< Genesis 49 >

1 Nígbà náà ni Jakọbu ránṣẹ́ pe àwọn ọmọ rẹ̀, ó sì wí pé, “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí n le è sọ ohun tí yóò ṣẹlẹ̀ ní ọjọ́ iwájú fún un yín.
Potem Jakub wezwał swoich synów i powiedział: Zbierzcie się, a oznajmię wam, co was spotka w [waszych] ostatnich dniach.
2 “Ẹ kó ara yín jọ pọ̀, kí ẹ sì tẹ́tí, ẹ̀yin ọmọ Jakọbu; ẹ fetí sí Israẹli baba yín.
Zbierzcie się i słuchajcie, synowie Jakuba, a słuchajcie waszego ojca Izraela.
3 “Reubeni, ìwọ ni àkọ́bí mi, agbára mi, ìpilẹ̀ṣẹ̀ ipá mi, títayọ ní ọlá àti títayọ ní agbára.
Rubenie, mój pierworodny, ty jesteś moją mocą i początkiem mojej siły, pierwszy dostojeństwem i pierwszy męstwem.
4 Ẹni ríru bí omi Òkun, ìwọ kì yóò tayọ mọ́, nítorí pé ìwọ gun ibùsùn baba rẹ, lórí àkéte mi, ìwọ sì bà á jẹ́ (ìwọ bá ọ̀kan nínú àwọn aya baba rẹ lòpọ̀).
Niestabilny jak woda, nie będziesz przodować, bo wstąpiłeś do łoża twego ojca; wstępując do mojego posłania, zbezcześciłeś je.
5 “Simeoni àti Lefi jẹ́ arákùnrin— idà wọn jẹ́ ohun èlò ogun alágbára.
Symeon i Lewi, bracia, ich miecze to narzędzia przemocy.
6 Kí ọkàn mi má ṣe ni àṣepọ̀ pẹ̀lú wọn, kí n má sì ṣe dúró níbí ìpéjọpọ̀ wọn, nítorí wọ́n ti pa àwọn ènìyàn ní ìbínú wọn, wọ́n sì da àwọn màlúù lóró bí ó ti wù wọ́n.
Niech moja dusza nie wchodzi w ich radę, niech moja sława nie jednoczy się z ich zgromadzeniem, bo w swej zapalczywości zabili człowieka, a w samowoli wywrócili mur.
7 Ìfibú ni ìbínú wọn nítorí tí ó gbóná púpọ̀, àti fún ìrunú wọn nítorí tí ó kún fún ìkà! Èmi yóò tú wọn ká ní Jakọbu, èmi ó sì fọ́n wọn ká ní Israẹli.
Przeklęta ich zapalczywość, bo uparta, i ich gniew, bo zatwardziały. Rozdzielę ich w Jakubie, a rozproszę ich w Izraelu.
8 “Juda, àwọn arákùnrin rẹ yóò yìn ọ, ọwọ́ rẹ yóò wà ní ọrùn àwọn ọ̀tá rẹ, àwọn ọmọkùnrin baba rẹ yóò foríbalẹ̀ fún ọ.
Judo, to ciebie będą chwalić twoi bracia, twoja ręka będzie na karku twoich nieprzyjaciół, synowie twego ojca będą ci się kłaniać.
9 Ọmọ kìnnìún ni ọ́, ìwọ Juda, o darí láti igbó ọdẹ, ọmọ mi. Bí i kìnnìún, o ba mọ́lẹ̀, o sì sùn sílẹ̀ bí i abo kìnnìún, ta ni ó tó bẹ́ẹ̀, kí o lé e dìde?
Judo, szczenię lwie, wróciłeś od łupu, mój synu. Skłonił się i położył się jak lew i jak lwica. Któż go obudzi?
10 Ọ̀pá oyè kì yóò kúrò ní Juda bẹ́ẹ̀ ni ọ̀pá-ìṣàkóso kì yóò kúrò láàrín ẹsẹ̀ rẹ̀, títí tí Ṣilo tí ó ni í yóò fi dé, tí gbogbo àwọn orílẹ̀-èdè yóò máa wárí fún un.
Nie będzie odjęte berło od Judy ani prawodawca spomiędzy jego nóg, aż przyjdzie Szylo i jemu będą posłuszne narody.
