< Ezra 6 >

1 Nígbà náà ni ọba Dariusi pàṣẹ, wọ́n sì wá inú ilé ìfí nǹkan pamọ́ sí ní ilé ìṣúra ní Babeli.
Thanne kyng Darius comaundide, and thei rekenyden in the biblet of bokis, that weren kept in Babiloyne.
2 A rí ìwé kíká kan ní Ekbatana ibi kíkó ìwé sí ní ilé olódi agbègbè Media, wọ̀nyí ni ohun tí a kọ sínú rẹ̀. Ìwé ìrántí.
And o book was foundun in Egbatanys, which is a castel in the prouynce of Medena, and sich a sentence of the kyng was writun therynne.
3 Ní ọdún kìn-ín-ní ìjọba ọba Kirusi, ọba pa àṣẹ kan nípa tẹmpili Ọlọ́run ní Jerusalẹmu. Jẹ́ kí a tún tẹmpili ibi tí a ti ń rú onírúurú ẹbọ kọ́, kí a fi ìpìlẹ̀ rẹ̀ lélẹ̀ ni gíga àti fífẹ̀ rẹ̀ jẹ́ àádọ́rùn-ún ẹsẹ̀ bàtà,
In the first yeer of kyng Cirus, Cirus the kyng demyde, that, `Goddis hows, which is in Jerusalem, schulde be bildid in the place where thei offren sacrifices, and that thei sette foundementis supportynge the heiythe of sixti cubitis, and the lengthe of sixti cubitis, thre ordris of stonys vnpolischid,
4 pẹ̀lú ipele òkúta ńlá ńlá mẹ́ta ọ̀tọ̀ọ̀tọ̀ àti ipele pákó kan, kí a san owó rẹ̀ láti inú ilé ìṣúra ọba.
and so ordris of newe trees. Sotheli costis schulen be youun of the kyngis hows.
5 Sì jẹ́ kí wúrà àti àwọn ohun èlò fàdákà ti ilé Ọlọ́run, tí Nebukadnessari kó láti ilé Olúwa ní Jerusalẹmu tí ó sì kó lọ sí Babeli, di dídápadà sí ààyè wọn nínú tẹmpili ní Jerusalẹmu; kí a kó wọn sí inú ilé Ọlọ́run.
But also the goldun and siluerne vessels of Goddis temple, whiche Nabugodonosor took fro the temple of Jerusalem, and brouyte tho in to Babiloyne, be yoldun, and borun ayen in to the temple of Jerusalem, and in to her place, whiche also be set in the temple of God.
6 Nítorí náà, kí ìwọ, Tatenai baálẹ̀ agbègbè Eufurate àti Ṣetar-bosnai àti àwọn ẹlẹgbẹ́ yín, àwọn ìjòyè ti agbègbè náà kúrò níbẹ̀.
Now therfor Tathannai, duyk of the cuntrei which is biyende the flood, and Starbusannai, and youre counseleris, Arphasacei, that ben byyende the flood, departe ye fer fro hem;
7 Ẹ fi iṣẹ́ ilé Ọlọ́run yìí lọ́rùn sílẹ̀ láì dí i lọ́wọ́. Ẹ jẹ́ kí baálẹ̀ àwọn Júù àti àwọn àgbàgbà Júù tún ilé Ọlọ́run yín kọ́ sí ipò rẹ̀.
and suffre ye, that thilke temple of God be maad of the duyk of Jewis, and of the eldre men of hem; and that thei bilde that hows of God in his place.
8 Síwájú sí i, mo pàṣẹ ohun tí ẹ gbọdọ̀ ṣe fún àwọn àgbàgbà Júù wọ̀nyí lórí kíkọ́ ilé Ọlọ́run yìí. Gbogbo ìnáwó àwọn ọkùnrin yìí ni kí ẹ san lẹ́kùnrẹ́rẹ́ lára ìṣúra ti ọba, láti ibi àkójọpọ̀ owó ìlú ti agbègbè Eufurate kí iṣẹ́ náà má bà dúró.
