< Isaiah 44 >

1 “Ṣùgbọ́n gbọ́ nísinsin yìí, ìwọ Jakọbu ìránṣẹ́ mi, àti Israẹli, ẹni tí mo ti yàn.
“No rĩrĩ, ta thikĩrĩria, wee Jakubu, ndungata yakwa, o we Isiraeli, ũrĩa niĩ thuurĩte.
2 Ohun tí Olúwa wí nìyìí ẹni tí ó dá ọ, ẹni tí ó ti mọ̀ ọ́n láti inú ìyá rẹ wá, àti ẹni tí yóò ràn ọ́ lọ́wọ́ pẹ̀lú. Má ṣe bẹ̀rù, ìwọ Jakọbu, ìránṣẹ́ mi, Jeṣuruni ẹni tí mo ti yàn.
Jehova, ũrĩa wakũũmbire na agĩgũthondeka ũrĩ nda ya maitũguo, o ũrĩa ũrĩgũteithagia, ekuuga atĩrĩ: Tiga gwĩtigĩra, wee Jakubu, ndungata yakwa, o nawe Jeshuruni, ũrĩa niĩ thuurĩte.
3 Nítorí èmi yóò da omi sí ilẹ̀ tí ń pòǹgbẹ àti àwọn odò ní ilẹ̀ gbígbẹ, Èmi yóò tú Ẹ̀mí mi sí ara àwọn ọmọ rẹ, àti ìbùkún mi sórí àwọn àrọ́mọdọ́mọ rẹ.
Nĩgũkorwo bũrũri ũrĩa mũngʼaru nĩngaũitĩrĩria maaĩ, nakuo kũndũ kũrĩa kũmũ nĩgũgathereraga tũrũũĩ; naruo rũciaro rwaku nĩngarũitĩrĩria Roho wakwa, nacio njiaro cianyu ndĩciitĩrĩrie kĩrathimo gĩakwa.
4 Wọn yóò dàgbàsókè gẹ́gẹ́ bí i koríko nínú pápá oko tútù, àti gẹ́gẹ́ bí igi Poplari létí odò tí ń sàn.
Nĩmakaingĩha o ta nyeki ya gĩtuamba ĩkunũkĩte, o na kana ta mĩtĩ ya mĩribina ĩrĩa ĩkũraga hũgũrũrũ-inĩ cia njũũĩ.
5 Ọ̀kan yóò wí pé, ‘Èmi jẹ́ ti Olúwa’; òmíràn yóò pe ara rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí orúkọ Jakọbu; bẹ́ẹ̀ ni òmíràn yóò kọ ọ́ sí ọwọ́ rẹ̀, ‘Ti Olúwa,’ yóò sì máa jẹ́ orúkọ náà Israẹli.
Mũndũ ũmwe nĩakoiga atĩrĩ, ‘Niĩ ndĩ wa Jehova’; nake ũrĩa ũngĩ akeĩtania na Jakubu; o nake ũngĩ eyandĩke guoko gwake atĩrĩ, ‘Ndĩ wa Jehova,’ na eetue rĩĩtwa rĩĩtanĩtio na Isiraeli.
6 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí ọba Israẹli àti Olùdáǹdè, àní Olúwa àwọn ọmọ-ogun. Èmi ni ẹni àkọ́kọ́ àti ẹni ìgbẹ̀yìn, lẹ́yìn mi kò sí Ọlọ́run kan.
“Atĩrĩrĩ, Mũthamaki wa Isiraeli na Mũkũũri wao, o we Jehova-Mwene-Hinya-Wothe, ekuuga atĩrĩ: Nĩ niĩ wa mbere na nĩ niĩ wa kũrigĩrĩria, gũtirĩ Ngai ũngĩ tiga niĩ.
