< Ezra 7 >

1 Lẹ́yìn nǹkan wọ̀nyí, ní àkókò ìjọba ọba Artasasta ní Persia, Esra ọmọ Seraiah, ọmọ Asariah, ọmọ Hilkiah,
Acum, după aceste lucruri, pe timpul domniei lui Artaxerxes, împăratul Persiei, Ezra fiul lui Seraia, fiul lui Azaria, fiul lui Hilchia,
2 ọmọ Ṣallumu, ọmọ Sadoku, ọmọ Ahitubu,
Fiul lui Şalum, fiul lui Ţadoc, fiul lui Ahitub,
3 ọmọ Amariah, ọmọ Asariah, ọmọ Meraioti,
Fiul lui Amaria, fiul lui Azaria, fiul lui Meraiot,
4 ọmọ Serahiah, ọmọ Ussi, ọmọ Bukki,
Fiul lui Zerahia, fiul lui Uzi, fiul lui Buchi,
5 ọmọ Abiṣua, ọmọ Finehasi, ọmọ Eleasari, ọmọ Aaroni olórí àlùfáà—
Fiul lui Abişua, fiul lui Fineas, fiul lui Eleazar, fiul lui Aaron, marele preot;
6 Esra yìí sì gòkè wá láti Babeli. Olùkọ́ tí ó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nípa òfin Mose, èyí tí Olúwa, Ọlọ́run Israẹli, ti fi fún wọn. Ọba sì fi gbogbo ohun tí ó béèrè fún un, nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára rẹ̀.
Acest Ezra s-a urcat din Babilon; şi el era un scrib iscusit în legea lui Moise, pe care DOMNUL Dumnezeul lui Israel o dăduse; şi împăratul i-a împlinit toată cererea, conform cu mâna DOMNULUI Dumnezeului său care era asupra lui.
7 Ní ọdún keje ọba Artasasta díẹ̀ lára àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà, àwọn ọmọ Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà àti àwọn tí ń ṣiṣẹ́ nínú tẹmpili náà gòkè wá sí Jerusalẹmu.
Şi s-au urcat câţiva dintre copiii lui Israel şi dintre preoţi şi leviţi şi cântăreţi şi portari şi netinimi la Ierusalim, în anul al şaptelea al lui Artaxerxes, împăratul.
8 Ní oṣù karùn-ún ọdún keje ọba yìí ni Esra dé sí Jerusalẹmu.
Şi Ezra a venit la Ierusalim în luna a cincea, care era în anul al şaptelea al împăratului.
9 Ó bẹ̀rẹ̀ ìrìnàjò rẹ̀ láti Babeli ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù kìn-ín-ní, ó sì dé Jerusalẹmu ní ọjọ́ kìn-ín-ní oṣù karùn-ún nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run rẹ̀ wà ní ara rẹ̀.
Pentru că în ziua întâi a lunii întâi a început el să se urce din Babilon şi în ziua întâi a lunii a cincea a ajuns la Ierusalim, conform cu mâna cea bună a Dumnezeului său care era asupra lui.
10 Esra ti fi ara rẹ̀ jì fún kíkọ́ àti pípa òfin Olúwa mọ́, ó sì ń kọ́ òfin àti ìlànà Mose ní Israẹli.
Fiindcă Ezra îşi pregătise inima să caute legea DOMNULUI şi să o împlinească şi să înveţe în Israel statute şi judecăţi.
11 Èyí ni ẹ̀dà lẹ́tà ti ọba Artasasta fún àlùfáà Esra olùkọ́ni, ẹni tó ní ìmọ̀ ìjìnlẹ̀ nínú àkọsílẹ̀ òfin àti ìlànà Olúwa fún Israẹli.
Acum, aceasta este copia scrisorii pe care împăratul Artaxerxes i-a dat-o lui Ezra, preotul, scribul, un scrib al cuvintelor poruncilor DOMNULUI şi al statutelor lui pentru Israel.
12 Artasasta, ọba àwọn ọba. Sí àlùfáà Esra, olùkọ́ òfin Ọlọ́run ọ̀run. Àlàáfíà.
Artaxerxes, împărat al împăraţilor, către Ezra preotul, un scrib al legii Dumnezeului cerului, pace desăvârşită în acest timp.
