< Exodus 1 >

1 Ìwọ̀nyí ni àwọn orúkọ ọmọ Israẹli tí wọ́n bá Jakọbu lọ sí Ejibiti, ẹnìkọ̀ọ̀kan pẹ̀lú ìdílé rẹ̀:
Oto imiona synów Izraela, którzy przybyli z Jakubem do Egiptu; każdy przybył ze swoją rodziną:
2 Reubeni, Simeoni, Lefi àti Juda;
Ruben, Symeon, Lewi i Juda;
3 Isakari, Sebuluni àti Benjamini;
Issachar, Zebulon i Beniamin;
4 Dani àti Naftali; Gadi àti Aṣeri.
Dan, Neftali, Gad i Aszer.
5 Àwọn ìran Jakọbu sì jẹ́ àádọ́rin ní àpapọ̀; Josẹfu sì ti wà ní Ejibiti.
A wszystkich dusz, które wyszły z bioder Jakuba, było siedemdziesiąt. Józef zaś [już] był w Egipcie.
6 Wàyí o, Josẹfu àti gbogbo àwọn arákùnrin rẹ̀ àti gbogbo ìran náà kú,
Potem umarli Józef, wszyscy jego bracia i całe to pokolenie.
7 ṣùgbọ́n àwọn ará Israẹli ń bí sí i, wọ́n ń pọ̀ sí i gidigidi, wọ́n kò sì ní òǹkà tí ó fi jẹ́ pé wọ́n kún ilẹ̀ náà.
A synowie Izraela byli płodni, rozrodzili się, rozmnożyli i bardzo umacniali, a ziemia była ich pełna.
8 Nígbà náà ni ọba tuntun mìíràn tí kò mọ Josẹfu jẹ ní ilẹ̀ Ejibiti.
Wówczas nastał nad Egiptem nowy król, który nie znał Józefa.
9 Ó sọ fún àwọn ènìyàn rẹ̀, “Ẹ wò ó, àwọn ará Israẹli ti pọ̀ ní iye àti agbára jù fún wa.
I powiedział do swego ludu: Oto lud synów Izraela stał się liczniejszy i potężniejszy od nas.
10 Ẹ wá, ẹ jẹ́ kí a lo ọgbọ́n àlùmọ̀kọ́rọ́yí láti dá wọn lẹ́kun, bí kò ṣe bẹ́ẹ̀ wọn yóò túbọ̀ máa pọ̀ sí i. Bí ogun bá sì bẹ́ sílẹ̀, wọn yóò darapọ̀ mọ́ àwọn ọ̀tá wa, wọn yóò sì da ojú ìjà kọ wá, wọn yóò sì sá àsálà kúrò ní ilẹ̀ yìí.”
Postąpmy więc z nimi mądrze, by się nie rozmnożyli, bo gdyby przyszła wojna, mogliby przyłączyć się do naszych wrogów i walczyć przeciwko nam, i opuścić ziemię.
11 Nítorí náà, wọ́n yan àwọn ọ̀gá akóniṣiṣẹ́ lé wọn lórí láti máa ni wọ́n lára pẹ̀lú iṣẹ́ àṣekára. Wọ́n sì kọ́ Pitomi àti Ramesesi gẹ́gẹ́ bí ìlú ìṣúra pamọ́ sí fún Farao.
Ustanowiono więc nad nimi nadzorców, aby ich gnębili ciężarami. I [lud Izraela] zbudował dla faraona miasta na składy: Pitom i Ramzes.
12 Ṣùgbọ́n bí a ti ń ni wọ́n lára tó, bẹ́ẹ̀ ni wọ́n ń pọ̀ sí i, tí wọ́n sì ń tànkálẹ̀. Nítorí náà, àwọn ará Ejibiti bẹ̀rù nítorí àwọn ará Israẹli.
Ale im bardziej ich gnębili, tym bardziej się rozmnażali i rośli, tak że zatrwożyli się z powodu synów Izraela.
