< Isaiah 33 >
1 Ègbé ni fún ọ, ìwọ apanirun, ìwọ tí a kò tí ì parun! Ègbé ni fún ọ, ìwọ ọ̀dàlẹ̀, ìwọ tí a kò tí ì dà ọ́! Nígbà tí o bá dẹ́kun à ń pa ni run; a ó pa ìwọ náà run, nígbà tí o bá dẹ́kun à ń dani, a ó da ìwọ náà.
Ve dig, du Ødelægger! du, som dog ikke er bleven ødelagt, og du Røver! du, som dog ikke er bleven et Rov; naar du har fuldendt at ødelægge, skal du ødelægges, naar du er bleven færdig med at røve, skal du selv blive et Rov.
2 Olúwa ṣàánú fún wa àwa ń ṣàfẹ́rí i rẹ. Máa jẹ́ agbára wa ní òròòwúrọ̀ ìgbàlà wa ní àsìkò ìpọ́njú.
Herre! vær os naadig, vi have biet efter dig; vær aarle vor Arm, tilmed vor Frelse i Nødens Tid.
3 Ní ìkérara ohùn rẹ, àwọn ènìyàn sá, nígbà tí o dìde sókè, àwọn orílẹ̀-èdè fọ́nká.
Folkene flyede for Tordenrøsten; Hedningerne adspredes, naar du rejser dig.
4 Ìkógun rẹ, ìwọ orílẹ̀-èdè ni a kórè gẹ́gẹ́ bí i ti ọ̀dọ́ eṣú; gẹ́gẹ́ bí àkójọpọ̀ eṣú, àwọn ènìyàn wọ ibẹ̀.
Og eders Bytte skal sankes, som man sanker Høskrækker; som Græshopper springe hid og did, skal man springe hid og did efter det.
5 A gbé Olúwa ga, nítorí pé ó ń gbé ibi gíga, Òun yóò kún Sioni pẹ̀lú ẹ̀tọ́ àti òdodo.
Herren er ophøjet, thi han bor i det høje; han har opfyldt Zion med Dom og Retfærdighed.
6 Òun yóò jẹ́ ìpìlẹ̀ tí ó dájú fún àkókò rẹ ibùjókòó ìgbàlà kíkún àti ọgbọ́n òun ìmọ̀; ìbẹ̀rù Olúwa ni kọ́kọ́rọ́ sí ìṣúra yìí.
Og Visdom og Kundskab skal give dine Tider Fasthed, en Rigdom af Frelse; Herrens Frygt skal være dit Liggendefæ.
7 Wò ó, àwọn onígboyà ọkùnrin wọn pohùnréré ẹkún ní òpópónà; àwọn ikọ̀ àlàáfíà sọkún kíkorò.
Se, deres Helte skrige derude; Fredens Bud græde beskelig.
8 Àwọn ojú ọ̀nà ńlá ni a ṣá tì, kò sí arìnrìn-àjò kankan ní ojú ọ̀nà. A ti ba àdéhùn jẹ́, a kẹ́gàn àwọn ẹlẹ́rìí, a kò bu ọlá fún ẹnikẹ́ni.
De banede Veje ere øde, der er ingen, som gaar frem ad Stien mere; han har brudt Pagten, ladet haant om Stæderne, ikke agtet et Menneske.
9 Ilẹ̀ ṣọ̀fọ̀ ó sì ṣòfò dànù, ojú ti Lebanoni ó sì sá Ṣaroni sì dàbí aginjù, àti Baṣani òun Karmeli rẹ àwọn èwe wọn.
Landet sørger, vansmægter, Libanon er beskæmmet, er henvisnet; Saron er som en øde Mark, og Basan og Karmel have kastet deres Blade.
10 “Ní ìsinsin yìí ni èmi yóò dìde,” ni Olúwa wí. “Ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi ga, ní ìsinsin yìí ni a ó gbé mi sókè.
Nu vil jeg gøre mig rede, siger Herren; nu vil jeg rejse mig, nu vil jeg ophøje mig.
11 Ìwọ lóyún ìyàngbò, o sì bí koríko; èémí yín bí iná tí yóò jẹ yín run.
I undfange Straa, føde Halm; eders Harme er en Ild, som skal fortære eder.
12 A ó jó àwọn ènìyàn run bí eérú; bí igbó ẹ̀gún tí a gé la ó dáná sí wọn.”
Og Folkene skulde vorde som det, der brændes til Kalk, som omhugne Torne, der opbrændes med Ild.
13 Ìwọ tí ó wà lọ́nà jíjìn, gbọ́ ohun tí mo ti ṣe; ìwọ tí ò ń bẹ nítòsí, jẹ́rìí agbára mi!
Hører, I, som ere langt borte, hvad jeg har gjort, og I, som ere nær, fornemmer min Styrke!
14 Ẹ̀rù ba àwọn ẹlẹ́ṣẹ̀ ní Sioni; ìwárìrì bá àwọn tí kò gba Ọlọ́run gbọ́: “Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná ajónirun? Ta ni nínú wa lólè gbé pẹ̀lú iná àìnípẹ̀kun?”
