< Genesis 22 >
1 Nígbà tí ó ṣe, Ọlọ́run dán Abrahamu wò, ó pè é, ó sì wí pé, “Abrahamu.” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Bu ixlardin keyin xundaⱪ boldiki, Huda Ibraⱨimni sinap uningƣa: — Əy Ibraⱨim! dedi. U: mana mǝn! — dǝp jawab bǝrdi.
2 Ọlọ́run sì wí pé, “Mú ọmọ rẹ, àní Isaaki ọmọ rẹ kan ṣoṣo nì, tí ìwọ fẹ́ràn, lọ sí ilẹ̀ Moria, kí o sì fi rú ẹbọ sísun níbẹ̀ lórí ọ̀kan nínú àwọn òkè tí èmi yóò sọ fún ọ.”
U: — Sǝn oƣlungni, yǝni sǝn sɵyidiƣan yalƣuz oƣlung Isⱨaⱪni elip, Moriya yurtiƣa berip, xu yǝrdǝ, Mǝn sanga eytidiƣan taƣlarning birining üstidǝ uni kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ süpitidǝ sunƣin, — dedi.
3 Abrahamu sì dìde ní kùtùkùtù òwúrọ̀ ọjọ́ kejì, ó sì di kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́ rẹ̀ ní gàárì, ó sì mú méjì nínú àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ àti Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì ṣẹ́ igi fún ẹbọ sísun, ó sì gbéra lọ sí ibi tí Ọlọ́run ti sọ fún un.
Ətisi Ibraⱨim sǝⱨǝr ⱪopup, exikini toⱪup, yigitliridin ikkiylǝn bilǝn Isⱨaⱪni billǝ elip, kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ üqün otun yerip, Huda uningƣa eytⱪan yǝrgǝ ⱪarap mangdi.
4 Nígbà tí ó di ọjọ́ kẹta, Abrahamu gbé ojú sókè, ó sì rí ibi tí ó ń lọ ní òkèrè,
Üqinqi küni Ibraⱨim bexini kɵtürüp ⱪarap, yiraⱪtin u yǝrni kɵrdi.
5 Abrahamu sì wí fún àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ pé, “Ẹ̀yin, ẹ dúró níhìn-ín pẹ̀lú kẹ́tẹ́kẹ́tẹ́, èmi àti ọmọ yìí yóò lọ sí ohunkóhun láti sin Ọlọ́run, a ó sì tún padà wá bá a yín.”
Ibraⱨim yigitlirigǝ: — Silǝr exǝk bilǝn muxu yǝrdǝ turup turunglar. Mǝn balam bilǝn u yǝrgǝ berip, sǝjdǝ ⱪilip, andin ⱪexinglarƣa yenip kelimiz, — dedi.
6 Abrahamu sì gbé igi ẹbọ sísun náà ru Isaaki, òun fúnra rẹ̀ sì mú iná àti ọ̀bẹ. Bí àwọn méjèèjì ti ń lọ,
Xuning bilǝn Ibraⱨim kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪⱪa kerǝklik otunni elip, oƣli Isⱨaⱪⱪa yüdküzüp, ɵzi ⱪoliƣa piqaⱪ bilǝn otni elip, ikkisi billǝ yürüp kǝtti.
7 Isaaki sì sọ fún Abrahamu baba rẹ̀ wí pé, “Baba mi.” Abrahamu sì dalóhùn pé, “Èmi nìyí ọmọ mi.” Isaaki sì tún wí pé, “Wò ó iná àti igi nìyí, ṣùgbọ́n níbo ni ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà wà?”
Isⱨaⱪ atisi Ibraⱨimƣa: — Əy ata! dewidi, u uningƣa jawab berip: — Mana mǝn, oƣlum, dedi. U uningdin: — Mana ot bilǝn otunƣu bar, ǝmma kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ bolidiƣan ⱪoza ⱪeni? — dǝp soriwidi,
8 Abrahamu sì dáhùn pé, “Ọmọ mi, Ọlọ́run fúnra rẹ̀ ni yóò pèsè ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun náà.” Bẹ́ẹ̀ ni àwọn méjèèjì jùmọ̀ ń lọ.