13 Àwọn ará Ejibiti sì mú àwọn ọmọ Israẹli sìn ní àsìnpa.
I Egipcjanie zmuszali synów Izraela do ciężkiej pracy.
14 Wọ́n mú wọn gbé ìgbé ayé kíkorò nípa iṣẹ́ bíríkì àti àwọn onírúurú iṣẹ́ oko; àwọn ará Ejibiti ń lò wọ́n ní ìlòkulò.
I uprzykrzali [im] życie uciążliwą pracą przy glinie i przy cegłach, i przy każdej robocie na polu. Do wszelkiej pracy zmuszali ich bez litości.
15 Ọba Ejibiti sọ fún àwọn agbẹ̀bí Heberu ti orúkọ wọn ń jẹ́ Ṣifura àti Pua pé,
I król Egiptu rozkazał hebrajskim położnym, z których jedna miała na imię Szifra, a druga Pua;
16 “Nígbà ti ẹ̀yin bá ń gbẹ̀bí àwọn obìnrin Heberu, tí ẹ sì kíyèsi wọn lórí ìkúnlẹ̀ ìrọbí wọn, bí ó bá jẹ́ ọkùnrin ni ọmọ náà, ẹ pa á; ṣùgbọ́n bí ó bá jẹ́ obìnrin, ẹ jẹ́ kí ó wà láààyè.”
Powiedział: Gdy będziecie przy porodach hebrajskich [kobiet] i zobaczycie, że urodził się syn, zabijcie go, a jeśli córka, niech zostanie przy życiu.
17 Ṣùgbọ́n àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, wọn kò sì ṣe gẹ́gẹ́ bí ọba Ejibiti ti wí fún wọn; wọ́n jẹ́ kí àwọn ọmọkùnrin wà láààyè.
Lecz położne bały się Boga i nie robiły tak, jak im rozkazał król Egiptu, ale pozostawiały chłopców przy życiu.
18 Ọba Ejibiti pe àwọn agbẹ̀bí ó sì béèrè lọ́wọ́ wọn pé, “Èéṣe tí ẹ̀yin fi ṣe èyí? Èéṣe tí ẹ̀yin fi dá àwọn ọmọkùnrin si?”
Wtedy król Egiptu wezwał położne i powiedział do nich: Dlaczego tak postąpiłyście, że pozostawiłyście chłopców przy życiu?
19 Àwọn agbẹ̀bí náà sì dá Farao lóhùn pé, “Àwọn obìnrin Heberu kò rí bí àwọn obìnrin Ejibiti, wọ́n ní agbára, wọ́n sì ti máa ń bí ọmọ kí àwọn agbẹ̀bí tó dé ọ̀dọ̀ wọn.”
Położne odpowiedziały faraonowi: Hebrajskie kobiety nie [są] takie jak egipskie [kobiety]. Są bowiem żywotne, rodzą wcześniej, zanim przyjdzie do nich położna.
20 Nítorí náà Ọlọ́run ṣàánú fún àwọn agbẹ̀bí náà, àwọn ọmọ Israẹli sì ń le sí i, wọ́n sì ń pọ̀ sí i jọjọ.
I Bóg dobrze czynił tym położnym, a lud się mnożył i bardzo się wzmocnił.
21 Nítorí pé àwọn agbẹ̀bí bẹ̀rù Ọlọ́run, Ọlọ́run sì fún wọn ni ìdílé tiwọn.
A ponieważ położne bały się Boga, zbudował im domy.
22 Nígbà náà ni Farao pàṣẹ yìí fún gbogbo àwọn ènìyàn rẹ̀ pé, “Gbogbo ọmọkùnrin tí a bí ni kí ẹ gbé jù sínú odò Naili, ṣùgbọ́n gbogbo àwọn ọmọbìnrin ni kí ẹ jẹ́ kí wọn ó wà láààyè.”
Wtedy faraon rozkazał całemu swemu ludowi: Każdego syna, który się urodzi, wrzućcie do rzeki, a każdą córkę pozostawcie przy życiu.

< Exodus 1 >