< Jeremiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
La parole qui vint à Jérémie de par l’Éternel, lorsque le roi Sédécias envoya vers lui Pashkhur, fils de Malkija, et Sophonie, fils de Maascéïa, le sacrificateur, disant:
2 “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
Consulte, je te prie, l’Éternel à notre égard, car Nebucadretsar, roi de Babylone, nous fait la guerre; peut-être que l’Éternel agira pour nous selon toutes ses merveilles et que [Nebucadretsar] montera d’auprès de nous.
3 Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
Et Jérémie leur dit: Vous direz ainsi à Sédécias:
4 ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
Ainsi dit l’Éternel, le Dieu d’Israël: Voici, je retourne en arrière les instruments de guerre qui sont en vos mains, avec lesquels vous combattez en dehors des murailles contre le roi de Babylone et contre les Chaldéens qui vous assiègent, et je les rassemblerai au-dedans de cette ville.
5 Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
Et moi je combattrai contre vous avec une main étendue, et avec un bras puissant, et avec colère, et avec fureur, et avec un grand courroux;
6 Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
et je frapperai les habitants de cette ville, et les hommes et les bêtes; ils mourront d’une grande peste.
7 Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
Et après cela, dit l’Éternel, je livrerai Sédécias, roi de Juda, et ses serviteurs, et le peuple, savoir ceux qui, dans cette ville, seront demeurés de reste de la peste, de l’épée et de la famine, en la main de Nebucadretsar, roi de Babylone, et en la main de leurs ennemis, et en la main de ceux qui cherchent leur vie; et il les frappera au tranchant de l’épée; il ne les épargnera pas, et n’en aura pas compassion et n’en aura pas pitié.
8 “Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
Et tu diras à ce peuple: Ainsi dit l’Éternel: Voici, je mets devant vous le chemin de la vie et le chemin de la mort.
9 Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
Celui qui demeurera dans cette ville mourra par l’épée, et par la famine, et par la peste; et celui qui en sortira et se rendra aux Chaldéens qui vous assiègent vivra et aura sa vie pour butin.
10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
Car j’ai mis ma face contre cette ville, pour le mal et non pour le bien, dit l’Éternel; elle sera livrée en la main du roi de Babylone, et il la brûlera par le feu.
11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Et quant à la maison du roi de Juda, écoutez la parole de l’Éternel.
12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
Maison de David, ainsi dit l’Éternel: Jugez justement, le matin, et délivrez de la main de l’oppresseur celui qui est pillé, de peur que ma fureur ne sorte comme un feu et ne brûle, sans qu’il y ait personne pour l’éteindre, à cause de l’iniquité de vos actions.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
Voici, je suis contre toi, qui habites la vallée, le rocher de la plaine, dit l’Éternel; [contre] vous qui dites: Qui descendra contre nous, et qui viendra dans nos habitations?
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”
Et je vous punirai selon le fruit de vos actions, dit l’Éternel; et j’allumerai un feu dans sa forêt, et il consumera tout ce qui est autour d’elle.

< Jeremiah 21 >