioni; wọn yóò yọ ayọ̀ níbi oore Olúwa. Àlìkámà ni, ọtí wáìnì tuntun àti òróró ọ̀dọ́-àgùntàn àti ọ̀dọ́ ọ̀wọ́ ẹran. Wọn ó dàbí ọgbà àjàrà tí a bomirin, ìkorò kò ní bá wọn mọ́.
And thei schulen come, and herye in the hil of Sion; and thei schulen flowe togidere to the goodis of the Lord, on wheete, wyn, and oile, and on the fruyt of scheep, and of neet; and the soule of hem schal be as a watri gardyn, and thei schulen no more hungre.
13 Àwọn wúńdíá yóò jó, wọn ó sì kún fún ayọ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni ọkùnrin àti obìnrin. Èmi yóò sọ ọ̀fọ̀ wọn di ayọ̀, dípò ìkorò èmi yóò tù wọ́n nínú. Èmi ó sì fún wọn ní ayọ̀.
Thanne a virgyn schal be glad in a cumpenye, yonge men and elde togidere; and Y schal turne the morenyng of hem in to ioie, and Y schal coumforte hem, and Y schal make hem glad of her sorewe.
14 Èmi ó tẹ́ àwọn àlùfáà lọ́rùn pẹ̀lú ọ̀pọ̀; àwọn ènìyàn mi yóò sì kún fún oore mi,” ni Olúwa wí.
And Y schal greetli fille the soule of prestis with fatnesse, and my puple schal be fillid with my goodis, seith the Lord.
15 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “A gbọ́ ohùn kan ní Rama tí ń ṣọ̀fọ̀ pẹ̀lú ẹkún kíkorò. Rakeli ń sọkún àwọn ọmọ rẹ̀; kò gbà kí wọ́n tu òun nínú, nítorí àwọn ọmọ rẹ̀ kò sí mọ́.”
The Lord seith these thingis, A vois of weilyng, and of wepyng, and of mourenyng, was herd an hiy; the vois of Rachel biwepynge hir sones, and not willynge to be coumfortid on hem, for thei ben not.
16 Báyìí ni Olúwa wí: “Dá ohùn rẹ dúró nínú ẹkún àti ojú rẹ nínú omijé; nítorí a ó fi èrè sí iṣẹ́ rẹ,” ni Olúwa wí. “Wọn ó sì padà wá láti ilẹ̀ ọ̀tá.
The Lord seith these thingis, Thi vois reste of wepyng, and thin iyen reste of teeres; for whi mede is to thi werk, seith the Lord; and thei schulen turne ayen fro the lond of the enemy.
17 Nítorí ìrètí wà fún ọjọ́ iwájú rẹ,” ni Olúwa wí. “Àwọn ọmọ rẹ yóò padà wá sí ilẹ̀ wọn.
And hope is to thi laste thingis, seith the Lord, and thi sones schulen turne ayen to her endis.
18 “Nítòótọ́, èmi ti gbọ́ ìpohùnréré Efraimu wí pé, ‘Ìwọ ti bá mi wí gẹ́gẹ́ bí ọmọ màlúù tí a kò kọ́ èmi sì ti gbọ́ ìbáwí. Rà mí padà, èmi yóò sì yípadà, nítorí ìwọ ni Olúwa Ọlọ́run mi.
I heringe herde Effraym passinge ouer; thou chastisidist me, and Y am lerned as a yong oon vntemyd; turne thou me, and Y schal be conuertid, for thou art my Lord God.
19 Lẹ́yìn tí èmi ti yípadà, mo ronúpìwàdà, lẹ́yìn tí èmi ti wá mọ̀, èmi lu àyà mi. Ojú tì mí, mo sì dààmú; nítorí èmi gba èrè ẹ̀gàn ìgbà èwe mi.’
For aftir that thou conuertidist me, Y dide penaunce; and aftir that thou schewidist to me, Y smoot myn hipe; Y am schent, and Y schamede, for Y suffride the schenschipe of my yongthe.
20 Efraimu kì í ha í ṣe ọmọkùnrin mi dáradára tí inú mi dùn sí bí? Bí èmi ti ń sọ̀rọ̀ sí i tó, síbẹ̀, èmi rántí rẹ̀. Nítorí náà, ọkàn mi ṣe ohun kan fún un, èmi káàánú gidigidi fún un,” ni Olúwa wí.
For Effraym is a worschipful sone to me, for he is a delicat child; for sithen Y spak of hym, yit Y schal haue mynde on hym; therfor myn entrails ben disturblid on him, Y doynge merci schal haue merci on hym, seith the Lord.
