< Jeremiah 21 >
1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
KA olelo i hiki mai io Ieremia la, mai o Iehova mai i ka wa i hoouna aku ai o Zedekia, ke alii, io na la, ia Pasehura, ke keiki a Malekia, a me Zepania, ke keiki a Maaseia, ke kahuna, i aku la,
2 “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
Ke noi aku nei au ia oe, e noi aku ia Iehova no kakou; no ka mea, ke kaua mai nei o Nebukaneza, ke alii o Babulona ia kakou; ina paha e hana mai o Iehova ia kakou, e like me kana hana kupanaha a pau, i pii aku ke alii o Babulona, mai o kakou aku.
3 Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
Alaila, olelo mai la o Ieremia ia lakou, Penei oukou e olelo aku ai ia Zedekia;
4 ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
Ke olelo mai nei o Iehova, ke Akua o ka Iseraela peneia, Aia hoi, e hoihoi hope aku no au i na mea kaua, na mea maloko o ko oukou lima, na mea a oukou i kaua ai i ke alii o Babulona, a i ko Kaledea, ka poe hoopilikia mai ia oukou mawaho o na pa, a e hoiliili au ia mau mea maloko o keia kulanakauhale.
5 Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
A owau no kekahi e kaua aku ia oe, me ka lima kakauha, a me ka lima ikaika, me ka huhu no, a me ka inaina, a me ka ukiuki loa.
6 Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
A e hahau no wau i ka poe noho ma keia kulauakauhale, i kanaka, a me na holoholona; a e make no lakou i ka mai ahulau nui.
7 Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
A mahope iho, wahi a Iehova, e haawi no wau ia Zedekia, i ke alii o ka Iuda, a me kana poe kauwa, a me kona poe kanaka, na mea o keia kulanakauhale i koe i ke ahulau, a me ka pahikaua, a me ka wi, a iloko o ka lima o Nebukaneza, o ke alii o Babulona, a iloko o ka lima o ko lakou poe enemi, a iloko o ka lima o ka poe imi i ko lakou ola; a e hahau mai no oia ia lakou i ka maka o ka pahikaua. Aole ia e hookoe ia lakou, aole e aloha mai, aole hoi e lokomaikai mai.
8 “Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
Ae olelo aku oe i keia poe kanaka, Ke olelo mai nei o Iehova penei, Aia hoi, ke kau nei au imua o oukou i ka aoao o ke ola, a me ka aoao o ka make.
9 Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
O ka mea e noho ma keia kulanakauhale, e make no ia i ka pahikaua, a me ka wi, a me ka mai ahulau; aka, o ka mea puka aku iwaho, a haule aku i ko Kaledea, ka poe e hoopilikia ana ia oukou, e ola no ia, a e koe no kona ola i waiwaipio nona iho.
10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
No ka mea, ua hooku e au i ko'u maka i keia kulanakauhale, ma ka hewa, aole ma ka maikai, wahi a Iehova; a e haawiia ia iloko o ka lima o ke alii o Babulona, a e puhi oia i keia wahi i ke ahi.
11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
E hoolohe oukou i ka olelo a Iehova, no ka hale o ke alii o ka Iuda.
12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
E ko ka hale o Davida, ke i mai nei o Iehova peneia, E hana oukou i ka hooponopono i kakahiaka, a e hoopakele i ka mea i haoia, mai ka lima aku o ka mea hookaumaha, o puka aku ko'u ukiuki, e like me ke ahi, a e a hoi, aole mea e hiki ia ia ke kinai, no ka hewa o ka oukou hana ana.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
Aia hoi, ua ku e no wau ia oe, e ka mea noho ma ke awawa, a ma ka pohaku o ka papu hoi, wahi a Iehova, ka poe olelo, Owai la ka mea iho ilalo e ku e ia makou? Owai la ka mea e komo iloko o ko makou wahi noho ai?
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”
Aka, e hoopai aku au ia oukou, e like me ka hua o ka oukou hana ana, wahi a Iehova; a e puhi no wau i ke ahi iloko o kolaila ululaau, a e hoopau no ia i na mea a pau, a puni ia wahi.