< Isaiah 7 >

1 Nígbà tí Ahasi ọmọ Jotamu ọmọ Ussiah jẹ́ ọba Juda, ọba Resini ti Aramu àti Peka ọmọ Remaliah ọba Israẹli gòkè wá láti bá Jerusalẹmu jà, ṣùgbọ́n wọn kò sì le è borí i rẹ̀.
Hĩndĩ ĩrĩa Ahazu mũrũ wa Jothamu, mũrũ wa Uzia, aarĩ mũthamaki wa Juda-rĩ, Rezini mũthamaki wa Suriata marĩ na Peka mũrũ wa Remalia mũthamaki wa Isiraeli, makĩambata mathiĩ magatharĩkĩre itũũra rĩa Jerusalemu, no matiigana kũrĩtooria.
2 Báyìí, a sọ fún ilé Dafidi pé, “Aramu mà ti lẹ̀dí àpò pọ̀ mọ́ Efraimu”; fún ìdí èyí, ọkàn Ahasi àti àwọn ènìyàn rẹ̀ wárìrì gẹ́gẹ́ bí igi oko ṣe ń wárìrì níwájú afẹ́fẹ́.
Na rĩrĩ, andũ a nyũmba ya Daudi nĩ meerirwo atĩrĩ, “Andũ a Suriata nĩmanyiitanĩte na andũ a Efiraimu”; nĩ ũndũ ũcio ngoro ya Ahazu o na ngoro cia andũ ake ikĩinaina o ta ũrĩa mĩtĩ ya mũtitũ ĩinainagio nĩ rũhuho.
3 Lẹ́yìn èyí, Olúwa sọ fún Isaiah pé, “Jáde, ìwọ àti ọ̀dọ́mọkùnrin rẹ Ṣeari-Jaṣubu láti pàdé Ahasi ní ìpẹ̀kun ìṣàn omi ti adágún òkè, ní òpópó ọ̀nà tí ó lọ sí pápá Alágbàfọ̀.
Hĩndĩ ĩyo Jehova akĩĩra Isaia atĩrĩ, “Umagara, wee mũrĩ na mũrũguo Sheari-Jashubu, mũthiĩ mũgatũnge Ahazu mũthia-inĩ wa mũtaro ũrĩa uumĩte Karia-inĩ ka Rũgongo, njĩra-inĩ ya gũthiĩ Gĩthaka kĩa Mũthambia-Nguo.
4 Sọ fún un, ‘Ṣọ́ra à rẹ, fi ọkàn balẹ̀, kí o má ṣe bẹ̀rù. Má ṣe ba ọkàn jẹ́ nítorí kùkùté igi ìdáná méjèèjì yìí, nítorí ìbínú gbígbóná Resini àti Aramu àti ti ọmọ Remaliah.
Ũmwĩre atĩrĩ, ‘Wĩmenyerere, ũikare ũhooreire na ndũgetigĩre. Ndũkareke ũũrwo nĩ hinya nĩ ũndũ wa icinga icio igĩrĩ iratooga ndogo; ndũgetigĩre marakara mahiũ ma Rezini, na ma Suriata, o na ma mũrũ wa Remalia.
5 Aramu, Efraimu àti Remaliah ti dìtẹ̀ ìparun rẹ, wọ́n wí pé,
Suriata, na Efiraimu, na mũrũ wa Remalia nĩmaciirĩire gũkwananga, makoiga atĩrĩ,
6 “Jẹ́ kí a kọlu Juda; jẹ́ kí a fà á ya pẹ́rẹpẹ̀rẹ, kí a sì pín in láàrín ara wa, kí a sì fi ọmọ Tabeli jẹ ọba lórí i rẹ̀.”
“Nĩtũtharĩkĩre Juda, tũkũnyariire na tũkũgayane, na tũtue mũrũ wa Tabeeli mũthamaki wakuo.”
7 Síbẹ̀ èyí ni ohun tí Olúwa Olódùmarè wí: “‘Èyí kò ní wáyé èyí kò le ṣẹlẹ̀,
No rĩrĩ, Mwathani Jehova ekuuga atĩrĩ: “‘Ũhoro ũcio ndũgaakinyanĩra, na ndũgekĩka,
8 nítorí Damasku ni orí Aramu, orí Damasku sì ni Resini. Láàrín ọdún márùnlélọ́gọ́ta Efraimu yóò ti fọ́ tí kì yóò le jẹ́ ènìyàn mọ́.
nĩgũkorwo itũũra inene rĩa Suriata nĩ Dameski, na mũnene wa Dameski no Rezini. Ihinda rĩa mĩaka mĩrongo ĩtandatũ na ĩtano ĩtaanathira-rĩ, andũ a Efiraimu magaakorwo maharaganĩtio ũndũ matangĩcooka gũtuĩka rũrĩrĩ.
