< Ezra 8 >

1 Wọ̀nyí ni àwọn olórí ìdílé àti àwọn tí ó fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú àwọn tì wọn gòkè pẹ̀lú mi láti Babeli ní àkókò ìjọba Artasasta ọba:
Therfor these ben the princes of meynees, and this is the genologie of hem, whiche beynge in the rewme of Artaxerses, kyng, stieden with me fro Babiloyne.
2 nínú àwọn ọmọ Finehasi: Gerṣomu; nínú àwọn ọmọ Itamari: Daniẹli; nínú àwọn ọmọ Dafidi: Hattusi,
Of the sones of Phynees, Gerson; of the sones of Ythamar, Danyel; of the sones of Dauid, Arcus;
3 nínú àwọn ọmọ Ṣekaniah; nínú àwọn ọmọ Paroṣi: Sekariah, àti pé àádọ́jọ ọkùnrin fi orúkọ sílẹ̀ pẹ̀lú rẹ;
of the sones of Sechemye and of the sones of Pharos, Zacarie, and with hym weren noumbrid an hundrid and fifti men;
4 nínú àwọn ọmọ Pahati-Moabu: Elihoenai ọmọ Serahiah àti àwọn igba ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
of the sones of Phet, Moab, and Elioneay, the sone of Zacharie, and with hym two hundrid men;
5 nínú àwọn ọmọ Sattu: Ṣekaniah ọmọ Jahasieli àti àwọn ọ̀ọ́dúnrún ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
of the sones of Sechemye, the sone of Ezechiel, and with hym thre hundrid men;
6 nínú àwọn ọmọ Adini: Ebedi ọmọ Jonatani, àti àádọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
of the sones of Addam, Nabeth, the sone of Jonathan, and with hym fifti men;
7 nínú àwọn ọmọ Elamu: Jeṣaiah ọmọ Ataliah àwọn àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
of the sones of Elam, Ysaie, the sone of Italie, and with him seuenti men;
8 nínú àwọn ọmọ Ṣefatia: Sebadiah ọmọ Mikaeli, àti ọgọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
of the sones of Saphacie, Zebedie, the sone of Mycael, and with him fourescore men;
9 nínú àwọn ọmọ Joabu: Obadiah ọmọ Jehieli àti ogún ó lé nígba ó dín méjì ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
of the sones of Joab, Obedie, the sone of Jehiel, and with him two hundrid and eiytene men;
10 nínú àwọn ọmọ Bani: Ṣelomiti ọmọ Josafiah, àti ọgọ́jọ ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
of the sones of Salomyth, the sone of Josphie, and with hym an hundrid and sixti men; of the sones of Belbai,
11 nínú àwọn ọmọ Bebai: Sekariah ọmọ Bebai àti ọkùnrin méjìdínlọ́gbọ̀n pẹ̀lú rẹ̀;
Zacarie, the sone of Belbai, and with hym twenti and eiyte men;
12 nínú àwọn ọmọ Asgadi: Johanani ọmọ Hakatani, àti àádọ́fà ọkùnrin pẹ̀lú rẹ̀;
of the sones of Ezead, Johannam, the sone of Ezethan, and with hym an hundrid and ten men;
13 nínú àwọn ọmọ Adonikami: àwọn ti ó gbẹ̀yìn, tì orúkọ wọn ń jẹ́ Elifaleti, Jeieli àti Ṣemaiah, àti ọgọ́ta ọkùnrin pẹ̀lú wọn;
of the sones of Adonycam, that weren the laste, and these ben the names of hem, Eliphelech, and Eihel, and Samaie, and with hem weren sexti men;
14 nínú àwọn ọmọ Bigfai: Uttai àti Sakkuri, àti àádọ́rin ọkùnrin pẹ̀lú wọn.
of the sones of Beguy, Vtai, and Zaccur, and with hem weren seuenti men.
