< Isaiah 34 >
1 Súnmọ́ tòsí, ẹ̀yin orílẹ̀-èdè láti gbọ́, tẹ́tí sílẹ̀ ẹ̀yin ènìyàn jẹ́ kí ayé gbọ́, àti ẹ̀kún rẹ̀, ayé àti ohun gbogbo tí ó ti inú rẹ̀ jáde.
Kommer nær, I Hedninger! for at høre, og I Folk! giver Agt; Jorden høre det, og dens Fylde, Jorderige og al dens Grøde!
2 Nítorí ìbínú Olúwa ń bẹ lára gbogbo orílẹ̀-èdè, àti ìrunú rẹ̀ lórí gbogbo ogun wọn: o ti fi wọ́n fún pípa.
Thi Herrens Vrede er over alle Hedningerne og hans Fortørnelse over al deres Hær; han har sat dem i Band, giver dem hen at slagtes.
3 Àwọn ti a pa nínú wọn ni a ó sì jù sóde, òórùn wọn yóò ti inú òkú wọn jáde, àwọn òkè ńlá yóò sì yọ̀ nínú ẹ̀jẹ̀ wọn.
Og deres ihjelslagne skulle henkastes, og Stanken af deres døde Kroppe skal stige op, og Bjergene skulle flyde af deres Blod.
4 Gbogbo àwọn ogun ọ̀run ni yóò di yíyọ́, a ó sì ká àwọn ọ̀run jọ bí i tákàdá, gbogbo ogun wọn yóò si ṣubú lulẹ̀, bí ewé ti n bọ́ kúrò lára àjàrà, àti bí i bíbọ́ èso lára igi ọ̀pọ̀tọ́.
Og Himmelens Hær skal svinde hen, og Himlene skulle rulles sammen som en Bog; og al deres Hær skal visne som et vissent Blad af et Vintræ og ligesom vissent Løv af et Figentræ.
5 Nítorí ti a rẹ idà mi ní ọ̀run, kíyèsi í, yóò sọ̀kalẹ̀ wá sórí Edomu, sórí àwọn ènìyàn tí mo ti parun fún ìdájọ́.
Thi mit Sværd er vædet i Himlene; se, til Dom skal det fare ned over Edom og over det Folk, som jeg har sat i Band.
6 Idà Olúwa kún fún ẹ̀jẹ̀ a mú un sanra fún ọ̀rá, àti fún ẹ̀jẹ̀ ọ̀dọ́-àgùntàn àti ewúrẹ́, fún ọ̀rá ìwé àgbò— nítorí Olúwa ni ìrúbọ kan ní Bosra, àti ìpakúpa ńlá kan ní ilẹ̀ Edomu.
Herrens Sværd er fuldt af Blod, er mættet af Fedme, af Lams og Bukkes Blod, af Vædres Nyrers Fedme; thi Herren har Slagtoffer i Bozra og en stor Slagtning i Edoms Land.
7 Àti àwọn àgbáǹréré yóò ba wọn sọ̀kalẹ̀ wá, àti àwọn ẹgbọrọ màlúù pẹ̀lú àwọn akọ màlúù, ilé wọn ni a ó fi ẹ̀jẹ̀ rin, a ó sì fi ọ̀rá sọ ekuru wọn di ọlọ́ràá.
Og Bøfler fældes tillige med dem, og Ungkvæg tillige med Tyre; og deres Land skal blive vædet af Blod og deres Jordbund mættes med Fedme.
8 Nítorí ọjọ́ ẹ̀san Olúwa ni, àti ọdún ìsanpadà, nítorí ọ̀ràn Sioni.
Thi det er Herrens Hævns Dag, Gengældelsens Aar for Zions Retssag.
9 Odò rẹ̀ ni a ó sì sọ di ọ̀dà, àti eruku rẹ̀ di imí-ọjọ́, ilẹ̀ rẹ̀ yóò sì di ọ̀dà tí ń jóná.
Og dets Bække skulle forvandles til Beg og dets Jordbund til Svovl, og dets Land skal blive til brændende Beg.