Ibraⱨim jawab berip: — Əy oƣlum, Huda Ɵzi Ɵzigǝ kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ ⱪozini tǝminlǝydu, — dedi. Andin ikkisi birgǝ yolini dawamlaxturdi.
9 Nígbà tí wọn sì dé ibi tí Ọlọ́run sọ fún Abrahamu, ó mọ pẹpẹ kan, ó sì to igi lé e lórí, ó sì di Isaaki ọmọ rẹ̀, ó sì da dùbúlẹ̀ lórí pẹpẹ náà.
Ahirida ular Huda Ibraⱨimƣa eytⱪan jayƣa yetip kǝldi. Ibraⱨim u yǝrdǝ ⱪurbangaⱨ yasap, üstigǝ otunni tizip ⱪoydi. Andin u oƣli Isⱨaⱪni baƣlap, uni ⱪurbangaⱨdiki otunning üstidǝ yatⱪuzdi.
10 Abrahamu sì nawọ́ mú ọ̀bẹ, láti dúńbú ọmọ rẹ̀.
Andin Ibraⱨim ⱪolini uzitip, oƣlini boƣuzliƣili piqaⱪni aldi.
11 Ṣùgbọ́n angẹli Olúwa ké sí i láti ọ̀run wá wí pé “Abrahamu! Abrahamu!” Abrahamu sì dáhùn pé, “Èmi nìyí.”
Xuan Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi asmandin uni qaⱪirip uningƣa: — Ibraⱨim, Ibraⱨim! — dǝp warⱪiridi. U: — Mana mǝn, — dedi.
12 Angẹli Olúwa sì wí pé, “Má ṣe fọwọ́ kan ọmọ náà, ìwọ kò sì gbọdọ̀ ṣe é ni ohun kan. Nísinsin yìí ni mo mọ̀ pé o bẹ̀rù Ọlọ́run, nítorí pé ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí.”
U uningƣa: — Sǝn baliƣa ⱪolungni tǝgküzmigin, uni ⱨeqnemǝ ⱪilmiƣin; qünki Mǝn sening Hudadin ⱪorⱪⱪanliⱪingni bildim; qünki sening oƣlungni, yǝni yalƣuz oƣlungni Mǝndin ayimiding, — dedi.
13 Abrahamu sì gbójú sókè, ó sì rí àgbò kan tí ó fi ìwo há pàǹtírí, ó sì lọ mú un, ó sì fi rú ẹbọ sísun dípò ọmọ rẹ̀.
Ibraⱨim bexini kɵtürüp ⱪariwidi, mana, arⱪisida münggüzliri qatⱪalƣa qirmixip ⱪalƣan bir ⱪoqⱪarni kɵrdi. Ibraⱨim berip ⱪoqⱪarni elip, uni oƣlining ornida kɵydürmǝ ⱪurbanliⱪ ⱪilip sundi.
14 Abrahamu sì pe orúkọ ibẹ̀ ni, Jehofah Jire. Bẹ́ẹ̀ ni a sì ń wí títí di òní olónìí pé, “Ní orí òkè Olúwa, ni a ó ti pèsè.”
Xuning bilǝn Ibraⱨim xu jayƣa «Yaⱨwǝⱨ-Yirǝⱨ» dǝp at ⱪoydi. Xunga kixilǝr: «Pǝrwǝrdigarning teƣida tǝminlinidu» degǝn bu sɵz bügüngǝ ⱪǝdǝr eytilip keliwatidu.