Syndere i Zion ere forskrækkede, Bævelse har betaget de vanhellige: „Hvo af os kan bo ved en fortærende Ild? hvo af os kan bo ved Evigheds Baal?”
15 Ẹni tí ó ń rìn lódodo tí ó ń sọ ohun tí ó tọ́, tí ó kọ èrè tí ó ti ibi ìlọ́nilọ́wọ́gbà wá, tí ó sì pa ọwọ́ rẹ̀ mọ́ kúrò nínú gbígba àbẹ̀tẹ́lẹ̀, tí ó di etí rẹ̀ sí ọ̀tẹ̀ láti pànìyàn tí ó sì di ojú rẹ̀ sí à ti pète ibi,
Den, som vandrer i Retfærdighed, og som taler Oprigtighed; den, som foragter Vinding, der kommer ved Undertrykkelse; den, som ryster sine Hænder, at han ej beholder Skænk; den, som stopper sit Øre til, saa at han ej hører Blodraad, og som tillukker sine Øjne, at han ej ser efter det onde:
16 Òun náà yóò gbé ní ibi gíga, ibi ààbò rẹ̀ yóò jẹ́ òkè ńlá olódi. A ó mú oúnjẹ fún un, omi rẹ̀ yóò sì dájú.
Han skal bo paa de høje Steder, Klippernes Befæstning skal være hans Tilflugt, Brød bliver givet ham, Vand er ham sikret.
17 Ojú rẹ yóò rí ọba nínú ẹwà rẹ̀ yóò sì rí ilẹ̀ kan tí ó tẹ́ lọ rẹrẹẹrẹ.
Dine Øjne skulle beskue Kongen i hans Skønhed, de skulle se et vidt udstrakt Land.
18 Nínú èrò rẹ ìwọ yóò rántí ẹ̀rù rẹ àtẹ̀yìnwá: “Níbo ni ọ̀gá àgbà náà wà? Níbo ni ẹni tí ń gba owó òde wà? Níbo ni òṣìṣẹ́ ti ó ń mójútó ilé ìṣọ́ wà?”
Dit Hjerte skal tænke paa Forfærdelsen: „Hvor er Skriveren? hvor er den, som vejede Pengene? hvor er den, som talte Taarnene?”
19 Ìwọ kì yóò rí àwọn agbéraga ènìyàn mọ́, àwọn ènìyàn tí èdè wọn fi ara sin, pẹ̀lú ahọ́n tí ó ṣàjèjì tí kò sì yé ni.
Du skal ikke mere se det haarde Folk, det Folk, som man ikke kan forstaa for dets dybe Mæles Skyld, det, som man ikke kan fatte for dets stammende Tunges Skyld.
20 Gbójú sókè sí Sioni, ìlú àjọ̀dún wa, ojú rẹ yóò rí Jerusalẹmu, ibùgbé àlàáfíà n nì, àgọ́ tí a kò ní yí padà; àwọn òpó rẹ̀ ni a kì yóò fàtu tàbí èyíkéyìí nínú okùn rẹ̀ kí já.
Besku Zion, vor Forsamlings Stad; dine Øjne skulle se Jerusalem som en sikker Bolig, som et Telt, der ikke skal flyttes, hvis Pæle ikke skulle oprykkes evindelig, og hvis Reb ikke skulle rives over.
21 Níbẹ̀ ni Olúwa yóò ti jẹ́ alágbára kan fún wa. Yóò sì dàbí ibi àwọn odò ńlá ńlá àti odò kéékèèké. Kì yóò sí ọkọ̀ ojú omi pẹ̀lú tí yóò kọjá lórí i wọn, ọkọ̀ ojú omi ńlá ni a kì yóò tù lórí wọn.
Men der skal Herren være os den herlige, være i Stedet for Floder og brede Strømme; intet Skib, som roes, farer der, og intet stort Skib gaar derover.
22 Nítorí Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa ni onídàájọ́ wa, Olúwa òun ni ọba wa; òun ni ẹni tí yóò gbà wá là.
Thi Herren er vor Dommer, Herren er vor Lovgiver, Herren er vor Konge, han skal frelse os.
23 Gbogbo okùn rẹ ni ó ti dẹ̀: Ìgbókùnró kò fìdímúlẹ̀, wọn kò taṣọ agbọ́kọ̀rìn, lẹ́yìn náà, ọ̀pọ̀lọpọ̀ ìkógun ni a ó pín àní arọ pẹ̀lú yóò ru ìkógun lọ.
Dine Reb ere blevne slappe; de holde ikke deres Mast stiv, de have ikke udbredet Flag; da deles røvet Bytte i Mængde, de halte røve Rov.
24 Kò sí ẹnikẹ́ni tí ó ń gbé Sioni tí yóò wí pé, “Ara mi kò yá,” a ó dárí gbogbo ẹ̀ṣẹ̀ àwọn ènìyàn tí ń gbé ibẹ̀ jì wọ́n.
Og ingen Indbygger skal sige: Jeg er syg; thi Folket, som bor derudi, har faaet Syndsforladelse.