But also it is comaundid of me, that that bihoueth to be maad of tho preestis of Jewys, that the hows of God be bildid, that is, that costis be youun bisili to tho men of the arke of the kyng, that is, of tributis, that ben youun of the contrei biyende the flood, lest the werk be lettid.
9 Ohunkóhun tí wọ́n bá fẹ́—àwọn ọ̀dọ́ akọ màlúù, àwọn àgbò, ọ̀dọ́-àgùntàn fún ẹbọ sísun sí Ọlọ́run ọ̀run, àti jéró, iyọ̀, wáìnì àti òróró, bí àwọn àlùfáà ní Jerusalẹmu ti béèrè ni ẹ gbọdọ̀ fún wọn lójoojúmọ́ láìyẹ̀.
That if it be nede, yyue thei bothe calues, and lambren, and kidis in to brent sacrifice to God of heuene; wheete, salt, and wyn, and oile, bi the custom of preestis that ben in Jerusalem, be youun to hem bi ech dai, that no pleynt be in ony thing.
10 Kí wọn lè rú àwọn ẹbọ tí ó tẹ́ Ọlọ́run ọ̀run lọ́rùn kí wọ́n sì gbàdúrà fún àlàáfíà ọba àti àwọn ọmọ rẹ̀.
And offre thei offryngis to God of heuene; and preye thei for the lijf of the kyng and of hise sones.
11 Síwájú sí i, mo pàṣẹ pé tí ẹnikẹ́ni bá yí àṣẹ yìí padà, kí fa igi àjà ilé rẹ̀ yọ jáde, kí a sì gbe dúró, kí a sì fi òun náà kọ́ sí orí rẹ̀ kí ó wo ilé rẹ̀ palẹ̀ a ó sì sọ ọ́ di ààtàn.
Therfor the sentence is set of me, that if ony man chaungith this comaundement, a tre be takun of his hows, and be reisid, and be he hangid therynne; sotheli his hows be forfetid.
12 Kí Ọlọ́run, tí ó ti jẹ́ kí orúkọ rẹ̀ máa gbé ibẹ̀, kí ó pa gbogbo ọba àti orílẹ̀-èdè rún tí ó bá gbé ọwọ́ sókè láti yí àṣẹ yìí padà tàbí láti wó tẹmpili yìí tí ó wà ní Jerusalẹmu run. Èmi Dariusi n pàṣẹ rẹ̀, jẹ́ kí ó di mímúṣẹ láìyí ohunkóhun padà.
Forsothe God, that makith his name to dwelle there, distrie alle rewmes and puple, that holdith forth her hond to impugne and destrie thilke hows of God, which is in Jerusalem. I Darius haue demyd the sentence, which Y wole be fillid diligentli.
13 Nígbà náà, nítorí àṣẹ tí ọba Dariusi pa, Tatenai, baálẹ̀ ti agbègbè Eufurate, àti Ṣetar-bosnai pẹ̀lú àwọn ẹlẹgbẹ́ wọn pa á mọ́ láìyí ọ̀kan padà.
Therfor Tathannai, duyk of the `cuntrei biyende the flood, and Starbusannai, and hise counseleris, diden execucioun, `ether filliden, so diligentli, bi that that kyng Darius hadde comaundid.
14 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn àgbàgbà Júù tẹ̀síwájú wọ́n sì ń gbèrú sí i lábẹ́ ìwàásù wòlíì Hagai àti wòlíì Sekariah, ìran Iddo. Wọ́n parí kíkọ́ ilé Olúwa gẹ́gẹ́ bí àṣẹ tí Ọlọ́run Israẹli àti àwọn àṣẹ Kirusi, Dariusi àti Artasasta àwọn ọba Persia pọ̀.
Sotheli the eldre men of Jewis bildiden, and hadden prosperite, bi the profesie of Aggey, the profete, and of Zacarie, the sone of Ado; and thei bildiden, and maden, for God of Israel comaundide, and for Cirus, and Darius, and Artaxerses, kyngis of Persis, comaundiden;
15 A parí ilé Olúwa ní ọjọ́ kẹta, oṣù Addari tí í se oṣù kejì ní ọdún kẹfà ti ìjọba ọba Dariusi.
and thei performyden this hows of God `til to the thridde dai of the monethe Adar, which is the sixte yeer of the rewme of king Darius.
