< Jeremiah 10 >

1 Gbọ́ ọ̀rọ̀ tí Olúwa sọ fún yín ẹ̀yin ilé Israẹli.
Słuchajcie słowa tego, które Pan mówi do was, o domie Izraelski!
2 Báyìí ni Olúwa wí: “Má ṣe kọ́ ìwà àwọn kèfèrí, kí àmì ọ̀run kí ó má sì dààmú yín, nítorí pé wọ́n ń dààmú orílẹ̀-èdè.
Tak mówi Pan: Drogi pogańskiej nie uczcie się, a zanamion niebieskich nie bójcie się; bo się ich poganie boją.
3 Nítorí pé asán ni àṣà àwọn ènìyàn, wọ́n gé igi láti inú igbó, oníṣọ̀nà sì gbẹ́ ẹ pẹ̀lú àáké rẹ̀.
Ustawy zaiste tych narodów są wierutna marność; bo uciąwszy drzewo siekierą w lesie, dzieło rąk rzemieślnika,
4 Wọ́n fi fàdákà àti wúrà ṣe é lọ́ṣọ̀ọ́. Wọ́n fi òòlù kàn án àti ìṣó kí ó má ba à ṣubú.
Srebrem i złotem ozdabia je, gwoździami i młotami utwierdza je, aby się nie ruchało.
5 Wọ́n wé mọ́ igi bí ẹ̀gúnsí inú oko, òrìṣà wọn kò le è fọhùn. Wọ́n gbọdọ̀ máa gbé wọn nítorí pé wọn kò lè rìn. Má ṣe bẹ̀rù wọn; wọn kò le è ṣe ibi kankan bẹ́ẹ̀ ni wọn kò si lè ṣe rere kan.”
Stoją prosto jako palma, a nie mówią; noszone być muszą, bo chodzić nie mogą. Nie bójcie się ich; bo źle czynić nie mogą, i dobrze czynić nie mogą.
6 Kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ Olúwa; o tóbi orúkọ rẹ sì tóbi lágbára.
Żaden z tych nie jest tobie podobny, Panie! wielkiś ty, i wielkie jest imię twoje w mocy.
7 Ta ni kò yẹ kí ó bẹ̀rù rẹ? Ọba àwọn orílẹ̀-èdè? Nítorí tìrẹ ni. Láàrín àwọn ọlọ́gbọ́n ènìyàn ní orílẹ̀-èdè àti gbogbo ìjọba wọn, kò sí ẹni tí ó dàbí rẹ.
Któżby się ciebie nie bał? Królu narodów! Tobie to zaiste należy, ponieważ między wszystkimi mędrcami narodów, i we wszystkich królestwach ich nigdy nie był podobny tobie.
8 Gbogbo wọn jẹ́ aláìlóye àti aṣiwèrè, wọ́n ń kọ́ ẹ̀kọ́ àwọn ère igi tí kò níláárí.
A wszakże społem zgłupieli i poszaleli; z drewna brać naukę, jest wierutna marność.
9 Fàdákà tí a ti kàn ni a mú wá láti Tarṣiṣi, àti wúrà láti Upasi. Èyí tí àwọn oníṣọ̀nà àti alágbẹ̀dẹ ṣe tí wọ́n kùn ní àwọ̀ aró àti elése àlùkò, èyí jẹ́ iṣẹ́ ọwọ́ àwọn ọlọ́gbọ́n oníṣọ̀nà.
Srebro ciągnione z zamorza przywożone bywa, a złoto z Ufas, dzieło rzemieślnicze, i ręki złotnika; hijacynt i szarłat odzienie ich, wszystko to jest dzieło umiejętnych.
10 Ṣùgbọ́n Olúwa ni Ọlọ́run tòótọ́, òun ni Ọlọ́run alààyè, ọba ayérayé. Nígbà tí ó bá bínú, ayé yóò wárìrì; orílẹ̀-èdè kò lè fi ara da ìbínú rẹ̀.
Ale Pan jest Bóg prawy, jest Bóg żywy, i król wieczny; przed jego zapalczywością ziemia drży, a narody nie mogą znieść rozgniewania jego.
11 “Sọ èyí fún wọn: ‘Àwọn ọlọ́run kéékèèké tí kò dá ọ̀run àti ayé ni yóò ṣègbé láti ayé àti ní abẹ́ ọ̀run.’”
Tak im tedy powiecie: Bogowie ci, którzy nieba i ziemi nie stworzyli, niech zginą z ziemi, a niech ich nie będzie pod niebem.
12 Ọlọ́run dá ayé pẹ̀lú agbára rẹ̀, ó dá àgbáyé pẹ̀lú ọgbọ́n rẹ̀, ó mú kí ọ̀run kí ó fẹ̀ síta nípa òye rẹ̀.
Ale on uczynił ziemię mocą swą; on utwierdził okrąg świata mądrością swoją, i roztropnością swoją rozciągnął niebiosa.
13 Nígbà tí ó bá sán àrá, àwọn omi lọ́run a sì pariwo; ó mú kí ìkùùkuu ru sókè láti òpin ayé. Ó rán mọ̀nàmọ́ná pẹ̀lú òjò, ó sì ń mú afẹ́fẹ́ wá láti ilé ìṣúra rẹ̀.