11 Yóò má so ọmọ ẹṣin rẹ̀ mọ́ igi àjàrà, àti ọmọ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ mọ́ ẹ̀ka tí ó dára jù. Yóò fọ aṣọ rẹ̀ nínú wáìnì àti ẹ̀wù rẹ̀ nínú omi-pupa ti èso àjàrà.
Przywiąże do winorośli swoje oślę, a do wybornej winorośli – oślątko swojej oślicy. Wypierze w winie swoją szatę, a we krwi winogron – swoje odzienie.
12 Ojú rẹ̀ yóò rẹ̀ dòdò ju wáìnì lọ, eyín rẹ yóò sì funfun ju omi-ọyàn lọ.
Jego oczy czerwone od wina, a zęby białe od mleka.
13 “Sebuluni yóò máa gbé ní etí Òkun, yóò sì jẹ́ èbúté fún ọkọ̀ ojú omi, agbègbè rẹ yóò tàn ká títí dé Sidoni.
Zebulon [będzie] mieszkać na morskim brzegu, przy porcie okrętów, a jego granice [będą] aż do Sydonu.
14 “Isakari jẹ́ kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ alágbára tí ó dùbúlẹ̀ láàrín agbo àgùntàn.
Issachar [jak] osioł kościsty leżący między dwoma brzemionami.
15 Nígbà tí ó bá rí bí ibi ìsinmi òun ti dára tó, àti bí ilẹ̀ rẹ̀ ti ní ìdẹ̀ra tó, yóò tẹ èjìká rẹ̀ ba láti ru àjàgà, yóò sì fi ara rẹ̀ fún iṣẹ́ ipá.
Zobaczył, że spoczynek jest dobry i ziemię, że [jest] urocza, nachylił swe ramię, by dźwigać, i stał się sługą składającym daninę.
16 “Dani yóò ṣe ìdájọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀ gẹ́gẹ́ bí ọ̀kan nínú àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Dan będzie sądzić swój lud jako jedno z pokoleń Izraela.
17 Dani yóò jẹ́ ejò ni pópónà àti paramọ́lẹ̀ ní ẹ̀bá ọ̀nà, tí ó bu ẹṣin jẹ ní ẹsẹ̀, kí ẹni tí ń gùn ún bá à le è ṣubú sẹ́yìn.
Dan będzie wężem na drodze, żmiją na ścieżce kąsającą końskie pięty, tak że jeździec spadnie do tyłu.
18 “Mo ń dúró de ìtúsílẹ̀ rẹ, Olúwa.
Oczekuję twego zbawienia, PANIE!
19 “Ẹgbẹ́ ogun àwọn ẹlẹ́ṣin yóò kọlu Gadi, ṣùgbọ́n yóò kọlu wọ́n ní gìgísẹ̀ wọn.
Gad będzie zwyciężony przez wojsko, ale on na koniec zwycięży.
20 “Oúnjẹ Aṣeri yóò dára; yóò ṣe àsè tí ó yẹ fún ọba.
Od Aszera [będzie] tłusty chleb, a on dostarczy przysmaków królewskich.
21 “Naftali yóò jẹ́ abo àgbọ̀nrín tí a tú sílẹ̀ tí ó ń bí ọmọ dáradára.
Neftali [jak] wypuszczona łania, mówiący piękne słowa.
22 “Josẹfu jẹ́ àjàrà eléso, àjàrà eléso ní etí odò, tí ẹ̀ka rẹ̀ gun orí odi.
Józef, latorośl płodna, latorośl płodna przy źródle, a [jej] szczepy rozchodzą się po murze.
23 Pẹ̀lú ìkorò, àwọn tafàtafà dojú ìjà kọ ọ́, wọ́n tafà sí í pẹ̀lú ìkanra.
Choć napoili go goryczą i strzelali do niego, i nienawidzili go strzelcy;
24 Ṣùgbọ́n ọrun rẹ̀ dúró ni agbára, ọwọ́ agbára rẹ̀ ni a sì mu lára le, nítorí ọwọ́ alágbára Jakọbu, nítorí olùtọ́jú àti aláàbò àpáta Israẹli,
Jednak jego łuk został potężny i wzmocniły się ramiona jego rąk dzięki rękom mocnego [Boga] Jakuba, stamtąd pasterz i opoka Izraela.