15 Angẹli Olúwa sì tún pe Abrahamu láti ọ̀run wá lẹ́ẹ̀kejì.
Pǝrwǝrdigarning Pǝrixtisi asmandin Ibraⱨimni ikkinqi ⱪetim qaⱪirip uningƣa: —
16 Ó sì wí pé, Olúwa wí pé, “Mo fi ara mi búra, níwọ̀n bí ìwọ ti ṣe èyí, tí ìwọ kò fi ọmọ rẹ, àní, ọmọ rẹ kan ṣoṣo dù mí,
Sǝn ɵz oƣlungni, yǝni yalƣuz oƣlungni ayimay bu ixni ⱪilƣining üqün Mǝn Ɵzüm bilǝn ⱪǝsǝm ⱪilimǝnki, dǝydu Pǝrwǝrdigar,
17 nítòótọ́, ní bíbùkún èmi ó bùkún fún ọ, àti ní bíbísí èmi ó sì mú ọ bí sí i bí i ìràwọ̀ ojú ọ̀run àti bí iyanrìn etí Òkun. Irú-ọmọ rẹ yóò sì gba ẹnu ibodè àwọn ọ̀tá wọn,
— Mǝn seni zor bǝrikǝtlǝp, nǝslingni asmandiki yultuzlardǝk nurƣun kɵpǝytip, dengiz saⱨilidiki ⱪumdǝk ƣolditimǝn; nǝsling bolsa düxmǝnlirining dǝrwaziliriƣa igǝ bolidu.
18 àti nípasẹ̀ irú-ọmọ rẹ ni a ó ti bùkún fún gbogbo orílẹ̀-èdè ayé nítorí tí ìwọ gbọ́rọ̀ sí mi lẹ́nu.”
Sǝn Mening awazimƣa ⱪulaⱪ salƣining üqün yǝr yüzidiki barliⱪ ǝl-yurtlar nǝslingning nami bilǝn ɵzliri üqün bǝht-bǝrikǝt tilǝydu, — dedi.
19 Nígbà náà ni Abrahamu padà tọ àwọn ìránṣẹ́ rẹ̀ lọ. Gbogbo wọn sì padà lọ sí Beerṣeba. Abrahamu sì jókòó ní Beerṣeba.
Andin Ibraⱨim yigitlirining ⱪexiƣa yenip bardi. Ular ⱨǝmmisi ornidin turuxup Bǝǝr-Xebaƣa yol aldi. Ibraⱨim Bǝǝr-Xebada turup ⱪaldi.
20 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí ni a wí fún Abrahamu pé, “Milka aya Nahori bí àwọn ọmọkùnrin fún un.
Bu ixlardin keyin Ibraⱨimƣa: «Mana Milkaⱨmu ining Naⱨorƣa birⱪanqǝ oƣul tuƣup beriptu», degǝn hǝwǝr yǝtti.
21 Usi àkọ́bí rẹ̀, Busi arákùnrin rẹ̀, Kemueli (baba Aramu).
Ular bolsa tunji oƣli uz, uning inisi Buz wǝ Aramning atisi bolƣan Kǝmuǝl,
22 Kesedi, Haso, Pildasi, Jidlafi, àti Betueli.”
andin Kǝsǝd, Hazo, Pildax, Yidlaf wǝ Betuǝl degǝn oƣullar idi.
23 Betueli sì ni baba Rebeka. Milka sì bí àwọn ọmọ mẹ́jọ wọ̀nyí fún Nahori arákùnrin Abrahamu.
(Betuǝldin Riwkaⱨ tɵrǝldi). Bu sǝkkizini Milkaⱨ Ibraⱨimning inisi Naⱨorƣa tuƣup bǝrdi.
24 Àlè rẹ̀ tí ń jẹ́ Reuma náà bí àwọn ọmọkùnrin wọ̀nyí fun un: Teba, Gahamu, Tahasi àti Maaka.
Xuningdǝk uning keniziki Rǝumaⱨmu Tebaⱨ, Gaⱨam, Tahax wǝ Maakaⱨ degǝnlǝrni tuƣup bǝrdi.