9 Orí Efraimu sì ni Samaria, orí Samaria sì ni ọmọ Remaliah. Bí ẹ̀yin kí yóò bá gbàgbọ́, lóòtítọ́, a kì yóò fi ìdí yín múlẹ̀.’”
Ningĩ itũũra inene rĩa Efiraimu nĩ Samaria, na mũnene wa Samaria no mũrũ wa Remalia. Mũngĩaga kũrũgama mũrũmĩte wega wĩtĩkio-inĩ wanyu-rĩ, mũtikehaanda o na atĩa.’”
10 Bákan náà Olúwa tún bá Ahasi sọ̀rọ̀,
Ningĩ Jehova nĩarĩirie Ahazu o rĩngĩ, akĩmwĩra atĩrĩ,
11 “Béèrè fún àmì lọ́wọ́ Olúwa Ọlọ́run rẹ, bóyá ní ọ̀gbun tí ó jì jùlọ tàbí àwọn òkè tí ó ga jùlọ.” (Sheol h7585)
“Ĩtia kĩmenyithia kuuma kũrĩ Jehova Ngai waku, o na kiumĩte kũndũ kũrĩa kũriku mũno, kana kiumĩte igũrũ kũrĩa kũraihu mũno.” (Sheol h7585)
12 Ṣùgbọ́n Ahasi sọ pé, “Èmi kì yóò béèrè; Èmi kò ní dán Olúwa wò.”
No Ahazu akiuga atĩrĩ, “Niĩ ndigwĩtia; niĩ ndikũgeria Jehova.”
13 Lẹ́yìn náà Isaiah sọ pé, “Gbọ́ ní ìsinsin yìí, ìwọ ilé Dafidi, kò ha tọ́ láti tán ènìyàn ní sùúrù, ìwọ yóò ha tan Ọlọ́run ní sùúrù bí?
Ningĩ Isaia akiuga atĩrĩ, “Ta iguai rĩu, inyuĩ andũ a nyũmba ya Daudi! Anga mũkuona arĩ ũndũ mũnini kũgeria ũkirĩrĩria wa andũ? Anga nĩmũũkũgeria ũkirĩrĩria wa Ngai wakwa o naguo?
14 Nítorí náà, Olúwa fúnra ara rẹ̀ ni yóò fún ọ ní àmì kan. Wúńdíá kan yóò lóyún, yóò sì bí ọmọkùnrin kan, yóò sì pe orúkọ rẹ̀ ní Emmanueli.
Nĩ ũndũ ũcio-rĩ, Mwathani we mwene nĩakamũhe kĩmenyithia: Nĩgũkorwo mũirĩtu gathirange nĩakagĩa nda aciare kahĩĩ, nake agatue Imanueli.
15 Òun yóò jẹ wàrà àti oyin nígbà tí ó bá ní ìmọ̀ tó láti kọ ẹ̀bi àti láti yan rere.
Iria imata na ũũkĩ nĩcio gakarĩĩaga rĩrĩa gakaamenya kũrega ũũru na gwĩthuurĩra maũndũ marĩa mega.
16 Ṣùgbọ́n kí ọ̀dọ́mọkùnrin náà tó mọ bí a ti ń kọ ẹ̀bi àti láti yan rere, ilẹ̀ àwọn ọba méjèèjì tí ń bà ọ́ lẹ́rù wọ̀nyí yóò ti di ahoro.
No mbere ya kahĩĩ kau kũmenya kũrega ũũru na gwĩthuurĩra maũndũ marĩa mega-rĩ, bũrũri ũcio wa athamaki acio eerĩ wĩtigĩrĩte nĩũkanangwo.
17 Olúwa yóò mú àsìkò mìíràn wá fún ọ àti àwọn ènìyàn rẹ àti lórí ilé baba rẹ irú èyí tí kò sí láti ìgbà tí Efraimu ti yà kúrò ní Juda, yóò sì mú ọba Asiria wá.”
