< Ezra 6 >

1 Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
Nake Mũthamaki Dario akĩruta watho, naguo ũhoro ũcio ũgĩtuĩrio nyũmba-inĩ ĩrĩa yaigĩtwo mabuku ma maũndũ ma tene marĩa maigĩtwo nyũmba ya kĩgĩĩna kũu Babuloni.
2 A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀. Ìwé ìrántí.
Ibuku rĩa gĩkũnjo rĩkĩoneka kũu nyũmba-inĩ ya ũthamaki ya Ekibatana, bũrũri-inĩ wa Media. Narĩo rĩandĩkĩtwo ta ũũ: Ũhoro wa Kũririkanania:
3 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu. Jẹ́ kí a tún tẹmpili ibi tí a ti ń rú onírúurú ẹbọ kọ́, kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ ni gíga àti fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ àádọ́rùn-ún ẹsẹ̀ bàtà,
Mwaka wa mbere wa Mũthamaki Kurusu, mũthamaki nĩathanire ũhoro ũkoniĩ hekarũ ya Ngai kũu Jerusalemu, akiuga atĩrĩ: Hekarũ nĩyakwo rĩngĩ ĩrĩ handũ ha kũrutagĩrwo magongona, na mĩthingi yayo yakwo. Ĩkorwo ĩrĩ mĩkono mĩrongo ĩtandatũ kũraiha na igũrũ, na mĩkono mĩrongo ĩtandatũ kwarama,
4 pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
ĩkorwo ĩrĩ na mĩhari ĩtatũ ya mahiga manene, na ũmwe wa mbaũ. Thogora ũcio ũrĩhwo kuuma kĩgĩĩna-inĩ kĩa ũthamaki.
5 Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
Ningĩ indo cia thahabu na cia betha cia nyũmba ya Ngai iria Nebukadinezaru aakuuĩte kuuma hekarũ ĩrĩa ĩrĩ Jerusalemu agĩcirehe Babuloni-rĩ, nĩicookio o kĩndũ harĩa kĩarĩ thĩinĩ wa hekarũ kũu Jerusalemu; na mũciige thĩinĩ wa nyũmba ya Ngai.
6 Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
Na rĩrĩ, wee Tatenai barũthi wa Mũrĩmo-wa-Farati, hamwe na Shetharu-Bozenai, na inyuĩ, anene a thiritũ yao, mũtigathiĩ kuo.
7 Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
Mũtikaingĩrĩre wĩra ũcio wa hekarũ ya Ngai. Barũthi wa Ayahudi na athuuri a Ayahudi nĩmarekwo maake rĩngĩ nyũmba ĩyo ya Ngai o harĩa yaakĩtwo.
8 Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí. Gbogbo ìnáwó àwọn ọkùnrin yìí ni kí ẹ san lẹ́kùnrẹ́rẹ́ lára ìṣúra ti ọba, láti ibi àkójọpọ̀ owó ìlú ti agbègbè Eufurate kí iṣẹ́ náà má bà dúró.
O na ningĩ nĩndathana ũrĩa mũgwĩkĩra athuuri aya a Ayahudi magĩaka nyũmba ĩyo ya Ngai: Mahũthĩro mothe ma andũ acio nĩ marĩhwo kuuma kĩgĩĩna-inĩ kĩa ũthamaki kĩa Mũrĩmo-wa-Farati, nĩgeetha wĩra ũyũ ndũkanarũgame.
9 Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
Kĩrĩa gĩothe kĩngĩendekana, tũtegwa, na ndũrũme, na tũtũrũme; cia kũrutwo maruta ma njino kũrĩ Ngai wa igũrũ, na ngano, na cumbĩ, na ndibei, na maguta, o ta ũrĩa ingĩĩtio nĩ athĩnjĩri-Ngai kũu Jerusalemu no nginya maheagwo o mũthenya itekwaga,
10 Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
nĩgeetha marutage magongona ma gwĩtĩkĩrĩka nĩ Ngai wa igũrũ, na mahooyagĩre kũgaacĩra kwa mũthamaki na ariũ ake.
11 Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
Ningĩ nĩndathana atĩ mũndũ o na ũrĩkũ ũngĩgarũra maandĩko macio, mũitĩrĩro ũkaarutwo nyũmba-inĩ yake na acooke oywo na igũrũ ohanĩtio naguo. Na nĩ ũndũ wa rĩhia rĩu nyũmba yake ĩgaatuuo iganjo rĩa mahuti.