13 Mo pàṣẹ pé ẹnikẹ́ni nínú àwọn ọmọ Israẹli, àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi, ti ó wà ní abẹ́ ìṣàkóso ìjọba mi, tí ó bá fẹ́ láti bá ọ lọ sí Jerusalẹmu lè tẹ̀lé ọ lọ.
Dau o hotărâre, ca toţi cei din poporul lui Israel şi dintre preoţii lui şi leviţi din domeniul meu, care doresc din propria lor voinţă să urce la Ierusalim, să meargă cu tine.
14 Ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ̀ méjèèje rán ọ lọ láti wádìí nípa òfin Ọlọ́run rẹ tí ó wà ní ọwọ́ rẹ nípa Juda àti Jerusalẹmu.
Pentru că tu eşti trimis de împărat şi de cei şapte sfătuitori ai lui, să cercetezi referitor la Iuda şi Ierusalim, conform cu legea Dumnezeului tău care este în mâna ta;
15 Síwájú sí i, kí ìwọ kí ó kó fàdákà àti wúrà lọ pẹ̀lú rẹ èyí tí ọba àti àwọn ìgbìmọ̀ rẹ fi tọkàntọkàn fún Ọlọ́run Israẹli, ẹni tí ibùjókòó rẹ̀ wà ní Jerusalẹmu,
Şi să duci argintul şi aurul, pe care împăratul şi sfătuitorii lui l-au oferit de bunăvoie Dumnezeului lui Israel, a cărui locuinţă este în Ierusalim,
16 pẹ̀lú gbogbo fàdákà àti wúrà tí ìwọ lè rí ní agbègbè ìjọba Babeli àti àwọn ọrẹ àtinúwá àwọn ènìyàn àti ti àwọn àlùfáà fún tẹmpili Ọlọ́run wọn ní Jerusalẹmu.
Şi tot argintul şi aurul pe care îl poţi găsi în toată provincia Babilonului, cu darul de bunăvoie al poporului şi al preoţilor, care oferă de bunăvoie pentru casa Dumnezeului lor care este în Ierusalim;
17 Pẹ̀lú owó yìí, rí i dájú pé ó ra àwọn akọ màlúù, àwọn àgbò àti akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, pẹ̀lú ọrẹ ohun jíjẹ, àti ọrẹ ohun mímu, kí ìwọ kí ó fi wọ́n rú ẹbọ lórí pẹpẹ tẹmpili Ọlọ́run rẹ ní Jerusalẹmu.
Ca tu să cumperi repede cu aceşti bani tauri, berbeci, miei, cu darurile lor de mâncare şi darurile lor de băutură şi să le oferi pe altarul casei Dumnezeului vostru care este în Ierusalim.
18 Ìwọ àti àwọn Júù arákùnrin rẹ lè fi èyí tókù fàdákà àti wúrà ṣe ohunkóhun tí ó bá dára lójú yín, ní ìbámu pẹ̀lú ìfẹ́ Ọlọ́run yín.
Şi orice ţi se va părea bine, ţie şi fraţilor tăi, pentru a face cu restul argintului şi al aurului, aceea faceţi după voia Dumnezeului vostru.
19 Kó gbogbo ohun èlò tí a fi sí ìkáwọ́ rẹ fún Ọlọ́run Jerusalẹmu fún ìsìn nínú tẹmpili Ọlọ́run rẹ.
Vasele de asemenea care îţi sunt date pentru serviciul casei Dumnezeului tău, să le dai înaintea Dumnezeului Ierusalimului.
20 Ohunkóhun mìíràn tí o bá nílò fún tẹmpili Ọlọ́run rẹ tí ó sì ní láti pèsè, o lè mú u láti inú ìṣúra ọba.
Şi orice va mai fi nevoie pentru casa Dumnezeului tău, ce vei avea ocazia să dăruieşti, dăruieşte aceasta din casa tezaurului împăratului.
21 Èmi, ọba Artasasta, pàṣẹ fún gbogbo olùtọ́jú ilé ìṣúra agbègbè Eufurate láìrójú láti pèsè ohunkóhun tí àlùfáà Esra, olùkọ́ni ní òfin Ọlọ́run ọ̀run bá béèrè lọ́wọ́ yín
Şi eu, chiar eu, împăratul Artaxerxes, dau o hotărâre tuturor trezorierilor care sunt dincolo de râu, ca orice va cere de la voi, preotul Ezra, scribul legii Dumnezeului cerului, să fie făcut repede,
22 tó ọgọ́rùn-ún kan tálẹ́ǹtì fàdákà, ọgọ́rùn-ún kan òsùwọ̀n àlìkámà, àti dé ọgọ́rùn-ún bati ọtí wáìnì, àti dé ọgọ́rùn-ún bati òróró olifi, àti ọ̀pọ̀lọpọ̀ iyọ̀.