21 “Gbé àmì ojú ọ̀nà dìde, ṣe atọ́nà àmì, kíyèsi òpópó ọ̀nà geere ojú ọ̀nà tí ó ń gbà. Yípadà ìwọ wúńdíá Israẹli, padà sí àwọn ìlú rẹ.
Ordeyne to thee an hiy totyng place, sette to thee bitternesses; dresse thin herte in to a streiyt weie, in which thou yedist; turne ayen, thou virgyn of Israel, turne ayen to these thi citees.
22 Ìwọ yóò ti ṣìnà pẹ́ tó, ìwọ aláìṣòótọ́ ọmọbìnrin; Olúwa yóò dá ohun tuntun lórí ilẹ̀, ọmọbìnrin kan yóò yí ọkùnrin kan ká.”
Hou longe, douyter of vnstidfast dwellyng, art thou maad dissolut in delices? for the Lord hath maad a newe thing on erthe, a womman schal cumpasse a man.
23 Báyìí ni ohun tí Olúwa àwọn ọmọ-ogun Israẹli wí: “Nígbà tí èmi bá kó wọn dé láti ìgbèkùn; àwọn ènìyàn tí ó wà ní ilẹ̀ Juda àti ní àwọn ìlú rẹ̀ yóò tún lo àwọn ọ̀rọ̀ yìí lẹ́ẹ̀kan sí i; wí pé, ‘Kí Olúwa kí ó bùkún fún ọ, ìwọ ibùgbé òdodo, ìwọ òkè ìwà mímọ́.’
The Lord of oostis, God of Israel, seith these thingis, Yit thei schulen seie this word in the lond of Juda, and in the citees therof, whane Y schal turne the caytifte of hem, The Lord blesse thee, thou fairnesse of riytfulnesse, thou hooli hil.
24 Àwọn ènìyàn yóò gbé papọ̀ ní Juda àti ní gbogbo àwọn ìlú rẹ̀; bákan náà ni àgbẹ̀ àti àwọn tí ń tẹ̀lé agbo ẹran wọn ká.
And Juda, and alle citees therof schulen dwelle in it togidere, erthetilieris, and thei that dryuen flockis.
25 Èmi yóò sọ aláàárẹ̀ di ọ̀tun, èmi yóò sì tẹ́ gbogbo ọkàn tí ń káàánú lọ́rùn.”
For Y fillide greetli a feynt soule, and Y haue fillid ech hungri soule.
26 Lórí èyí ni mo jí, mo sì wò yíká, oorun mi sì dùn mọ́ mi.
Therfor Y am as reisid fro sleep, and Y siy; and my sleep was swete to me.
27 “Wò ó, ọjọ́ ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “nígbà tí èmi yóò gbin ilé Israẹli àti ilé Juda pẹ̀lú irúgbìn ọmọ ènìyàn àti ẹranko.
Lo! daies comen, seith the Lord, and Y schal sowe the hous of Israel and the hous of Juda with the seed of men, and with the seed of werk beestis.
28 Gẹ́gẹ́ bí mo ṣe ń ṣọ́ wọn, láti fàtu, àti láti wó lulẹ̀, àti láti gba ìṣàkóso, láti bàjẹ́ àti láti mú ibi wá, bẹ́ẹ̀ ni èmi yóò ṣọ́ wọn láti kọ́ àti láti gbìn,” ni Olúwa wí.
And as Y wakide on hem, to drawe vp bi the roote, and to distrie, and to scatere, and to leese, and to turmente; so Y schal wake on hem, to bilde, and to plaunte, seith the Lord.
29 “Ní ọjọ́ wọ̀n-ọn-nì àwọn ènìyàn kò ní sọ mọ́ pé: “‘Àwọn baba ti jẹ èso àjàrà àìpọ́n àti pé eyín kan àwọn ọmọdé.’
In tho daies thei schulen no more seie, The fadres eeten a sour grape, and the teeth of sones weren astonyed; but ech man schal die in his wickidnesse,
30 Ṣùgbọ́n olúkúlùkù ni yóò kú fún ẹ̀ṣẹ̀ rẹ̀, ẹnikẹ́ni tí ó bá jẹ èso kíkan ni eyín yóò kan.
ech man that etith a sour grape, hise teeth schulen be astonyed.
31 “Ìgbà kan ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí Èmi yóò bá ilé Israẹli àti ilé Juda dá májẹ̀mú tuntun.
Lo! daies comen, seith the Lord, and Y schal smyte a newe boond of pees to the hous of Israel, and to the hous of Juda;
32 Kò ní dàbí májẹ̀mú tí mo bá àwọn baba ńlá wọn dá, nígbà tí mo fà wọ́n lọ́wọ́, tí mo mú wọn jáde ní Ejibiti nítorí wọ́n da májẹ̀mú mi. Lóòótọ́ ọkọ ni èmi jẹ́ fún wọn,” ni Olúwa wí.
not bi the couenaunte which Y made with youre fadris, in the dai in which Y took the hond of hem, to lede hem out of the lond of Egipt, the couenaunte which thei made voide; and Y was Lord of hem, seith the Lord.