7 Ta ni ó dàbí ì mi? Jẹ́ kí o kéde rẹ̀. Jẹ́ kí ó wí kí ó sì gbé síwájú mi kí ni ó ti ṣẹlẹ̀ láti ìgbà tí mo fi ìdí àwọn ènìyàn ìṣẹ̀ǹbáyé kalẹ̀, àti kí ni ohun tí ń sì ń bọ̀, bẹ́ẹ̀ ni, jẹ́ kí ó sọ àsọtẹ́lẹ̀ ohun tí ń bọ̀ wá.
Nũũ ũkĩhaana ta niĩ? Nĩarekwo oimbũre ũhoro ũcio. Nĩaheane ũhoro ũcio na oimbũre arĩ mbere yakwa, ũrĩa gwatariĩ kuuma rĩrĩa ndoombire andũ akwa a tene, na onanie ũrĩa gũgaikara thuutha-inĩ; ĩĩ, nĩakĩrathe ũhoro wa maũndũ marĩa magooka.
8 Má ṣe wárìrì, má ṣe bẹ̀rù. Ǹjẹ́ èmi kò ti kéde èyí tí mo sì ti sọ àsọtẹ́lẹ̀ rẹ̀ tipẹ́tipẹ́? Ẹ̀yin ni ẹlẹ́rìí mi. Ǹjẹ́ Ọlọ́run kan ha ń bẹ lẹ́yìn mi? Bẹ́ẹ̀ kọ́, kò sí àpáta mìíràn; Èmi kò mọ ọ̀kankan.”
Tigai kũinaina, o na kana mwĩtigĩre. Githĩ ndioimbũrire maũndũ maya, na ngĩratha ũhoro ũyũ kuuma o tene? Inyuĩ nĩ inyuĩ aira akwa. Nĩ kũrĩ Ngai ũngĩ tiga niĩ? Aca, gũtirĩ rwaro rũngĩ rwa Ihiga, niĩ ndirĩ ũngĩ njũũĩ.”
9 Gbogbo àwọn tí ń gbẹ́ ère jásí asán, àti àwọn ohun tí wọn ń kó pamọ́ kò jámọ́ nǹkan kan. Àwọn tí yóò sọ̀rọ̀ fún wọn fọ́ lójú; wọ́n jẹ́ aláìmọ̀kan sí ìtìjú ara wọn.
Andũ arĩa othe mathondekaga mĩhianano ya kũhooywo nĩ a tũhũ, na indo iria meriragĩria mũno itirĩ bata. Andũ arĩa mangĩaria ithenya rĩao nĩ atumumu; gũtirĩ ũndũ mamenyaga, ũguo nĩguo ũmaconorithagia.
10 Ta ni ó mọ òrìṣà kan tí ó sì ya ère, tí kò lè mú èrè kankan wá fún un?
Nũũ wacũhagia mũhianano wa kũhooywo, o na ageturĩra mũhianano wa gũtwekio ũrĩa ũtangĩmũguna?
11 Òun àti nǹkan rẹ̀ wọ̀nyí ni a ó dójútì; àwọn oníṣọ̀nà kò yàtọ̀, ènìyàn ni wọ́n. Jẹ́ kí gbogbo wọn gbárajọ kí wọ́n sì fi ìdúró wọn hàn; gbogbo wọn ni a ó mú bọ́ sínú ìpayà àti àbùkù.
We na arĩa macihooyaga nĩmagaconorithio; mabundi o nao no andũ matarĩ kĩene. Othe nĩmongane hamwe na matue itua; nao nĩmakanyiitwo nĩ guoya mũnene na maconorithio.
12 Alágbẹ̀dẹ mú ohun èlò, ó fi ń ṣiṣẹ́ nínú èédú; ó fi òòlù ya ère kan, ó ṣe é pẹ̀lú agbára apá rẹ̀, ebi ń pa á, àárẹ̀ sì mú un; kò mu omi rárá, ìrẹ̀wẹ̀sì dé bá a.
Mũturi wa igera ooyaga kĩndũ kĩa wĩra, na agakĩrutĩra wĩra agagĩcina na makara; agathondeka ngai ya mũhianano na nyondo, akaũtura na hinya wa guoko gwake. Mũndũ ũcio ahũũtaga, akoorwo nĩ hinya; akaga kũnyua maaĩ, akaringĩka.