Jehova nĩagakũrehithĩria wee mwene na andũ aku, o na andũ a nyũmba ya thoguo maũndũ matarĩ moneka kuuma rĩrĩa Efiraimu aatiganire na Juda; Jehova akaarehera mũthamaki wa Ashuri.”
18 Ní ọjọ́ náà ni Olúwa yóò súfèé pe àwọn eṣinṣin láti àwọn odò tó jìnnà ní Ejibiti wá, àti fún àwọn oyin láti ilẹ̀ Asiria.
Hĩndĩ ĩyo Jehova nĩakahuuhĩra ngi mĩrũri, aciĩte kuuma tũrũũĩ-inĩ twa kũraya twa bũrũri wa Misiri, na eete njũkĩ iria irĩ bũrũri wa Ashuri.
19 Gbogbo wọn yóò sì wá dó sí gẹ̀rẹ́gẹ̀rẹ́ òkè àti pàlàpálá òkúta, lára koríko ẹ̀gún àti gbogbo ibi ihò omi.
Nacio ciothe nĩcigooka ciikare iharũrũka-inĩ cia mĩkuru, na mĩatũka-inĩ ya ndwaro cia mahiga, na ihinga-inĩ ciothe cia mĩigua, na marima-inĩ mothe ma maaĩ.
20 Ní ọjọ́ náà, Olúwa yóò lo abẹ fífẹ́lẹ́ tí a yá láti ìkọjá odò Eufurate, ọba Asiria, láti fá irun orí àti ti àwọn ẹsẹ̀ ẹ yín, àti láti mú irùngbọ̀n yín kúrò pẹ̀lú.
Mũthenya ũcio Mwathani nĩakahũthĩra rwenji rũkomboretwo kuuma mũrĩmo wa Rũũĩ rwa Farati; naruo nĩruo mũthamaki wa Ashuri; nake nĩakenja mĩtwe yanyu na njuĩrĩ cia magũrũ manyu, o na ningĩ enje nderu cianyu.
21 Ní ọjọ́ náà, ọkùnrin kan yóò máa sin ọ̀dọ́ abo màlúù kan àti ewúrẹ́ méjì.
Mũthenya ũcio, mũndũ akaarĩithia o moori ĩmwe na ngʼondu igĩrĩ.
22 Àti nítorí ọ̀pọ̀lọpọ̀ wàrà tí wọn yóò máa fún un, yóò ní wàràǹkàṣì láti jẹ. Gbogbo àwọn tí ó bá kù ní ilẹ̀ náà yóò jẹ wàràǹkàṣì àti oyin.
Na tondũ wa ũingĩ wa iria rĩrĩa igaakamagwo-rĩ, mũndũ ũcio akaanyuuaga iria imata. Arĩa othe magaatigara kũu bũrũri ũcio makaanyuuaga iria imata, na marĩĩage ũũkĩ.
23 Ní ọjọ́ náà, ni gbogbo ibi tí àjàrà tí ó tó ẹgbẹ̀rún ṣékélì fàdákà, ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n nìkan ni yóò wà níbẹ̀.
Mũthenya ũcio, kũndũ kũrĩa guothe kwarĩ mĩthabibũ 1,000 ĩngĩendirio cekeri 1,000 ya betha, gũgaakũra o congʼe na mĩtĩ ya mĩigua.
24 Àwọn ènìyàn yóò máa lọ síbẹ̀ pẹ̀lú ọrun àti ọfà nítorí pé ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n ni yóò bo gbogbo ilẹ̀ náà.
Andũ magaathiiaga kuo marĩ na ũta na mĩguĩ, nĩgũkorwo bũrũri ũcio ũkaiyũra congʼe, na mĩtĩ ya mĩigua.
25 Àti ní orí àwọn òkè kéékèèké tí a ti ń fi ọkọ́ ro nígbà kan rí, ẹ kò ní lọ síbẹ̀ mọ́ nítorí ìbẹ̀rù ẹ̀gún àti ẹ̀wọ̀n, wọn yóò di ibi tí a ń da màlúù lọ, àti ibi ìtẹ̀mọ́lẹ̀ fún àwọn àgùntàn kéékèèké.
Nakuo irĩma-inĩ guothe kũrĩa kwanarĩmwo na icembe, mũtigacooka gũthiĩ nĩ ũndũ wa gwĩtigĩra congʼe, na mĩtĩ ya mĩigua; kũndũ kũu gũgaatuĩka gwa kũrĩithagio ngʼombe, na gwa kũrangagwo nĩ ndũũru cia ngʼondu.

< Isaiah 7 >