33 “Èyí ni májẹ̀mú tí èmi yóò bá ilé Israẹli dá lẹ́yìn ìgbà náà,” ni Olúwa wí pé: “Èmi yóò fi òfin mi sí ọkàn wọn, èmi ó sì kọ ọ́ sí àyà wọn. Èmi ó jẹ́ Olúwa wọn; àwọn ó sì jẹ́ ènìyàn mi.
But this schal be the couenaunte, which Y schal smyte with the hous of Israel aftir tho daies, seith the Lord; Y schal yyue my lawe in the entrails of hem, and Y schal write it in the herte of hem, and Y schal be in to God to hem, and thei schulen be in to a puple to me.
34 Kò ní sí pé ọkùnrin kan ń kọ́ àwọn ará ilé rẹ̀ tàbí ọkùnrin ń kọ́ arákùnrin rẹ̀ pé, ‘Ẹ mọ Olúwa,’ nítorí gbogbo wọn ni yóò mọ̀ mí láti ẹni kékeré wọn títí dé ẹni ńlá,” ni Olúwa wí. “Nítorí èmi ó dárí àìṣedéédéé wọn jì, èmi kò sì ní rántí ẹ̀ṣẹ̀ wọn mọ́.”
And a man schal no more teche his neiybore, and a man his brother, and seie, Knowe thou the Lord; for alle schulen knowe me, fro the leeste of hem `til to the mooste, seith the Lord; for Y schal be merciful to the wickidnessis of hem, and Y schal no more be myndeful on the synne of hem.
35 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: ẹni tí ó mú oòrùn tan ìmọ́lẹ̀ ní ọ̀sán, tí ó mú òṣùpá àti ìràwọ̀ ràn ní òru; tí ó rú omi Òkun sókè tó bẹ́ẹ̀ tí ìjì rẹ̀ fi ń hó Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
The Lord seith these thingis, that yyueth the sunne in the liyt of dai, the ordre of the moone and of sterris in the liyt of the niyt, whiche disturblith the see, and the wawis therof sownen, the Lord of oostis is name to hym.
36 “Àyàfi tí ìlànà yìí bá kúrò níwájú mi,” ni Olúwa wí. “Ǹjẹ́ àwọn ọmọ Israẹli yóò dẹ́kun láti jẹ́ orílẹ̀-èdè níwájú mi láéláé.”
If these lawis failen bifore me, seith the Lord, thanne and the seed of Israel schal faile, that it be not a folk bifore me in alle daies.
37 Èyí ni ohun tí Olúwa wí: “Àyàfi tí a bá lé àwọn ọ̀run lókè tí ìpìlẹ̀ ayé sì di àwárí ní ìsàlẹ̀, ni èmi yóò kọ àwọn Israẹli nítorí ohun gbogbo tí wọ́n ti ṣe,” ni Olúwa wí.
The Lord seith these thingis, If heuenes aboue moun be mesurid, and the foundementis of erthe bynethe be souyt out, and Y schal caste awei al the seed of Israel, for alle thingis whiche thei diden, seith the Lord.
38 “Ọjọ́ náà ń bọ̀,” ni Olúwa wí, “tí wọn yóò tún ìlú yìí kọ́ fún mi láti ilé ìṣọ́ Hananeli dé igun ẹnu ibodè.
Lo! daies comen, seith the Lord, and a citee schal be bildid to the Lord, fro the tour of Ananeel `til to the yate of the corner.
39 Okùn ìwọ̀n yóò sì nà jáde láti ibi gígùn lọ sí òkè Garebu yóò sì lọ sí Goa.
And it schal go out ouer the reule of mesure, in the siyt therof, on the hil Gareb, and it schal cumpasse Goatha,
40 Gbogbo àfonífojì níbi tí wọ́n ń da òkú àti eérú sí, àti gbogbo àfonífojì Kidironi ní ìhà ìlà-oòrùn títí dé igun ẹnu ibodè ẹṣin yóò jẹ́ mímọ́ sí Olúwa. A kì yóò fa ìlú náà tu tàbí kí a wó o palẹ̀.”
and al the valei of careyns, and it schal cumpasse aischis, and al the cuntrei of deth, `til to the stronde of Cedron, and til to the corner of the eest yate of horsis; the hooli thing of the Lord schal not be drawun out, and it schal no more be destried with outen ende.

< Jeremiah 31 >