13 Gbẹ́nàgbẹ́nà fi ìwọ̀n wọ́n ọ́n ó sì fi lẹ́ẹ̀dì ṣe àmì sí ara rẹ̀, Ó tún fi ìfà fá a jáde ó tún fi òsùwọ̀n ṣe àmì sí i. Ó gbẹ́ ẹ ní ìrí ènìyàn gẹ́gẹ́ bí ènìyàn nínú ògo rẹ̀, kí ó lè máa gbé nínú ilé òrìṣà.
Mũtharamara aigaga rũrigi rwa kũrũngaria mũhari, agacooka agakurura na karamu; mũhianano ũcio egũthondeka akaũhũũra randa, ningĩ akaũthima gĩthiũrũrĩ, na agacooka kũwacũhia wega ũhaanane na mũhianĩre wa mũndũ, o ta mũndũ ũrĩ na riiri wake wothe, nĩgeetha ũtũũre ihooero-inĩ rĩaguo.
14 Ó gé igi kedari lulẹ̀, tàbí bóyá ó mú sípírẹ́ṣì tàbí igi óákù. Ó jẹ́ kí ó dàgbà láàrín àwọn igi inú igbó, ó sì le gbin igi páínì, èyí tí òjò mú kí ó dàgbà.
Mũndũ aatemire mĩtarakwa, na agĩĩthuurĩra mũkarakaba kana mũgandi. Akĩreka ũkũranĩre na mĩtĩ ĩrĩa ĩngĩ ya mũtitũ, kana akĩhaanda mũthengera, nayo mbura ĩkĩũkũria.
15 Ohun èlò ìdáná ni fún ènìyàn; díẹ̀ nínú rẹ̀ ni ó mú láti mú kí ara rẹ̀ lọ́wọ́ọ́rọ́, ó dá iná ó sì fi ṣe àkàrà. Ṣùgbọ́n bákan náà ni ó ṣe òrìṣà tí ó sì ń sìn ín; ó yá ère, ó sì ń foríbalẹ̀ fún un.
Mũtĩ ũcio nĩ wa kuunwo ngũ; oyaga imwe agaakia mwaki, agoota, no iria ingĩ agaakia mwaki, akaruga mĩgate. Ningĩ gĩcunjĩ kĩmwe agethondekera ngai ya mũhianano, akamĩhooyaga. Ĩĩ ti-itherũ, athondekaga mũhianano mũicũhie akaũinamagĩrĩra.
16 Ìlàjì igi náà ni ó jó nínú iná; lórí i rẹ̀ ni ó ti ń tọ́jú oúnjẹ rẹ̀, ó dín ẹran rẹ̀ ó sì jẹ àjẹyó. Ó tún mú ara rẹ̀ gbóná ó sì sọ pé, “Á à! Ara mi gbóná, mo rí iná.”
Nuthu ya ngũ agaakia mwaki nacio; akarugĩra irio ciake ho, na akahĩhĩria nyama ciake ho, akarĩa, akahũũna. Ningĩ agoota mwaki, akoiga atĩrĩ, “Hĩ! Nĩndaigua ũrugarĩ; nĩndona mwaki.”
17 Nínú èyí tí ó kù ni ó ti ṣe òrìṣà, ère rẹ̀; ó foríbalẹ̀ fún un, ó sì sìn ín. Ó gbàdúrà sí i, ó wí pé, “Gbà mí, ìwọ ni Ọlọ́run mi.”
Ngũ iria ciatigara agathondeka ngai, mũhianano wake wa kũhooya; akaũinamĩrĩra na akaũturĩria maru. Akaũhooya, akoiga atĩrĩ, “Honokia; wee nĩwe ngai yakwa.”
18 Wọn kò mọ nǹkan kan, nǹkan kan kò yé wọn; a fi ìbòjú bo ojú wọn, wọn kò lè rí nǹkan kan; bẹ́ẹ̀ ni àyà wọn sébọ́, wọn kò lè mọ nǹkan kan.
