< Isaiah 1 >

1 Ìran sí Juda àti Jerusalẹmu èyí tí Isaiah ọmọ Amosi rí ní àsìkò ìjọba Ussiah, Jotamu, Ahasi àti Hesekiah àwọn ọba Juda.
Widzenie Izajasza, syna Amosowego, które widział nad Judą i nad Jeruzalemem, za dni Ozeasza, Joatama, Achaza, i Ezechijasza, królów Judzkich.
2 Gbọ́ ẹ̀yin ọ̀run! Fi etí sílẹ̀, ìwọ ayé! Nítorí Olúwa ti sọ̀rọ̀: “Mo tọ́ àwọn ọmọ dàgbà, ṣùgbọ́n wọ́n ti ṣọ̀tẹ̀ sí mi.
Słuchajcie niebiosa, a ty ziemio przyjmij w uszy swe! Albowiem Pan mówi: Synówem wychował i wywyższył; ale oni odstąpili odemnie.
3 Màlúù mọ olówó rẹ̀, kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ sì mọ ibùjẹ olówó rẹ̀, ṣùgbọ́n Israẹli kò mọ̀, òye kò yé àwọn ènìyàn mi.”
Zna wół gospodarza swego, i osieł żłób pana swego; ale Izrael mię nie zna, lud mój nie zrozumiewa.
4 Á à! Orílẹ̀-èdè ẹlẹ́ṣẹ̀, àwọn ènìyàn tí ẹ̀bi ẹ̀ṣẹ̀ ń pa lẹ́rù, ìran àwọn aṣebi, àwọn ọmọ tó ti di aṣèbàjẹ́! Wọn ti kọ Olúwa sílẹ̀ wọn ti gan Ẹni Mímọ́ Israẹli, wọn sì ti kẹ̀yìn sí i.
Biada narodowi grzesznemu, ludowi obciążonemu nieprawością, nasieniu złośliwych; synom skażonym! Opuścili Pana, do gniewu pobudzili świętego Izraelskiego, odwrócili się nazad.
5 Èéṣe tí a ó fi tún lù yín mọ́? Èéṣe tí ẹ ò dẹ́kun ọ̀tẹ̀ ṣíṣe? Gbogbo orí yín jẹ́ kìkì ọgbẹ́, gbogbo ọkàn yín sì ti pòruurù.
Przeczże tem więcej przyczyniacie przestępstwa, im więcej was biją? Wszystka głowa chora, i wszystko serce mdłe.
6 Láti àtẹ́lẹsẹ̀ yín dé àtàrí yín kò sí àlàáfíà rárá, àyàfi ọgbẹ́ òun ìfarapa àti ojú egbò, tí a kò nù kúrò tàbí kí á dì tàbí kí a kùn ún ní òróró.
Od stopy nogi aż do wierzchu głowy niemasz na nim nic całego; rana i siność, i rany zagniłe nie są wyciśnione, ani zawiązane, ani olejkiem odmiękczone.
7 Orílẹ̀-èdè yín dahoro, a dáná sun àwọn ìlú yín, oko yín ni àwọn àjèjì ti jẹ run lójú ara yín náà, ni gbogbo rẹ̀ ṣòfò bí èyí tí àwọn àjèjì borí rẹ̀.
Ziemia wasza spustoszona, miasta wasze popalone ogniem. Ziemię waszę cudzoziemcy przed wami pożerają i pustoszą, jako zwykli cudzoziemcy.
8 Ọmọbìnrin Sioni ni a fi sílẹ̀ gẹ́gẹ́ bí àtíbàbà nínú ọgbà àjàrà, gẹ́gẹ́ bí abà nínú oko ẹ̀gúnsí, àti bí ìlú tí a dó tì.
I została córka Syońska jako chłodnik na winnicy, jako budka w ogrodzie ogórczanym, i jako miasto zburzone.
9 Àyàfi bí Olúwa àwọn ọmọ-ogun bá ṣẹ́ díẹ̀ kù fún wà, a ò bá ti rí bí Sodomu, a ò bá sì ti dàbí Gomorra.
By nam był Pan zastępów nie zostawił trochy ostatków, bylibyśmy jako Sodoma, stalibyśmy się byli Gomorze podobnymi.
10 Gbọ́ ọ̀rọ̀ Olúwa, ẹ̀yin aláṣẹ Sodomu, tẹ́tí sí òfin Ọlọ́run wa, ẹ̀yin ènìyàn Gomorra!
Słuchajcie słowa Pańskiego, książęta Sodemscy! przyjmujcie w uszy zakon Boga naszego, ludzie Gomorscy!