16 Nígbà náà ni àwọn ènìyàn Israẹli—àwọn àlùfáà, àwọn Lefi àti àwọn ìgbèkùn tí ó padà, ṣe ayẹyẹ yíya ilé Ọlọ́run sí mímọ́ pẹ̀lú ayọ̀.
Forsothe the sones of Israel, the preestis and dekenes, and the othere of the sones of transmygracioun, `that is, that camen fro transmigracioun, `ether caitifte, maden the halewyng of Goddis hows in ioie;
17 Fún yíya ilé Ọlọ́run yìí sí mímọ́, wọ́n pa ọgọ́rùn-ún akọ màlúù, igba àgbò àti irinwó akọ ọ̀dọ́-àgùntàn, àti gẹ́gẹ́ bí ọrẹ ẹ̀ṣẹ̀ fún gbogbo Israẹli, àgbò méjìlá, ọ̀kọ̀ọ̀kan fún olúkúlùkù àwọn ẹ̀yà Israẹli.
and offriden, `in the halewyng of Goddis hows, an hundrid caluys, twei hundryd wetheris, foure hundrid lambren, twelue buckis of geet for the synne of al Israel, bi the noumbre of lynagis of Israel.
18 Wọ́n sì fi àwọn àlùfáà sí àwọn ìpín wọ́n àti àwọn Lefi sì ẹgbẹẹgbẹ́ wọn fún ìsin ti Ọlọ́run ní Jerusalẹmu, gẹ́gẹ́ bí ohun tí a kọ sínú ìwé Mose.
And thei ordeyneden preestis in her ordris, and dekenes in her whilis, on the werkis of God in Jerusalem, as it is writun in the book of Moises.
19 Ní ọjọ́ kẹrìnlá ti oṣù Nisani, àwọn tí a kó ní ìgbèkùn ṣe ayẹyẹ àjọ ìrékọjá.
Forsothe the sones of transmygracioun maden pask, in the fourtenthe dai of the firste monethe.
20 Àwọn àlùfáà àti àwọn ará Lefi ti ya ara wọn sí mímọ́, wọ́n sì jẹ́ mímọ́. Àwọn ará Lefi pa ọ̀dọ́-àgùntàn ti àjọ ìrékọjá fún gbogbo àwọn tí a kó ní ìgbèkùn, fún àwọn àlùfáà arákùnrin wọn àti fún ara wọn.
For the preestis and dekenes as o man weren clensid, alle weren clene for to offre pask to alle the sones of transmygracioun, and to her britheren preestis, and to hem silf.
21 Bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Israẹli tí ó ti dé láti ìgbèkùn jẹ ẹ́ lápapọ̀ pẹ̀lú gbogbo àwọn tí ó ti ya ara wọn kúrò nínú gbogbo iṣẹ́ àìmọ́ ti àwọn kèfèrí aládùúgbò wọn láti wá Olúwa Ọlọ́run Israẹli.
And the sones of Israel eeten, that turneden ayen fro transmygracioun, and ech man eet, that hadde departid hym silf fro al the defoulyng of hethene men of the lond, for to seke the Lord God of Israel.
22 Fún ọjọ́ méje, wọ́n ṣe ayẹyẹ àkàrà àìwú pẹ̀lú àjẹtì àkàrà. Nítorí tí Olúwa ti kún wọn pẹ̀lú ayọ̀ nípa yíyí ọkàn ọba Asiria padà, tí ó fi ràn wọ́n lọ́wọ́ lórí iṣẹ́ ilé Ọlọ́run, Ọlọ́run Israẹli.
And thei maden solempnyte of therf looues seuene daies in gladnesse; for the Lord hadde maad hem glad, and hadde turned the herte of the kyng of Assur to hem, that he wolde helpe `her hondis in the werk of the hows of the Lord God of Israel.

< Ezra 6 >