Matirĩ ũndũ mooĩ, na matirĩ ũndũ mamenyaga; maitho mao nĩmahumbĩre, nĩ ũndũ ũcio matingĩona, na meciiria mao nĩmahingĩtwo makaaga kũmenya maũndũ.
19 Kò sí ẹni tí ó dúró láti ronú, kò sí ẹni tí ó ní ìmọ̀ tàbí òye láti sọ wí pé, “Ìlàjì rẹ̀ ni mo fi dáná; mo tilẹ̀ ṣe àkàrà lórí èédú rẹ̀, mo dín ẹran, mo sì jẹ ẹ́. Ǹjẹ́ ó wá yẹ kí n ṣe ohun ìríra kan nínú èyí tí ó ṣẹ́kù bí? Ǹjẹ́ èmi yóò ha foríbalẹ̀ fún ìtì igi?”
Gũtirĩ mũndũ ũkiraga ageciiria, gũtirĩ mũndũ ũrĩ na ũũgĩ kana ũmenyo oige atĩrĩ, “Nuthu ya ngũ ndahũthĩrire na gwakia mwaki; o na ngĩrugĩra mĩgate makara-inĩ macio, na ngĩcooka ngĩhĩhia nyama na ngĩrĩa. Ti-itherũ no ngĩthondeke kĩndũ kĩrĩ magigi kuuma kũrĩ ngũ iria itigaire? Ti-itherũ no nyinamĩrĩre gĩcunjĩ kĩa mũtĩ?”
20 Ó ń jẹ eérú, ọkàn ẹlẹ́tàn ni ó ṣì í lọ́nà; òun kò lè gba ara rẹ̀ là, tàbí kí ó wí pé, “Ǹjẹ́ nǹkan tí ó wà lọ́wọ́ ọ̀tún mi yìí irọ́ kọ́?”
Arĩĩaga mũhu, ahĩtithĩtio nĩ ngoro ĩrĩa ĩheenekete; ndangĩhota kwĩhonokia, kana oige atĩrĩ, “Githĩ kĩndũ gĩkĩ kĩrĩ guoko gwakwa kwa ũrĩo ti maheeni?”
21 “Rántí àwọn nǹkan wọ̀nyí, ìwọ Jakọbu, nítorí ìránṣẹ́ mi ni ìwọ, ìwọ Israẹli. Èmi ti dá ọ, ìránṣẹ́ mi ni ìwọ ṣe, ìwọ Israẹli, Èmi kì yóò gbàgbé rẹ.
“Ririkana maũndũ maya, wee Jakubu, o wee Isiraeli, tondũ ũrĩ ndungata yakwa. Nĩ niĩ ndakũũmbire, wee ũrĩ ndungata yakwa; atĩrĩ, wee Isiraeli, ndikaariganĩrwo nĩwe.
22 Èmi ti gbá gbogbo ìkùnà rẹ dànù bí i kurukuru, àwọn ẹ̀ṣẹ̀ rẹ bí ìrì òwúrọ̀. Padà sọ́dọ̀ mi, nítorí mo ti rà ọ́ padà.”
Nĩnjeheretie mahĩtia maku magathira biũ, o ta ũrĩa itu rĩa mbura rĩthiraga, mehia maku ngamaniina ta kĩbii kĩa rũciinĩ. Njookerera tondũ nĩngũkũũrĩte.”
23 Kọrin fáyọ̀, ẹ̀yin ọ̀run, nítorí Olúwa ló ti ṣe èyí; kígbe sókè, ìwọ ilẹ̀ ayé nísàlẹ̀. Bú sí orin, ẹ̀yin òkè ńlá, ẹ̀yin igbó àti gbogbo igi yín, nítorí Olúwa ti ra Jakọbu padà, ó ti fi ògo rẹ̀ hàn ní Israẹli.