15 Èmi kó wọn jọ pọ̀ si etí odò ti ń sàn lọ sí Ahafa, a pàgọ́ síbẹ̀ fún odidi ọjọ́ mẹ́ta, nígbà ti mo wo àárín àwọn ènìyàn àti àárín àwọn àlùfáà, ń kò rí ọmọ Lefi kankan níbẹ̀.
Forsothe Y gaderide hem togidere at the flood, that renneth doun to Hanna; and we dwelliden there thre daies. And `Y souyte in the puple, and in the prestis of the sonus of Leuy, and Y fonde not there.
16 Nígbà náà ni mo pe Elieseri, Arieli, Ṣemaiah, Elnatani, Jaribi, Elnatani, Natani, Sekariah, àti Meṣullamu, tí wọ́n jẹ́ olórí, àti Joiaribu àti Elnatani tí wọ́n jẹ́ onímọ̀ ìjìnlẹ̀,
Therfor Y sente Eliezer, and Ariehel, and Semeam, and Helnathan, and Jaubeth, and an other Helnathan, and Nathan, and Zacharie, and Mesollam, princes; and Joarib, and Elnathan, wise men;
17 mo sì rán wọn tí àwọn ti àṣẹ sí ọ̀dọ̀ Iddo, tí ó jẹ́ olórí ní ibi ti a ń pè ni Kasifia, mo sì sọ fún wọn ohun tí wọn yóò wí fun Iddo àti àwọn Lefi arákùnrin rẹ̀, tí wọ́n jẹ́ òṣìṣẹ́ tẹmpili ní Kasifia pé, kí wọn mú àwọn ìránṣẹ́ wá sí ọ̀dọ̀ wa fún ilé Ọlọ́run wa.
and Y sente hem to Heldo, which is `the firste in the place of Casphie, and Y puttide in the mouth of hem wordis, whiche thei schulden speke to Heldo, and to hise britheren, Natynneis, in the place of Casphie, for to brynge to vs the mynystris of the hows of oure God.
18 Nítorí ọwọ́ àánú Ọlọ́run wa wà lára wa, wọ́n sì mú Ṣerebiah wá fún wa, ẹni tí ó kún ojú òsùwọ̀n láti ìran Mahili, ọmọ Lefi, ọmọ Israẹli, àti àwọn ọmọ Ṣerebiah àti àwọn arákùnrin rẹ̀, wọ́n jẹ́ ọkùnrin méjìdínlógún.
And `thei brouyten to vs, bi the good hoond of oure God on vs, a ful wijs man of the sones of Mooli, the sone of Leuy, sone of Israel; and Sarabie, and his sones twenti, and his britheren eiytene;
19 Àti Haṣabiah, pẹ̀lú Jeṣaiah láti ìran Merari, pẹ̀lú àwọn arákùnrin rẹ àti àwọn ọmọ wọ́n jẹ́ ogún ọkùnrin.
and Azabie, and Isaie, with him of the sones of Merari, thei brouyten his britheren, and his sones, twenti;
20 Wọ́n sì tún mú ogún lé nígba àwọn òṣìṣẹ́ tẹmpili wá—àwọn ènìyàn tí Dafidi àti àwọn ìjòyè rẹ̀ gbé kalẹ̀ láti ran àwọn ọmọ Lefi lọ́wọ́. Gbogbo wọn ni a ṣe àkọsílẹ̀ orúkọ wọn.
and of Nathynneis, whiche Dauid and the princis hadden youe to the seruyces of dekenes, thei brouyten two hundrid and twenti Nathynneis; alle these weren clepid bi her names.
21 Níbẹ̀, ní ẹ̀bá odò Ahafa, mo kéde àwẹ̀, kí a ba à le rẹ ara wa sílẹ̀ níwájú Ọlọ́run, kí a sì béèrè lọ́wọ́ rẹ̀ fún ìrìnàjò àìléwu fún wa àti àwọn ọmọ wa àti fún gbogbo ohun ìní wa.
And `Y prechide there fastyng bisidis the flood of Hanna, that we schulden be turmentid bifor `oure Lord God, and that we schulden axe of him the riytful weie to vs, and to oure sones, and to al oure catel.