25 nítorí Ọlọ́run baba rẹ tí ó ràn ọ́ lọ́wọ́, nítorí Olódùmarè tí ó bùkún ọ pẹ̀lú láti ọ̀run wá, ìbùkún ọ̀gbìn tí ó wà ní ìsàlẹ̀, ìbùkún ti ọmú àti ti inú.
Od Boga twego ojca, który [będzie] cię wspomagał, i od Wszechmogącego, który ci pobłogosławi błogosławieństwami nieba z wysoka [i] błogosławieństwami głębin leżących na dole, [i] błogosławieństwami piersi i łona.
26 Ìbùkún baba rẹ pọ̀ púpọ̀ ju ìbùkún àwọn òkè ńlá ìgbàanì, ju ẹ̀bùn ńlá àwọn òkè láéláé. Jẹ́ kí gbogbo èyí sọ̀kalẹ̀ sí orí Josẹfu, lé ìpéǹpéjú ọmọ-aládé láàrín arákùnrin rẹ̀.
Błogosławieństwa twego ojca będą mocniejsze niż błogosławieństwa moich przodków aż do granic pagórków wiecznych. Będą nad głową Józefa i nad wierzchem głowy odłączonego od swych braci.
27 “Benjamini jẹ́ ìkookò tí ó burú; ní òwúrọ̀ ni ó jẹ ẹran ọdẹ rẹ, ní àṣálẹ́, ó pín ìkógun.”
Beniamin [jak] drapieżny wilk, rano będzie jeść zdobycz, a wieczorem będzie dzielił łupy.
28 Gbogbo ìwọ̀nyí ni àwọn ẹ̀yà Israẹli méjìlá, èyí sì ni ohun tí baba wọn sọ fún wọn nígbà tí ó súre fún wọn, tí ó sì fún ẹnìkọ̀ọ̀kan ní ìbùkún tí ó tọ́ sí i.
Oto wszystkich dwanaście pokoleń Izraela i to, co im powiedział ich ojciec, gdy im błogosławił. Każdemu według jego błogosławieństwa błogosławił.
29 Nígbà náà ni ó fún wọn ní àwọn ìlànà yìí, “Ọjọ́ ikú mi kù fẹ́ẹ́rẹ́. Kí ẹ sin mí sí ibojì pẹ̀lú àwọn baba mi ní inú àpáta ní ilẹ̀ Hiti ará Efroni.
Potem im nakazał: Ja będę przyłączony do mojego ludu. Pogrzebcie mnie z moimi ojcami w jaskini, która jest na polu Efrona Chetyty;
30 Ihò àpáta tí ó wà ní ilẹ̀ Makpela, nítòsí Mamre ní Kenaani, èyí tí Abrahamu rà gẹ́gẹ́ bí ilẹ̀ ìsìnkú lọ́wọ́ Efroni ará Hiti pẹ̀lú ilẹ̀ rẹ̀.
W jaskini, która [jest] na polu Makpela naprzeciwko Mamre w ziemi Kanaan. Kupił ją wraz z polem Abraham od Efrona Chetyty jako grób na własność.
31 Níbẹ̀ ni a sin Abrahamu àti aya rẹ̀ Sara sí, níbẹ̀ ni a sin Isaaki àti Rebeka aya rẹ̀ sí, níbẹ̀ sì ni mo sìnkú Lea sí.
Tam pogrzebano Abrahama i jego żonę Sarę, tam pogrzebano Izaaka i jego żonę Rebekę. Tam też pogrzebałem Leę.
32 Ilẹ̀ náà àti ihò àpáta tí ó wà nínú rẹ̀ ni a rà lọ́wọ́ ará Hiti.”
Pole to i jaskinię na nim kupiono od synów Cheta.
33 Nígbà tí Jakọbu ti pàṣẹ yìí fún àwọn ọmọ rẹ̀, ó gbé ẹsẹ̀ rẹ̀ sókè sórí ibùsùn, ó sì kú, a sì ko jọ pọ̀ mọ́ àwọn ènìyàn rẹ̀.
A gdy Jakub przestał mówić do swoich synów, złożył swoje nogi na łoże i umarł, i został przyłączony do swego ludu.

< Genesis 49 >