< Isaiah 6 >

1 Ní ọdún tí ọba Ussiah kú, mo rí Olúwa tí ó jókòó lórí ìtẹ́ tí ó ga tí a gbé sókè, ìṣẹ́tí aṣọ ìgúnwà rẹ̀ sì kún inú tẹmpili.
Na rĩrĩ, mwaka ũrĩa Mũthamaki Uzia aakuire-rĩ, nĩguo ndonire Mwathani aikarĩire gĩtĩ kĩa ũnene, kĩrĩ igũrũ na gĩtũũgĩrĩtio, nayo nguo yake yaiyũrĩte hekarũ nĩ ũndũ wa ũrĩa yaraihĩte.
2 Àwọn Serafu wà ní òkè rẹ̀, ọ̀kọ̀ọ̀kan wọn ní ìyẹ́ mẹ́fà, wọ́n fi ìyẹ́ méjì bo ojú wọn, wọ́n fi méjì bo ẹsẹ̀ wọn, wọ́n sí ń fi méjì fò.
Igũrũ wake kwarũgamĩte aserafi, na o mũserafi ũmwe aarĩ na mathagu matandatũ: nao makehumbĩra mothiũ mao na mathagu meerĩ, namo meerĩ makehumbĩra magũrũ namo, na meerĩ makombũka namo.
3 Wọ́n sì ń kọ sí ara wọn wí pé, “Mímọ́, mímọ́, mímọ́ ni Olúwa àwọn ọmọ-ogun gbogbo ayé kún fún ògo rẹ̀.”
Nao metanaga makerana atĩrĩ: “Jehova Mwene-Hinya-Wothe nĩwe mũtheru, ĩĩ nĩwe mũtheru, ti-itherũ nĩwe mũtheru; thĩ yothe ĩiyũrĩtwo nĩ riiri wake.”
4 Nípa ìró ohùn un wọn, òpó ìlẹ̀kùn àti gbogbo ògiri ilé náà sì mì tìtì, gbogbo inú tẹmpili sì kún fún èéfín.
Nĩ ũndũ wa mũrurumo wa mĩgambo yao, itugĩ cia mĩrango na hingĩro ciaguo ikĩenyenya, nayo hekarũ ĩkĩiyũra ndogo.
5 Mo kígbe pé, “Ègbé ni fún mi! Mo ti gbé!” Nítorí mo jẹ́ ènìyàn aláìmọ́ ètè, mo sì ń gbé láàrín àwọn ènìyàn aláìmọ́ ètè, ojú mi sì ti rí ọba, Olúwa àwọn ọmọ-ogun jùlọ.
Na niĩ ngĩanĩrĩra ngiuga atĩrĩ, “Hĩ! Kaĩ ndĩ na haaro-ĩ! Ndĩĩgũthira! Nĩgũkorwo ndĩ mũndũ wa mĩromo ĩtarĩ mĩtheru, o na ningĩ ndũũranagia na andũ matarĩ mĩromo mĩtheru, na maitho makwa nĩmonete Mũthamaki, o we Jehova Mwene-Hinya-Wothe.”
6 Nígbà náà ni ọ̀kan nínú àwọn Serafu wọ̀nyí fò wá sí ọ̀dọ̀ mi pẹ̀lú ẹ̀yín iná ní ọwọ́ rẹ̀, èyí tí ó ti fi ẹ̀mú mú ní orí pẹpẹ.
Hĩndĩ ĩyo mũserafi ũmwe akĩũmbũka, agĩũka harĩ niĩ akuuĩte ikara rĩa mwaki na guoko, rĩrĩa aarutĩte na mĩĩhato kĩgongona-inĩ.
7 Èyí ni ó fi kàn mí ní ẹnu tí ó sì wí pé, “Wò ó, èyí ti kan ètè rẹ; a ti mú ẹ̀bi rẹ kúrò, a sì ti wẹ ẹ̀ṣẹ̀ rẹ nù.”
Mũserafi ũcio akĩĩhutia kanua na ikara rĩu, akiuga atĩrĩ, “Kuona atĩ ikara rĩrĩ nĩrĩahutia mĩromo yaku, mahĩtia maku nĩmeherio, o namo mehia maku nĩmahoroherio.”