12 Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run. Èmi Dariusi n pàṣẹ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mímúṣẹ láìyí ohunkóhun padà.
Ngai ũrĩa ũtũmĩte Rĩĩtwa rĩake rĩtũũre kũu aroeheria mũthamaki o wothe kana andũ arĩa mangĩgeria kũgarũra watho ũyũ kana kũharagania hekarũ ĩyo ĩrĩ Jerusalemu. Niĩ Dario nĩ niĩ ndaruta watho ũcio. Nĩwathĩkĩrwo na kĩyo.
13 Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
Ningĩ, nĩ ũndũ wa watho ũrĩa warutĩtwo nĩ Mũthamaki Dario, Tatenai barũthi wa Mũrĩmo-wa-Farati, na Shetharu-Bozenai, marĩ na athiritũ ao nĩmathĩkĩire watho ũcio na kĩyo.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
Nĩ ũndũ ũcio athuuri a Ayahudi magĩthiĩ o na mbere gwaka na kũgaacĩra makĩhunjagĩrio nĩ mũnabii Hagai, na Zekaria wa rũciaro rwa Ido. Makĩrĩkia gwaka hekarũ kũringana na rĩathani rĩa Ngai wa Isiraeli na watho wa Kurusu, na wa Dario, na wa Aritashashita, athamaki a Perisia.
15 A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
Hekarũ ĩyo yarĩkire mũthenya wa gatatũ wa mweri wa Adari, mwaka wa gatandatũ wa gũthamaka kwa Mũthamaki Dario.
16 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
Hĩndĩ ĩyo andũ a Isiraeli na athĩnjĩri-Ngai, na Alawii, na andũ arĩa angĩ maatahĩtwo, magĩkũngũĩra kwamũrwo kwa nyũmba ya Ngai marĩ na gĩkeno.
17 Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
Indo iria maarutire nĩ ũndũ wa kwamũrwo kwa nyũmba ya Ngai ciarĩ ndegwa igana rĩmwe, na ndũrũme magana meerĩ, na tũtũrũme magana mana, irĩ iruta rĩa kũhoroheria Isiraeli othe mehia mao, na thenge ikũmi na igĩrĩ, o ĩmwe kũrĩ o mũhĩrĩga wa Isiraeli.
18 Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
Nao magĩtoonyia athĩnjĩri-Ngai wĩra-inĩ kũringana na ikundi ciao, na Alawii kũringana na matuanĩra mao, nĩ ũndũ wa wĩra wa gũtungatĩra Ngai kũu Jerusalemu o ta ũrĩa kwandĩkĩtwo Ibuku-inĩ rĩa Musa.
19 Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
Mũthenya wa ikũmi na ĩna wa mweri wa mbere, andũ arĩa maatahĩtwo magĩkũngũĩra Gĩathĩ gĩa Bathaka.
20 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
Athĩnjĩri-Ngai na Alawii nĩmetheretie na othe maarĩ atheru. Alawii nĩo maathĩnjire gatũrũme ka Bathaka, nĩ ũndũ wa arĩa othe maatahĩtwo, na nĩ ũndũ wa ariũ a ithe wao athĩnjĩri-Ngai, o na nĩ ũndũ wao ene.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
Nĩ ũndũ ũcio andũ a Isiraeli arĩa maacookete kuuma kũrĩa maatahĩirwo makĩrĩa Bathaka ĩyo, hamwe na arĩa othe meyamũranĩtie na mĩtugo ya thaahu ya ndũrĩrĩ iria mariganĩtie nacio nĩgeetha marongorie Jehova Ngai wa Isiraeli.
22 Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
Nĩmakũngũĩire Gĩathĩ kĩa Mĩgate ĩtarĩ Mĩĩkĩre Ndawa ya Kũimbia marĩ na gĩkeno ihinda rĩa mĩthenya mũgwanja, tondũ Jehova nĩamaiyũrĩtie gĩkeno nĩ ũndũ wa kũgarũra meciiria ma mũthamaki wa Ashuri, nake akĩmateithia wĩra-inĩ wa gwaka nyũmba ya Ngai, o we Ngai wa Isiraeli.

< Ezra 6 >