< Jeremiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
Cuvântul care a venit la Ieremia, de la DOMNUL, când împăratul Zedechia a trimis la el pe Pașhur fiul lui Malchiia și pe Țefania, fiul lui Maaseia, preotul, spunând:
2 “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
Întreabă, te rog, pe DOMNUL pentru noi, pentru că Nebucadnețar, împăratul Babilonului, face război împotriva noastră; poate că DOMNUL se va purta cu noi conform cu toate lucrările lui minunate, ca Nebucadnețar să plece de la noi.
3 Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
Atunci Ieremia le-a spus: Astfel să îi spuneți lui Zedechia:
4 ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
Astfel spune DOMNUL Dumnezeul lui Israel: Iată, voi întoarce înapoi armele de război care sunt în mâinile voastre, cu care luptați împotriva împăratului Babilonului și împotriva caldeenilor care vă asediază în afara zidului; și le voi aduna în mijlocul acestei cetăți.
5 Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
Și eu însumi voi lupta împotriva voastră cu o mână întinsă și cu un braț puternic, în mânie și în furie și în mare indignare.
6 Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
Și voi lovi pe locuitorii acestei cetăți, deopotrivă pe om și pe animal; aceștia vor muri de o ciumă cumplită.
7 Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
Și după aceea, spune DOMNUL, îl voi da pe Zedechia, împăratul lui Iuda, și pe servitorii lui și pe popor și pe cei care au rămas în această cetate după ciumă, după sabie și după foamete, în mâna lui Nebucadnețar împăratul Babilonului, și în mâna dușmanilor lor și în mâna celor ce le caută viața; și el îi va lovi cu tăișul sabiei: nu îi va cruța, nici nu va avea îndurare, nici nu va avea milă.
8 “Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
Și acestui popor să îi spui: Astfel spune DOMNUL: Iată, pun înaintea voastră calea vieții și calea morții.
9 Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
Cel ce rămâne în această cetate va muri de sabie și de foamete și de ciumă; dar cel care iese și se predă caldeenilor care vă asediază va trăi și viața lui îi va fi drept pradă.
10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
Pentru că mi-am îndreptat fața împotriva acestei cetăți pentru rău și nu pentru bine, spune DOMNUL: ea va fi dată în mâna împăratului Babilonului și el o va arde cu foc.
11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Și referitor la casa împăratului lui Iuda, spune: Ascultați cuvântul DOMNULUI:
12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
Casă a lui David, astfel spune DOMNUL: Faceți judecată dimineața și eliberați-l pe cel prădat, din mâna opresorului, ca nu cumva furia mea să izbucnească precum un foc și să ardă astfel încât să nu fie nimeni să îl poată stinge, din cauza răutății facerilor voastre.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
Iată, eu sunt împotriva ta, locuitoare a văii și stâncă mare a câmpului, spune DOMNUL; care spuneți: Cine va coborî împotriva noastră? Sau, cine va intra în locuințele noastre?
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”
Dar eu vă voi pedepsi conform cu rodul facerilor voastre, spune DOMNUL; și voi aprinde un foc în pădurea lui și acesta va mistui toate lucrurile de jur împrejurul lui.

< Jeremiah 21 >