22 Mo tijú láti béèrè lọ́wọ́ ọba fún àwọn jagunjagun orí ilẹ̀, àti ti orí ẹṣin láti dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá ní ọ̀nà wa, nítorí àti sọ fún ọba pé, “Ọwọ́ àánú Ọlọ́run wà ní ara gbogbo ẹni tí ó gbé ojú sókè sí i, ṣùgbọ́n ìbínú ńlá rẹ wà lórí ẹni tó kọ̀ ọ́ sílẹ̀.”
For Y schamede to axe of the kyng help, and horse men, that schulden defende vs fro enemyes in the weie, for we hadden seid to the king, The hond of oure God is on alle men that seken hym in goodnesse; and his lordschip, and his strengthe, and strong veniaunce ben on alle men that forsaken hym.
23 Bẹ́ẹ̀ ni a sì gbààwẹ̀, a sì bẹ̀bẹ̀ fún èyí lọ́dọ̀ Ọlọ́run wa, òun sì gbọ́ àdúrà wa.
Forsothe we fastiden, and preieden oure God for this thing, and it bifelde to vs `bi prosperite.
24 Nígbà náà ni mo ya àwọn àlùfáà tó jẹ́ aṣáájú méjìlá sọ́tọ̀, pẹ̀lú Ṣerebiah, Haṣabiah àti mẹ́wàá lára àwọn arákùnrin wọn,
And `Y departide twelue of the princes of prestis, Sarabie, and Asabie, and ten of her britheren with hem;
25 mo sì fi òsùwọ̀n wọn ọrẹ fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò tí ọba, àti ti àwọn ìgbìmọ̀, àti ti àwọn ìjòyè, àti ti gbogbo ọmọ Israẹli tí ó wà níbẹ̀, tí wọ́n gbe sílẹ̀ fún ilé Ọlọ́run wa.
and Y bitook vndur certeyn weiyte and noumbre to hem the siluer and gold, and the halewid vessels of the hows of oure God, whiche the kyng hadde offrid, and hise counseleris, and hise princes, and `al Israel, of hem that weren foundun.
26 Mo fi òsùwọ̀n wọn ẹgbẹ̀ta lé láàádọ́ta tálẹ́ǹtì fàdákà, àti ohun èlò fàdákà tí ó wọn ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì, ọgọ́rùn-ún tálẹ́ǹtì wúrà,
And Y bitook vndur certeyn weiyte and noumbre in the hondis of hem sixe hundrid and fifti talentis of siluer, and an hundrid siluerne vessels; an hundrid talentis of gold,
27 ogún ago wúrà tí iye rẹ̀ tó ẹgbẹ̀rún dariki, àti ohun èlò idẹ dáradára méjì ti ó ni iye lórí bí i wúrà.
and twenti goldun cuppis, that hadden a thousynde peesis of gold; and twei faire vessels of best bras, schynynge as gold.
28 Mo wí fún wọn pé, “Ẹ̀yin àti àwọn ohun èlò wọ̀nyí ni a ti yà sí mímọ́ fún Olúwa. Fàdákà àti wúrà sì jẹ́ ọrẹ àtinúwá sí Olúwa Ọlọ́run àwọn baba yín.
And Y seide to hem, Ye ben the hooli men of the Lord,
29 Ẹ máa tọ́jú wọn dáradára títí ẹ̀yin yóò fi fi òsùwọ̀n wọ̀n wọ́n jáde kúrò ni ilé Olúwa ni Jerusalẹmu ní iwájú àwọn aṣáájú, àwọn àlùfáà àti àwọn ọmọ Lefi, àti ní iwájú olórí ìdílé gbogbo ni Israẹli.”
and wake ye, and kepe the hooli vessels, and siluer and gold, which is offrid bi fre wille to the Lord God of oure fadris, til ye yelde vndur certeyn weiyte and noumbre bifor th princes of prestis, and of dekenes, and bifor the duykis of meynees of Israel in Jerusalem, in to the tresour of Goddis hows.
