< Genesis 20 >

1 Abrahamu sì kó kúrò níbẹ̀ lọ sí ìhà gúúsù ó sì ń gbé ní agbede-méjì Kadeṣi àti Ṣuri; ó sì gbé ní ìlú Gerari fún ìgbà díẹ̀.
Ibraⱨim u yǝrdin qiⱪip, jǝnub tǝrǝptiki Nǝgǝwgǝ kɵqüp kelip, Ⱪadǝx bilǝn Xurning ariliⱪida turup ⱪaldi; bir mǝzgildin keyin Gǝrarda olturaⱪlaxti.
2 Abrahamu sì sọ ní ti Sara aya rẹ̀ níbẹ̀ pé, “Arábìnrin mi ni.” Abimeleki ọba Gerari sì ránṣẹ́ mú Sara wá sí ààfin rẹ̀.
Xu yǝrdǝ Ibraⱨim ayali Saraⱨ toƣrisida: «U mening singlimdur», degǝnidi. Xuning bilǝn Gǝrarning padixaⱨi Abimǝlǝk adǝm ǝwǝtip, Saraⱨni [ɵzigǝ] hotun boluxⱪa eliwaldi.
3 Ṣùgbọ́n Ọlọ́run tọ Abimeleki wá ní ojú àlá lọ́jọ́ kan, ó sì wí fún un pé, “Kíyèsi, kò sí ohun tí o fi sàn ju òkú lọ, nítorí obìnrin tí ìwọ mú sọ́dọ̀ n nì, aya ẹni kan ní íṣe.”
Lekin [bir küni] keqisi qüxidǝ Huda Abimǝlǝkkǝ kelip uningƣa: — Mana, sǝn ɵzünggǝ eliwalƣan ayal sǝwǝbidin ǝmdi ɵlgǝn adǝmdursǝn; qünki u baxⱪa birsining ayalidur — dedi.
4 Ṣùgbọ́n Abimeleki kò tí ìbá obìnrin náà lòpọ̀, nítorí náà ó wí pé, “Olúwa ìwọ yóò run orílẹ̀-èdè aláìlẹ́bi bí?
Əmma Abimǝlǝk uningƣa tehi yeⱪinqiliⱪ ⱪilmiƣanidi. U Hudaƣa: — I Rǝb, ⱨǝⱪⱪaniy bir hǝlⱪnimu ⱨalak ⱪilamsǝn?
5 Ǹjẹ́ òun kò sọ fún mi pé, ‘Arábìnrin mi ni,’ obìnrin náà pẹ̀lú sì sọ pé, ‘Arákùnrin mí ni’? Ní òtítọ́ pẹ̀lú ọkàn mímọ́ àti ọwọ́ mímọ́, ni mo ṣe èyí.”
U ɵzimu manga: «U mening singlim» dǝp eytmidimu? Yǝnǝ kelip, bu ayalmu «U mening akam», dǝp eytⱪanidi. Mǝn bolsam sap kɵnglüm wǝ durus niyitim bilǝn bu ixni ⱪildim, — dedi.
6 Nígbà náà ni Ọlọ́run wí fún un nínú àlá náà pé, “Bẹ́ẹ̀ ni, mo mọ̀ pé pẹ̀lú òtítọ́ inú ni ìwọ ṣe èyí, èyí ni mo fi pa ọ́ mọ́ tí ń kò jẹ́ kí o ṣẹ̀ sí mi. Ìdí nìyí tí n kò fi jẹ́ kí o ní ìbálòpọ̀ pẹ̀lú obìnrin náà.
Huda qüxidǝ uningƣa yǝnǝ: — Bu ixni sap kɵngül bilǝn ⱪilƣiningni bilimǝn; xu sǝwǝbtin Mǝn seni aldimda gunaⱨ ⱪilixtin tosup, uningƣa tegixinggǝ ⱪoymidim.
7 Nísinsin yìí, dá aya ọkùnrin náà padà, nítorí pé wòlíì ni, yóò sì gbàdúrà fún ọ, ìwọ yóò sì yè. Ṣùgbọ́n bí ìwọ kò bá dá a padà, mọ̀ dájú pé ìwọ àti gbogbo ẹni tí í ṣe tìrẹ yóò kú.”
Əmdi u kixining ayalini ɵzigǝ ⱪayturup bǝr; qünki u Pǝyƣǝmbǝr, u sening ⱨǝⱪⱪingdǝ dua ⱪilidu wǝ sǝn tirik ⱪalisǝn. Əgǝr uni yandurup bǝrmisǝng xuni bilip ⱪoyƣinki, sǝn wǝ ⱨǝmmǝ adǝmliring ⱪoxulup jǝzmǝn ɵlisilǝr, — dedi.
8 Ní òwúrọ̀ kùtùkùtù ọjọ́ kejì, Abimeleki pe gbogbo àwọn ìjòyè rẹ̀. Nígbà tí ó sì sọ gbogbo ohun tí ó ṣẹlẹ̀ fún wọn, ẹ̀rù bà wọ́n gidigidi.
Abimǝlǝk ǝtigǝn tang sǝⱨǝrdǝ ⱪopup, ⱨǝmmǝ hizmǝtkarlirini qaⱪirip, bu sɵzlǝrning ⱨǝmmisini ularning ⱪulaⱪliriƣa saldi; bu adǝmlǝr naⱨayiti ⱪorⱪuxup kǝtti.