Wee igũrũ ina nĩ gũkena, nĩgũkorwo nĩ Jehova wĩkĩte ũndũ ũcio; nawe thĩ ũrĩ rungu rwa igũrũ-rĩ, anĩrĩra. Na inyuĩ irĩma-rĩ, inai rwĩmbo, o na inyuĩ mĩtitũ na mĩtĩ yanyu yothe inai, nĩgũkorwo Jehova nĩakũũrĩte Jakubu, na akoonania riiri wake kũu Isiraeli.
24 “Ohun tí Olúwa wí nìyìí Olùràpadà rẹ tí ó mọ ọ́ láti inú ìyá rẹ wá: “Èmi ni Olúwa tí ó ti ṣe ohun gbogbo tí òun nìkan ti na àwọn ọ̀run tí o sì tẹ́ ayé pẹrẹsẹ òun tìkára rẹ̀,
“Jehova, Mũkũũri waku, ũrĩa wakũũmbĩire nda ya maitũguo, ekuuga atĩrĩ: “Niĩ nĩ niĩ Jehova ũrĩa wombire indo ciothe, ũrĩa watambũrũkirie igũrũ ndĩ nyiki, ũrĩa waaraganirie thĩ ndĩ nyiki,
25 ta ni ó ba àmì àwọn wòlíì èké jẹ́ tí ó sì sọ àwọn aláfọ̀ṣẹ di òmùgọ̀, tí ó dojú ìmọ̀ àwọn ọlọ́gbọ́n délẹ̀ tí ó sì sọ wọ́n di òmùgọ̀,
nĩ niĩ ngiragĩrĩria ciama cia anabii a maheeni, nao aragũri ngamatua irimũ, ningĩ ngagarũra ũũgĩ wa arĩa oogĩ, ngaũtua ũrimũ mũtheri.
26 ẹni tí ó gbé ọ̀rọ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ jáde tí ó sì mú àsọtẹ́lẹ̀ àwọn ìránṣẹ́ rẹ wá sí ìmúṣẹ, “ẹni tí ó wí nípa ti Jerusalẹmu pé, ‘A ó máa gbé inú rẹ̀,’ àti ní ti àwọn ìlú Juda, ‘A ó tún kọ́,’ àti àwọn ahoro rẹ̀, ‘Èmi yóò mú un bọ̀ sípò,’
Nĩ niĩ njĩkagĩra ciugo cia ndungata ciakwa hinya, na ngahingia ũrathi wa atũmwo akwa, na ha ũhoro wa Jerusalemu ngoiga atĩrĩ, ‘Nĩrĩgatũũrwo,’ na ha ũhoro wa matũũra ma Juda ngoiga atĩrĩ, ‘Nĩmagaakwo,’ o na kũndũ gwakuo kũrĩa kwanangĩtwo ngoiga atĩrĩ, ‘Nĩngagũcookereria.’
27 ta ni ó sọ fún omi jíjìn pé, ‘Ìwọ gbẹ, èmi yóò sì mú omi odò rẹ gbẹ,’
Nĩ niĩ njĩĩraga maaĩ ma kũrĩa kũriku atĩrĩ, ‘Hũai, na nĩngahũithia tũrũũĩ twanyu.’
28 ta ni ó sọ nípa Kirusi pé, ‘Òun ni Olùṣọ́-àgùntàn mi àti pé òun yóò ṣe ohun gbogbo tí mo fẹ́; òun yóò sọ nípa Jerusalẹmu pé, “Jẹ́ kí a tún kọ́,” àti nípa tẹmpili, “Jẹ́ kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lé ilẹ̀.”’”
Nĩ niĩ njugaga ũhoro wa Mũthamaki Kurusu atĩrĩ, ‘Nĩwe mũrĩithi wa mbũri ciakwa, na nĩwe ũkaahingia ũrĩa wothe nyendaga wĩkwo; Nĩakoiga ũhoro wa Jerusalemu atĩrĩ, “Nĩrĩakwo,” na ha ũhoro wa hekarũ oige atĩrĩ, “Mĩthingi yayo nĩyakwo.”’”

< Isaiah 44 >