< Jeremiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
Šis ir tas vārds, kas notika uz Jeremiju no Tā Kunga, kad ķēniņš Cedeķija pie viņa sūtīja Pašhuru, Malhijas dēlu, un priesteri Cefaniju, Maāsejas dēlu, un sacīja:
2 “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
Vaicā jel To Kungu par mums; jo Nebukadnecars, Bābeles ķēniņš, pret mums karo. Varbūt ka Tas Kungs ar mums darīs pēc saviem brīnumiem, ka šis no mums atstātos.
3 Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
Tad Jeremija uz tiem sacīja: sakāt tā Cedeķijam:
4 ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
Tā saka Tas Kungs Israēla Dievs: redzi, Es griezīšu atpakaļ tos kara ieročus, kas ir jūsu rokās, ar ko jūs karojat pret Bābeles ķēniņu un pret Kaldejiem, kas pret jums ārpus mūriem apmetušies, un tos sapulcināšu šīs pilsētas vidū.
5 Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
Un Es pats pret jums karošu ar izstieptu roku un ar stipru elkoni un ar bardzību un ar karstumu un lielām dusmām.
6 Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
Un Es kaušu šās pilsētas iedzīvotājus, gan cilvēkus, gan lopus; caur lielu mēri tiem būs mirt.
7 Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
Un pēc tam, saka Tas Kungs, Es nodošu Cedeķiju, Jūda ķēniņu, un viņa kalpus un tos ļaudis, kas šai pilsētā atlikuši no mēra, no zobena un no bada, Nebukadnecara, Bābeles ķēniņa, rokā un viņu ienaidnieku rokā un to rokā, kas viņu dzīvību meklē. Un viņš tos sitīs ar zobena asmeni, viņš tos nesaudzēs, netaupīs, nežēlos.
8 “Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
Un uz šiem ļaudīm tev būs sacīt: tā saka Tas Kungs: redzi, Es jums lieku priekšā dzīvības ceļu un nāves ceļu.
9 Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
Kas šai pilsētā paliek, tie mirs caur zobenu, caur badu un caur mēri. Bet kas iziet un dodas pie tiem Kaldejiem, kas pret jums ir apmetušies, tas dzīvos un mantos savu dvēseli.
10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
Jo Es Savu vaigu esmu griezis pret šo pilsētu par ļaunu un ne par labu, saka Tas Kungs; tā Bābeles ķēniņam taps rokā dota un viņš to sadedzinās ar uguni.
11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Un par Jūda ķēniņa namu klausiet Tā Kunga vārdu:
12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
Ak Dāvida nams, tā saka Tas Kungs, nesiet ik rītu tiesu un izglābiet aplaupīto no spaidītāja rokas, ka Mana dusmība neizšaujās kā uguns un nedeg, ka neviens nevar dzēst, jūsu darbu ļaunuma dēļ.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
Redzi, Es celšos pret tevi, kas dzīvo ielejā, tu klajuma klints, saka Tas Kungs, pret jums, kas teiciet: kas mums varētu uzbrukt vai nākt mūsu māju vietās?
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”
Es jūs piemeklēšu pēc jūsu darbu augļiem, saka Tas Kungs, un Es iededzināšu viņas mežā uguni, tas aprīs visu viņas apkārtni.

< Jeremiah 21 >