30 Nígbà náà ni àwọn àlùfáà àti àwọn Lefi gba fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ́ tí a ti wọ̀n jáde fún kíkó lọ sí ilé Ọlọ́run wa ní Jerusalẹmu.
Sotheli the preestis and dekenes token the weiyte of siluer, and of gold, and of vessels, for to bere in to Jerusalem, in to the hows of oure God.
31 Ní ọjọ́ kejìlá oṣù kìn-ín-ní ni a gbéra kúrò ní ẹ̀bá odò Ahafa láti lọ sí Jerusalẹmu. Ọwọ́ Ọlọ́run wa wà lára wa, ó sì dáàbò bò wá kúrò lọ́wọ́ àwọn ọ̀tá àti àwọn adigunjalè ní ọ̀nà wa.
Therfor we mouyden forth fro the flood of Hanna, in the tweluethe dai of the firste monethe, for to go in to Jerusalem; and the hond of oure God was on vs, and delyuerde vs fro the hond of enemye and of aspiere in the weie.
32 Bẹ́ẹ̀ ni a gúnlẹ̀ sí Jerusalẹmu, níbi tí a ti sinmi fún ọjọ́ mẹ́ta.
And we camen to Jerusalem, and we dwelliden there thre daies.
33 Ní ọjọ́ kẹrin, a wọn ohun èlò fàdákà àti wúrà àti àwọn ohun èlò mímọ lé àlùfáà Meremoti ọmọ Uriah lọ́wọ́, láti inú ilé Ọlọ́run wa, Eleasari ọmọ Finehasi wà pẹ̀lú rẹ̀, bẹ́ẹ̀ ni àwọn ọmọ Lefi; Josabadi ọmọ Jeṣua àti Noadiah ọmọ Binnui wà níbẹ̀ pẹ̀lú.
Forsothe in the fourthe dai the siluer was yoldun vndur certeyn weiyte and noumbre, and the gold, and the vessels, `in the hows of oure God, by the noumbre and weiyte of alle thingis, bi the hond of Remmoth, `sone of Vrie, preest; and with him was Eleazar, the sone of Phynees, and with him weren Jozaded, the sone of Josue, and Noadaie, the sone of Bennoy, dekenes;
34 Gbogbo nǹkan ni a kà, tí a sì wọ̀n, gbogbo iye ìwọ̀n ni a sì ṣe àkọsílẹ̀ rẹ̀ sínú ìwé ní ìgbà náà.
and al the weiyte was discriued in that tyme.
35 Nígbà náà ni àwọn ìgbèkùn tí ó ti padà láti ilẹ̀ àjèjì rú ẹbọ sísun sí Ọlọ́run Israẹli: akọ màlúù méjìlá fún gbogbo Israẹli, àgbò mẹ́rìndínlọ́gọ́rùn-ún, ọ̀dọ́-àgùntàn mẹ́tàdínlọ́gọ́rin, àti òbúkọ méjìlá fún ẹbọ ẹ̀ṣẹ̀. Gbogbo èyí jẹ́ ẹbọ sísun sí Olúwa.
But also the sones of transmygracioun, that camen fro caitifte, offriden brent sacrifices to the Lord God of Israel, `twelue calues for al the puple of Israel, nynti and sixe rammes, seuene and seuenti lambren, twelue buckis of geet for synne; alle thingis in to brent sacrifice to the Lord.
36 Wọ́n sì jíṣẹ́ àṣẹ ọba fún àwọn ìjòyè àti àwọn baálẹ̀ agbègbè Eufurate, wọ́n sì ṣe ìrànlọ́wọ́ fún àwọn ènìyàn àti ilé Ọlọ́run.
Forsothe thei yauen the comaundementis of the kyng to the princes, that weren of the siyt of the king, and to the duykis biyende the flood; and thei reisiden the puple, and the hows of God.

< Ezra 8 >