Până la o sută de talanţi de argint şi o sută de măsuri de grâu şi o sută de baţi de vin şi o sută de baţi de untdelemn şi sare fără să se ţină seama.
23 Ohunkóhun tí Ọlọ́run ọ̀run bá fẹ́, jẹ́ kí ó di ṣíṣe ní pípé fún tẹmpili Ọlọ́run ọ̀run. Èéṣe tí ìbínú yóò ṣe wá sí agbègbè ọba àti sí orí àwọn ọmọ rẹ̀?
Orice este poruncit de Dumnezeul cerului, să fie făcut cu hărnicie pentru casa Dumnezeului cerului, pentru că de ce să fie furie împotriva domeniului împăratului şi a fiilor săi?
24 Ìwọ sì ní láti mọ̀ pé ìwọ kò ní àṣẹ láti sọ sísan owó orí, owó òde tàbí owó bodè di dandan fún àwọn àlùfáà, àwọn Lefi, àwọn akọrin, àwọn aṣọ́nà, àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili tàbí àwọn òṣìṣẹ́ mìíràn nínú ilé Ọlọ́run yìí.
De asemenea vă facem cunoscut, că referitor la oricare dintre preoţi şi leviţi, cântăreţi, portari, netinimi, sau servitori ai acestei case a lui Dumnezeu, nu va fi legiuit să impuneţi taxă, tribut sau vamă asupra lor.
25 Ìwọ Esra, ní ìbámu pẹ̀lú ọgbọ́n Ọlọ́run rẹ̀, èyí tí ó ní, yan àwọn adájọ́ àgbà àti àwọn onídàájọ́ láti máa ṣe ìdájọ́ fún àwọn ènìyàn agbègbè Eufurate, gbogbo àwọn tí ó mọ òfin Ọlọ́run rẹ. Ìwọ yóò sì kọ́ ẹnikẹ́ni tí kò mọ̀ àwọn òfin náà.
Şi tu, Ezra, după înţelepciunea Dumnezeului tău, care este în mâna ta, pune magistraţi şi judecători, care să judece tot poporul care este dincolo de râu, pe toţi cei care cunosc legile Dumnezeului tău; şi învăţaţi pe cei care nu le cunosc.
26 Ẹnikẹ́ni tí kò bá ṣe ìgbọ́ràn sí òfin Ọlọ́run rẹ àti sí òfin ọba ní ó gbọdọ̀ kú tàbí kí a lé e jáde tàbí kí a gbẹ́sẹ̀ lé ẹrù rẹ̀ tàbí kí a sọ ọ́ sínú ẹ̀wọ̀n.
Şi oricine nu va împlini legea Dumnezeului tău şi legea împăratului, judecata să fie executată repede asupra lui, fie spre moarte, sau spre alungare, sau spre confiscarea bunurilor, sau spre închisoare.
27 Olùbùkún ni Olúwa, Ọlọ́run àwọn baba wa, ẹni tí ó fi sí ọkàn ọba láti mú ọlá wá sí ilé Olúwa ní Jerusalẹmu ní ọ̀nà yìí.
Binecuvântat fie DOMNUL Dumnezeul părinţilor noştri, care a pus un astfel de lucru ca acesta în inima împăratului, pentru a înfrumuseţa casa DOMNULUI care este în Ierusalim;
28 Ẹni tí ó jẹ́ kí ojúrere rẹ̀ tàn kàn mí níwájú ọba àti àwọn olùbádámọ̀ràn àti ní iwájú àwọn alágbára ìjòyè ọba. Nítorí ọwọ́ Olúwa Ọlọ́run wà lára mi, mo mú ọkàn le, mo sì kó àwọn olórí jọ láàrín àwọn ènìyàn Israẹli láti gòkè lọ pẹ̀lú mi.
Şi şi-a întins mila asupra mea înaintea împăratului şi a sfătuitorilor lui şi înaintea tuturor prinţilor puternici ai împăratului. Şi eu am fost întărit când mâna DOMNULUI Dumnezeului meu era peste mine şi am adunat din Israel bărbaţi de seamă să se urce cu mine.

< Ezra 7 >