< Jeremiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
The word which came unto Jeremiah from the Lord, when king Zedekiah sent unto him Pashchur the son of Malkiyah, and Zephanyah the son of Ma'asseyah the priest, saying,
2 “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
Inquire, I pray thee, in our behalf of the Lord; for Nebuchadrezzar the king of Babylon maketh war against us; peradventure the Lord will deal with us according to all his wondrous deeds, so that he may withdraw from us.
3 Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
Then said Jeremiah unto them, Thus shall ye say to Zedekiah:
4 ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
Thus hath said the Lord the God of Israel, Behold, I will turn back the weapons of war that are in your hands, wherewith ye fight against the king of Babylon, and against the Chaldeans, who besiege you without the walls, and I will assemble them into the midst of this city.
5 Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
And I myself will fight against you with an outstretched hand and with a strong arm, and in anger, and in fury, and in great wrath.
6 Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
And I will smite the inhabitants of this city, both man and beast: of a great pestilence shall they die.
7 Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
And afterward, saith the Lord, will I give up Zedekiah the king of Judah, and his servants, and the people, and those that are left in this city from the pestilence, from the sword, and from the famine, into the hand of Nebuchadrezzar the king of Babylon, and into the hand of their enemies, and into the hand of those that seek their life: and he shall smite them with the edge of the sword; he will not spare them, nor have pity, nor have mercy.
8 “Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
And unto this people shalt thou say, Thus hath said the Lord, Behold, I set before you the way of life, and the way of death.
9 Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
He that remaineth in this city shall die by the sword, or by the famine, or by the pestilence; but he that goeth out, and runneth away to the Chaldeans that besiege you, shall remain alive, and his life shall be unto him as a booty.
10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
For I have set my face against this city for evil, and not for good, saith the Lord: into the hand of the king of Babylon shall it be given up, and he will burn it with fire.
11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
And to the house of the king of Judah [say], Hear ye the word of the Lord:
12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
O house of David, thus hath said the Lord, Exercise justice on [every] morning, and deliver him that is robbed out of the hand of the oppressor; lest my fury go forth like fire, and burn so that none can quench it, because of the evil of your doings.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
Behold, I am against thee, O inhabitress of the valley, [about] the rock of the plain, saith the Lord; who say, Who shall descend down against us? or who shall enter into our habitations?
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”
But I will inflict punishment on you according to the fruit of your doings, saith the Lord: and I will kindle a fire in its forest, and it shall devour all its environs.

< Jeremiah 21 >