< Jeremiah 21 >

1 Ọ̀rọ̀ Olúwa sì tọ Jeremiah wá nígbà tí ọba Sedekiah rán Paṣuri ọmọ Malkiah àti àlùfáà Sefaniah ọmọ Maaseiah sí i; wọ́n wí pé:
Slovo, kteréž se stalo k Jeremiášovi od Hospodina, když poslal k němu král Sedechiáš Paschura syna Malkiášova a Sofoniáše syna Maaseiášova, kněze, aby řekli:
2 “Wádìí lọ́wọ́ Olúwa fún wa nítorí Nebukadnessari ọba Babeli ń kọlù wá. Bóyá Olúwa yóò ṣe ìyanu fún wa gẹ́gẹ́ bí ti àtẹ̀yìnwá, kí ó sì yípadà kúrò lọ́dọ̀ wa.”
Poraď se medle o nás s Hospodinem, nebo Nabuchodonozor král Babylonský bojuje proti nám, zdali by snad naložil Hospodin s námi podlé všech divných skutků svých, aby on odtáhl od nás.
3 Ṣùgbọ́n Jeremiah dáhùn wí pé, “Sọ fún Sedekiah,
Tedy řekl Jeremiáš k nim: Tak rcete Sedechiášovi:
4 ‘Èyí ni Olúwa, Ọlọ́run Israẹli wí, Èmi fẹ́ kọjú idà tí ó wà lọ́wọ́ yín sí yín, èyí tí ẹ̀ ń lò láti bá ọba àti àwọn ará Babeli tí wọ́n wà lẹ́yìn odi jà, Èmi yóò sì kó wọn jọ sínú ìlú yìí.
Takto praví Hospodin Bůh Izraelský: Aj, já odvrátím nástroje válečné, kteréž jsou v rukou vašich, jimiž vy bojujete proti králi Babylonskému a Kaldejským, kteříž oblehli vás vně za zdí, a shromáždím je do prostřed města tohoto.
5 Èmi gan an yóò sì bá yín jà pẹ̀lú ohun ìjà olóró nínú ìbínú àti ìrunú líle.
Bojovati zajisté budu já proti vám rukou vztaženou a ramenem silným, a to v hněvě a v rozpálení i v prchlivosti veliké.
6 Èmi yóò sì lu gbogbo ìlú yìí, ènìyàn àti ẹranko, gbogbo wọn ni àjàkálẹ̀-ààrùn yóò kọlù tí wọn yóò sì kú.
A raním obyvatele města tohoto, tak že lidé i hovada morem velikým pomrou.
7 Olúwa sọ pé lẹ́yìn èyí, èmi yóò fi Sedekiah ọba Juda, àti àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀, àti àwọn ènìyàn, àti àwọn tí ó kù ní ìlú yìí lọ́wọ́ àjàkálẹ̀-ààrùn àti lọ́wọ́ idà, àti lọ́wọ́ ìyàn; èmi yóò fi wọ́n lé Nebukadnessari ọba Babeli lọ́wọ́, àti lé ọwọ́ àwọn ọ̀tá wọn, àti lé ọwọ́ àwọn tí ń lépa ẹ̀mí wọn, òun yóò sì fi ojú idà pa wọ́n, kì yóò sì dá wọn sí, bẹ́ẹ̀ ni kì yóò ní ìyọ́nú tàbí ṣàánú wọn.’
Potom pak (dí Hospodin), dám Sedechiáše krále Judského a služebníky jeho i lid, totiž ty, kteříž pozůstanou v městě tomto po moru, po meči a po hladu, v ruku Nabuchodonozora krále Babylonského, a v ruku nepřátel jejich, a tak v ruku hledajících bezživotí jejich. Kterýžto je zbije ostrostí meče, neodpustí jim, aniž jich šanovati bude, aniž se smiluje.
8 “Síwájú sí i, sọ fún àwọn ènìyàn, ‘Èyí ni ọ̀rọ̀ Olúwa tí ó sọ: Wò ó, Èmi ń fi ọ̀nà ìyè àti ikú hàn yín.
Protož rci lidu tomuto: Takto praví Hospodin: Aj, já kladu před vás cestu života i cestu smrti.
9 Ẹnikẹ́ni tí ó bá dúró sí ìlú yìí yóò ti ipa idà, ìyàn tàbí àjàkálẹ̀-ààrùn kú. Ṣùgbọ́n ẹni tí ó bá jáde tí ó sì jọ̀wọ́ ara rẹ̀ fún àwọn Babeli tí ó ń lépa yín yóò sì yè. Òun yóò sá àsálà fún ẹ̀mí rẹ̀.
Kdokoli zůstane v městě tomto, zahyne od meče, neb hladem, neb morem, ale kdož vyjde a poddá se Kaldejským, kteříž oblehli vás, jistotně živ zůstane, a bude míti život svůj místo kořisti.
10 Mo ti pinnu láti jẹ ìlú yìí ní yà, ni Olúwa wí. A ó sì gbé e fún ọba Babeli, yóò sì run ún pẹ̀lú iná.’
Nebo postavil jsem zůřivou tvář svou proti městu tomuto k zlému, a ne k dobrému, dí Hospodin. V ruku krále Babylonského vydáno bude, i vypálí je ohněm.
11 “Ẹ̀wẹ̀, wí fún ìdílé ọba Juda pé, ‘Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa.
Domu pak krále Judského rci: Slyšte slovo Hospodinovo,
12 Ilé Dafidi èyí ni ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ: “‘Ṣe ìdájọ́ tí ó tọ́ ní àràárọ̀; yọ ọ́ kúrò lọ́wọ́ ẹni tí ó ń ni í lára ẹni tí a ti jà lólè bí bẹ́ẹ̀ kọ́ ìbínú mi yóò jáde síta, yóò sì jó bí iná. Nítorí ibi tí a ti ṣe yóò sì jó láìsí ẹni tí yóò pa á.
Ó dome Davidův, takto praví Hospodin: Držívejte každého jitra soud, a vychvacujte obloupeného z ruky násilníka, aby nevyšla jako oheň prchlivost má, a nehořela, tak že by nebylo žádného, kdo by uhasiti mohl, pro nešlechetnost předsevzetí vašich.
13 Mo kẹ̀yìn sí ọ, Jerusalẹmu, ìwọ tí o gbé lórí àfonífojì lórí òkúta tí ó tẹ́jú, ni Olúwa wí. Ìwọ tí o ti wí pé, “Ta ni ó le dojúkọ wá? Ta ni yóò wọ inú ibùgbé wa?”
Aj já, dí Hospodin, na tebe, kteráž přebýváš v údolí tomto, skálo roviny této, kteříž říkáte: Kdo by přitáhl na nás, aneb kdo by všel do příbytků našich?
14 Èmi yóò jẹ ọ ní ìyà gẹ́gẹ́ bí iṣẹ́ ọwọ́ rẹ̀ ni Olúwa wí. Èmi yóò mú kí iná jó ilé rẹ̀; yóò si jó gbogbo ohun tí ó wà ní àyíká rẹ.’”
Nebo trestati vás budu podlé skutků vašich, dí Hospodin, a zanítím oheň v lese tvém, kterýž zžíře všecko vůkol něho.

< Jeremiah 21 >