9 Nígbà náà ni Abimeleki pe Abrahamu ó sì wí fún un pé, “Èwo ni èyí tí ìwọ ṣe sí wa yìí? Ẹ̀ṣẹ̀ wo ni mo ṣẹ̀ ọ́ tí ìwọ fi mú ìdálẹ́bi ńlá wá sí orí èmi àti ìjọba mi? Kò yẹ kí ìwọ hu irú ìwà yìí sí mi.”
Andin Abimǝlǝk Ibraⱨimni qaⱪirip uningƣa: — Bu bizgǝ nemǝ ⱪilƣining? Mǝn sanga zadi nemǝ gunaⱨ ⱪildim, sǝn mǝn wǝ padixaⱨliⱪimƣa eƣir bir gunaⱨni yüklǝp ⱪoydung? Manga ⱪilmaydiƣan ixlarni ⱪilding! — dedi.
10 Abimeleki sì bi Abrahamu pé, “Kín ló dé tí ìwọ fi ṣe èyí?”
Abimǝlǝk Ibraⱨimƣa yǝnǝ: — Sǝn zadi bizning nemǝ iximizni kɵrgining üqün muxu ixni ⱪilding? — dedi.
11 Abrahamu sì dáhùn pé, “Mo ṣe èyí nítorí mo rò nínú ara mi pé, ẹ̀yin tí ẹ wà níhìn-ín, ẹ kò bẹ̀rù Ọlọ́run, pé, ẹ sì le pa mí nítorí aya mi.
Ibraⱨim jawab berip: — «Bu yǝrdǝ xübⱨisizki ⱨeqkim Hudadin ⱪorⱪmaydikǝn, ular meni ayalim tüpǝylidin ɵltürüwetidu», dǝp oyliƣanidim.
12 Yàtọ̀ fún ìyẹn, òtítọ́ ni pé arábìnrin mi ni. Ọmọ baba kan ni wá, bí ó tilẹ̀ jẹ́ pé, a kì í ṣe ọmọ ìyá kan. Mo sì fẹ́ ẹ ní aya.
Əmǝliyǝttǝ, uning mening singlim ikǝnliki rast, lekin u mening ata bir, ana bɵlǝk singlim; keyin u mening ayalim boldi.
13 Nígbà tí Ọlọ́run sì mú mi rìn kiri kúrò ní ilé baba mi, mo wí fún un pé, ‘Èyí ni ọ̀nà tí ó lè gbà fihàn pé ó fẹ́ràn mi. Gbogbo ibi tí a bá dé máa sọ pé, “Arákùnrin rẹ ni mí.”’”
Lekin Huda meni atamning ɵyidin qiⱪirip sǝrgǝrdanliⱪⱪa yürgüzginidǝ, mǝn ayalimƣa: — Biz ⱪǝyǝrgila barsaⱪ, sǝn manga xundaⱪ xapaǝt kɵrsǝtkǝysǝnki, mening toƣramda: «Bu mening akam bolidu», degin, — dǝp eytⱪanidim — dedi.
14 Nígbà náà ni Abimeleki mú àgùntàn àti màlúù wá, àti ẹrúkùnrin àti ẹrúbìnrin, ó sì kó wọn fún Abrahamu, ó sì dá Sara aya rẹ̀ padà fún un.
Andin Abimǝlǝk ⱪoy-kalilar, ⱪullar wǝ dedǝklǝrni elip ularni Ibraⱨimƣa bǝrdi wǝ ayali Saraⱨnimu uningƣa ⱪayturup bǝrdi.
15 Abimeleki sì tún wí fún un pé, “Gbogbo ilẹ̀ mí nìyí níwájú rẹ, máa gbé ní ibikíbi tí o fẹ́ níbẹ̀.”
Abimǝlǝk: — Mana mening zeminim bolsa aldingda turuptu; kɵzünggǝ ⱪaysi yǝr yaⱪsa xu yǝrdǝ turƣin, — dedi.
16 Abimeleki sì wí fún Sara pé, “Mo fi ẹgbẹ̀rún owó ẹyọ fàdákà fún arákùnrin rẹ. Èyí ni owó ìtánràn ẹ̀ṣẹ̀ mi sí ọ níwájú gbogbo ẹni tí ó wà pẹ̀lú rẹ àti pé, a dá ọ láre pátápátá.”
U Saraⱨⱪa: «Mana, mǝn akangƣa ming kümüx tǝnggǝ bǝrdim; mana bular ɵz yeningdikilǝr, xundaⱪla ⱨǝmmǝ adǝmlǝrning kɵz aldida uyatni yapⱪuqi bolidu; xuning bilǝn sǝn ⱨǝrⱪandaⱪ daƣ-ǝyibtin halas bolisǝn».
17 Nígbà náà, Abrahamu gbàdúrà sí Ọlọ́run, Ọlọ́run sì wo Abimeleki àti aya rẹ̀ àti àwọn ẹrúbìnrin rẹ̀ sàn. Wọ́n sì tún ń bímọ,
Ibraⱨim Hudaƣa dua ⱪildi, Huda Abimǝlǝk, ayali wǝ kenizǝklirini saⱪaytti; andin ular [yǝnǝ] bala tuƣalaydiƣan boldi; qünki Pǝrwǝrdigar Ibraⱨimning ayali Saraⱨ tüpǝylidin Abimǝlǝkning ɵyidiki ⱨǝmmǝ hotunlarning baliyatⱪulirini etip ⱪoyƣanidi.
18 nítorí Olúwa ti sé gbogbo ará ilé Abimeleki nínú nítorí Sara aya Abrahamu.

< Genesis 20 >