< Jeremiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
The word which was maad of the Lord to Jeremye, whanne king Sedechie sente to hym Phassur, the sone of Helchie, and Sofonye, the preest, the sone of Maasie, and seide,
2 “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
Axe thou the Lord for vs, for Nabugodonosor, the kyng of Babiloyne, fiytith ayens vs; if in hap the Lord do with vs bi alle hise merueilis, and he go awei fro vs.
3 Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
And Jeremye seide to hem, Thus ye schulen seie to Sedechie,
4 ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
The Lord God of Israel seith these thingis, Lo! Y schal turne the instrumentis of batel that ben in youre hondis, and with which ye fiyten ayens the king of Babiloyne, and ayens Caldeis, that bisegen you in the cumpas of wallis; and Y schal gadere tho togidere in the myddis of this citee.
5 Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
And Y schal ouercome you in hond stretchid forth, and in strong arm, and in stronge veniaunce, and indignacioun, and in greet wraththe;
6 Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
and Y schal smyte the dwelleris of this citee, men and beestis schulen die bi greet pestilence.
7 Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
And after these thingis, seith the Lord, Y schal yyue Sedechie, kyng of Juda, and hise seruauntis, and his puple, and that ben left in this citee fro pestilence, and swerd, and hungur, in the hond of Nabugodonosor, kyng of Babiloyne, and in the hond of her enemyes, and in the hond of men sekynge the lijf of hem; and he schal smyte hem bi the scharpnesse of swerd; and he schal not be bowid, nether schal spare, nether schal haue mercy.
8 “Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
And thou schalt seie to this puple, The Lord God seith these thingis, Lo! Y yyue bifore you the weie of lijf, and the weie of deth.
9 Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
He that dwellith in this citee, schal die bi swerd, and hungur, and pestilence; but he that goith out, and fleeth ouer to Caldeis that bisegen you, schal lyue, and his lijf schal be as a prey to hym.
10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
For Y haue set my face on this citee in to yuel, and not in to good, seith the Lord; it schal be youun in the hond of the king of Babiloyne, and he schal brenne it with fier.
11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
And thou schalt seie to the hous of the king of Juda, the hous of Dauid, Here ye the word of the Lord.
12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
The Lord seith these thingis, Deme ye eerli doom, and delyuere ye hym that is oppressid bi violence fro the hond of the fals chalenger; lest perauenture myn indignacioun go out as fier, and be kyndlid, and noon be that quenche, for the malice of youre studies.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
Lo! Y to thee, dwelleresse of the sad valei and pleyn, seith the Lord, which seien, Who schal smyte vs, and who schal entre in to oure housis?
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”
And Y schal visite on you bi the fruyt of youre studies, seith the Lord; and Y schal kyndle fier in the forest therof, and it schal deuoure alle thingis in the cumpas therof.

< Jeremiah 21 >