Gdy on wydaje głos, szum wód bywa na niebie, i to sposabia, aby występowały pary z krajów ziemi; błyskawice z deszczem przywodzi, a wywodzi wiatry z skarbów swoich.
14 Gbogbo ènìyàn jẹ́ aṣiwèrè àti aláìnímọ̀, ojú ti gbogbo alágbẹ̀dẹ níwájú ère rẹ̀, nítorí ère dídá rẹ̀ èké ni, kò sì ṣí ẹ̀mí nínú rẹ̀.
Tak zgłupiał każdy człowiek, że tego nie zna, iż pohańbiony bywa każdy rzemieślnik dla bałwana; bo fałszem jest to, co ulał, i niemasz ducha w nich.
15 Asán ni wọ́n, iṣẹ́ ìṣìnà; nígbà ìbẹ̀wò wọn, wọn yóò ṣègbé.
Marnością są, a dziełem błędów; czasu nawiedzenia swego poginą.
16 Ẹni tí ó bá jẹ́ ìpín Jakọbu kò sì dàbí èyí, nítorí òun ni ó ṣẹ̀dá ohun gbogbo àti Israẹli tí ó jẹ́ ẹ̀yà ìjogún rẹ̀. Olúwa àwọn ọmọ-ogun ni orúkọ rẹ̀.
Nie jest tym podobien dział Jakóbowy, bo on jest stworzyciel wszystkiego; Izrael także jest prętem dziedzictwa jego, Pan zastępów jest imię jego.
17 Kó ẹrù rẹ kúrò láti fi ilẹ̀ náà sílẹ̀ ìwọ tí o ń gbé ní ìlú tí a dó tì.
Zbierz z ziemi towary twoje, ty, która mieszkasz na miejscu obronnem.
18 Nítorí èyí ni Olúwa wí: “Ní àkókò yìí, èmi yóò gbọn àwọn tí ó ń gbé ilẹ̀ náà jáde. Èmi yóò mú ìpọ́njú bá wọn, kí wọn kí ó lè rí wọn mú.”
Bo tak mówi Pan: Oto Ja jako z procy ugodzę obywateli ziemi jednym razem, i udręczę, aby tego doznali i rzekli:
19 Ègbé ni fún mi nítorí ìpalára mi! Ọgbẹ́ mi jẹ́ èyí tí kò lè sàn, bẹ́ẹ̀ ni mọ sọ fún ara mi, “Èyí ni àìsàn mi, mo sì gbọdọ̀ fi orí tì í.”
Biada mnie nad zniszczeniem mojem: bolesna jest rana moja, chociażem był rzekł: Zaiste tę niemoc będę mógł znieść.
20 Àgọ́ mi bàjẹ́, gbogbo okùn rẹ̀ sì já. Àwọn ọmọ mi ti lọ lọ́dọ̀ mi, wọn kò sì sí mọ́, kò sí ẹnìkankan tí yóò na àgọ́ mi ró mọ́, tàbí yóò ṣe ibùgbé fún mi.
Namiot mój zburzony jest, i wszystkie powrozy moje porwane są; synowie moi poszli odemnie, i niemasz ich; niemasz, ktoby więcej rozbijał namiot mój, a rozciągał opony moje.
21 Àwọn olùṣọ́-àgùntàn jẹ́ aṣiwèrè, wọn kò sì wá Olúwa: nítorí náà wọn kì yóò ṣe rere àti pé gbogbo agbo wọn ni yóò túká.
Bo pasterze zgłupieli, a Pana się nie dokładali; dlatego nie powodzi się im szczęśliwie, a wszystka trzoda pastwiska ich rozproszona jest.
22 Fetísílẹ̀! ariwo igbe ń bọ̀, àti ìdàrúdàpọ̀ ńlá láti ilẹ̀ àríwá wá! Yóò sì sọ ìlú Juda di ahoro, àti ihò ọ̀wàwà.
Oto wieść pewna przychodzi, a wzruszenie wielkie z ziemi północnej, aby obrócone były miasta Judzkie w pustynie, i w mieszkanie smoków.
23 Èmi mọ̀ Olúwa wí pé ọ̀nà ènìyàn kì í ṣe ti ara rẹ̀, kì í ṣe fún ènìyàn láti tọ́ ìgbésẹ̀ ara rẹ̀.
Wiem, Panie! że nie jest w mocy człowieka droga jego, ani jest w mocy męża tego, który chodzi, aby sprawował postępki swe.
24 Tún mi ṣe Olúwa, pẹ̀lú ìdájọ́ nìkan kí o má sì ṣe é nínú ìbínú rẹ, kí ìwọ má ṣe sọ mí di òfo.
Karz mię, Panie! ale łaskawie, nie w gniewie swym, byś mię snać wniwecz nie obrócił.
25 Tú ìbínú rẹ jáde sórí àwọn orílẹ̀-èdè tí kò mọ̀ ọ́n, sórí àwọn ènìyàn tí wọn kò pe orúkọ rẹ. Nítorí pé wọ́n ti jẹ Jakọbu run, wọ́n ti jẹ ẹ́ run pátápátá, wọ́n sì sọ ibùgbé rẹ̀ di ahoro.
Wylej popędliwość twoję na te narody, które cię nie znają, i na rodzaje, które imienia twego nie wzywają; bo jedzą Jakóba, i pożerają go, aby go wszystkiego strawili, i mieszkanie jego w pustki obrócili.

< Jeremiah 10 >