11 “Ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín kín ni ọ̀pọ̀lọpọ̀ ẹbọ yín jásí fún mi?” ni Olúwa wí. “Mo ti ní ànító àti àníṣẹ́kù ẹbọ sísun ti àgbò àti ọ̀rá ẹran àbọ́pa, Èmi kò ní inú dídùn nínú ẹ̀jẹ̀ akọ màlúù, ti àgùntàn àti ti òbúkọ.
Cóż mi po mnóstwie ofiar waszych? mówi Pan. Jużem syty całopalenia baranów, i łoju tłustego bydła; a krwi cielców, i baranków, i kozłów nie pragnę.
12 Nígbà tí ẹ wá farahàn níwájú mi, ta ni ó béèrè èyí lọ́wọ́ yín, gìrì gìrì ẹsẹ̀ nínú àgbàlá mi?
Gdy przychodzicie, abyście się okazywali przed twarzą moją, któż tego żądał z rąk waszych, abyście deptali sieni moje?
13 Ẹ má mú ọrẹ asán wá mọ́! Ìríra ni tùràrí yín jásí fún mi, oṣù tuntun àti ọjọ́ ìsinmi àti àwọn àpéjọ, Èmi kò lè faradà á, ẹ̀ṣẹ̀ ni àpéjọ yín wọ̀nyí.
Nie ofiarujcież więcej ofiary daremnej. Kadzenie jest mi obrzydłością; nowiu miesiąca i sabatu, gdy zwoływacie zgromadzenia, nie mogę ścierpieć (bo nieprawością jest) ani dnia zapowiedzianego.
14 Ayẹyẹ oṣù tuntun yín àti àjọ̀dún tí a yàn, ni ọkàn mi kórìíra. Wọ́n ti di àjàgà sí mi ní ọrùn, Ó sú mi láti fi ara dà wọ́n.
Nowych miesięcy waszych, i uroczystych świąt waszych nienawidzi dusza moja; stały mi się ciężarem; upracowałem się nosząc je.
15 Nígbà tí ẹ bá tẹ́ ọwọ́ yín sókè ni àdúrà, Èmi yóò fi ojú mi pamọ́ fún un yín, kódà bí ẹ bá gba ọ̀pọ̀lọpọ̀ àdúrà, Èmi kò ni tẹ́tí sí i. “Ọwọ́ yín kún fún ẹ̀jẹ̀.
Przetoż gdy wyciągniecie ręce wasze, skryję oczy moje przed wami; a gdy rozmnożycie modlitwę, nie wysłucham; bo ręce wasze krwi są pełne.
16 “Wẹ̀ kí ẹ sì jẹ́ kí ara yín mọ́. Ẹ mú ìwà ibi yín kúrò níwájú mi! Dáwọ́ àìṣedéédéé dúró,
Omyjcie się, czystymi bądźcie, odejmijcie złość uczynków waszych od oczów moich; przestańcie źle czynić.
17 kọ́ láti ṣe rere! Wá ìdájọ́ òtítọ́, tu àwọn tí a ń pọ́n lójú nínú. Ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, gbà ẹjọ́ opó rò.
Uczcie się dobrze czynić; szukajcie sądu, podźwignijcie uciśnionego, sąd czyńcie sierocie, ujmujcie się o krzywdę wdowy.
18 “Ẹ wá ní ìsinsin yìí, ẹ jẹ́ kí a jọ ṣàṣàrò,” ni Olúwa wí. “Bí ẹ̀ṣẹ̀ yín bá rí bí osùn, wọn ó sì funfun bí i yìnyín, bí wọn bá sì pọ́n bí ẹ̀jẹ̀, wọn ó sì dàbí ẹ̀gbọ̀n òwú.
Przyjdźcież teraz, a rozpierajmy się z sobą, mówi Pan: Choćby były grzechy wasze jako szarłat, jako śnieg zbieleją; choćby były czerwone jako karmazyn, jako wełna białe będą.
19 Tí ẹ̀yin bá fẹ́, tí ẹ sì gbọ́rọ̀, ẹ̀yin yóò sì jẹ ojúlówó adùn ilẹ̀ náà.
Będziecieli powolni, a posłuchacie mię, dóbr ziemi pożywać będziecie.
20 Ṣùgbọ́n tí ẹ bá kọ̀ tí ẹ sì ṣọ̀tẹ̀, idà ni a ó fi pa yín run.” Nítorí ẹnu Olúwa la ti sọ ọ́.
Lecz jeźli nie będziecie posłusznymi, ale odpornymi, od miecza pożarci będziecie; bo usta Pańskie mówiły.