10 A kì yóò pa á ní òru tàbí ní ọ̀sán; èéfín rẹ̀ yóò gòkè láéláé: yóò dahoro láti ìran dé ìran, kò sí ẹnìkan tí yóò là á kọjá láé àti láéláé.
Det skal ikke slukkes Dag eller Nat, Røgen deraf skal stige op evindelig; det skal være øde fra Slægt til Slægt, fra Evighed til Evighed skal ingen gaa igennem det.
11 Òwìwí aginjù, àti àkàlà ni yóò ni ín, àti òwìwí àti ẹyẹ ìwò ni yóò máa gbé inú rẹ̀. Ọlọ́run yóò sì na sórí Edomu okùn ìwọ̀n ìparun àti òkúta òfo.
Men Rørdrum og Pindsvin skulle eje det, og Hornuglen og Ravnen skulle bo i det; thi han skal udstrække Maalesnoren over det, at det bliver øde, og veje det ud, at det skal blive Ørk.
12 Ní ti àwọn ìjòyè rẹ̀ ẹnìkan kì yóò sí níbẹ̀ tiwọn ó pè wá sí ìjọba, gbogbo àwọn olórí i rẹ̀ yóò sì di asán.
Af dets ædle er der ingen, man kan kalde til Konge; og alle dets Fyrster skulle blive til intet.
13 Ẹ̀gún yóò sì hù jáde nínú àwọn ààfin rẹ̀ wọ̀nyí, ẹ̀gún ọ̀gán nínú ìlú olódi rẹ̀. Yóò jẹ́ ibùgbé àwọn akátá àti àgbàlá fún àwọn òwìwí.
Og der skal opvokse Tjørn; paa dets Paladser, Nælder og Tidsler i dets Befæstninger; og det skal være Dragers Bolig, Strudsungers Gaard.
14 Àwọn ẹranko ijù àti àwọn ìkookò ni yóò pàdé, àti ewúrẹ́ igbó kan yóò máa kọ sí èkejì rẹ̀, iwin yóò máa gbé ibẹ̀ pẹ̀lú, yóò sì rí ibi ìsinmi fún ara rẹ̀.
Og Ørkens Vildt og Ulve skulle møde hverandre, og den ene Skovtrold skal raabe til den anden, kun Vætter skulle slaa sig til Ro der og finde Hvile for sig.
15 Òwìwí yóò tẹ́ ìtẹ́ rẹ̀ síbẹ̀, yóò yé, yóò sì pa, yóò sì kójọ lábẹ́ òjìji rẹ̀: àwọn gúnnugún yóò péjọ síbẹ̀ pẹ̀lú, olúkúlùkù pẹ̀lú ẹnìkejì rẹ̀.
Pilslangen skal bygge Rede der og lægge Æg og udklække Unger og samle dem under sin Skygge; kun Glenter flokkes der, den ene hos den anden.
16 Ẹ wo ìwé Olúwa, kí ẹ sì kà. Ọ̀kan nínú ìwọ̀nyí kì yóò yẹ̀, kò sí ọ̀kan tí yóò fẹ́ èkejì rẹ̀ kù: nítorí Olúwa ti pàṣẹ ẹnu rẹ̀ ló sì fi kó wọn jọ Ẹ̀mí rẹ̀ ló sì fi tò wọ́n jọ.
Søger i Herrens Bog og læser, der fattes ikke een af disse Ting, det ene savner ikke det andet; thi hans Mund har budet det, og hans Aand har sanket dem.
17 Ó ti di ìbò fún wọn, ọwọ́ rẹ̀ sì ti pín in fún wọn nípa títa okùn, wọn ó jogún rẹ̀ láéláé, láti ìran dé ìran ni wọn ó máa gbé inú rẹ̀.
Og han har kastet Lod for dem, og hans Haand har delt det ud iblandt dem ved Maalesnoren; de skulle eje det evindelig, fra Slægt til Slægt skulle de bo deri.