8 Nígbà náà ni mo sì gbọ́ ohùn Olúwa wí pé, “Ta ni èmi yóò rán? Ta ni yóò sì lọ fún wa?” Nígbà náà ni èmi sì wí pé, “Èmi nìyí, rán mi!”
Ningĩ ngĩigua mũgambo wa Mwathani ũkĩũria atĩrĩ, “Nũũ ngũtũma? Na nũũ ũgũthiĩ handũ haitũ?” Na niĩ ngĩcookia atĩrĩ, “Niĩ ũyũ haha. Ndũma!”
9 Òun sì wí pé, “Tọ àwọn ènìyàn yìí lọ kí o sì wí fún wọn pé, “‘Ní gbígbọ́ ẹ̀yin yóò gbọ́, kì yóò sì yé e yín; ní rí rí ẹ̀yin yóò ri, ẹ̀yin kì yóò mọ òye.’
Nake akĩnjĩĩra atĩrĩ, “Thiĩ ũkeere andũ aya atĩrĩ: “‘Inyuĩ tũũrai o mũiguaga no mũtikanamenye ũndũ; tũũrai muonaga no mũtikanakuũke.’
10 Mú kí àyà àwọn ènìyàn wọ̀nyí yigbì, mú kí etí wọn kí ó wúwo, kí o sì dìwọ́n ní ojú. Kí wọn kí ó má ba fi ojú wọn ríran, kí wọn kí ó má ba fi etí wọn gbọ́rọ̀, kí òye kí ó má ba yé ọkàn wọn, kí wọn kí ó má ba yípadà kí a má ba mú wọn ní ara dá.”
Tũma ngoro cia andũ aya ciũme, o na ũtũme matũ mao magĩe njiika mage kũigua, o na ũhinge maitho mao matige kuona. Tondũ maahota kuona na maitho mao, na maigue na matũ mao, na ngoro ciao igĩe na ũmenyo, macooke magarũrũke mahonio.”
11 Nígbà náà ni mo wí pé, “Báwo ni yóò ti pẹ́ tó Olúwa?” Òun sì dáhùn pé: “Títí àwọn ìlú ńlá yóò fi dahoro, láìsí olùgbé nínú rẹ̀ mọ́, títí tí àwọn ilé yóò fi wà láìsí ènìyàn, títí tí ilẹ̀ yóò fi dahoro pátápátá.
Na niĩ ngĩcooka ngĩũria atĩrĩ, “Mwathani, nĩ nginya rĩ?” Nake akĩnjookeria atĩrĩ: “Nĩ nginya hĩndĩ ĩrĩa matũũra marĩa manene magaakorwo maanangĩtwo na matarĩ na wa kũmatũũra, nacio nyũmba ikorwo ĩtiganĩirio, na mĩgũnda ĩkaanangwo na ĩgathũkio biũ,
12 Títí tí Olúwa yóò fi rán gbogbo wọn jìnnà réré tí ilẹ̀ náà sì di ìkọ̀sílẹ̀ pátápátá.
o nginya rĩrĩa Jehova agaakorwo atwarĩte andũ othe kũraya, naguo bũrũri ũgatiganĩrio biũ.
13 Bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé ìdámẹ́wàá ṣẹ́kù lórí ilẹ̀ náà, yóò sì tún pàpà padà di rírun. Ṣùgbọ́n gẹ́gẹ́ bí igi tẹrẹbinti àti igi óákù, ti í fi kùkùté sílẹ̀ nígbà tí a bá gé wọn lulẹ̀, bẹ́ẹ̀ gẹ́gẹ́ ni irúgbìn mímọ́ náà yóò di kùkùté ní ilẹ̀ náà.”
Na rĩrĩ, o na kũngĩkorwo kũrĩ na gĩcunjĩ gĩa ikũmi kĩa andũ gĩtigaire bũrũri-inĩ-rĩ, bũrũri ũcio no ũkaanangwo rĩngĩ. No rĩrĩ, o ta ũrĩa mũceneni na mũgandi ĩtigagio ithukĩ yatemwo-rĩ, ũguo noguo rũciaro rũrũ rwamũre rũgaatigario gĩtina kĩaruo bũrũri-inĩ ũcio.”

< Isaiah 6 >