21 Wo bí ìlú òtítọ́ ṣe di àgbèrè! Ó ti kún fún ìdájọ́ òtítọ́ nígbà kan rí, òdodo ń gbé ibẹ̀ tẹ́lẹ̀ rí, ṣùgbọ́n báyìí àwọn apànìyàn!
Jakoć się stało nierządnicą to miasto wierne, pełne sądu? Sprawiedliwość mieszkała w niem; lecz teraz mężobójcy.
22 Fàdákà rẹ ti di ìpẹ́pẹ́, ààyò wáìnì rẹ la ti bu omi là.
Srebro twoje obróciło się w żużeł; wino twoje pomięszało się z wodą.
23 Ọlọ̀tẹ̀ ni àwọn aláṣẹ yín, akẹgbẹ́ àwọn olè, gbogbo wọn ló fẹ́ràn àbẹ̀tẹ́lẹ̀ wọ́n sì ń wá ẹ̀bùn kiri. Wọ́n kì í ṣàtìlẹyìn fún ẹ̀tọ́ aláìní baba, ẹjọ́ opó kì í sì í dé iwájú wọn.
Książęta twoi są uporni, i towarzysze złodziei; każdy z nich miłuje dary, a jadą za nagrodą; sierocie nie czynią sprawiedliwości, a sprawa wdowy nie przychodzi przed nich.
24 Nítorí náà ni Olúwa, Olúwa àwọn ọmọ-ogun, alágbára kan ṣoṣo tí Israẹli sọ wí pé: “Á à! Èmi yóò ní ìfọ̀kànbalẹ̀ lórí àwọn ọ̀tá mi n ó sì gbẹ̀san lára àwọn ọ̀tá mi.
Przetoż mówi Pan, Pan zastępów, możny Izraelski: Oto ucieszę się nad nieprzyjaciółmi moimi, a pomszczę się nad przeciwnikami swymi.
25 Èmi yóò pa ọwọ́ mi dà sí ọ, èmi ó sì ku ìpẹ́pẹ́ rẹ dànù, n ó sì mú gbogbo ìdọ̀tí rẹ kúrò.
I obrócę rękę moję na cię, a wypalę aż do czysta zużelicę twoję, i odpędzę wszystkę cenę twoję.
26 Èmi yóò mú àwọn adájọ́ rẹ bọ̀ sí ipò gẹ́gẹ́ bí i ti àtijọ́, àti àwọn olùdámọ̀ràn rẹ̀ bí i ti ìbẹ̀rẹ̀ pẹ̀pẹ̀. Lẹ́yìn náà ni a ó pè ọ ní ìlú òdodo, ìlú òtítọ́.”
A przywrócę sędziów twoich, jako przedtem byli, i radców twoich, jako na początku. Potem cię nazywać będą miastem sprawiedliwości, miastem wiernem.
27 A ó fi ìdájọ́ òtítọ́ ra Sioni padà, àti àwọn tí ó ronúpìwàdà pẹ̀lú òdodo.
Syon w sądzie okupione będzie, a ci, co się do niego nawrócą, w sprawiedliwości.
28 Ṣùgbọ́n àwọn ọlọ̀tẹ̀ àti àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ni a ó parun. Àwọn tí ó bá sì kọ Olúwa sílẹ̀ ni yóò ṣègbé.
Ale przewrotnicy i grzesznicy wespół starci będą, a ci, co opuścili Pana, zniszczeją.
29 “Ojú yóò tì yín nítorí igi óákù mímọ́ èyí tí ẹ ní inú dídùn sí, a ó kàn yín lábùkù nítorí àwọn ọgbà yìí tí ẹ ti yàn fúnra yín.
Albowiem zawstydzeni będziecie dla gajów, którycheście pożądali; i pohańbieni dla ogrodów, któreście sobie obrali.
30 Ẹ ó sì dàbí igi óákù tí ewé rẹ̀ ti rọ, bí ọgbà tí kò ní omi.
Gdy się staniecie jako dąb, z którego liście opadły, a jako ogród, w którym wody niemasz.
31 Alágbára ọkùnrin náà yóò sì dàbí ohun ìdáná, iṣẹ́ rẹ̀ bí ẹ̀ṣẹ́-iná, àwọn méjèèjì ni yóò jóná papọ̀, láìsí ẹni tí yóò lè pa iná yìí.”
I będzie mocarz jako zgrzebia, a ten, który go uczynił, jako iskra; i zapalą się oboje pospołu, a nie będzie, ktoby zagasił.

< Isaiah 1 >